< II Samuela 16 >

1 A gdy Dawid zszedł trochę z wierzchu góry, oto Syba, sługa Mefiboseta, zaszedł mu drogę z parą osłów osiodłanych, na których było dwieście chlebów, i sto wiązanek rodzynków, i sto wiązanek fig, i łagiew wina.
Nígbà tí Dafidi sì fi díẹ̀ kọjá orí òkè náà, sì wò ó, Ṣiba ìránṣẹ́ Mefiboṣeti sì ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, òun àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì tí a ti dì ní gàárì, àti igba ìṣù àkàrà lórí wọn, àti ọgọ́rùn-ún síírí àjàrà gbígbẹ, àti ọgọ́rùn-ún èso ẹ̀rún, àti ìgò ọtí wáìnì kan.
2 Tedy rzekł król do Syby: Na cóż to? I odpowiedział Syba: Osły te dla czeladzi królewskiej, aby na nich jeździła, a chleby i figi, aby jedli słudzy, a wino, aby pił, ktoby ustał na puszczy.
Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Kí ni wọ̀nyí?” Ṣiba sì wí pé, “Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ̀nyí ni fún àwọn ará ilé ọba láti máa gùn àti àkàrà yìí, àti èso ẹ̀rún yìí ni fún àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin láti jẹ; àti ọtí wáìnì yìí ni fún àwọn aláàárẹ̀ ní ijù láti mu.”
3 I rzekł mu król: A gdzież jest syn pana twego? I odpowiedział Syba królowi: Oto został w Jeruzalemie; albowiem mówił: Dziś mi przywróci dom Izraelski królestwo ojca mego.
Ọba sì wí pé, “Ọmọ olúwa rẹ dà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, ó jókòó ní Jerusalẹmu; nítorí tí ó wí pé, ‘Lónìí ni ìdílé Israẹli yóò mú ìjọba baba mi padà wá fún mi.’”
4 Zatem rzekł król do Syby: Oto twoje jest wszystko, cokolwiek miał Mefiboset. I rzekł Syba, pokłon uczyniwszy: Niech znajdę łaskę przed oczyma twemi, królu, panie mój.
Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Wò ó, gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Mefiboṣeti jẹ́ tìrẹ.” Ṣiba sì wí pé, “Mo túúbá, jẹ́ kí n rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ, olúwa mi ọba.”
5 I przyszedł król Dawid aż do Bahurym, a oto, stamtąd mąż wyszedł z rodu domu Saulowego, a imię jego było Semej, syn Giery; który wyszedłszy, idąc złorzeczył.
Dafidi ọba sì dé Bahurimu, sì wò ó, ọkùnrin kan ti ibẹ̀ jáde wá, láti ìdílé Saulu wá, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣimei, ọmọ Gera, ó sì ń bú èébú bí o tí ń bọ̀.
6 A ciskał kamieńmi na Dawida, i na wszystkie sługi króla Dawida, choć wszystek lud, i wszystko rycerstwo szło po prawej stronie jego, i po lewej stronie jego.
Ó sì sọ òkúta sí Dafidi, àti sí gbogbo ìránṣẹ́ Dafidi ọba, àti sí gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn alágbára ọkùnrin sì wà lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti lọ́wọ́ òsì rẹ̀.
7 I tak mówił Semej, złorzecząc mu: Wynijdź, wynijdź mężu krwi, i mężu niezbożny.
Báyìí ni Ṣimei sì wí nígbà tí ó ń yọ èébú, “Jáde, ìwọ ọkùnrin ẹ̀jẹ̀, ìwọ ọkùnrin Beliali.
8 Obrócił na cię Pan wszystkę krew domu Saulowego, na któregoś miejscu królował, a podał Pan królestwo w ręce Absaloma, syna twego; a otoś ty we złem twojem, boś jest mężem krwi.
Olúwa mú gbogbo ẹ̀jẹ̀ ìdílé Saulu padà wá sí orí rẹ, ní ipò ẹni tí ìwọ jẹ ọba; Olúwa ti fi ìjọba náà lé Absalomu ọmọ rẹ lọ́wọ́: sì wò ó, ìwà búburú rẹ ni ó mú èyí wá bá ọ, nítorí pé ọkùnrin ẹ̀jẹ̀ ni ìwọ.”
9 I rzekł Abisaj, syn Sarwii, do króla: Czemuż złorzeczy ten zdechły pies królowi, panu memu? Niech idę proszę, a utnę głowę jego.
Abiṣai ọmọ Seruiah sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí òkú ajá yìí fi ń bú olúwa mi ọba? Jẹ́ kí èmi kọjá, èmi bẹ̀ ọ́, kí èmi sì bẹ́ ẹ́ lórí.”
10 Ale król rzekł: Cóż wam do tego, synowie Sarwii, że złorzeczy? Ponieważ mu Pan rzekł: Złorzecz Dawidowi, i któżby śmiał rzec: Czemu tak czynisz?
Ọba sì wí pé, “Kín ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah? Bí ó bá ń bú èébú, nítorí tí Olúwa ti wí fún un pé, ‘Bú Dafidi!’ Ta ni yóò sì wí pé, ‘Kín ni ìdí tí o fi ṣe bẹ́ẹ̀.’”
