< II Kronik 16 >

1 Roku trzydziestego i szóstego królowania Azy, wyciągnął Baaza, król Izraelski, przeciwko Judzie, i zbudował Ramę, aby nie dopuścił wychodzić i wchodzić nikomu do Azy, króla Judzkiego.
Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
2 Tedy wziąwszy Aza srebro i złoto ze skarbów domu Pańskiego i domu królewskiego, posłał je do Benadada, króla Syryjskiego, który mieszkał w Damaszku, mówiąc:
Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
3 Przymierze jest między mną i między tobą, i między ojcem moim i między ojcem twoim: otoć posyłam srebro i złoto. Idźże, a wzrusz przymierze twoje z Baazą, królem Izraelskim, aby odciągnął odemnie.
“Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
4 I usłuchał Benadad króla Azy, a posławszy hetmanów z wojskami, które miał, przeciwko miastom Izraelskim, zburzył Hijon i Dan i Abelmaim, i wszystkie miasta obronne Neftalimskie, w których były skarby.
Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
5 To gdy usłyszał Baaza, przestał budować Ramy, i zaniechał roboty swej.
Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
6 Tedy król Aza wziąwszy z sobą wszystek lud Judzki, pobrali z Ramy kamienie, i drzewo jego, z którego budował Baaza, a zbudował z niego Gabaa i Masfa.
Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
7 A onegoż czasu przyszedł Hanani, widzący, do Azy, króla Judzkiego, i mówił do niego: Iżeś spoległ na królu Syryjskim, a nie spoległeś na Panu, Bogu twoim, dlatego uszło wojsko króla Syryjskiego z ręki twojej.
Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
8 Azaż Etyjopczycy, i Lubimczycy nie mieli wojsk bardzo wielkich z wozami i z jezdnymi w mnóstwie bardzo wielkiem? a wżdy gdyś spoległ na Panu, podał je w rękę twoję.
Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
9 Albowiem oczy Pańskie przepatrują wszystkę ziemię, aby dokazywał mocy swej przy tych, którzy przy nim stoją sercem doskonałem. Głupioś to uczynił: przetoż od tego czasu powstaną przeciwko tobie wojny.
Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
10 Tedy Aza rozgniewawszy się na widzącego, podał go do więzienia; bo się był nań o to rozgniewał; i utrapił Aza niektórych z ludu onego czasu.
Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
11 Ale inne sprawy Azy pierwsze i pośledniejsze, zapisane są w księgach o królach Judzkich i Izraelskich.
Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
12 Potem rozniemógł się Aza roku trzydziestego i dziewiątego królowania swego, na nogi swoje, chorobą bardzo ciężką; a wszakże w onej chorobie swej nie szukał Pana, ale lekarzy.
Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
13 A tak zasnął Aza z ojcami swymi, a umarł roku czterdziestego i pierwszego królowania swego.
Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
14 I pochowano go w grobie jego, który sobie był wykopał w mieście Dawidowem; i położono go na łożu, które był napełnił rzeczami wonnemi, i rozmaitemi maściami aptekarską robotą przygotowanemi. I palili mu zapał wonny bardzo wielki.
wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.

< II Kronik 16 >