< Zacharie 8 >

1 La parole de l'Eternel des armées me fut encore [adressée], en disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun si tún tọ́ mí wá.
2 Ainsi a dit l'Eternel des armées: J'ai été jaloux pour Sion d'une grande jalousie, et j'ai été jaloux pour elle avec une grande indignation.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Owú ńlá ńlá ni mo jẹ fún Sioni, pẹ̀lú ìbínú ńlá ńlá ni mo fi jowú fún un.”
3 Ainsi a dit l'Eternel: Je me suis retourné vers Sion, et j'habiterai au milieu de Jérusalem; et Jérusalem sera appelée, Ville de vérité; et la montagne de l'Eternel des armées [sera appelée], montagne de sainteté.
Báyìí ni Olúwa wí, “Mo yípadà sí Sioni èmi ó sì gbé àárín Jerusalẹmu. Nígbà náà ni a ó sì pé Jerusalẹmu ni ìlú ńlá òtítọ́; àti òkè ńlá Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni a ó pè ní òkè ńlá mímọ́.”
4 Ainsi a dit l'Eternel des armées: Il demeurera encore des vieillards et des vieilles femmes dans les places de Jérusalem, et chacun aura son bâton à la main à cause de son grand âge.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Arúgbó ọkùnrin, àti arúgbó obìnrin, yóò gbé ìgboro Jerusalẹmu, àti olúkúlùkù pẹ̀lú ọ̀pá ni ọwọ́ rẹ̀ fún ogbó.
5 Et les place de la ville seront remplies de fils et de filles, qui se joueront dans ses places.
Ìgboro ìlú yóò sì kún fún ọmọdékùnrin, àti ọmọdébìnrin, tí ń ṣiré ní ìta wọn.”
6 Ainsi a dit l'Eternel des armées: S'il semble difficile devant les yeux du reste de ce peuple, [que cela arrive] en ces jours-là, sera-t-il pourtant difficile devant mes yeux, Dit l'Eternel des armées?
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Bí ó bá ṣe ìyanu ní ojú ìyókù àwọn ènìyàn yìí ni ọjọ́ wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó ha lè jẹ́ ìyanu ni ojú mi bí?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
7 Ainsi a dit l'Eternel des armées: Voici, je m'en vais délivrer mon peuple du pays de l'Orient, et du pays du soleil couchant;
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Kíyèsi i, èmi ó gba àwọn ènìyàn mi kúrò ni ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti kúrò ni ilẹ̀ ìwọ̀-oòrùn.
8 Et je les ferai venir et ils habiteront dans Jérusalem, et ils seront mon peuple, et je serai leur Dieu en vérité et en justice.
Èmi ó sì mú wọn padà wá, wọn ó sì máa gbé àárín Jerusalẹmu. Wọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ní òtítọ́, àti ní òdodo.”
9 Ainsi a dit l'Eternel des armées: Vous qui entendez en ces jours-ci ces paroles de la bouche des Prophètes qui ont été au jour que la maison de l'Eternel a été fondée, et le Temple rebâti, que vos mains soient fortifiées.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Jẹ́ kí ọwọ́ yín le ẹ̀yin ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní ọjọ́ wọ̀nyí ni ẹnu àwọn wòlíì tí ó wà ni ọjọ́ tí a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun lélẹ̀, jẹ́ ki ọwọ́ rẹ̀ le kí a bá lè kọ́ tẹmpili.
10 Car avant ces jours-ci il n'y avait point de salaire pour l'homme, ni de salaire pour la bête; et il n'y avait point de paix pour les allants, ni pour les venants, à cause de la détresse, et j'envoyais tous les hommes l'un contre l'autre.
Nítorí pé, ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, owó ọ̀yà ènìyàn kò tó nǹkan, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀yà ẹran pẹ̀lú, bẹ́ẹ̀ ni kò sí àlàáfíà fún ẹni ń jáde lọ, tàbí ẹni ti ń wọlé bọ, nítorí ìpọ́njú náà: nítorí mo dojú gbogbo ènìyàn, olúkúlùkù kọ aládùúgbò rẹ̀.
