< II Królewska 10 >

1 A miał Achab siedmdziesiąt synów w Samaryi. I napisał Jehu list, a posłał go do Samaryi do książąt Jezreelskich, i do starszych i do tych, którzy wychowywali syny Achabowe, w te słowa:
Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
2 Skoro was dojdzie ten list, gdyż u was są synowie pana waszego, i u was wozy, i konie, i miasto obronne, i rynsztunek;
“Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
3 Obierzcież najgodniejszego i najsposobniejszego z synów pana waszego, a posadźcie na stolicy ojca jego, i walczcie o dom pana waszego.
yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
4 Ale się oni bardzo bojąc rzekli: Oto dwaj królowie nie ostali się przed nim, a jakoż my się ostoimy?
Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
5 A tak posłał ten, który był sprawcą domu, i ten, który był sprawcą miasta, i starsi, i ci, którzy wychowywali syny królewskie, do Jehu, mówiąc: Słudzyśmy twoi, a co nam rozkażesz, uczynimy. Nie postanowiemy króla żadnego; co dobrego jest w oczach twoich, czyń.
Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
6 I napisał do nich list drugi, mówiąc: Jeźliście moi, a głosu mego słuchacie, weźmijcież głowy synów pana waszego, a przyjdźcie do mnie jutro o tym czasie do Jezreel. A synów królewskich było siedmdziesiąt mężów u najprzedniejszych w mieście, którzy je wychowywali.
Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
7 A gdy ich list doszedł, wziąwszy syny królewskie, pobili onych siedmdziesiąt mężów, a składłszy głowy ich do koszów, posłali je do niego do Jezreela.
Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
8 I przyszedł poseł, który mu oznajmił, mówiąc: Przyniesiono głowy synów królewskich. A on rzekł: Składźcie je na dwie kupie u wejścia bramy aż do poranku.
Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
9 A gdy rano wyszedł, stanął, i rzekł do wszystkiego ludu: Sprawiedliwiście wy. Otom się ja sprzysiągł przeciwko panu memu, i zabiłem go; ale te wszystkie któż pobił?
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
10 Wiedzcież teraz, że nie upadło próżno żadne z słów Pańskich na ziemię, które mówił Pan przeciwko domowi Achabowemu, gdyż uczynił Pan, co był powiedział przez sługę swego Elijasza.
Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
11 A tak pobił Jehu wszystkie, którzy pozostali z domu Achabowego w Jezreelu, i wszystkie najprzedniejsze jego, i przyjaciele jego, i kapłany jego, tak iż nie zostawił po nim żadnego żywego.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
12 Potem wstawszy odszedł, i pojechał do Samaryi. A gdy był a domu, gdzie pasterze strzygali owce na drodze,
Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
13 Tedy Jehu znalazł u braci Ochozyjasza króla Judzkiego, i rzekł: Któście wy? I odpowiedzieli: Braciaśmy Ochozyjaszowi, a idziemy, abyśmy pozdrowili syny królewskie, i syny królowej.
Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
14 Tedy rzekł: Pojmajcie je żywo. I pojmali je żywo, i pobili je u studni onegoż domu, gdzie strzygano owce, czterdziestu i dwóch mężów, i nie zostawił żadnego z nich.
“Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
15 Potem odjechawszy stamtąd, trafił Jonadaba, syna Rechabowego, idącego przeciwko sobie, a pozdrowił go i rzekł do niego: Jestże serce twoje szczere, jako serce moje z sercem twojem? I odpowiedział mu Jonadab: Jest. A jest? rzekł Jehu, dajże mi rękę twoję. Tedy mu dał rękę swą; i kazał mu wsiąść do siebie na wóz.
Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
16 I rzekł: Jedź ze mną, a przypatrz się gorliwości mojej za Pana. A tak wiózł go na wozie swoim.
Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
17 A gdy przyjechał do Samaryi, bił wszystkie, którzy byli pozostali z domu Achabowego w Samaryi, i wytracił je według słowa Pańskiego, który mówił do Elijasza.
Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
18 Zatem zebrał Jehu wszystek lud, i rzekł do niego: Achab służył Baalowi mało, Jehu mu będzie służył więcej.
Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
19 Przetoż teraz wszystkich proroków Baalowych, i wszystkich sług jego, i wszystkich kapłanów jego, zwołajcie do mnie aż do jednego; albowiem ofiarę wielką będę sprawował Baalowi. Ktoby się kolwiek nie stawił, nie zostanie żyw. A to Jehu chytrze czynił, chcąc wytracić chwalce Baalowe.
Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
20 Nadto rzekł Jehu: Zapowiedzcie święto Baalowi. I obwołano je.
Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
21 I rozesłał Jehu do wszystkiego Izraela. I zeszli się wszyscy chwalcy Baalowi, tak że nie został żaden, któryby nie przyszedł. I weszli do kościoła Baalowego, a napełniony był dom Baalowy od końca aż do końca.
Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
22 Tedy rzekł temu, który był nad szatami: Wynieś szaty wszystkim chwalcom Baalowym. I wyniósł im szaty.
Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
23 Zatem wszedł Jehu i Jonadab, syn Rechabowy, do domu Baalowego, i rzekł chwalcom Baalowym: Dowiedzcie się, a obaczcie, by snać nie był kto z wami z chwalców Pańskich, oprócz samych chwalców Baalowych.
Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
24 A tak weszli, aby sprawowali ofiary, i całopalenia. Ale Jehu sporządził był sobie na dworze ośmdziesiąt mężów, którym był rzekł: Jeźliby kto uszedł z ludu tego, który ja podawam w ręce wasze, dusza wasza będzie za duszę onego.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
25 A gdy się dokończyły ofiary całopalenia, rzekł Jehu żołnierzom i rotmistrzom swym: Wnijdzcie, a pomordujcie je, aby żaden nie uszedł. A tak pomordowali je ostrzem miecza, i rozrzucili je żołnierze i rotmistrze; potem odeszli do każdego miasta, gdzie był dom Baalowy.
Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
26 A wyrzuciwszy bałwany z domu Baalowego, popalili je.
Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
27 Obalili też słup Baalowy, obalili i dom jego, a uczynili z niego wychody, aż do tego czasu.
Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
28 A tak wygładził Jehu Baala z Izraela.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
29 Wszakże od grzechów Jeroboama, syna Nabatowego, który do grzechu przywiódł Izraela, nie odstąpił Jehu, ani opuścił cielców złotych, które były w Betel, i które były w Dan.
Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
30 Tedy rzekł Pan do Jehu: Ponieważeś się pilnie starał, abyś uczynił, co dobrego jest w oczach moich, według wszystkiego, co było w sercu mojem, uczyniłeś domowi Achabowemu: synowie twoi aż do czwartego pokolenia siedzieć będą na stolicy Izraelskiej.
Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
31 Ale Jehu nie strzegł tego, aby chodził w zakonie Pana, Boga Izraelskiego, ze wszystkiego serca swego, ani odstąpił od grzechów Jeroboamowych, który do grzechu przywiódł Izraela.
Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
32 W one dni począł Pan umniejszać Izraela: bo je poraził Hazael po wszystkich granicach Izraelskich:
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
33 Od Jordanu aż na wschód słońca, wszystkę ziemię Galaadską, Gadową, i Rubenową, i Manasesową od Aroer, które jest u potoku Arnon, i Galaad, i Basan.
Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
34 Ale ostatek spraw Jehu, i wszystko, co czynił, i wszystka moc jego, azaż tego nie napisano w kronikach królów Izraelskich?
Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
35 I zasnął Jehu z ojcami swymi, i pochowali go w Samaryi; a królował Joachaz, syn jego, miasto niego.
Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
36 A czas, którego królował Jehu nad Izraelem w Samaryi, było dwadzieścia i ośm lat.
Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.

< II Królewska 10 >