< Daniela 10 >

1 Roku trzeciego Cyrusa, króla Perskiego objawione było słowo Danijelowi, którego imię nazwano Baltazar; a to słowo było prawdziwe, i czas zamierzony długi; i zrozumiał ono słowo, bo wziął zrozumienie w widzeniu.
Ní ọdún kẹta Kirusi ọba Persia, a fi ìran kan hàn Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belteṣassari). Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ ìran náà, ó sì ní í ṣe pẹ̀lú àsìkò ìpọ́njú ńlá, òye ọ̀rọ̀ náà wá bá a nínú ìran.
2 W one dni ja Danijel byłem smutny przez trzy tygodnie dni;
Ní àsìkò náà, èmi Daniẹli ṣọ̀fọ̀ fún ọ̀sẹ̀ mẹ́ta.
3 Chlebam smacznego nie jadł, a mięso i wino nie wchodziło w usta moje, anim się mazał olejkiem, aż się wypełniły dni trzech tygodni.
Èmi kì í jẹ oúnjẹ tí ó dára, èmi kò fi ẹran tàbí wáìnì kan ẹnu mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi òróró para títí ọ̀sẹ̀ mẹ́ta fi kọjá.
4 A dnia dwudziestego i czwartego miesiąca pierwszego byłem nad brzegiem rzeki wielkiej, to jest Chydekel;
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù àkọ́kọ́, bí mo ti dúró sí etí i bèbè odò ńlá Tigirisi,
5 A podniósłszy oczy moje ujrzałem, a oto mąż niejaki ubrany w szatę lnianą, a biodra jego przepasane były złotem szczerem z Ufas;
mo wo òkè, mo rí ọkùnrin kan tí ó wọ aṣọ àlà, ẹ̀gbẹ́ ẹni tí a fi wúrà Upasi dáradára dì ní àmùrè.
6 A ciało jego było jako Tarsys, a oblicze jego na wejrzeniu jako błyskawica, a oczy jego były jako lampy gorejące, a ramiona jego i nogi jego na wejrzeniu jako miedź wypolerowana, a głos słów jego jako głos mnóstwa.
Ara rẹ̀ dàbí berili, ojú u rẹ̀ dàbí mọ̀nàmọ́ná, ẹyin ojú u rẹ̀ dàbí iná àtẹ̀tàn, apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ dàbí ìtànná ìmọ́lẹ̀ tí o kún fún idẹ, àti ohùn rẹ̀ dàbí i ti ìjọ ènìyàn púpọ̀.
7 A widziałem ja Danijel sam to widzenie; lecz mężowie, którzy byli ze mną nie widzieli tego widzenia; ale strach wielki przypadł na nich, i pouciekali a pokryli się.
Èmi Daniẹli, ni ẹnìkan tí ó rí ìran náà, àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú u mi, wọn kò rí i, ṣùgbọ́n ìpayà ńlá dà bò wọ́n, wọ́n sálọ wọ́n sì fi ara pamọ́.
8 A jam sam został, i widziałem to wielkie widzenie; ale siła nie została we mnie, i krasa moja odmieniła się we mnie, i skaziła się, i nie miałem żadnej siły.
Ó sì ku èmi nìkan, tí mo rí ìran ńlá yìí, kò sì ku okun kankan fún mi, ojú u mi sì rẹ̀wẹ̀sì gidigidi, n kò sì ní agbára mọ́.
9 Tedym słyszał głos słów jego; a usłyszawszy głos słów jego usnąłem twardo na twarzy mojej, na twarzy mojej, mówię, na ziemi.
Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ó ń sọ̀rọ̀, bí mo ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí i, mo sùn lọ fọnfọn, ní ìdojúbolẹ̀.
10 Wtem oto ręka dotknęła się mnie, i podniosła mię na kolana moje, i na dłonie rąk moich.
Ọwọ́ kan kàn mí, ó gbé mi dìde ní ìwárìrì lórí ọwọ́ àti eékún mi.
11 I rzekł do mnie: Danijelu, mężu wielce przyjemny! miej wzgląd na słowa moje, które ja będę mówił do ciebie, a stój na miejscu swem, bom teraz posłany do ciebie. A gdy przemówił do mnie to słowo, stałem drżąc.
