< I Samuela 20 >

1 Ale Dawid uciekłszy z Najotu, który jest w Ramacie, przyszedł, i mówił przed Jonatanem, cóżem uczynił? co za nieprawość moja? i co za grzech mój przeciw ojcu twemu, że szuka duszy mojej?
Nígbà náà ni Dafidi sá kúrò ní Naioti ti Rama ó sì lọ sọ́dọ̀ Jonatani ó sì béèrè pé, “Kí ni mo ṣe? Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Báwo ni mo ṣe ṣẹ baba rẹ, tí ó sì ń wá ọ̀nà láti gba ẹ̀mí mi?”
2 Który mu odpowiedział: Boże uchowaj! nie umrzesz; oto nie czyni ojciec mój nic wielkiego albo małego, aż mi pierwej oznajmi; azażby taić miał ojciec mój przedemną i tego? Nie uczyni tego.
Jonatani dáhùn pé, “Kí a má rí i! Ìwọ kò ní kú! Wò ó baba mi kì í ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí tí ó kéré, láìfi lọ̀ mí. Èéṣe tí yóò fi fi èyí pamọ́ fún mi? Kò rí bẹ́ẹ̀.”
3 A nadto przysiągł Dawid, rzekłszy: Wie zaiste ojciec twój, żem znalazł łaskę w oczach twoich, i myśli: Niech o tem niewie Jonatan, by się snać nie frasował; i owszem jako żywy Pan, żywa i dusza twoja, że tylko krok jeden jest między mną, i między śmiercią.
Ṣùgbọ́n Dafidi tún búra, ó sì wí pé, “Baba rẹ mọ̀ dáradára pé mo rí ojúrere ní ojú rẹ, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, ‘Jonatani kò gbọdọ̀ mọ èyí yóò sì bà á nínú jẹ́.’ Síbẹ̀ nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà láààyè, ìgbésẹ̀ kan ni ó wà láàrín ìyè àti ikú.”
4 I odpowiedział Jonatan Dawidowi: Co mi kolwiek rzecze dusza twoja, uczynięć.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe, èmi yóò ṣe é fún ọ.”
5 Tedy rzekł Dawid do Jonatana: Oto, nów miesiąca jutro, a jam zwykł siadać z królem przy stole; puść mię tedy, że się skryję na polu aż do wieczora trzeciego dnia.
Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Wò ó, ọ̀la ni oṣù tuntun, mo sì gbọdọ̀ bá ọba jẹun, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó lọ láti fi ara pamọ́ lórí pápá títí di àṣálẹ́ ọjọ́ kẹta.
6 A jeźliby się pilnie pytał o mnie ojciec twój, rzeczesz: Prosił mię bardzo Dawid, aby szedł do Betlehem, miasta swego; bo tam ofiarę uroczystą ma sprawować wszystka rodzina jego.
Bí ó bá sì ṣe pé baba rẹ bá fẹ́ mi kù, kí o sì wí fún un pé, ‘Dafidi fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ béèrè ààyè láti sáré lọ sí Bẹtilẹhẹmu ìlú rẹ̀ nítorí wọ́n ń ṣe ẹbọ ọdọọdún ní ibẹ̀ fún gbogbo ìdílé rẹ̀.’
7 Jeźli tak rzecze: Dobrze, pokój będzie słudze twemu; ale jeźli się rozgniewa, wiedz, iż się dopełniła złość jego.
Tí o bá wí pé, ‘Àlàáfíà ni,’ nígbà náà, ìránṣẹ́ rẹ wà láìléwu. Ṣùgbọ́n tí ó bá bínú gidigidi, ìwọ yóò mọ̀ dájú pé ó pinnu láti ṣe ìpalára mi.
8 Przetoż uczyń miłosierdzie nad sługą twoim, gdyżeś w przymierze Pańskie przywiódł z sobą sługę twego; a jeźli we mnie jest nieprawość, ty mię zabij; a do ojca twego przeczbyś mię miał wodzić?
Ṣùgbọ́n ní tìrẹ ìwọ, fi ojúrere wo ìránṣẹ́ rẹ; nítorí tí ìwọ ti bá a dá májẹ̀mú pẹ̀lú rẹ níwájú Olúwa. Tí mo bá jẹ̀bi, pa mí fún ara rẹ! Èéṣe tí ìwọ yóò fi fi mí lé baba rẹ lọ́wọ́?”
9 I rzekł Jonatan: Boże cię tego uchowaj; bo jeźli się pewnie dowiem, że się dopełniła złość ojca mego, aby przyszła przeciw tobie, izalibym ci tego nie oznajmił?
