< II Kronik 20 >

1 I stało się potem, że przyciągnęli synowie Moabowi, i synowie Ammonowi, a z nimi niektórzy mieszkający z Ammonitami, przeciwko Jozafatowi na wojnę.
Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
2 I przyszło, a opowiedziano Jozafatowi, mówiąc: Przyciągnęło przeciwko tobie wojsko wielkie z zamorza, z Syryi, a oto są w Chasesontamar, które jest Engaddy.
Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
3 I uląkł się, a obrócił Jozafat twarz swoję, aby szukał Pana, i zapowiedział post wszystkiemu ludowi Judzkiemu.
Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
4 Tedy się zgromadził lud Judzki, aby szukali Pana; także ze wszystkich miast Judzkich zeszli się szukać Pana.
Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
5 A tak stanął Jozafat w zgromadzeniu Judzkiem i Jeruzalemskiem w domu Pańskiem przed sienią nową.
Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
6 I rzekł: Panie, Boże ojców naszych: Izaliś nie ty sam Bogiem na niebie? a nie ty panujesz na wszystkiemi królestwami narodów? azaż nie w rękach twoich jest moc i siła? a nie masz, ktoby się mógł ostać przed tobą.
O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
7 Izaliś nie ty, Boże nasz! wypędził obywateli tej ziemi przed twarzą ludu twego Izraelskiego, i podałeś ją nasieniu Abrahama przyjaciela twego na wieki?
Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
8 I miszkali w niej, i zbudowali tobie w niej świątnicę dla imienia twego, mówiąc:
Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
9 Jeźliby na nas przyszło złe, miecz pomsty, albo powietrze, albo głód, a staniemy przed tym domem, i przed obliczem twojem, gdyż imię twoje jest w domu tym, a zawołamy do ciebie w uciskach naszych, tedy wysłuchasz i wybawisz.
‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
10 Teraz tedy, oto synowie Ammonowi, i Moabowi, i góra Seir, przez którycheś ty nie dopuścił przejść Izraelowi, gdy szli z ziemi Egipskiej, ale ich minęli, a nie wytracili ich.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
11 Oto teraz nam oni oddawają, gdyż przyszli, aby nas wyrzucili z dziedzictwa twego, któreś nam dał prawem dziedzicznem.
Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
12 O Boże nasz! izali ich nie będziesz sądził? W nasci zaiste nie masz żadnej mocy przeciw mnóstwu tak wielkiemu, które przyszło na nas, i nie wiemy, co czynić mamy, tylko ku tobie obracamy oczy nasze.
Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
13 Wszystek też lud Judzki stał przed Panem, i dziatki ich, żony ich, i synowie ich.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
14 Ale Jehazyjel, syn Zacharyjasza, syna Benajaszowego, syna Jehyjelowego, syna Matanijaszowego, Lewita z synów Asafowych, na którego przyszedł Duch Pański w pośród onego zgromadzenia,
Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
15 Rzekł: Słuchajcie wszyscy z Judy, i obywatele Jeruzalemscy, i ty królu Jozafacie! Tak wam powiada Pan: Nie bójcie się wy, ani się lękajcie tego mnóstwa tak wielkiego; nie wasza jest walka, ale Boża.
Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
16 Jutro się ruszcie przeciwko nim; oto oni pójdą stroną góry Sys, i znajdziecie ich na końcu potoku przeciw puszczy Jeruel.
Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
17 Nie wy się potykać będziecie w tej bitwie; stawcie się, i stójcie, a oglądajcie wybawienie Pańskie nad wami, o Judo, i Jeruzalemie! Nie bójcież się, ani się lękajcie; jutro wynijdziecie przeciwko nim, a Pan będzie z wami.
Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
18 I pokłonił się Jozafat twarzą ku ziemi, a wszystek lud Judzki, i obywatele Jeruzalemscy padli przed obliczem Pańskiem, kłaniając się Panu.
Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
19 Wstali też Lewitowie z synów Kaatowych, i z synów Korego, i chwalili Pana, Boga Izraelskiego, głosem wielkim i wyniosłym.
Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
20 Potem wstawszy rano ciągnęli na puszczę Tekuła; a gdy wychodzili, stanął Jozafat, i rzekł: Słuchajcie mię Judo, i obywatele Jeruzalemscy! Wierzcie Panu, Bogu waszemu, a będziecie bezpieczni; wierzcież prorokom jego, a będzie się wam szczęściło.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
21 A wszedłszy w radę z ludem, postanowił śpiewaków Panu, którzyby go chwalili w ozdobie świętobliwości, idąc przed uszykowanymi do bitwy, i mówiąc: Wysławiajcie Pana, albowiem na wieki miłosierdzie jego.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
22 A wtenczas, gdy oni zaczęli śpiewanie i chwały, obrócił Pan zasadzkę na synów Ammonowych i Moabowych, i na obywateli góry Seir, która była przyszła przeciw Judzie, i bili się sami.
Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
23 Bo powstali synowie Ammonowi i Moabowi przeciwko obywatelom góry Seir, aby ich pobili i wygładzili. A gdy już do końca porazili onych, co mieszkali w Seir, oburzył się jeden przeciw drugiemu, aż się spólnie wybili.
Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
24 A wtem lud Judzki przyszedł do Masfa, blisko puszczy; i spojrzawszy na ono mnóstwo widzieli, a oto trupy leżały po ziemi, tak iż nikt nie uszedł.
Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
25 Przetoż przyszedł Jozafat i lud jego, aby rozchwycili łupy ich; i znaleźli przy nich bardzo wiele bogactw i na trupach klejnotów kosztownych, których rozchwycili między się tak wiele, że ich zanieść nie mogli: przez trzy dni brali one łupy, albowiem ich było bardzo wiele.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
26 Potem dnia czwartego zebrali się w dolinie Beracha; bo iż tam błogosławili Pana, przetoż nazwali imię miejsca onego doliną Beracha, aż do dzisiejszego dnia.
Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
27 Zatem obrócili się wszyscy mężowie Judzcy i Jeruzalemscy, i Jozafat przed nimi, aby się wrócili do Jeruzalemu z radością; albowiem ucieszył ich był Pan nad nieprzyjaciołami ich.
Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
28 I wjechali do Jeruzalemu z harfami, i z cytrami, i z trąbami, do domu Pańskiego.
Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
29 Tedy przypadł strach Boży na wszystkie królestwa ziemi, gdy usłyszały, iż Pan walczył przeciw nieprzyjaciołom ludu Izraelskiego.
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
30 A tak uspokoiło się królestwo Jozafatowe, bo mu dał odpocznienie Bóg jego zewsząd.
Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
31 I królował Jozafat nad Judą, a miał trzydzieści i pięć lat, gdy królować począł, a dwadzieścia i pięć lat królował w Jeruzalemie; a imię matki jego było Azuba, córka Salajowa.
Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
32 A chodził drogą ojca swego Azy, i nie uchylał się od niej, czyniąc co było dobrego w oczach Pańskich.
Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
33 Wszakże wyżyny nie były zniesione; bo jeszcze lud nie zgotował był serca swego ku Bogu ojców swoich.
Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
34 A ostatek spraw Jozafatowych pierwszych i poślednich jest zapisany w księdze Jehu, syna Hananiego, któremu było rozkazane, aby to włożył w księgi królów Izraelskich.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
35 Potem stowarzyszył się Jozafat, król Judzki, z Ochozyjaszem, królem Izraelskim, którego sprawy były bardzo niepobożne.
Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
36 A stowarzyszył się z nim na to, aby nabudowali okrętów, któreby chodziły do Tarsys; i budowali one okręty w Asjongaber.
Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
37 Przetoż prorokował Eliezer, syn Dodawahowy z Maresy, przeciw Jozafatowi mówiąc: Iżeś się stowarzyszył z Ochozyjaszem, rozerwał Pan sprawy twoje, i porozbijały się okręty, i nie mogły iść do Tarsys.
Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.

< II Kronik 20 >