< I Samuela 19 >

1 Tedy mówił Saul do Jonatana, syna swego, i do wszystkich sług swoich, aby zabili Dawida; ale Jonatan syn Saula, kochał się w Dawidzie bardzo.
Saulu sọ fún Jonatani ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé kí wọ́n pa Dafidi. Ṣùgbọ́n Jonatani fẹ́ràn Dafidi púpọ̀
2 I oznajmił to Jonatan Dawidowi, mówiąc: Saul, ojciec mój, myśli cię zabić; przetoż teraz strzeż się proszę aż do zaranku, a zataisz się, i skryjesz się.
Jonatani sì kìlọ̀ fún Dafidi pé, “Baba mi Saulu wá ọ̀nà láti pa ọ́, kíyèsi ara rẹ di òwúrọ̀ ọ̀la; lọ sí ibi ìkọ̀kọ̀, kí o sì sá pamọ́ sí ibẹ̀.
3 A ja wynijdę, i stanę podle ojca mego na polu, gdzie ty będziesz, i będę mówił o tobie z ojcem moim, a cokolwiek pobaczę, toć oznajmię.
Èmi yóò jáde lọ láti dúró ní ọ̀dọ̀ baba mi ní orí pápá níbi tí ó wà. Èmi yóò sọ̀rọ̀ fún un nípa à rẹ, èmi yóò sì sọ ohun tí òun bá wí fún ọ.”
4 A tak mówił Jonatan o Dawidzie dobrze do Saula, ojca swego, i rzekł do niego: Niech nie grzeszy król przeciwko słudze swemu Dawidowi: boć nic nie winien, owszem sprawy jego byłyć bardzo pożyteczne;
Jonatani sọ̀rọ̀ rere nípa Dafidi fún Saulu baba rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Má ṣe jẹ́ kí ọba kí ó ṣe ohun tí kò dára fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀; nítorí tí kò ṣẹ̀ ọ́, ohun tí ó sì ṣe pé ọ púpọ̀.
5 Gdyż położył duszę swą w ręce swej, i zabił Filistyńczyka, i uczynił Pan wybawienie wielkie wszystkiemu Izraelowi. Coś widział, i uradowałeś się. Przeczżebyś tedy miał grzeszyć przeciw krwi niewinnej, chcąc zabić Dawida bez przyczyny?
Ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu nígbà tí ó pa Filistini. Olúwa ṣẹ́ ogun ńlá fún gbogbo Israẹli, ìwọ rí i inú rẹ dùn. Ǹjẹ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Dafidi aláìṣẹ̀, tí ìwọ yóò fi pa á láìnídìí?”
6 I usłuchał Saul słów Jonatanowych, i przysiągł Saul: Jako żywy Pan, że nie umrze.
Saulu fetísí Jonatani, ó sì búra báyìí, “Níwọ́n ìgbà tí Olúwa bá ti ń bẹ láààyè, a kì yóò pa Dafidi.”
7 A tak przyzwał Jonatan Dawida, i opowiedział mu Jonatan wszystkie one słowa; i przywiódł Jonatan Dawida do Saula, i był przed nim, jako i przedtem.
Nítorí náà Jonatani pe Dafidi, ó sì sọ gbogbo àjọsọ wọn fún un. Ó sì mú un wá fún Saulu, Dafidi sì wà lọ́dọ̀ Saulu gẹ́gẹ́ bí i ti tẹ́lẹ̀.
8 I wszczęła się znowu wojna, a ciągnął Dawid, i walczył przeciwko Filistynom, i poraził je porażką wielką, i uciekli przed obliczem jego.
Lẹ́ẹ̀kan an sí i ogun tún wá, Dafidi sì jáde lọ, ó sì bá àwọn ara Filistini jà. Ó sì pa wọn pẹ̀lú agbára, wọ́n sì sálọ níwájú u rẹ̀.
9 Wtem Duch Pański zły przypadł na Saula, który w domu swym siedział, mając włócznią swoję w ręce swej, a Dawid grał ręką swą.
Ṣùgbọ́n ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí orí Saulu bí ó ti jókòó ní ilé e rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀. Bí Dafidi sì ti fọn ohun èlò orin olókùn,
10 I myślił Saul przebić Dawida włócznią aż ku ścianie: ale się uchylił przed Saulem, i uderzyła włócznia w ścianę, a Dawid uciekł, i uszedł onej nocy.
Saulu sì wá ọ̀nà láti gún un mọ́ ògiri pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi yẹ̀ ẹ́ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Saulu ti ju ọ̀kọ̀ náà mọ́ ara ògiri. Ní alẹ́ ọjọ́ náà Dafidi sì fi ara pamọ́ dáradára.
11 Potem posłał Saul posły do domu Dawidowego, aby nań strzegli, i zabili go rano. I oznajmiła to Dawidowi Michol, żona jego, mówiąc: Jeźliże nie ochronisz duszy twojej tej nocy, jutro zabity będziesz.
Saulu rán ènìyàn sí ilé Dafidi láti ṣọ́ ọ kí wọ́n sì pa á ní òwúrọ̀. Ṣùgbọ́n Mikali, ìyàwó Dafidi kìlọ̀ fún un pé, “Tí o kò bá sá fún ẹ̀mí rẹ ní alẹ́ yìí, ní ọ̀la ni a yóò pa ọ́.”
