< Ezechiela 21 >

1 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
2 Synu człowieczy! obróć twarz swoję ku Jeruzalemowi, a krop jako rosą przeciwko miejscom świętym, i prorokuj przeciwko ziemi Izraelskiej,
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
3 A powiedz ziemi Izraelskiej: Tak mówi panujący Pan: Otom Ja przeciwko tobie, i dobędę miecza mego z pochew jego, i wytnę z ciebie sprawiedliwego i niezbożnego.
Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
4 Abym tedy wyciął z ciebie sprawiedliwego, i niezbożnego, przeto wynijdzie miecz mój z pochew swoich na wszelkie ciało od południa aż ku północy.
Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
5 I dowie się wszelkie ciało, żem Ja Pan dobył miecza mego z pochew jego; a nie obróci się więcej.
Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
6 A ty, synu człowieczy! wzdychaj, jakobyś miał biodro złamane, a w gorzkości wzdychaj przed oczyma ich.
“Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
7 A gdyć rzeką: Dlaczego wzdychasz? Tedy odpowiesz: Dla wieści, która idzie, na którą się rozpłynie wszelkie serce, i osłabieją wszelkie ręce, i ściśniony będzie wszelki duch, i wszelkie kolano rozpłynie się jako woda; oto idzie, i stanie się, mówi panujący Pan.
Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
8 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
9 Synu człowieczy! prorokuj, a rzecz: Tak mówi Pan: Powiedz, miecz, miecz naostrzony jest i wypolerowany;
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
10 Wyostrzony jest na pomordowanie ku zabiciu naznaczonych, wypolerowany jest, aby się lśnił. Izali się weselić mamy? Gdyż rózga syna mego każde drzewo lekce waży.
a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
11 Dałci go na wypolerowanie, aby mógł być ujęty ręką, jestci wyostrzony ten miecz, jest i wypolerowany, aby dany był do ręki zabijającego.
“‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
12 Wołaj a kwil, synu człowieczy, przeto, że ten miecz będzie przeciwko ludowi memu, ten też przeciwko wszystkim książętom Izraelskim; strachy miecza przyjdą na lud mój; przetoż się w biodrę uderz.
Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
13 Gdym ich karał, cóż to pomogło? I nie mamże rózgi wszystko lekce poważającej na nich wyciągnąć? mówi panujący Pan.
“‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
14 Ty tedy, synu człowieczy! prorokuj, a bij ręką w rękę; bo powtóre i potrzecie miecz przyjdzie, miecz mordujących, ten miecz mordujących bez litości, przenikający aż do pokojów ich.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
15 We wszystkich bramach ich dałem strach miecza, aby się rozpłynęło serce, i upadków się namnożyło. Ach! wypolerowany jest, aby się błyszczał, a wyostrzony, aby zabijał.
Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
16 Zbierz się mieczu, udaj się na prawo i na lewo, gdziekolwiek jest chęć twarzy twojej.
Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
17 Boć i Ja uderzę ręką moją w rękę moję, i uspokoję rozgniewanie moje. Ja Pan mówiłem to.
Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
18 Wtem się stało słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
19 A ty, synu człowieczy! połóż przed sobą dwie drogi, którędyby iść miał miecz króla Babilońskiego; z jednej ziemi niech wychodzą obiedwie, a na rozdrożu obierz tę ku miastu, tę obierz.
“Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
20 Pokaż drogę, którąby miecz iść miał, czyli ku Rabbacie synów Ammonowych, czyli ku ziemi Judzkiej na Jeruzalemskie twierdze.
La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
21 Albowiem stanie król Babiloński na rozdrożu, na początku dwóch dróg, pytając się wieszczby; będzie polerował strzały, będzie się radził bałwanów, będzie patrzył na wątrobę.
Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
22 Po prawej ręce jego wieszczba ukaże Jeruzalem, aby szykował hetmanów, którzyby pobudzali do mordowania, a podnosili głos z okrzykiem, aby zasadzili tarany przeciwko bramom, aby usypali wał, a urobili szańce.
Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
23 I będą to mieli za próżną wieszczbę przed oczyma swemi ci, co się obowiązali przysięgami; a to przywiedzie na pamięć nieprawość ich, aby pojmani byli.
Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
24 Przetoż tak mówi panujący Pan: Dlatego, że na pamięć przywodzicie nieprawość swoję, a odkrywa się przestępstwo wasze, tak, że jawne są grzechy wasze we wszystkich sprawach waszych, przto, mówię, że na pamięć przychodzicie, tą ręką pojmani będziecie.
“Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
25 A ty, nieczysty bezbożniku, księciu Izraelski! którego dzień przychodzi, gdy nieprawość skończona będzie:
“‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
26 Tak mówi panujący Pan: Zdejm tę czapkę, a zrzuć tę koronę, która już nigdy takowa nie będzie; tego, który w poniżenie przyszedł, wywyższę, a wywyższonego poniżę.
èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
27 W niwecz, w niwecz, w niwecz ją obrócę, czego pierwej nie bywało, aż przyjdzie ten, co do niej ma prawo, którem mu dał.
Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
28 Ale ty, synu człowieczy! prorokuj, a mów: Tak mówi panujący Pan o synach Ammonowych i o hańbie ich; rzecz mówię: Miecz, miecz dobyty jest, ku zabijaniu wypoleroawny jest, aby wytracił wszystko, i aby się błyskał.
“Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
29 I chociaż ci opowiadają marność, i wróżą kłamstwo, aby cię przyłożyli do szyi niezbożników pobitych, których dzień przychodzi, gdy nieprawość, skończona będzie.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
30 Schowaj jednak miecz do pochew jego; na miejscu, na któremeś spłodzona, w ziemi mieszkania twego, sądzić cię będę.
“‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
31 I wyleję na cię rozgniewanie moje; ogniem popędliwości mojej na cię dmuchać będę, i podam cię w ręce ludzi zuchwałych i przemyślnych na wytracenie.
Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
32 Ogniowi potrawą będziesz, krew twoja będzie w pośrodku ziemi, nie będziesz więcej wspominana; bo Ja Pan mówiłem to.
Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”

< Ezechiela 21 >