< Ezechiela 24 >

1 I stało się słowo Pańskie do mnie roku dziewiątego, miesiąc dziesiątego, dziesiątego dnia tegoż miesiąca, mówiąc:
Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Synu człowieczy! napisz sobię imię dnia tego, tegoż właśnie dnia; bo obległ król Babiloński Jeruzalem prawie tegoż dnia.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
3 A rzecz przez przypowieść do tego domu odpornego, podobieństwo mówiąc do nich: Tak mówi panujący Pan: Przystaw ten garniec, przystaw, a nalej weń wody;
Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
4 A zebrawszy sztuki należące do niego, każdą sztukę dobrą, udziec i łopatkę, najlepszemi kościami napełń go.
Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
5 Weźmijże i co najwyborniejsze bydlę, a nałóż ogień z kości pod niem; sprawże aby to wrzało i kipiało, żeby i kości jego rozewrzały w niem.
mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
6 Przetoż tak mówi panujący Pan: Biada temu miastu krwawemu, garncowi, w którym zostaje przywara jego, z którego, mówię, przywara jego nie wychodzi: po sztukach, po sztukach wyciągaj z niego, nie padnieć nań los.
Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
7 Bo iż krew jego jest w pośrodku jego, na wierzchu skały wystawiło ją, nie wylało jej na ziemię, aby była zakryta prochem;
“‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
8 Tedy i Ja rozniecę zapalczywość na wykonanie pomsty, wystawię krew jego na wierzchu skały, aby nie była zakryta.
Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
9 Przetoż tak mówi panujący Pan: Biada temu miastu krwawemu; bo i Ja naniecę wielki ogień,
Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
10 Przykładając drew, rozniecając ogień, wniwecz obracając mięso, i zaprawiając korzeniem, tak, że i kości spalone będą;
Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
11 A postawię ten garniec na węgle jego próżny, aby się zagrzała i rozpaliła miedź jego, a żeby się rozpłynęły w pośród jego plugastwa jego, a iżby zniesiona była przywara jego.
Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
12 Utrudziło mię kłamstwami swemi, przetoż nie wynijdzie z niego wielkość szumowin jego, do ognia muszą szumowiny jego.
Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
13 W nieczystości twojej jest sprosność; dlatego, żem cię oczyszczał; a przecięś nie oczyszczona, i od nieczystości twojej nie będziesz więcej oczyszczana, aż uspokoję na tobie rozgniewanie moje.
“‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
14 Ja Pan mówiłem; przyjdzie to, i uczynię to, nie cofnę się, ani sfolguję, ani mi żal będzie; według dróg twoich, i według spraw twoich sądzić cię będę, mówi panujący Pan.
“‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
16 Synu człowieczy! oto Ja od ciebie odejmę żądność oczów twoich z prędka; wszakże nie kwil, ani płacz, a niech nie wychodzą łzy twoje.
“Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
17 Zaniechaj kwilenia, nie czyń żałoby, jako bywa nad umarłym; czapkę twoję włóż na się, a obuwie twoje wzuj na nogi twoje, a nie zasłaniaj warg, a chleba niczyjego nie jedz.
Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
18 Co gdym z poranku ludowi powiedział, tedy umarła żona moja w wieczór; i uczyniłem rano, jako mi rozkazano.
Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
19 I mówił lud do mnie: I nie oznajmiszże nam, co nam te rzeczy znaczą, które ty czynisz?
Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
20 Tedym rzekł do nich: Słowo Pańskie stało się do mnie, mówiąc:
Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
21 Powiedz domowi Izraelskiemu: Tak mówi panujący Pan: Oto Ja splugawię świątnicę moję, wyniosłość mocy waszej, żądność oczów waszych, i to, w czem się kocha dusza wasza, a synowie wasi i córki wasze, któreście zostawili, od miecza polegną.
Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
22 I uczynicie, jakom uczynił; nie zasłonicie wargi, a chleba niczyjego jeść nie będziecie;
Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
23 A czapki swe na głowach swych, i bóty swoje na nogach swoich mając, nie będziecie kwilić ani płakać; ale będziecie schnąć dla nieprawosci waszych, a wzdychać jeden z drugim.
Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
24 Bo wam jest Ezechyjel dziwem, według wszystkiego, co on czyni, czynić będziecie; a gdy to przyjdzie, dowiecie się, żem ja panujący Pan.
Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
25 A ty, synu człowieczy! azaż w ten dzień, którego Ja odejmę od nich moc ich, wesele ozdoby ich, żądność oczów ich, i to, po czem tęskni dusza ich, synów ich i córki ich,
“Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
26 Izali dnia onego nie przyjdzie do ciebie ten, co uciecze, oznajmując ci to?
ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
27 Dnia onego otworza się usta twoje przy tym, który ujdzie; a będziesz mówił, i nie będziesz więcej niemym; i będziesz im dziwem, a poznają, żem Ja Pan.
Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”

< Ezechiela 24 >