< Daniela 5 >

1 Balsazar król uczynił ucztę wielką na tysiąc książąt swoich, i przed onym tysiącem pił wino.
Belṣassari, ọba ṣe àsè ńlá fún ẹgbẹ̀rún kan nínú àwọn ọlọ́lá rẹ̀, ó sì mu wáìnì pẹ̀lú u wọn.
2 A gdy pił wino Balsazar, rozkazał przynieść naczynie złote i srebrne, które był zabrał Nabuchodonozor, ojciec jego, z kościoła Jeruzalemskiego, aby pili z niego król i książęta jego, żony jego, i założnice jego.
Bí Belṣassari ṣe ń mu wáìnì, ó pàṣẹ pé kí wọn kó kọ́ọ̀bù wúrà àti ti fàdákà wá, èyí tí Nebukadnessari baba rẹ̀ kó wá láti inú tẹmpili ní Jerusalẹmu, kí ọba àti àwọn ọlọ́lá rẹ̀, àwọn ìyàwó àti àwọn àlè rẹ̀ kí ó ba à le fi mu wáìnì.
3 Tedy przyniesiono naczynia złote, które byli zabrali z kościoła domu Bożego, który był w Jeruzalemie, i pili z nich król i książęta jego, żony jego, i założnice jego;
Wọ́n sì kó kọ́ọ̀bù wúrà àti fàdákà àti fàdákà èyí tí wọ́n kó jáde láti inú tẹmpili, ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àwọn ìyàwó àti àwọn àlè rẹ̀, sì fi mu wáìnì.
4 A pijąc wino chwalili bogi złote i srebrne, miedziane, żelazne, drewniane, i kamienne.
Bí wọ́n ṣe ń mu wáìnì bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń yin òrìṣà wúrà àti fàdákà, ti idẹ, irin, igi àti òkúta.
5 Tejże godziny wyszły palce ręki człowieczej, które pisały przeciwko świecznikowi na ścianie pałacu królewskiego, a król widział część ręki, która pisała.
Lójijì, ìka ọwọ́ ènìyàn jáde wá, ó sì ń kọ̀wé sára ẹfun ògiri ní ẹ̀gbẹ́ ibi tí fìtílà ń dúró ní ààfin ọba. Ọba ń wo ọwọ́ náà bí ó ṣe ń kọ ọ́.
6 Tedy się jasność królewska zmieniła, a myśli jego zatrwożyły nim, i zwiąski biódr jego rozwiązały się, a kolana jego jedno o drugie się tłukły.
Ojú ọba sì yí padà, ẹ̀rù sì bà á, tó bẹ́ẹ̀ tí orúnkún ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì rẹ̀ fi ń gbá ara wọn.
7 I zawołał król ze wszystkiej siły, aby przywiedziono praktykarzy, Chaldejczyków i wieszczków. A mówiąc król rzekł do mędrców Babilońskich: Ktokolwiek to pismo przeczyta, a wykład jego mnie oznajmi, obleczony będzie w szarłat, a łańcuch złoty dadzą na szyję jego, i trzecim w królestwie po mnie będzie.
Ọba kígbe pé, kí wọn pe àwọn awòràwọ̀, àwọn onídán, àti àwọn aláfọ̀ṣẹ wá, ọba sì sọ fún àwọn amòye Babeli pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá lè ka àkọsílẹ̀ yìí kí ó sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀, ẹni náà ni a ó fi aṣọ elése àlùkò wọ̀ àti ẹ̀gbà wúrà ni a ó fi sí ọrùn un rẹ̀, òun ni yóò sì ṣe olórí kẹta ní ìjọba à mi.”
8 Tedy weszli wszyscy mędrcy królewscy; ale nie mogli ani pisma przeczytać, ani wykładu jego królowi oznajmić.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn amòye ọba wọ ilé, ṣùgbọ́n, wọn kò le è ka àkọsílẹ̀ náà tàbí sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọba.
9 Skąd król Balsazar był bardzo zatrwożony, a jasność jego zmieniła się na nim, i książęta jego potrwożyli się.
Nígbà náà ni Belṣassari ọba bínú gidigidi, ojú u rẹ̀ sì túbọ̀ dàrú sí i. Ẹ̀rù sì ba àwọn ìjòyè Belṣassari.
10 Tedy królowa weszła do domu uczty dla tego, co się przydało królowi i książętom jego; a przemówiwszy królowa rzekła: Królu, żyj na wieki! Niech cię nie trwożą myśli twoje, a jasność twoja niech się nie mieni.
Nígbà tí ayaba gbọ́ ohùn ọba àti àwọn ọlọ́lá rẹ̀, ó wá ilé àsè wá. Ó wí pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Má ṣe jẹ́ kí inú rẹ bàjẹ́, má sì ṣe jẹ́ kí ojú u rẹ fàro.
11 Jest mąż w królestwie twojem, w którym jest duch bogów świętych, w którym się znalazło za dni ojca twego oświecenie, i rozum, i mądrość, jako mądrość bogów, którego król Nabuchodonozor, ojciec twój, przedniejszym między mędrcami, i praktykarzami Chaldejczykami, i wieszczkami, postanowił, ojciec twój mówię, o królu!