Jonatani wí pé, “Kí a má rí i! Ti mo bá ti gbọ́ tí baba mi ti pinnu láti pa ọ́ lára, ṣé èmi kò ní sọ fún ọ?”
10 I rzekł Dawid do Jonatana: Któż mi oznajmi, jeźliżeć co odpowie ojciec twój przykrego?
Nígbà náà ni Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Ta ni yóò sọ fún mi tí baba rẹ̀ bá dá ọ lóhùn ní ohùn líle?”
11 Odpowiedział Jonatan Dawidowi: Pójdź, a wynijdźmy na pole. I wyszli obaj na pole.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Wá, jẹ́ kí a jáde lọ sórí pápá.” Nígbà náà wọ́n sì jáde lọ.
12 Tedy rzekł Jonatan do Dawida; Pan, Bóg Izraelski, (skoro się wywiem o woli ojca mego o tym czasie jutro, albo dnia trzeciego, a będzie co dobrego o Dawidzie, a jeźli zarazem nie poślę do ciebie, i nie oznajmięć, )
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Mo fi Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli búra pé, èmi yóò rí i dájú pé mo gbọ́ ti ẹnu baba mi ní ìwòyí ọ̀la tàbí ní ọ̀túnla! Bí ó bá sì ní inú dídùn sí ọ, èmi yóò ránṣẹ́ sí ọ, èmi yóò sì jẹ́ kí o mọ̀?
13 To niech uczyni Pan, Bóg Izraelski, mówię, Jonatanowi, i to niech przyczyni. A jeźliże będzie chciał ojciec mój przywieść złe na cię, i toć objawię, i puszczę cię, abyś szedł w pokoju, a niech będzie Pan z tobą, jako był z ojcem moim.
Ṣùgbọ́n tí baba mi bá fẹ́ pa ọ́ lára, kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí Jonatani; tí èmi kò bá jẹ́ kí o mọ̀, kí n sì jẹ́ kí o lọ ní àlàáfíà. Kí Olúwa kí ó wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pẹ̀lú baba mi.
14 Także i ty, będęli żyw, i ty mówię uczynisz ze mną miłosierdzie Pańskie, a choćbym i umarł,
Ṣùgbọ́n fi àìkùnà inú rere hàn mí bí inú rere Olúwa, níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè kí wọ́n má ba à pa mí.
15 Przecię nie oddalisz miłosierdzia twego od domu mego aż na wieki, ani gdy wykorzeni Pan nieprzyjacioły Dawidowe wszystkie z ziemi.
Má ṣe ké àánú rẹ kúrò lórí ìdílé mi títí láé. Bí Olúwa tilẹ̀ ké gbogbo ọ̀tá Dafidi kúrò lórí ilẹ̀.”
16 I uczynił Jonatan przymierze z domem Dawidowym, mówiąc: Niech tego szuka Pan z ręki nieprzyjaciół Dawidowych.
Nígbà náà ni Jonatani bá ilé Dafidi dá májẹ̀mú wí pé, “Olúwa yóò pe àwọn àti Dafidi láti ṣírò.”
17 Nadto jeszcze Jonatan przysiągł Dawidowi przez miłość, którą go miłował; bo jako miłował duszę swoję, tak go też miłował.
Jonatani mú kí Dafidi tún ìbúra ṣe nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí i, nítorí tí ó fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti fẹ́ràn ara rẹ̀.
18 I rzekł do niego Jonatan: Jutro nów miesiąca, a będą się pytać o tobie, ponieważ próżne będzie miejsce twoje.
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Lọ́la ní ibi àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun, a yóò fẹ́ ọ kù, nítorí ààyè rẹ yóò ṣófo.
19 Przetoż przez trzy dni będziesz się ukrywał, i zstąpisz prędko, a przyjdziesz na miejsce, gdzieś się był ukrył, gdy była sprawa o tobie, a będziesz siedział u kamienia Ezel.
Ní ọ̀túnla lọ́wọ́ alẹ́ lọ sí ibi tí o sá pamọ́ sí nígbà tí ìṣòro yìí bẹ̀rẹ̀, kí o sì dúró níbi òkúta Eselu.
20 A ja wystrzelę trzy strzały po bok jego, zmierzając sobie do celu.
Èmi yóò ta ọfà mẹ́ta sí ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀, gẹ́gẹ́ bí i pé mo ta á sí àmì ibìkan.
21 A potem poślę chłopca, mówiąc mu: Idź, najdzij strzały. A jeźli rzekę chłopcu: Owo strzały za tobą sam bliżej, przynieś je, tedy przyjdź; bo masz pokój, i nie stanieć się nic złego, jako żywy Pan.