12 Przetoż spuściła Michol Dawida oknem, który uszedłszy uciekł, i zachowany jest.
Nígbà náà Mikali sì gbé Dafidi sọ̀kalẹ̀ ó sì fi aṣọ bò ó.
13 A wziąwszy Michol obraz, położyła na łożu, a wezgłówko z koziej skóry położyła pod głowę jego, i przykryła szatą.
Mikali gbé ère ó sì tẹ́ e lórí ibùsùn, ó sì fi irun ewúrẹ́ sí ibi orí rẹ̀.
14 Tedy posłał Saul posły, aby porwali Dawida; ale rzekła: Choruje.
Nígbà ti Saulu rán ènìyàn láti lọ fi agbára mú Dafidi, Mikali wí pé, “Ó rẹ̀ ẹ́.”
15 Znowu posłał Saul posły, aby oglądali Dawida, mówiąc: Przynieście go na łożu do mnie, abym go zabił.
Nígbà náà ni Saulu rán ọkùnrin náà padà láti lọ wo Dafidi ó sì sọ fún wọn pé, “Mú wa fún mi láti orí ibùsùn rẹ̀ kí èmi kí ó le pa á.”
16 A gdy przyszli posłowie, oto obraz na łożu, a wezgłówko z koziej skóry pod głowami jego.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ère ni ó bá lórí ibùsùn àti irun ewúrẹ́ ní orí ère náà.
17 I rzekł Saul do Michol: Czemuś mię tak oszukała, a wypuściłaś nieprzyjaciela mego, aby uszedł? Tedy rzekła Michol Saulowi: Bo mi mówił, puść mię, inaczej zabiję cię.
Saulu wí fún Mikali pé, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí báyìí tí o sì jẹ́ kí ọ̀tá mi sálọ tí ó sì bọ́?” Mikali sọ fún un pé, “Ó wí fún mi, ‘Jẹ́ kí èmi ó lọ. Èéṣe tí èmi yóò fi pa ọ́?’”
18 A tak Dawid uciekłszy uszedł, a przyszedł do Samuela, do Ramaty, i oznajmił mu wszystko, co mu czynił Saul. Poszedł tedy on i Samuel, a mieszkali w Najot.
Nígbà tí Dafidi ti sálọ tí ó sì ti bọ́, ó sì lọ sọ́dọ̀ Samuẹli ní Rama ó sì sọ gbogbo ohun tí Saulu ti ṣe fún un. Òun àti Samuẹli lọ sí Naioti láti dúró níbẹ̀.
19 I oznajmiono Saulowi, mówiąc: Oto Dawid jest w Najot w Ramacie.
Ọ̀rọ̀ sì tọ Saulu wá pé, “Dafidi wà ní Naioti ní Rama,”
20 Tedy posłał Saul posły, aby pojmali Dawida; którzy gdy ujrzeli gromadę proroków prorokujących, i Samuela stojącego, a przełożonego nad nimi, przyszedł i na posły Saulowe Duch Boży, a prorokowali i oni.
Saulu sì rán àwọn ènìyàn láti fi agbára mú Dafidi wá ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Samuẹli dúró níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì wá sórí àwọn arákùnrin Saulu àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀.
21 Co gdy oznajmiono Saulowi, posłał inne posły, a prorokowali oni. Znowu tedy Saul posłał i trzecie posły, lecz prorokowali i ci.
Wọ́n sì sọ fún Saulu nípa rẹ̀, ó sì rán ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn lọ àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀. Saulu tún rán oníṣẹ́ lọ ní ìgbà kẹta, àwọn náà bẹ̀rẹ̀ sí ní sọtẹ́lẹ̀.
22 Potem szedł i sam do Ramaty, i przyszedł aż do studni wielkiej, która jest w Sokot, i pytał się a mówił: Gdzie jest Samuel i Dawid? i powiedziano mu: Oto są w Najot w Ramacie.
Nígbẹ̀yìn, òun fúnra rẹ̀ sì lọ sí Rama ó sì dé ibi àmù ńlá kan ní Seku. Ó sì béèrè, “Níbo ni Samuẹli àti Dafidi wà?” Wọ́n wí pé, “Wọ́n wà ní ìrékọjá ní Naioti ní Rama.”
23 I szedł tam do Najot w Ramacie, a przyszedł też nań Duch Boży; a tak idąc dalej prorokował, aż przyszedł do Najot w Ramacie.
Saulu sì lọ sí Naioti ni Rama. Ṣùgbọ́n, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e lórí ó sì ń lọ lọ́nà, ó sì ń sọtẹ́lẹ̀ títí tí ó fi dé Naioti.
24 I zewlekł też sam szaty swoje, a prorokował i on przed Samuelem, a padłszy leżał nagim przez on cały dzień i przez całą noc; stądże weszło w przypowieść: Azaż i Saul między prorokami?
Ó sì bọ́ aṣọ rẹ̀, òun pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú Samuẹli. Ó sì dùbúlẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà àti ní òru. Ìdí nìyìí tí àwọn ènìyàn fi wí pé, “Ṣé Saulu náà wà lára àwọn wòlíì ni?”

< I Samuela 19 >