Ọkùnrin kan wà ní ìjọba à rẹ, ẹni tí ẹ̀mí ọlọ́run mímọ́ ń gbé inú rẹ̀. Ní ìgbà ayé e baba à rẹ, òun ni ó ní ojú inú, òye àti ìmọ̀ bí i ti ọlọ́run òun ni ọba Nebukadnessari, baba rẹ̀ fi jẹ olórí àwọn apidán, awòràwọ̀, apògèdè àti aláfọ̀ṣẹ.
12 Dlatego, iż duch obfity, i umiejętność, i zrozumienie, wykładanie snów, i objawienie zagadek, i rozwiązanie rzeczy trudnych znalazły się przy Danijelu, któremu król dał imię Baltazar, teraz tedy niech przyzowią Danijela, a oznajmić ten wykład.
Ọkùnrin náà ni Daniẹli ẹni tí ọba ń pè ní Belṣassari, ó ní ẹ̀mí tí ó tayọ, ìmọ̀ àti òye, àti agbára láti túmọ̀ àlá, ó máa ń ṣe àlàyé àlá àti àwọn ọ̀rọ̀ tí ó bá da ojú rú, ránṣẹ́ pè é, yóò sì sọ nǹkan tí àkọsílẹ̀ ìwé náà túmọ̀ sí.”
13 Tedy przywiedziony jest Danijel do króla; a król mówiąc rzekł Danijelowi: Tyżeś jest on Danijel, któryś jest z synów więźniów Judzkich, którego przywiódł król, ojciec mój, z ziemi Judzkiej?
Nígbà náà ni a mú Daniẹli wá síwájú ọba, ọba sì sọ fún un wí pé, “Ṣé ìwọ ni Daniẹli, ọ̀kan lára àwọn tí baba mi mú ní ìgbèkùn láti Juda!
14 Słyszałem zaiste o tobie, iż duch bogów jest w tobie, a oświecenie i rozum i mądrość obfita znalazła się w tobie.
Mo ti gbọ́ wí pé ẹ̀mí ọlọ́run ń gbé inú rẹ àti wí pé ìwọ ní ojú inú, òye, àti ọgbọ́n tí ó tayọ.
15 A teraz przywiedziono przed mię mędrców i praktykarzy, aby mi to pismo przeczytali, i wykład jego oznajmili: wszakże nie mogli wykładu tej rzeczy oznajmić.
A ti mú àwọn amòye àti àwọn awòràwọ̀ wá sí iwájú mí kí wọn ba à le è wá ka àkọsílẹ̀ yìí kí wọn sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n wọn kò le è sọ ìtumọ̀ ohun tí ó jẹ́.
16 A jam słyszał o tobie, że możesz to, co jest niepojętego, wykładać, a co jest trudnego, rozwiązywać; przetoż teraz, możeszli to pismo przeczytać a wykład jego mnie oznajmić, w szarłat obleczony będziesz, i łańcuch złoty na szyję twoję włożony będzie, a trzecim w królestwie po mnie będziesz.
Ṣùgbọ́n mo ti gbọ́ wí pé, ìwọ lè sọ ìtumọ̀, àti wí pé o lè yanjú àwọn ìṣòro tó lágbára. Tí o bá lè ka àkọsílẹ̀ ìwé yìí kí o sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀, a ó fi aṣọ elése àlùkò wọ̀ ọ́ pẹ̀lú ẹ̀gbà wúrà ni a ó fi sí ọ lọ́rùn, a ó sì fi ọ́ ṣe olórí kẹta ní ìjọba mi.”
17 Tedy odpowiedział Danijel przed królem i rzekł: Upominki twoje niech tobie zostaną, a dary twoje daj innemu; wszakże pismo przeczytam królowi, i wykład mu oznajmię.
Nígbà náà ni Daniẹli dá ọba lóhùn wí pé, “Fi ẹ̀bùn rẹ pamọ́ fún ara rẹ, tàbí kí o fún ẹlòmíràn. Síbẹ̀ èmi yóò ka àkọsílẹ̀ náà fún ọba, èmi yóò sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀.
18 Ty, królu! słuchaj. Bóg najwyższy królestwo i wielmożność i sławę, i zacność dał Nabuchodonozorowi, ojcu twemu;
“Ìwọ ọba, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo fún Nebukadnessari baba rẹ ní ìjọba, títóbi ògo àti ọlá.
19 A dla wielmożności, którą mu był dał, wszyscy ludzie, narody i języki drżeli i bali się przed obliczem jego; bo kogo chciał, zabijał, a kogo chciał, żywił, a kogo chciał, wywyższał, a kogo chciał, poniżał.
Nítorí ipò ńlá tí a fi fún un, gbogbo ènìyàn orílẹ̀-èdè àti èdè gbogbo fi ń páyà tí wọ́n sì ń bẹ̀rù rẹ̀. Ó ń pa àwọn tí ó bá wù ú, ó sì ń dá àwọn tí ó bá wù ú sí, ó ń gbé àwọn tí ó bá wù ú ga, ó sì ń rẹ àwọn tí ó bá wù ú sílẹ̀.