Èmi yóò rán ọmọdékùnrin kan èmi yóò wí fún un wí pé, ‘Lọ, kí o lọ wá ọfà náà.’ Tí mo bá sọ fún un wí pé, ‘Wò ó, ọfà wọ̀nyí wà ní ibi báyìí ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ rẹ; kó wọn wá síbí,’ kí o sì wá, nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wà ní ààyè, o wà ní àlàáfíà; kò sí ewu.
22 Ale jeźliż rzekę chłopcu: Oto strzały przed tobą tam dalej; idź, bo cię wypuścił Pan.
Ṣùgbọ́n tí mo bá sọ fún ọmọdékùnrin náà pé, ‘Wò ó, àwọn ọfà náà ń bẹ níwájú rẹ,’ ǹjẹ́ máa bá tìrẹ lọ, nítorí Olúwa ni ó rán ọ lọ.
23 A tego, o czemeśmy mówili ja i ty, tego Pan świadkiem będzie między mną a między tobą aż na wieki.
Nípa ọ̀rọ̀ tí èmi àti ìwọ jọ sọ, rántí Olúwa jẹ́ ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti èmi títí láéláé.”
24 A tak skrył się Dawid w polu. A gdy przyszedł nów miesiąca, siadł król do stołu, aby jadł.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sá pamọ́ sínú pápá. Nígbà tí àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun sì dé, ọba sì jókòó láti jẹun.
25 A gdy usiadł król na stolicy swojej według zwyczaju, na stolicy przy ścianie, powstał Jonatan; i siadł Abner podle Saula, a zostało próżne miejsce Dawidowe.
Ọba sì jókòó gẹ́gẹ́ bí ipò o rẹ̀ ní ibi tí ó máa ń jókòó lórí ìjókòó tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri, ní òdìkejì Jonatani, Abneri sì jókòó ti Saulu, ṣùgbọ́n ààyè Dafidi sì ṣófo.
26 Lecz nie rzekł Saul nic onego dnia, bo myślał: Przydało mu się podobno coś, lub jest czystym lub nieczystym.
Saulu kò sọ nǹkan kan ní ọjọ́ náà, nítorí ó rò pé, “Nǹkan kan ti ṣẹlẹ̀ sí Dafidi láti jẹ́ kí ó di aláìmọ́ lóòtítọ́ ó jẹ́ aláìmọ́.”
27 A gdy było nazajutrz dnia wtórego po nowiu miesiąca, było zaś próżne miejsce Dawidowe. I rzekł Saul do Jonatana, syna swego: Czemuż nie przyszedł syn Isajego, ani wczoraj, ani dziś do stołu?
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì, ní ọjọ́ kejì oṣù, ààyè Dafidi sì tún ṣófo. Nígbà náà ni Saulu wí fún ọmọ rẹ̀ Jonatani pé, “Kí ni ó dé tí ọmọ Jese kò fi wá sí ibi oúnjẹ, lánàá àti lónìí?”
28 Odpowiedział Jonatan Saulowi: Usilnie mię prosił Dawid, aby szedł do Betlehem;
Jonatani sì dáhùn pé, “Dafidi bẹ̀ mí tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ fún ààyè láti lọ sí Bẹtilẹhẹmu.
29 I mówił: Puść mię proszę, bo sprawuje ofiarę rodzina nasza w mieście; tamże mię wezwał brat mój. A tak teraz jeźlim znalazł łaskę w oczach twoich, pójdę proszę, i oglądam bracią moję; dla tegoć nie przyszedł do stołu królewskiego.
Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí n lọ, nítorí pé ìdílé wa ń ṣe ìrúbọ ní ìlú, àwọn ẹ̀gbọ́n ọ̀n mi sì ti pàṣẹ fún mi láti wà níbẹ̀; tí èmi bá rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí n lọ láti lọ rí àwọn ẹ̀gbọ́n mi.’ Ìdí nìyìí tí kò fi wá sí orí tábìlì oúnjẹ ọba.”
30 I zapalił się gniewem Saul na Jonatana, i rzekł mu: Synu złośliwy, a upornej matki, azaż nie wiem, iżeś sobie obrał syna Isajego, ku zelżywości twojej, i ku pohańbieniu i sromocie matki twojej?
Ìbínú Saulu sì ru sí Jonatani ó sì wí fún un pé, “Ìwọ ọmọ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀ búburú yìí, ṣé èmi kò ti mọ̀ pé, ìwọ ti yan ọmọ Jese fún ìtìjú ti ara rẹ àti fún ìtìjú màmá rẹ tí ó bí ọ?
31 Bo po wszystkie dni, których syn Isajego będzie żył na ziemi, nie będziesz umocniony, ty i królestwo twoje; a tak teraz poślij, a przywiedź go do mnie, bo jest godzien śmierci.