11 Nadto rzekł Dawid do Abisajego i do wszystkich sług swoich: Oto syn mój, który wyszedł z żywota mego, szuka duszy mojej, jakoż daleko więcej teraz syn Jemini? Zaniechajcie go, niech złorzeczy; boć mu Pan rozkazał.
Dafidi sì wí fún Abiṣai, àti fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, ọmọ mi tí ó ti inú mi wá, ń wá mi kiri, ǹjẹ́ mélòó mélòó ni ará Benjamini yìí yóò sì ṣe? Fi í sílẹ̀, sì jẹ́ kí o máa yan èébú; nítorí pé Olúwa ni ó sọ fún un.
12 Snać wejrzy Pan na utrapienie moje, a odda mi Pan dobrem za złorzeczenia jego dzisiejsze.
Bóyá Ọlọ́run yóò wo ìpọ́njú mi, Olúwa yóò sì fi ìre san án fún mi ní ipò èébú rẹ̀ lónìí.”
13 A tak szedł Dawid, i mężowie jego drogą, a Semej szedł stroną góry przeciwko niemu, a idąc złorzeczył, i ciskał kamieńmi przeciw niemu, i miotał prochem.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń lọ ní ọ̀nà, Ṣimei sì ń rìn òdìkejì òkè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, ó sì ń yan èébú bí ó ti ń lọ, ó sì ń sọ ọ́ lókùúta, ó sì ń fọ́n erùpẹ̀.
14 I przyszedł król ze wszystkim ludem, który był przy nim spracowany, i tamże odpoczął.
Ọba, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì dé Jordani, ó sì rẹ̀ wọ́n, wọ́n sì sinmi níbẹ̀.
15 Lecz Absalom i wszystek lud mężów Izraelskich, przyszli do Jeruzalemu, także i Achitofel z nim.
Absalomu àti gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn ọkùnrin Israẹli sì wá sí Jerusalẹmu, Ahitofeli sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
16 A gdy szedł Chusaj Arachita, przyjaciel Dawida, do Absaloma, rzekł Chusaj do Absaloma: Niech żyje król, niech żyje król!
Ó sì ṣe, nígbà tí Huṣai ará Arki, ọ̀rẹ́ Dafidi tọ Absalomu wá, Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Kí ọba ó pẹ́! Kí ọba ó pẹ́.”
17 Tedy rzekł Absalom do Chusaja: A takaż to miłość twoja ku przyjacielowi twemu? przeczżeś nie szedł z przyjacielem twoim?
Absalomu sì wí fún Huṣai pé, “Oore rẹ sí ọ̀rẹ́ rẹ ni èyí? Èéṣe tí ìwọ kò bá ọ̀rẹ́ rẹ lọ?”
18 Odpowiedział Chusaj Absalomowi: Nie; ale którego obrał Pan, i lud ten, i wszyscy mężowie Izraelscy, tego będę, i z nim zostanę.
Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ nítorí ẹni tí Olúwa, àti gbogbo àwọn ènìyàn yìí, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli bá yàn, tirẹ̀ lèmi ó jẹ́, òun lèmi ó sì bá jókòó.
19 Do tego, komuż ja będę służył? izali nie synowi jego? Jakom służył ojcu twemu, tak będę i tobie.
Àti pé, ta ni èmi ó sì sìn? Kò ha yẹ kí èmi ó máa sìn níwájú ọmọ rẹ̀? Gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń sìn rí níwájú baba rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sìn níwájú rẹ.”
20 Rzekł potem Absalom do Achitofela: Radźcież, co mam czynić?
Absalomu sì wí fún Ahitofeli pé, “Ẹ bá ará yín gbìmọ̀ ohun tí àwa ó ṣe.”
21 Odpowiedział Achitofel Absalomowi: Wnijdź do założnic ojca twego, które zostały, aby strzegły domu; a usłyszawszy wszystek Izrael, żeś się omierzył ojcu twemu, zmocnią się ręce wszystkich, którzy są z tobą.
Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ lọ, tí ó fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́ pé, ìwọ di ẹni ìríra sí baba rẹ, ọwọ́ gbogbo àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ yóò sì le.”
22 Przetoż rozbili Absalomowi namiot na dachu. I szedł Absalom do założnic ojca swego przed oczyma wszystkiego Izraela.
Wọ́n sì tẹ́ àgọ́ kan fún Absalomu ní òrùlé; Absalomu sì wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ̀ lójú gbogbo Israẹli.
23 A rada Achitofelowa, którą dawał, była na on czas w takiej wadze, jakoby się kto radził Boga. Takować była wszelka rada Achitofelowa, jako u Dawida, tak u Absaloma.
Ìmọ̀ Ahitofeli tí ó máa ń gbà ni ìgbà náà, ó dàbí ẹni pé ènìyàn béèrè nǹkan lọ́wọ́ Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ìmọ̀ Ahitofeli fún Dafidi àti fún Absalomu sì rí.

< II Samuela 16 >