< Ezechiela 17 >

1 Stało się zaś słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ní wá wí pé:
2 Synu człowieczy! zadaj zagadkę, a mów w podobieństwie o domu Izraelskim,
“Ọmọ ènìyàn pa àlọ́ kan, sì pa òwe kan fún ilé Israẹli.
3 I rzecz: Tak mówi panujący Pan: Orzeł wielki z wielkiemi skrzydłami i z długiemi pióry, pełen pierza pstrego, przyleciał na Liban, i wziął wierzch cedru.
Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, idì ńlá kan tó ní apá títóbi àti ìyẹ́ gígùn tó kún fún àwọ̀ oríṣìíríṣìí wa si Lebanoni, ó sì mu ẹ̀ka igi kedari tó ga jùlọ,
4 Wierzch młodocianych latorośli jego ułamał, i zaniósł go do ziemi kupieckiej, a w mieście kupieckiem położył go.
ó gé ọ̀mùnú orí ẹ̀ka yìí kúrò, ó mú un lọ sí ilẹ̀ oníṣòwò, ó sì gbìn ín sí ìlú àwọn oníṣòwò.
5 Wziął też nasienia onej ziemi, a wsadził je na polu urodzajnem, a wsadził je bardzo ostrożnie przy wodach wielkich;
“‘Ó mú lára irúgbìn ilẹ̀ náà, ó gbìn ín sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi, ó gbìn ín bí igi wílóò.
6 Które weszłoby było, i byłoby winną macicą bujną, choć niskiego wzrostu; i byłyby latorośli jej ku niemu, a korzenie jej byłyby mu poddane. A tak byłoby było macicą winną, któraby była wydała latorośli, i wypuściła gałązki.
Ó dàgbà, ó sì di àjàrà tó kúrú ṣùgbọ́n to bolẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kọjú sí i, gbòǹgbò rẹ̀ sì dúró lábẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó di àjàrà, ó sì mu ẹ̀ka àti ewé jáde.
7 Ale był orzeł jeden wielki z wielkiemi skrzydłami i z gęstem pierzem, a oto ona winna macica przypoiła korzenie swoje ku niemu, i gałązki swe rozciągnęła do niego, aby ją odwilżał z brózd sadu swego.
“‘Ṣùgbọ́n ẹyẹ idì ńlá mìíràn tún wá, tó ní apá títóbi pẹ̀lú ìyẹ́ púpọ̀. Gbòǹgbò àjàrà náà sì ta lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti orí ilẹ̀ tí wọn gbìn ín sí, ó wá pẹ̀ka lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ kí ó le fún un ni omi.
8 Choć na polu dobrem przy wodach wielkich wsadzona była, aby wypuściła latorośli, i przyniosła owoce, i była macicą winną wspaniałą.
Orí ilẹ̀ tó dára lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi ni a gbìn ín sí, kí ó bá à le pẹ̀ka, kò sì so èso, ó sì wá di igi àjàrà tó lọ́lá púpọ̀.’
9 Rzeczże tedy: Tak mówi panujący Pan: Izali się jej poszczęści? Izali orzeł korzenia jej nie wyrwie, i owocu jej nie oberwie, i nie posuszy? Izali wszystkich latorośli wyrosłych z niej nie ususzy? Izali z wielką mocą a z obfitym ludem jej nie wygładzi z korzenia jej?
“Sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyí, yóò wá gbilẹ̀ bí? A kò wá ní i wú gbòǹgbò rẹ̀, ki a si gé èso rẹ̀ kúrò kí ó bá à le rọ? Gbogbo ewé rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ ni yóò rẹ̀. Kò sì nígbà agbára tàbí ènìyàn púpọ̀ láti fà gbòǹgbò rẹ̀ tu.
10 Oto jakożkolwiek wsadzona jest, izali się jej poszczęści? Izali do szczętu nie uschnie, skoro się jej dotknie wiatr wschodni? Izali przy brózdach, przy którch się przyjęła, nie uschnie?
Bí a tilẹ̀ tún un gbìn, yóò wa gbilẹ̀ bí? Kò wá ní i rọ pátápátá nígbà ti afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn bá kọlù ú. Gbogbo ewé rẹ̀ yóò rẹ̀ lórí ilẹ̀ tó ti dàgbà?’”
11 Zatem stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Nígbà náà, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá pé:
12 Mów teraz do domu odpornego: Azaż nie wiecie, co to jest? Zatem mów: Oto przyciągnął król Babiloński do Jeruzalemu, i zabrał króla jego, i książąt jego, i zawiódł ich z sobą do Babilonu.
“Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé yìí, ‘Ǹjẹ́ ẹ mọ ìtumọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?’ Sọ fún wọn: ‘Ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó ọba àti àwọn ìjòyè ọmọ-aládé ibẹ̀ lọ sí Babeli lọ́dọ̀ rẹ̀.
13 Wziął też z nasienia królewskiego, a uczyniwszy z nim przymierze, zawiązał go przysięgą, i mocnych z onej ziemi zabrał,
Lẹ́yìn èyí, ó bá ọ̀kan nínú ọmọ ọba dá májẹ̀mú, ó mú un ìbúra, ó tún kó àwọn alágbára ilẹ̀ náà lọ.
