< II Królewska 24 >

1 Za dni jego wyciągnął Nabuchodonozor, król Babiloński. I stał się Joakim niewolnikiem jego przez trzy lata, a potem wybił się z mocy jego.
Nígbà ìjọba Jehoiakimu, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun sí ilẹ̀ náà, Jehoiakimu sì di ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́ta. Ṣùgbọ́n nígbà náà ó yí ọkàn rẹ̀ padà ó sì ṣọ̀tẹ̀ sí Nebukadnessari.
2 Przetoż posłał Pan przeciwko niemu wojska Chaldejskie, i wojsko Syryjskie, i wojska Moabskie, i wojska synów Ammonowych; i posłał je na Judę, aby go wytracili według słowa Pańskiego, które był powiedział przez sługi swe proroki.
Olúwa sì rán àwọn ará Babeli, àwọn ará Aramu, àwọn ará Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni. Ó rán wọn láti pa Juda run, ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ nípasẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì.
3 Zaiste stało się to podług słowa Pańskiego przeciwko Judzie, aby go odrzucił od oblicza swego dla grzechów Manasesowych, według wszystkiego, co był uczynił;
Nítòótọ́ eléyìí ṣẹlẹ̀ sí Juda gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa, láti mú wọn kúrò níwájú rẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ Manase àti gbogbo nǹkan tí ó ṣe.
4 I dla krwi niewinnej, którą wylewał, i napełnił Jeruzalem krwią niewinną, czego mu nie chciał Pan odpuścić.
Àti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ tí a ta sílẹ̀ nítorí ó ti kún Jerusalẹmu pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ tí Olúwa kò sì fẹ́ láti dáríjì.
5 A inne sprawy Joakimowe, i wszystko co czynił, zapisane w kronikach o królach Judzkich.
Ní ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoiakimu, àti gbogbo nǹkan tí ó ṣe, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ọba Juda?
6 A tak zasnął Joakim z ojcami swymi, a królował Joachyn, syn jego, miasto niego.
Jehoiakimu sùn pẹ̀lú baba rẹ̀, Jehoiakini ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
7 Ale nie ruszał się więcej król Egipski z ziemi swej. Bo był wziął król Babiloński wszystko od rzeki Egipskiej aż do rzeki Eufrates, co przynależało królowi Egipskiemu.
Ọba Ejibiti kò sì tún jáde ní ìlú rẹ̀ mọ́, nítorí ọba Babeli ti gba gbogbo agbègbè rẹ̀ láti odò Ejibiti lọ sí odò Eufurate.
8 Ośmnaście lat miał Joachyn, gdy królować począł, a trzy miesiące królował w Jeruzalemie. Imię matki jego było Nehusta, córka Elnatanowa z Jeruzalemu.
Jehoiakini jẹ́ ẹni ọdún méjìdínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Nehuṣita ọmọbìnrin Elnatani; ó wá láti Jerusalẹmu.
9 I czynił złe przed oczyma Pańskiemi, według wszystkiego, jako czynił ojciec jego.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ ti ṣe.
10 Czasu onego przyciągnęli słudzy Nabuchodonozora, króla Babilońskiego, przeciwko Jeruzalemowi, i przyszło miasto w oblężenie.
Ní àkókò náà àwọn ìránṣẹ́ Nebukadnessari ọba Babeli gbé ogun wá Jerusalẹmu, wọ́n sì gbé dó ti ìlú náà,
11 Przyciągnął też Nabuchodonozor, król Babiloński, przeciwko miastu, gdy słudzy jego leżeli około niego.
Nebukadnessari ọba Babeli fúnra rẹ̀ wá sókè sí ìlú nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ fi ogun dó tì í.
12 Tedy wyszedł Joachyn, król Judzki, do króla Babilońskiego, on i matka jego, i słudzy jego, i książęta jego, i dworzanie jego, i wziął go król Babiloński roku ósmego królowania swego.
Jehoiakini ọba Juda àti ìyá rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìwẹ̀fà àti àwọn ìjòyè gbogbo wọn sì jọ̀wọ́ ara wọn fún un. Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀ ti ọba Babeli ó mú Jehoiakini ẹlẹ́wọ̀n.
13 I wyniósł stamtąd wszystkie skarby domu Pańskiego, i skarby domu królewskiego, i potłukł wszystkie naczynia złote, które był sprawił Salomon, król Izraelski, w kościele Pańskim, jako był powiedział Pan.
Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ Nebukadnessari kó gbogbo ìṣúra láti inú ilé Olúwa àti láti ilé ọba, ó sì mú u lọ gbogbo ohun èlò wúrà ti Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Olúwa.
14 I przeniósł wszystko Jeruzalem, i wszystkich książąt, i wszystek lud rycerski, więźniów dziesięć tysięcy, i wszystkich cieśli, i kowali, a nie został tam nikt, oprócz ubogiego ludu onej ziemi.
Ó kó wọn lọ sí ìgbèkùn gbogbo Jerusalẹmu: gbogbo ìjòyè àti àwọn akọni alágbára ọkùnrin, àti gbogbo oníṣọ̀nà àti ọlọ́nà tí àpapọ̀ rẹ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá, àwọn tálákà ènìyàn ilẹ̀ náà nìkan ni ó kù.
15 Przeniósł i Joachyna do Babilonu, i matkę królewską, i żony królewskie, i dworzan jego, i rycerski lud onej ziemi zawiódł w niewolę z Jeruzalemu do Babilonu.
Nebukadnessari mú Jehoiakini ní ìgbèkùn lọ sí Babeli. Ó sì tún mú ìyá ọba láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, ìyàwó rẹ̀ àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn olórí ilé náà.
16 Wszystkich też mężów walecznych siedm tysięcy, i cieśli, także i kowali tysiąc, i wszystkich godnych ku bojowi, tych zawiódł w niewolę król Babiloński do Babilonu.
Àti gbogbo àwọn ọkùnrin ọlọ́lá tí ó jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin alágbára ọkùnrin, àti àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ, ẹgbẹ̀rún, gbogbo àwọn alágbára tí ó yẹ fún ogun ni ọba Babeli kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli.
17 A królem postanowił król Babiloński króla Matanijasza, stryja jego, miasto niego, i odmienił mu imię, a nazwał go Sedekijasz.
Ọba Babeli sì mú Mattaniah arákùnrin baba Jehoiakini, jẹ ọba ní ìlú rẹ̀ ó sì yí orúkọ rẹ̀ padà sí Sedekiah.
18 Dwadzieścia i jeden lat miał Sedekijasz, gdy królować począł, a jedenaście lat królował w Jeruzalemie; a imię matki jego było Chamutal, córka Jermijaszowa z Lebny.
Sedekiah jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó sì wá láti Libina.
19 I czynił złe przed oczyma pańskiemi według wszystkiego, jako czynił Joakim.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Jehoiakimu ti ṣe.
20 Albowiem się to stało dla rozgniewania Pańskiego przeciwko Jeruzalemowi i Judzie, aż je odrzucił od twarzy swojej. Wtem zasię odstąpił Sedekijasz od króla Babilońskiego.
Nítorí tí ìbínú Olúwa, ni gbogbo èyí ṣe ṣẹ sí Jerusalẹmu, àti Juda, ní òpin ó ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀. Nísinsin yìí Sedekiah sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Babeli.

< II Królewska 24 >