< Daniela 1 >

1 Roku trzeciego królowania Joakima, króla Judzkiego, przyciągnął Nabuchodonozor, król Babiloński, do Jeruzalemu, i obległ je.
Ní ọdún kẹta tí Jehoiakimu jẹ ọba Juda, Nebukadnessari ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kọlù ú pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
2 I podał Pan w rękę jego Joakima, króla Judzkiego, i część naczynia domu Bożego, który je zawiózł do ziemi Senaar, do domu boga swego, i wniósł ono naczynie do domu skarbu boga swego.
Olúwa sì fa Jehoiakimu ọba Juda lé e lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó lọ sí ilé òrìṣà ní Babeli, sí inú ilé ìṣúra òrìṣà rẹ̀.
3 I rozkazał król Aspenasowi przełożonemu nad komornikami swymi, aby przyprowadził z synów Izraelskich, i z nasienia królewskiego i z książąt,
Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Aṣipenasi, olórí àwọn ìwẹ̀fà ààfin rẹ̀ pé, kí ó mú nínú àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n wá láti ìdílé ọba àti lára àwọn tí ó wá láti ilé ọlá.
4 Młodzieńców, na którychby nie było żadnej zmazy, a pięknych na wejrzeniu i dowcipnych do wszelakiej mądrości, i sposobnych do umiejętności, i dostąpienia jej, i którzyby byli sposobni, aby stali w pałacu królewskim, a uczyli się pisma i języka chaldejskiego.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí kò ní àbùkù ara, tí wọ́n rẹwà, tí wọ́n sì fi ìfẹ́ sí ẹ̀kọ́ hàn, tí wọ́n sì ní ìmọ̀, tí òye tètè ń yé àti àwọn tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ṣiṣẹ́ ní ààfin ọba kí ó kọ́ wọ́n ní èdè àti onírúurú ẹ̀kọ́ ìwé ti àwọn Babeli.
5 I postanowił im król obrok na każdy dzień z potraw swoich królewskich i z wina, które on sam pijał, a żeby ich tak chował przez trzy lata, a po wyjściu ich żeby stawali przed obliczem królewskiem.
Ọba pèsè oúnjẹ ojoojúmọ́ àti wáìnì láti orí tábìlì i rẹ̀ fún wọn, ó sì kọ́ wọn fún ọdún mẹ́ta. Lẹ́yìn náà ni wọn yóò bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ fún ọba.
6 A byli między nimi z synów Judzkich: Danijel, Ananijasz, Misael, i Azaryjasz.
Lára àwọn wọ̀nyí ni àwọn tó wá láti Juda: Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah.
7 I dał im przełożony nad komornikami imiona, a Danijela nazwał Baltazarem, a Ananijasza Sadrachem, a Misaela Mesachem, a Azaryjasza Abednegiem.
Olórí àwọn ìwẹ̀fà fún wọn ní orúkọ tuntun: Ó fún Daniẹli ní Belteṣassari, ó fún Hananiah ní Ṣadraki, ó fún Miṣaeli ní Meṣaki àti Asariah ní Abednego.
8 Ale Danijel postanowił w sercu swojem, żeby się nie mazał pokarmem potraw królewskich, ani winem, które król pijał; przetoż tego szukał u przełożonego nad komornikami, żeby się nie zmazał.
Ṣùgbọ́n Daniẹli pinnu ní ọkàn ara rẹ̀ pé òun kò ní ba ara òun jẹ́ pẹ̀lú oúnjẹ àti wáìnì ọba, nígbà náà ni ó gba ààyè lọ́wọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà wí pé òun kò fẹ́ ba ara òun jẹ́ ní ọ̀nà yìí.
9 I zjednał Bóg Danijelowi łaskę i miłość przed obliczem przełożonego nad komornikami.
Ọlọ́run mú kí Daniẹli rí ojúrere àti àánú gbà láti ọwọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà,
10 I rzekł przełożony nad komornikami do Danijela: Ja się boję króla, pana mego, który wam postanowił pokarm wasz i napój wasz: który jeźliby obaczył, że twarzy wasze chudsze są niż innych młodzieńców, którzy jednako z wami mają być wychowani, tedy mię przyprawicie o gardło u króla.