14 Aby było królestwo zniżone, przeto, żeby się nie wyniosło, żeby tak strzegąc przymierza jego, stało.
Kí ìjọba ilẹ̀ náà le rẹ ilẹ̀, kí ó má lè gbé ara rẹ̀ sókè, kí ó lè dúró nípa pípa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
15 Ale mu się sprzeciwił, posławszy posłów swych do Egiptu, aby mu dał koni i wiele ludu. Izali się to poszczęści? Izali pomsty ujdzie ten, co tak uczynił? Ten, który wzrusza przymierze, izali pomsty ujdzie?
Ṣùgbọ́n ọba ṣọ̀tẹ̀ sí i nípa ríran àwọn ikọ̀ rẹ̀ lọ sí Ejibiti, kí wọn bá à lè fún un ni ẹṣin àti àwọn ọmọ-ogun púpọ̀. Yóò ha ṣe àṣeyọrí? Ṣe ẹni tó ṣe irú nǹkan yìí yóò sì bọ́ níbẹ̀? Yóò ha dalẹ̀ tán kí ó sì bọ́ níbẹ̀ bí?
16 Jako żyję Ja, mówi panujący Pan, że na miejscu króla tego, który go królem uczynił, którego przysięgą wzgardził, a którego przymierze wzruszył, u niego w Babilonie umrze.
“‘Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, òun yóò kú ní Babeli, ní ilẹ̀ ọba tó fi sórí oyè, ìbúra ẹni tí ó kẹ́gàn àti májẹ̀mú ẹni tí ó dà.
17 Ani mu Farao z wielkim wojskiem i z ludem gęstym co pomoże na wojnie, gdy usypie wał, i porobi szańce, aby wykorzenił mnóstwo ludu,
Farao pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun àti àjọ ńlá rẹ̀ kò ní lè ṣe ìrànwọ́ fún un lójú ogun. Nígbà tí wọ́n bá pa bùdó ogun tì í, tí wọ́n sì mọ odi láti pa ọ̀pọ̀ ènìyàn.
18 Ponieważ pogardził przysięgą, zrzuciwszy przymierze; bo oto dał na to rękę swą, a przecie to wszystko uczyni; nie ujdzie pomsty.
Nítorí pé ó kẹ́gàn ìbúra nípa dída májẹ̀mú, àti pé ó juwọ́ sílẹ̀ nínú ṣíṣe ìlérí, kì yóò bọ níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn nǹkan tí ó ṣe yìí.
19 Dlatego tak mówi panujący Pan: Jako żyję Ja, że przysięgę swoję, którą wzgardził, i przymierze moje, które wzruszył, pewnie obrócę na głowę jego.
“‘Nítorí náà Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà láààyè, Èmi yóò mú ẹ̀san ẹ̀jẹ́ mi tó kẹ́gàn àti májẹ̀mú mi tó dà wa sórí rẹ̀.
20 Bo rozciągnę nań sieć moję, a będzie niewodem moim pojmany, i zawiodę go do Babilonu, a tam się z nim rozsądzę o występek jego, którym wystąpił przeciwko mnie.
Èmi yóò ta àwọ̀n mi sórí rẹ̀, yóò sì bọ sínú okùn mi, Èmi yóò mú ọ lọ Babeli láti ṣe ìdájọ́ ìwà ọ̀dàlẹ̀ tó hù sí mi.
21 A wszyscy też, którzy uciekli od niego ze wszystkiemi hufami jego, od miecza polegną, a pozostali na wszystkie strony rozproszeni będą, a dowiecie się, że Ja Pan mówiłem to.
Gbogbo ìgbèkùn àti ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ ni yóò kú pẹ̀lú idà, èmi yóò sì fọn àwọn ìyókù ká sínú afẹ́fẹ́ káàkiri. Nígbà náà ni yóò mọ̀ pé, “Èmi Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.”
22 Tak mówi panujący Pan: Wszakże wezmę z wierzchu tego wysokiego cedru, i wsadzę; z wierzchu młodocianych latorośli jego młodą latorostkę ułamię, a wszczepię ją na górze wysokiej i wyniosłej;
“‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi fúnra mi yóò mú ọ̀kan lára ẹ̀ka tí ó ga jùlọ lórí igi kedari gíga, tí èmi yóò sì gbìn ín, èmi yóò sì gé ọ̀mùnú tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ láti òkè, èmi yóò sì gbìn ín sórí òkè tó ga tó sì lókìkí.
23 Na wysokiej górze Izraelskiej wszczepię ją, i wypuści gałązki, i wyda owoc, i będzie cedrem zacnym; i będzie pod nim mieszkać wszelkie ptastwo, i wszystko, co ma skrzydła, pod cieniem gałęzia jego mieszkać będzie.
Ní ibi gíga òkè Israẹli ni èmi yóò gbìn ín sí; yóò pẹ̀ka, yóò sì so èso, yóò wa di igi kedari tí ó lọ́lá. Oríṣìíríṣìí ẹyẹ yóò sì fi òjìji abẹ ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé; wọn yóò ṣe ibùgbé si abẹ́ òjìji ẹ̀ka rẹ̀.
24 A tak poznają wszystkie drzewa polne, żem Ja Pan poniżył drzewo wysokie, a wywyższyłem drzewo niskie, ususzyłem drzewo zielone, a uczyniłem, że zakwitło drzewo suche. Ja Pan rzekłem to, i uczynię.
Gbogbo igi inú oko yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó mú igi gíga walẹ̀, tí mo sì mú kúkúrú ga sókè, tí mo mu igi tútù gbẹ, tí mo sì mú igi gbígbẹ rúwé. “‘Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì ṣe e.’”

< Ezechiela 17 >