20 Ale gdy się wyniosło serce jego, a duch jego zmocnił się w pysze, złożony jest z stolicy królestwa swego, a sława odjęta była od niego;
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn rẹ̀ ga, tí ó sì le koko. Ó bẹ̀rẹ̀ sí i hùwà ìgbéraga, a mú u kúrò lórí ìtẹ́ ọba rẹ̀, a sì gba ògo rẹ̀ kúrò.
21 I był wyrzucony od synów ludzkich, a serce jego zwierzęcemu podobne było, i z dzikiemi osłami było mieszkanie jego; trawą się pasł jako wół, i rosą niebieską ciało jego skrapiane było, dokąd nie poznał, że Bóg najwyższy ma władzę nad królestwem ludzkiem, a tego, kogo chce, stanowi nad niem.
A lé e kúrò láàrín ènìyàn, a sì fún un ní ọkàn ẹranko; ó sì ń gbé pẹ̀lú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì ń jẹ koríko bí i ti màlúù; ìrì ọ̀run ṣì sẹ̀ sí ara rẹ̀, títí tó fi mọ̀ pé, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ń jẹ ọba lórí ìjọba ọmọ ènìyàn, òun sì ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.
22 Ty, też, Balsazarze, synu jego! nie upokorzyłeś serca swego, chociażeś to wszystko wiedział.
“Ṣùgbọ́n ìwọ ọmọ rẹ̀, Belṣassari, ìwọ kò rẹ ara à rẹ sílẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ mọ nǹkan wọ̀nyí.
23 Owszem, przeciwko Panu nieba podniosłeś się, i naczynie domu jego przyniesiono przed cię; a ty i książęta twoi, żony twoje, i założnice twoje, piliście wino z niego; nadto bogi srebrne i złote, miedziane, żelazne, drewniane, i kamienne, którzy nie widzą, ani słyszą, i nic nie wiedzą, chwaliłeś, a Boga, w którego ręku jest tchnienie twoje, i u którego są wszystkie drogi twoje, nie uczciłeś.
Dípò èyí, ìwọ gbé ara à rẹ ga sí Olúwa ọ̀run, a mú ohun èlò inú tẹmpili rẹ̀ wá sí iwájú rẹ, ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ, àwọn ìyàwó ò rẹ àti àwọn àlè rẹ fi ń mu wáìnì. Ìwọ ń yin àwọn òrìṣà fàdákà àti wúrà, idẹ, irin, igi àti ti òkúta, èyí tí kò lè ríran, tí kò le è gbọ́rọ̀ tàbí ní òye nǹkan kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò bu ọlá fún Ọlọ́run ẹni tó ni ẹ̀mí rẹ lọ́wọ́, tí ó sì mọ gbogbo ọ̀nà rẹ.
24 Przetoż teraz od niego posłana jest ta część ręki, i pismo to wyrażone jest.
Nítorí náà, ó rán ọwọ́ tí ó kọ àkọlé yìí.
25 A toć jest pismo, które wyrażone jest: Mene, Mene, Thekel, upharsin.
“Èyí ni àkọlé náà tí a kọ: Mene, mene, tekeli, peresini.
26 A tenci jest wykład tych słów: Mene, zliczył Bóg królestwo twoje i do końca je przywiódł.
“Èyí ni nǹkan tí ọ̀rọ̀ náà túmọ̀ sí: “Mene: Ọlọ́run ti ṣírò ọjọ́ ìjọba rẹ. Ó sì ti mú u wá sí òpin.
27 Thekel, zważonyś na wadze, a znalezionyś lekki.
“Tekeli: A ti gbé ọ lórí òsùwọ̀n, ìwọ kò sì tó ìwọ̀n.
28 Peres, rozdzielone jest królestwo twoje, a dane jest Medom i Persom.
“Peresini: A ti pín ìjọba rẹ a sì ti fi fún àwọn Media àti àwọn Persia.”
29 Tedy rozkazał Balsazar; i obleczono Danijela w szarłat, a łańcuch złoty włożono na szyję jego, i obwołano o nim, że ma być trzecim panem w królestwie.
Nígbà náà ni Belṣassari pàṣẹ pé kí a wọ Daniẹli ní aṣọ elése àlùkò, kí a sì fi ẹ̀gbà wúrà sí i lọ́rùn, a sì kéde rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí kẹta ní ìjọba rẹ̀.
30 Tejże nocy zabity jest Balsazar, król Chaldejski.
Ní alẹ́ ọjọ́ náà ni a pa Belṣassari, ọba àwọn ara Kaldea.
31 A Daryjusz, Medczyk, ujął królestwo, mając lat około sześćdziesiąt i dwa.
Dariusi ará Media sì gba ìjọba nígbà tí ó di ọmọ ọdún méjìlélọ́gọ́ta.

< Daniela 5 >