< Wyjścia 18 >

1 A gdy usłyszał Jetro, kapłan Madyjański, świekier Mojżesza, wszystko, co uczynił Bóg Mojżeszowi, i Izraelowi, ludowi swemu, że wywiódł Pan Izraela z Egiptu;
Jetro, àlùfáà Midiani, àna Mose, gbọ́ gbogbo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe fún Mose àti fún Israẹli àwọn ènìyàn rẹ̀, àti bí Olúwa ti mú àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Ejibiti wá.
2 Tedy wziął Jetro, świekier Mojżesza, Zeforę, żonę Mojżeszowę, którą był odesłał.
Nígbà náà ni Jetro mu aya Mose tí í ṣe Sippora padà lọ sọ́dọ̀ rẹ (nítorí ó ti dá a padà sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ tẹ́lẹ̀),
3 I dwu synów jej, z których imię jednemu Gerson; bo był powiedział Mojżesz: Byłem przychodniem w ziemi cudzej.
Òun àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ méjèèjì. Orúkọ àkọ́bí ń jẹ́ Gerṣomu; nítorí Mose wí pé, “Èmi ń ṣe àlejò ni ilẹ̀ àjèjì.”
4 A imię drugiego Eliezer; iż mówił: Bóg ojca mego był mi ku pomocy, i wyrwał mię od miecza Faraonowego.
Èkejì ń jẹ́ Elieseri; ó wí pé, “Ọlọ́run baba mi ni alátìlẹ́yìn mi, ó sì gbà mí là kúrò lọ́wọ́ idà Farao.”
5 I przyszedł Jetro, świekier Mojżesza, z synami jego i z żoną jego do Mojżesza na puszczą, gdzie się był obozem położył przy górze Bożej.
Jetro, àna Mose, òun àti aya àti àwọn ọmọ Mose tọ̀ ọ́ wá nínú aginjù tí ó tẹ̀dó sí, nítòsí òkè Ọlọ́run.
6 I wskazał do Mojżesza: Ja świekier twój Jetro idę do ciebie, i żona twoja, i jej dwa synowie z nią.
Jetro sì ti ránṣẹ́ sí Mose pé, “Èmi Jetro, àna rẹ, ni mo ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, èmi àti aya àti àwọn ọmọkùnrin rẹ méjèèjì.”
7 Zatem Mojżesz wyszedł przeciwko świekrowi swemu, a ukłoniwszy się całował go; i przywitawszy jeden drugiego, potem weszli do namiotu.
Mose sì jáde lọ pàdé àna rẹ̀, ó tẹríba fún un, ó sì fi ẹnu kò ó ni ẹnu. Wọ́n sì béèrè àlàáfíà ara wọn, wọ́n sì wọ inú àgọ́ lọ.
8 I rozpowiadał Mojżesz świekrowi swemu wszystko, co uczynił Pan Faraonowi i Egipczanom za przyczyną Izraela; i wszystkę trudność, która je spotykała w drodze, i jako je Pan wybawił.
Mose sọ fún àna rẹ̀ nípa ohun gbogbo ti Olúwa tí ṣe sí Farao àti àwọn ará Ejibiti nítorí Israẹli. Ó sọ nípa gbogbo ìṣòro tí wọn bá pàdé ní ọ̀nà wọn àti bí Olúwa ti gbà wọ́n là.
9 I radował się Jetro ze wszystkiego dobrego, które uczynił Pan Izraelowi, iż go wyrwał z ręki Egipczanów.
Inú Jetro dùn láti gbọ́ gbogbo ohun rere ti Olúwa ṣe fún Israẹli, ẹni tí ó mú wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
10 I rzekł Jetro: Błogosławiony Pan, który was wyrwał z ręki Egipczanów i z ręki Faraonowej, który wyrwał lud z niewoli Egipskiej.
Jetro sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa, ẹni tí ó gba yín là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti àti lọ́wọ́ Farao, ẹni tí ó sì gba àwọn ènìyàn là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti.
11 Terazem doznał, że większy jest Pan nad wszystkie bogi; albowiem czem oni hardzie powstawali przeciwko niemu, tem poginęli.
Mo mọ nísinsin yìí pé Olúwa tóbi ju gbogbo àwọn òrìṣà lọ; nítorí ti ó gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìgbéraga àti ìkà àwọn ará Ejibiti.”
12 I wziął Jetro, świekier Mojżesza, całopalenie i ofiary Bogu. Przyszedł też Aaron i wszyscy starsi Izraelscy, aby jedli chleb z świekrem Mojżeszowym przed Bogiem.
Jetro, àna Mose, mú ẹbọ sísun àti ẹbọ wá fún Ọlọ́run. Aaroni àti gbogbo àgbàgbà Israẹli sì wá láti bá àna Mose jẹun ní iwájú Ọlọ́run.
13 I stało się nazajutrz, że usiadł Mojżesz, aby sądził lud, i stał lud przed Mojżeszem od poranku aż do wieczora.
Ní ọjọ́ kejì, Mose jókòó láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀; àwọn ènìyàn sì dúró ti Mose fún ìdájọ́ wọn láti òwúrọ̀ títí di ìrọ̀lẹ́.
14 A widząc świekier Mojżesza wszystko, co on czynił z ludem, rzekł: Cóż to jest, co ty czynisz z ludem? czemuż ty sam siedzisz, a lud wszystek stoi przed tobą od poranku aż do wieczora?
Nígbà tí àna Mose rí bí àkókò ti èyí ń gba ti pọ̀ tó àti ti àwọn ènìyàn ti ń dúró pẹ́ tó, ó wí pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ń ṣe sí àwọn ènìyàn? Èéṣe ti ìwọ nìkan jókòó gẹ́gẹ́ bí adájọ́, nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí dúró yí ọ ká láti òwúrọ̀ di ìrọ̀lẹ́?”