Níwọ́n ìgbà tí ọmọ Jese bá wà láààyè lórí ilẹ̀ ayé, a kì yóò fi ẹsẹ̀ ìwọ tàbí ti ìjọba rẹ múlẹ̀. Nísinsin yìí ránṣẹ́ kí o sì lọ mú un wá fún mi, nítorí ó gbọdọ̀ kú!”
32 Tedy odpowiedział Jonatan Saulowi, ojcu swemu, i rzekł do niego: Przecz ma umrzeć? cóż uczynił?
Jonatani béèrè lọ́wọ́ baba rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwa yóò fi pa á? Kí ni ó ṣe?”
33 I cisnął Saul włócznią na niego, aby go przebił. Tedy poznał Jonatan, że koniecznie ojciec jego umyślił zabić Dawida.
Ṣùgbọ́n Saulu ju ọ̀kọ̀ rẹ̀ sí Jonatani láti gún un pa. Nígbà náà ni Jonatani mọ̀ pé baba rẹ̀ mọ̀ ọ́n mọ̀ fẹ́ pa Dafidi ni.
34 I wstał Jonatan od stołu z wielkim gniewem, i nie jadł dnia wtórego po nowiu miesiąca chleba; bo się zafrasował o Dawida, a iż go zelżył ojciec jego.
Bẹ́ẹ̀ ni Jonatani sì fi ìbínú dìde kúrò ni ibi oúnjẹ, kò sì jẹun ni ọjọ́ kejì oṣù náà, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ gidigidi fún Dafidi, nítorí pé baba rẹ̀ dójútì í.
35 A rano wyszedł Jonatan na pole według czasu postanowionego z Dawidem, i chłopiec mały z nim.
Ó sì ṣe, ní òwúrọ̀ ni Jonatani jáde lọ sí oko ní àkókò tí òun àti Dafidi ti fi àdéhùn sí, ọmọdékùnrin kan sì wá pẹ̀lú rẹ̀.
36 I rzekł do chłopca swego: Bież, szukaj prędko strzał, które ja wystrzelę. Tedy chłopiec bieżał; a on wystrzelił strzały dalej przedeń.
Ó si wí fún ọmọdékùnrin rẹ̀ pé, “Sáré, kí o si wá àwọn ọfà tí èmi ó ta.” Bí ọmọdé náà sì ti ń sáré, òun sì tafà rékọjá rẹ̀.
37 A gdy przyszedł chłopiec aż na miejsce strzały, którą był wystrzelił Jonatan, zawołał Jonatan za chłopcem, i rzekł: Azaż strzała nie jest za tobą tam dalej?
Nígbà tí ọmọdékùnrin náà sì dé ibi ọfà tí Jonatani ta, Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà ó sì wí pé, “Ọfà náà kò ha wà níwájú rẹ bi?”
38 I wołał Jonatan za chłopcem: Spiesz się co najrychlej, nie stój. Tedy zebrawszy chłopiec Jonatana strzały, przyszedł do pana swego.
Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà pé, “Sáré! Yára! Má ṣe dúró!” Ọmọdékùnrin Jonatani sì ṣa àwọn ọfà náà, ó sì tọ olúwa rẹ̀ wá.
39 (Ale chłopiec nic nie wiedział, tylko Jonatan i Dawid wiedzieli, co się działo.)
(Ọmọdékùnrin náà kò sì mọ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n Jonatani àti Dafidi ni ó mọ ọ̀ràn náà.)
40 I dał Jonatan oręż swój chłopcu, który z nim był, i rzekł mu: Idź, odnieś do miasta.
Jonatani sì fi apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú.”
41 A gdy odszedł chłopiec, Dawid wstał od strony południowej, i upadłszy twarzą swoją na ziemię, ukłonił się po trzy kroć, i pocałowawszy jeden drugiego, płakali pospołu; ale Dawid obficiej.
Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dafidi sì dìde láti ibi ìhà gúúsù òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jonatani, wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sọkún, èkínní pẹ̀lú èkejì rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi sọkún púpọ̀ jù.
42 I rzekł Jonatan do Dawida: Idź w pokoju; a to, cośmy sobie obaj przysięgli przez imię Pańskie, mówiąc: Pan niech będzie między mną i między tobą, i między nasieniem mojem, i między nasieniem twojem świadkiem aż na wieki, trzymać będziemy. A tak wstawszy Dawid odszedł, a Jonatan wszedł do miasta.
Jonatani sì wí fún Dafidi pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí jùmọ̀ búra ni orúkọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrín èmi àti ìwọ, láàrín irú-ọmọ mi àti láàrín irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jonatani sì lọ sí ìlú.

< I Samuela 20 >