ṣùgbọ́n olórí àwọn ìwẹ̀fà sọ fún Daniẹli pé, “Mo bẹ̀rù olúwa mi, ẹni tí o ti pèsè oúnjẹ àti ohun mímu rẹ. Báwo ni ìrísí rẹ yóò ṣe burú jù ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ẹlẹgbẹ́ ẹ̀ rẹ lọ? Nígbà náà ni èmi yóò fi orí mi wéwu lọ́dọ̀ ọba.”
11 I rzekł Danijel do sługi, którego był postanowił przełożony nad komornikami nad Danijelem, Ananijaszem, Misaelem i Azaryjaszem:
Nígbà náà ni Daniẹli sọ fún olùṣọ́ tí olórí àwọn ìwẹ̀fà yàn lórí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah pé,
12 Doświadcz proszę sług twoich przez dziesięć dni, a niech nam dadzą jarzyn, którebyśmy jedli, i wody, którąbyśmy pili.
“Jọ̀wọ́ dán àwa ìránṣẹ́ rẹ wò fún ọjọ́ mẹ́wàá. Má ṣe fún wa ní ohun kankan, àfi ewébẹ̀ láti jẹ àti omi láti mu.
13 Potem przypatrzysz się twarzom naszym, i twarzom innych młodzieńców, którzy jadają pokarm z potraw królewskich, a jako obaczysz, tak uczynisz z sługami twymi.
Nígbà náà ni kí o fi ìrísí i wa wé ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba, kí o sì ṣe àwa ìránṣẹ́ rẹ ní ìbámu pẹ̀lú u bí o bá ṣe rí i sí.”
14 I usłuchał ich w tem, a doświadczył ich przez dziesięć dni.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì gbà láti dán wọn wò fún ọjọ́ mẹ́wàá.
15 A po wyjściu dziesięciu dni okazało się, że twarze ich były piękniejsze, i byli tłustsi na ciele, niż wszyscy młodzieńcy, którzy jadali pokarm z potraw królewskich.
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹwàá ara wọn le, wọ́n sì sanra ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba lọ.
16 Przetoż on sługa brał on obrok potraw ich, i wino napoju ich, a dawał im jarzyny.
Bẹ́ẹ̀ ni olùṣọ́ mú oúnjẹ àdídùn àti wáìnì tí ó yẹ kí wọ́n mu kúrò, ó sì fún wọn ní ewébẹ̀ dípò rẹ̀.
17 A onym czterem młodzieńcom dał Bóg umiejętność i rozum we wszelakiem piśmie i mądrości; nadto Danijelowi dał wyrozumienie wszelakiego widzenia i snów.
Ọlọ́run fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ní ìmọ̀ àti òye nínú gbogbo onírúurú ìwé àti ẹ̀kọ́ ọ wọn: Daniẹli sì ní òye ìran àti àlá ní oríṣìíríṣìí.
18 A gdy wyszły dni, po których ich król przyprowadzić rozkazał, przywiódł ich przełożony nad komornikami przed twarz Nabuchodonozora.
Ní òpin ìgbà tí ọba dá, pé kí a mú wọn wá sínú ààfin, olórí àwọn ìwẹ̀fà mú wọn wá síwájú ọba Nebukadnessari.
19 I mówił z nimi król; ale nie był znaleziony między onymi wszystkimi, jako Danijel, Ananijasz, Misael i Azaryjasz; i stawali przed obliczem królewskiem.
Ọba sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì rí i pé kò sí ẹni tí ó dàbí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah; nítorí náà wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe iṣẹ́ ọba.
20 A w każdem słowie mądrości i rozumu, o które się ich król pytał, znalazł ich dziesięć kroć bieglejszych nad wszystkich mędrców i praktykarzy, którzy byli we wszystkiem królewstwie jego.
Nínú gbogbo ọ̀ràn ọgbọ́n àti òye tí ọba ń béèrè lọ́wọ́ wọn, ó rí i pé wọ́n sàn ní ìlọ́po mẹ́wàá ju gbogbo àwọn amòye àti ọlọ́gbọ́n tí ó wà ní gbogbo ìjọba rẹ̀.
21 I był tam Danijel aż do roku pierwszego króla Cyrusa.
Daniẹli sì wà níbẹ̀ títí di ọdún kìn-ín-ní ọba Kirusi.

< Daniela 1 >