< Ezechiela 18 >

1 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
2 Cóż wam po tem, iż używacie tej przypowieści o ziemi Izraelskiej mówiąc: Ojcowie jedli jagodę cierpką, a synów zęby drętwieją.
“Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan, eyín àwọn ọmọ sì kan.’
3 Jako żyję Ja, mówi panujący Pan, że wy nie będziecie więcej mogli używać tej przypowieści w Izraelu.
“Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli.
4 Oto dusze wszystkie moje są, jako dusza ojcowska tak i dusza synowska moje są; dusza, która grzeszy, ta umrze.
Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.
5 Bo byłliby mąż sprawiedliwy, a czyniłby sąd i sprawiedliwość,
“Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà, tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ
6 Któryby na górach nie jadał, a oczówby swych nie podnosił do plugawych bałwanów domu Izraelskiego, a żonyby bliźniego swego nie zmazał, i do niewiasty dla nieczystoty oddalonej nie przystąpił;
tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga, tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli, ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́ tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.
7 Któryby nikogo nie uciskał, zastawby dłużnikowi swemu wracał, cudzegoby gwałtem nie brał, chlebaby swego łaknącemu udzielał, a nagiegoby szatą przyodziewał;
Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀ gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un, kò fi ipá jalè ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.
8 Któryby na lichwę nie dawał, i płatuby nie brał, od nieprawościby odwracał rękę swoję, a sądby sprawiedliwy czynił między mężem a mężem;
Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá, tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù. Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.
9 Któryby w ustawach moich chodził, a sądówby moich przestrzegał, czyniąc, co jest prawego: ten sprawiedliwy pewnie żyć będzie, mówi panujący Pan.
Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo. Ó jẹ́ olódodo, yóò yè nítòótọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.
10 A gdyby spłodził syna łotra, krew wylewającego, któryby czemkolwiek z tych rzeczy bratu szkodził,
“Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀
11 A tegoby wszystkiego nie czynił, owszemby i na górach jadał, i żonęby bliźniego swego zmazał,
(tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì): “Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga, tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.
12 Ubogiegoby i nędznego uciskał, co cudzego jest, gwałtemby zabierał, zastawuby nie wracał, a do plugawych bałwanów podnosiłby oczy swoje, i obrzydliwościby czynił,
Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára, ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí, o gbójú sókè sí òrìṣà, ó sì ń ṣe ohun ìríra.
13 Na lichwęby dawał, i płat brał, izali żyć będzie? Nie będzie żył; ponieważ te wszystkie obrzydliwości czynił: śmiercią umrze, krew jego na nim będzie.
Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù. Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.
14 A oto jeżeliby spłodził syna, któryby widział wszystkie grzechy ojca swego, które czynił, a widząc nie czyniłby tak;
“Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:
15 Na górachby nie jadał, a oczówby swych nie podnosił do plugawych bałwanów domu Izraelskiego, żonyby bliźniego swego nie zmazał,
“Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli, tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
16 I nikogoby nie uciskał, zastawuby nie zatrzymywał, a cudzegoby gwałtem nie brał, chlebaby swego łaknącemu udzielał, a nagiegoby szatą przyodział,
tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, tí kò dá ohun ògo dúró tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ, tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.
17 Od nieprawegoby odwrócił rękę swoję, lichwyby i płatu nie brał, sądyby moje czynił, w ustawachby moich chodził: ten nie umrze dla nieprawości ojca swego, ale pewnie żyć będzie.
Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀, kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù, tí ó ń pa òfin mi mọ́, tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi. Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè!
18 Lecz ojciec jego, przeto, że czynił krzywdę, co jest cudzego, bratu gwałtem brał, a to, co jest dobrego, nie czynił w pośrodku ludu swego: przetoż oto umrze dla nieprawości swojej.
Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
19 Ale mówicie: Czemuż? Izali nie poniesie syn nieprawości ojcowskiej? Gdy syn sąd i sprawiedliwość czyni, wszystkich ustaw moich strzeże i czyni je, pewnie żyć będzie.
“Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè.
20 Dusza, która grzeszy, ta umrze; ale syn nie poniesie nieprawości ojcowskiej, ani ojciec poniesie nieprawości synowskiej; sprawiedliwość sprawiedliwego przy nim zostanie, a niepobożność niepobożnego nań przypadnie.
Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.
21 A jeźliby się niepobożny odwrócił od wszystkich grzechów swoich, które czynił, a strzegłby wszystkich ustaw moich, i czyniłby sąd i sprawiedliwość, pewnie żyć będzie, nie umrze;
“Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú.
22 Żadne przestępstwa jego, których się dopuścił, nie będą mu przypominane; w sprawiedliwości swej, którąby czynił, żyć będzie.
A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè.
23 Azaż Ja się kocham w śmierci niepobożnego? mrwi panujący Pan. Izali nie raczej, gdy się odwróci od dróg swoich, aby żył?
Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?
24 Ale jeźliby się odwrócił sprawiedliwy od sprawiedliwości swojej, a czyniłby nieprawość, czyniąc według wszystkich obrzydliwości, które czyni niezbożny, izali taki żyć będzie? Wszystkie sprawiedliwości jego, które czynił, nie będą wspominane; dla przestępstwa swego, które popełniał, i dla grzechu swego, którego się dopuścił, dla tych rzeczy umrze.
“Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.
25 A iż mówicie: Nie prosta jest droga Pańska; słuchajcież teraz, o domie Izraelski! izali droga moja nie jest prosta? Izali drogi wasze nie są krzywe?
“Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ ilé Israẹli. Ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún?
26 Gdyby się odwrócił sprawiedliwy od sprawiedliwości swojej, a czyniąc nieprawość w temby umarł, dla nieprawości swojej, którą czynił, umrze.
Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá.
27 Ale gdyby się odwrócił niezbożny od niezbożności swojej, której się dopuścił, a czyniłby sąd i sprawiedliwość, ten duszę swoję zachowa.
Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
28 Bo obaczywszy się odwrócił się od wszystkich występków swoich, których się dopuszczał, pewnie żyć będzie, nie umrze.
Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú.
29 A przecie mówi dom Izraelski: Nie prosta jest droga Pańska; izali drogi moje nie są proste, o domie Izraelski? Izali nie raczej drogi wasze są krzywe?
Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?
30 A przetoż każdego z was według dróg jego sądzić będę, o domie Izraelski! mówi panujący Pan. Nawróćcież się, a odwróćcie się od wszystkich występków waszych, aby wam nieprawość nie była na obrażenie.
“Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín.
31 Odrzućcie od siebie wszystkie przestępstwa wasze, którycheście się dopuszczali, a uczyńcie sobie serce nowe i ducha nowego. I przeczże macie umrzeć, o domie Izraelski?
Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli?
32 Albowiem się Ja nie kocham w śmierci umierającego, mówi panujący Pan; nawróćcież się tedy, a żyć będziecie.
Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!

< Ezechiela 18 >