15 Tedy Mojżesz odpowiedział świekrowi swemu: Iż przychodzi lud do mnie, aby się radził Boga.
Mose dá a lóhùn pé, “Nítorí àwọn ènìyàn ń tọ̀ mí wá láti mọ́ ìfẹ́ Ọlọ́run.
16 Gdy sprawę jaką mają, przychodzą do mnie, a rozsądzam między nimi, oznajmując ustawy Boże i prawa jego.
Nígbà tí wọ́n bá ní ẹjọ́, wọn a mú un tọ̀ mí wá, èmi a sì ṣe ìdájọ́ láàrín ẹnìkínní àti ẹnìkejì, èmi a sì máa mú wọn mọ òfin àti ìlànà Ọlọ́run.”
17 Zatem rzekł świekier Mojżesza do niego: Nie dobra rzecz, którą ty czynisz.
Àna Mose dá a lóhùn pé, “Ohun tí o ń ṣe yìí kò dára.
18 Pewnie ustaniesz, i ty i lud ten, który jest z tobą, bo cięższa to rzecz nad siły twoje; nie będziesz jej mógł ty sam podołać.
Ìwọ àti àwọn ènìyàn ti ń tọ̀ ọ́ wá yìí yóò dá ara yín ní agara; iṣẹ́ yìí pọ̀jù fún ọ, ìwọ nìkan kò lè dá a ṣe.
19 Przetoż usłuchaj teraz głosu mego, poradzęć, a będzie Bóg z tobą; stój ty za lud przed Bogiem, a odnoś sprawy do Boga;
Nísinsin yìí, fetísílẹ̀ sí mi, èmi yóò sì gbà ọ́ ni ìmọ̀ràn, Ọlọ́run yóò sì wà pẹ̀lú rẹ. Ìwọ gbọdọ̀ jẹ́ aṣojú àwọn ènìyàn wọ̀nyí níwájú Ọlọ́run, ìwọ yóò sì mú èdè-àìyedè wá sí iwájú rẹ̀.
20 A onych też nauczaj ustaw i praw, oznajmując im drogę, którą by chodzić, i dzieło, które by czynić mieli.
Kọ́ wọn ní òfin àti ìlànà Ọlọ́run, fi ọ̀nà igbe ayé ìwà-bí-Ọlọ́run hàn wọ́n àti iṣẹ́ tí wọn yóò máa ṣe.
21 Ty też upatrz ze wszystkiego ludu męże stateczne, bojące się Boga, męże prawdomówne, którzy by nienawidzili łakomstwa, a postanów z nich przełożone, tysiączniki, setniki, pięćdziesiątniki i dziesiątniki.
Ṣa àwọn tí ó kún ojú òsùwọ̀n nínú gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn tó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti wọ́n jẹ́ olóòtítọ́, tí wọ́n kórìíra ìrẹ́jẹ; yàn wọ́n ṣe olórí, lórí ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún, ọgọ́rùn-ún ọgọ́rùn-ún, àádọ́ta-dọ́ta àti mẹ́wàá mẹ́wàá.
22 Którzy na każdy czas lud sądzić będą; a gdy będzie rzecz wielka, odniosą do ciebie, a każdą rzecz małą sądzić będą sami; tedy ulżysz sobie, gdy poniosą ciężar z tobą.
Jẹ́ kí wọn ó máa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn ni gbogbo ìgbà, ṣùgbọ́n jẹ́ kí wọn mú ẹjọ́ tí ó bá nira fún wọn láti dá tọ̀ ọ́ wá; kí wọn kí ó máa dá ẹjọ́ kéékèèké. Èyí ni yóò mú iṣẹ́ rẹ rọrùn, wọn yóò sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ lórí ìdájọ́ ṣíṣe.
23 To jeźli uczynisz, a rozkażeć Bóg, ostoisz się, i ten wszystek lud na miejsca swoje wracać się będzie w pokoju.
Bí ìwọ bá ṣe èyí, bí Ọlọ́run bá sì fi àṣẹ sí i fún ọ bẹ́ẹ̀, àárẹ̀ kò sì ní tètè mu ọ, àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò sì padà lọ ilé wọn ni àlàáfíà.”
24 I usłuchał Mojżesz rady świekra swojego, a uczynił wszystko, jako mu powiedział.
Mose fetísílẹ̀ sí àna rẹ̀, ó sì ṣe ohun gbogbo tí ó wí fún un.
25 I wybrał Mojżesz męże stateczne ze wszystkiego Izraela, i postanowił je przełożonymi nad ludem, tysiączniki, setniki, pięćdziesiątniki i dziesiątniki.
Mose sì yan àwọn ènìyàn tí wọ́n kún ojú òsùwọ̀n nínú gbogbo Israẹli; ó sì fi wọ́n jẹ olórí àwọn ènìyàn, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá.
26 Którzy sądzili lud każdego czasu; trudne rzeczy odnosili do Mojżesza, a każdą rzecz mniejszą sami sądzili.
Wọ́n sì ń ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn ní ìgbà gbogbo. Wọ́n sì ń mú ẹjọ́ tó le tọ Mose wá; ṣùgbọ́n wọ́n ń dá ẹjọ́ tí kò le fúnra wọn.
27 Zatem puścił od siebie Mojżesz świekra swego, który odszedł do ziemi swej.
Mose sì jẹ́ kí àna rẹ̀ lọ ní ọ̀nà rẹ̀, Jetro sì padà sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.

< Wyjścia 18 >