Ó sọ pé, “Daniẹli ẹni tí a yàn fẹ́ gidigidi gba ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ bá ọ sọ yìí yẹ̀ wò dáradára, kí o sì dìde, nítorí tí a rán mi sí ọ.” Bí ó ṣe sọ èyí fún mi, mo dìde ní ìwárìrì.
12 I rzekł do mnie: Nie bój się Danijelu! bo od pierwszego dnia, jakoś przyłożył serce twoje ku wyrozumieniu i trapiłeś się Bogiem twoim, wysłuchane są słowa twoje, a jam przyszedł dla słów twoich.
Nígbà náà ni ó tẹ̀síwájú, pé, “Má ṣe bẹ̀rù Daniẹli. Láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fi ọkàn rẹ sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run rẹ, a gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ, mo sì wá nítorí ọ̀rọ̀ náà.
13 Lecz książę królestwa Perskiego sprzeciwiał mi się przez dwadzieścia dni i jeden, aż oto Michał, jeden z przedniejszych książąt, przyszedł mi na pomoc; przetożem ja tam został przy królach Perskich.
Ṣùgbọ́n ọmọ-aládé ìjọba Persia dá mi dúró fún ọjọ́ mọ́kànlélógún. Nígbà náà ni Mikaeli, ọ̀kan lára ìjòyè àwọn ọmọ-aládé, wá láti ràn mi lọ́wọ́, nítorí a dá mi dúró níbẹ̀ pẹ̀lú ọba Persia.
14 Alem przyszedł, abym ci oznajmił, co ma przyjść na lud twój w ostateczne dni; bo jeszcze widzenie będzie o tych dniach.
Ní ìsinsin yìí mo wá láti ṣàlàyé ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú, nítorí ìran náà ń sọ nípa ọjọ́ iwájú.”
15 A gdy mówił do mnie temi słowy, spuściłem twarz moję ku ziemi, i zamilknąłem.
Bí ó sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún mi, mo sì dorí kodò mo sì dákẹ́.
16 A oto jako podobieństwo synów ludzkich dotknęło się warg moich; a otworzywszy usta swe mówiłem i rzekłem do stojącego przeciwko mnie: Panie mój! dla tego widzenia obróciły się na mię boleści moje, i nie miałem żadnej siły.
Nígbà náà, ni ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kan ètè mi, mo la ẹnu mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ ọ̀rọ̀, mo sọ fún ẹni tí ó dúró níwájú mi, “Ìrònú sì mú mi, nítorí ìran náà, olúwa mi, n kò sì ní okun.
17 A jakoż będzie mógł taki sługa Pana mego rozmówić się z takim Panem moim? Gdyż od tegoż czasu nie została we mnie siła, ani tchnienie zostało we mnie.
Ǹjẹ́ báwo ni èmi ìránṣẹ́ ẹ̀ rẹ ṣe lè bá ọ sọ̀rọ̀, olúwa mi? Agbára mi ti lọ, agbára káká ni mo fi ń mí.”
18 Tedy się mnie znowu dotknął na wejrzeniu jako człowiek, i posilił mię,
Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára.
19 I rzekł: Nie bój się, mężu wielce przyjemny, pokój tobie! posil się, posil się, mówię. A gdy mówił ze mną, wziąłem siłę i rzekłem: Niech mówi Pan mój; albowiemeś mię posilił.
Ó sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin olùfẹ́ gidigidi. Àlàáfíà ni fún ọ, mú ara le, àní mú ara le.” Nígbà tí ohun bá mi sọ̀rọ̀, a sì mú mi lára le. “Mo sì wí pé, kí olúwa mi kí ó máa sọ̀rọ̀, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ ti mú mi ní ara le.”
20 I rzekł: Wieszże, dlaczegom przyszedł do ciebie? Potem się wrócę, abym walczył z książęciem Perskim, a gdy odejdę, oto książę Grecki przyciągnie.
Nígbà náà, ni ó wí pé, “Ṣé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ-aládé Persia jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ-aládé Giriki yóò wá;
21 Wszakże oznajmięć to, co jest wyrażono w piśmie prawdy; ale i jednego niemasz, któryby mężnie stał przy mnie w tych rzeczach, oprócz Michała, książęcia waszego.
ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Mikaeli, ọmọ-aládé e yín.

< Daniela 10 >