< Ozeasza 1 >

1 Słowo Pańskie, które się stało do Ozeasza, syna Berowego, za dni Uzyjasza, Joatama, Achaza, Ezechyjasza, królów Judzkich, i za dni Jeroboama, syna Joazowego, króla Izraelskiego.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
2 Gdy począł Pan mówić do Ozeasza, rzekł Pan do Ozeasza: Idź, pojmij sobie żonę wszetecznicę, i spłódź dzieci z wszeteczeństwa; bo się ta ziemia, bez wstydu wszeteczeństwo płodząc, od Pana odwróciła.
Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
3 Odszedł tedy, i pojął Gomorę, córkę Dyblaimską, która poczęła i porodziła mu syna.
Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
4 I rzekł Pan do niego: Nazów imię jego Jezreel: bo jeszcze po małym czasie nawiedzę krew Jezreel nad domem Jehu, a sprawię to, że ustanie królestwo domu Izraelskiego.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
5 A dnia onego złamię łuk Izraelski w dolinie Jezreel.
Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
6 I poczęła znowu i porodziła córkę; i rzekł mu Pan: Nazów imię jej Loruchama; bo się więcej nie zmiłuję nad domem Izraelskim, lecz ich zapewne wygładzę.
Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
7 Ale nad domem Judzkim zmiłuję się, i wybawię ich przez Pana, Boga ich, a nie wybawię ich przez łuk, i przez miecz, i przez wojnę, i przez konie i przez jezdnych.
Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
8 Potem ostawiwszy Loruchamę znowu poczęła i porodziła syna.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
9 I rzekł Pan: Nazów imię jego Loami; boście wy nie ludem moim, a Ja też nie będę waszym.
Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
10 Wszakże liczba synów Izraelskich będzie jako piasek morski, który ani zmierzony ani zliczony być może; i stanie się, że miasto tego, co im rzeczono: Nie jesteście wy ludem moim, rzeczono im będzie: Wyście synami Boga żyjącego.
“Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
11 I będą zgromadzeni synowie Judzcy i synowie Izraelscy wespół, a postanowiwszy nad sobą głowę jednę, wynijdą z tej ziemi; bo będzie wielki dzień Jezreela.
Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.

< Ozeasza 1 >