< Ezechiela 22 >

1 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 A ty, synu człowieczy! izalibyś się zastawiał, izalibyś się zastawiał za to miasto krwi? Raczej mu oznajmij wszystkie obrzydliwości jego.
“Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
3 I rzecz: Tak mówi panujący Pan: O miasto, które wylejesz krew w pośrodku siebie; a czynisz plugwe bałwany samo przeciwko sobie, abyś się splugawiło, przychodzić czas twój.
Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
4 Tyś wylaniem krwi twojej zgrzeszyło, i plugawemi bałwanami swemi, którycheś naczyniło, siebieś skalało, i sprawiłoś, że się przybliżyły dni twoje, a żeś przyszło aż do lat swoich; przetoż cię podam na pohańbienie narodom, i na pośmiech wszystkim ziemiom.
Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
5 Biliskie i dalekie od ciebie będą się naśmiewać z ciebie, o miasto złej sławy i zwad pełne!
Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
6 Oto książęta Izraelscy, każdy wszystką siłą na to się udali, aby krew w tobie przelewali.
“‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
7 Ojca i matkę znieważają w tobie, przychodniowi krzywdę czynią w pośród ciebie, sierotę i wdowę uciskają w tobie.
Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
8 Świętemi rzeczami mojemi pogardzasz, a sabaty moje splugawiasz.
Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
9 Potwarcy są w tobie, aby wylewali krew; i na górach jadają w tobie, złości popełniają w pośrodku ciebie.
Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
10 Nagość ojcowską syn odkrywa w tobie, a oddalone dla nieczystości gwałcą w tobie.
Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
11 A drugi z żoną bliźniego swego czyni obrzydliwość, a inny z synową swoją sprośnie się maże; inny zaś siostrę swoję, córkę ojca swego, gwałci w tobie.
Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
12 Podarki biorą w tobie na wylewanie krwi; lichwę i płat bierzesz, a zysku szukasz z uciskiem bliźniego swego, a na mię zapominasz, mówi panujący Pan.
Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
13 Przetoż otom Ja klasnął rękami swemi nad zyskiem twoim, którego nabywasz, i nad krwią twoją, która była w pośrodku ciebie.
“‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
14 Izali wytrzyma serce twoje? izali zdołają ręce twoje dniom, których Ja z tobą będę miał sprawę? Ja Pan rzekłem, i uczynię.
Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
15 Bo cię rozproszę między pogany, i rozwieję cię po ziemiach, i uprzątnę do końca nieczystość twoję z ciebie.
Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
16 I będziesz splugawione przed oczyma pogan, aż poznasz, żem Ja Pan.
Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
17 Potem się stało słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
18 Synu człowieczy, dom Izraaelski mi się obrócił w zużelicę; wszyscy zgoła są miedzią i cyną i żelazam i ołowiem w pośród pieca, zużelicą srebra się stali.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
19 Przetoż tak mówi panujący Pan: Dlatego, żeście wy się wszyscy obrócili w zużelicę, przetoż oto Ja zgromadzę was do Jeruzalemu.
Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
20 Jako zgromadzają srebro, i miedź, i żelazo, i ołów i cynę w pośród pieca, aby rozdymano ogień koło nich dla roztopienia, tak was zgromadzę w zapalczywości mojej i w gniewie moim, a złożywszy roztapiać was będę.
Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
21 Owa zgromadzę was a rozedmę około was ogień popędliwości mojej, i roztopieni będziecie w pośrodku niego.
Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
22 Jako się srebro topi w pośrodku pieca, tak się roztopicie w pośrodku niego, a dowiesie się, że Ja Pan wylałem na was popędliwość swoję.
Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
23 Nadto stało się słowo Pańskie do mnie mówiąc:
Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
24 Synu człowieczy! mów do tej ziemi: Ty ziemio nieczystaś jest, nie będziesz deszczem odwilżana w dzień zapalczywości.
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
25 Sprzysiężenie proroków jej jest w pośrodku jej; podobni są lwowi ryczącemu, obłów chwytającemu; dusze pożerają, bogactwa i drogie rzeczy zbierają, a czynią wiele wdów w pośrodku niej.
Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
26 Kapłani jej gwałcą zakon mój, i święte rzeczy moje splugawiają; między świętym i pospolitym różności nie czynią, a między nieczystym a czystym nie rozsądzają. Nadto od sabatów moich zakrywają oczy swe, tak, iż zelżony bywam między nimi.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
27 Książęta jej w pośrodku jej są jako wilki chwytające łup, wylewający krew, tracący dusze, udawający się za zyskiem.
Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
28 A prorocy ich tynkują wapnem nieczynionem, prorokując marność, a wróżąc im kłamstwo mówiąc: Tak mówi panujący Pan, choć Pan nie mówi panujący Pan: Biada temu miastu krwawemu, garncowi, w którym zostaje przywara jego, z którego, mówię, przywara jego nie wychodzi; po sztukach, po sztukach wyciągaj z niego, a padnieć nań los.
Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
29 Lud tej ziemi gwałt czyni, gwałtem biorąc, co jest cudzego; ubogiemu i nędznemu krzywdę czynią, a przychodnia bezprawnie uciskają.
Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
30 Szukałem między nimi męża, któryby płot ugrodził, i stanął w przerwie przed twarzą moją za tą ziemią, abym jej nie zburzył; alem żadnego nie znalazł.
“Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
31 Przetoż wyleję na nich gniew mój, ogniem popędliwości mojej wyniszczę ich; drogę ich na głowę ich obrócę, mówi panujący Pan.
Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ezechiela 22 >