< Wyjścia 17 >

1 Ruszyło się tedy wszystko mnóstwo synów Izraelskich z puszczy Zyn stanowiskami swemi, według rozkazania Pańskiego, i położyli się obozem w Rafidym, gdzie wody nie było, aby pił lud.
Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli si gbéra láti jáde kúrò láti aginjù Sini wọ́n ń lọ láti ibi kan de ibi kan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ. Wọ́n pàgọ́ sí Refidimu, ṣùgbọ́n kò sí omi fún àwọn ènìyàn láti mú.
2 Przetoż swarzył się lud z Mojżeszem, mówiąc: Dajcie nam wody, abyśmy pili. Którym odpowiedział Mojżesz: Cóż się swarzycie ze mną? a czemu kusicie Pana?
Àwọn ènìyàn sì sọ̀ fún Mose, wọ́n wí pé, “Fún wa ni omi mu.” Mose dá wọn lóhùn wí pé, “Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń bá mi jà? Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń dán Olúwa wò?”
3 I pragnął tam lud wody, a szemrał przeciwko Mojżeszowi, mówiąc: Po cóżeś nas wywiódł z Egiptu, abyś pomorzył mnie, i syny moje, i bydło moje pragnieniem?
Ṣùgbọ́n òǹgbẹ ń gbẹ àwọn ènìyàn, wọ́n sì ń kùn sí Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde kúrò ní Ejibiti láti mú kí òǹgbẹ pa àwa, àwọn ọmọ wa àti ohun ọ̀sìn wa ku fún òǹgbẹ.”
4 Zawołał tedy Mojżesz do Pana, mówiąc: Cóż mam czynić ludowi temu? blisko tego, że mię ukamionują.
Nígbà náà ni Mose gbé ohùn rẹ̀ sókè sí Olúwa pé, “Kí ni kí èmi kí ó ṣe fún àwọn ènìyàn yìí? Wọ́n múra tan láti sọ mi ni òkúta.”
5 I rzekł Pan do Mojżesza: Idź przed ludem, a weźmij z sobą niektóre z starszych Izraelskich; laskę też twoję którąś uderzył w rzekę, weźmij w rękę twoję, a idź.
Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Máa lọ síwájú àwọn ènìyàn, mú nínú àwọn àgbàgbà Israẹli pẹ̀lú rẹ, mú ọ̀pá tí ìwọ fi lu odò Naili lọ́wọ́ kí ó sì máa lọ.
6 Oto, Ja stanę przed tobą tam na skale w Horeb, i uderzysz w skałę, a wynijdą z niej wody, które będzie pił lud. I uczynił tak Mojżesz przed oczyma starszych Izraelskich.
Èmi yóò dúró ni ibẹ̀ dè ọ ni orí àpáta ni Horebu. Ìwọ ó sì lu àpáta, omi yóò sì jáde nínú rẹ̀ fún àwọn ènìyàn láti mu.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀ ni iwájú àwọn àgbàgbà Israẹli.
7 I nazwał imię onego miejsca Masa i Meryba, dla swarów synów Izraelskich, a iż kusili Pana mówiąc: I jestże Pan między nami czyli nie?
Ó sì sọ orúkọ ibẹ̀ ni Massa àti Meriba, nítorí àwọn ọmọ Israẹli sọ̀, wọ́n sì dán Olúwa wò, wọ́n wí pé, “Ǹjẹ́ Olúwa ń bẹ láàrín wa tàbí kò sí?”
8 Tedy przyciągnął Amalek, aby walczył z Izraelem w Rafidym.
Àwọn ara Amaleki jáde, wọ́n sì dìde ogun sí àwọn ọmọ Israẹli ni Refidimu.
9 I rzekł Mojżesz do Jozuego: Wybierz nam męże, a wyszedłszy, stocz bitwę z Amalekity: a jutro stanę na wierzchu pagórka, mając laskę Bożą w ręce mojej.
Mose sì sọ fún Joṣua pé, “Yàn lára àwọn ọkùnrin fún wa, kí wọn ó sì jáde lọ bá àwọn ará Amaleki jà. Ní ọ̀la, èmi yóò dúró ni orí òkè pẹ̀lú ọ̀pá Ọlọ́run ní ọwọ́ mi.”
10 I uczynił Jozue, jako mu rozkazał Mojżesz, i stoczył bitwę z Amalekiem; a Mojżesz, Aaron i Chur wstąpili na wierzch pagórka.
Joṣua ṣe bí Mose ti wí fún un, ó sì bá àwọn ará Amaleki jagun; nígbà tí Mose, Aaroni àti Huri lọ sí orí òkè náà.
11 A gdy podnosił Mojżesz rękę swoję, przemagał Izrael; a gdy opuszczał rękę swoję, przemagał Amalek.
Níwọ́n ìgbà tí Mose bá gbé apá rẹ̀ sókè, Israẹli n borí ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá sì rẹ apá rẹ̀ sílẹ̀, Amaleki a sì borí.
12 Ale ręce Mojżeszowe ociężały były; wziąwszy tedy kamień, podłożyli podeń, i usiadł na nim; a Aaron, i Chur podpierali ręce jego, jeden z jednej, drugi z drugiej strony; i nie ustały ręce jego aż do zajścia słońca.
Ṣùgbọ́n apá ń ro Mose, wọ́n mú òkúta, wọ́n sì fi sí abẹ́ rẹ̀, ó sì jókòó lé òkúta náà; Aaroni àti Huri sì mu ní apá rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àti èkejì ni apá òsì; apá rẹ̀ méjèèjì sì dúró gangan títí di ìgbà ti oòrùn wọ.
13 Tedy poraził Jozue Amaleka i lud jegoż ostrzem miecza.
Joṣua sì fi ojú idà ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki.
14 Potem rzekł Pan do Mojżesza: Wpisz to dla pamięci w księgi, a włóż to w uszy Jozuego, że pewnie wygładzę pamiątkę Amaleka pod niebem.
Olúwa sì sọ fun Mose pé. “Kọ èyí sì inú ìwé fún ìrántí, kí o sì sọ fún Joṣua pẹ̀lú; nítorí èmi yóò pa ìrántí Amaleki run pátápátá kúrò lábẹ́ ọ̀run.”
15 I zbudował Mojżesz ołtarz, a nazwał imię jego: Pan chorągiew moja;
Mose sì tẹ́ pẹpẹ kan, ó sì sọ orúkọ pẹpẹ náà ní Olúwa ni Àsíá mi.
16 Bo rzekł: Iż ręka stolicy Pańskiej, i wojna Pańska, będzie przeciwko Amalekowi od rodzaju do rodzaju.
Ó wí pé, “A gbé ọwọ́ sókè sí ìtẹ́ Olúwa. Olúwa yóò bá Amaleki jagun láti ìran dé ìran.”

< Wyjścia 17 >