11 Mais maintenant je ne [ferai] point à ceux qui sont restés de ce peuple, comme [j'ai fait] les jours précédents; dit l'Eternel des armées.
Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí èmi kì yóò ṣè sí ìyókù àwọn ènìyàn yìí gẹ́gẹ́ bí tí ìgbà àtijọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
12 Mais ce [qu'ils sèmeront] sera une semence de prospérité, la semence de paix [sera là]; la vigne rendra son fruit, et la terre donnera son rapport; les cieux donneront leur rosée, et je ferai hériter toutes ces choses à ceux qui seront restés de ce peuple.
“Nítorí irúgbìn yóò gbilẹ̀, àjàrà yóò ṣo èso rẹ̀, ilẹ̀ yóò sì hu ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan rẹ̀ jáde, àwọn ọ̀run yóò sì mu ìrì wọn wá; èmi ó sì mu kí èyí jẹ ogún ìní àwọn ìyókù ènìyàn yìí ni gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
13 Et il arrivera, ô maison de Juda et maison d'Israël! Que comme vous avez été en malédiction parmi les nations, ainsi je vous en délivrerai, et vous serez en bénédiction; ne craignez point, [mais] que vos mains soient fortifiées.
Yóò sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí jẹ́ ègún láàrín àwọn kèfèrí, ẹ̀yin ilé Juda, àti ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó gbà yín sílẹ̀; ẹ̀yin o sì jẹ́ ìbùkún, ẹ má bẹ̀rù, ṣùgbọ́n jẹ́ ki ọwọ́ yín le.”
14 Car ainsi a dit l'Eternel des armées: Comme j'ai pensé de vous affliger, quand vos pères ont provoqué mon indignation, dit l'Eternel des armées, et je ne m'en suis point repenti;
Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Gẹ́gẹ́ bí mo ti rò láti ṣe yín níbi nígbà tí àwọn baba yín mú mi bínú,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, tí èmi kò sì ronúpìwàdà.
15 Ainsi au contraire je me suis retourné, et j'ai pensé en ces jours-ci de faire du bien à Jérusalem, et à la maison de Juda; ne craignez point.
“Bẹ́ẹ̀ ni èmi sì ti ro ọjọ́ wọ̀nyí láti ṣe rere fún Jerusalẹmu, àti fún ilé Juda: ẹ má bẹ̀rù.
16 [Et] ce sont ici les choses que vous devez faire: Parlez en vérité, chacun avec son prochain; prononcez la vérité et un jugement de paix dans vos portes.
Wọ̀nyí ni nǹkan tí ẹ̀yin ó ṣe: ki olúkúlùkù yín kí ó máa ba ọmọnìkejì rẹ̀ sọ òtítọ́; ṣe ìdájọ́ tòótọ́ àti àlàáfíà ní àwọn ibodè yín.
17 Et que personne ne machine du mal dans son cœur contre son prochain; et n'aimez point le faux serment: car ce sont là des choses que je hais, dit l'Eternel.
Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ro ibi ni ọkàn rẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀; ẹ má fẹ́ ìbúra èké; nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo kórìíra,” ni Olúwa wí.
18 Puis la parole de l'Eternel des armées me fut [adressée], en disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun sì tọ mi wá wí pé.
19 Ainsi a dit l'Eternel des armées: Le jeûne du quatrième mois, et le jeûne du cinquième, et le jeûne du septième, et le jeûne du dixième, seront changés pour la maison de Juda en joie et en allégresse, et en des fêtes solennelles de réjouissance; aimez donc la vérité et la paix.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwẹ̀ oṣù kẹrin, karùn-ún, keje, àti tí ẹ̀kẹwàá, yóò jẹ́ ayọ̀ àti dídùn inú, àti àpéjọ àríyá fún ilé Juda; nítorí náà, ẹ fẹ́ òtítọ́ àti àlàáfíà.”
20 Ainsi a dit l'Eternel des armées: Encore il arrivera que les peuples et les habitants de plusieurs villes viendront;
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Àwọn ènìyàn yóò sá à tún wa, àti ẹni tí yóò gbe ìlú ńlá púpọ̀.
21 Et que les habitants de l'une iront à l'autre, en disant: Allons, allons supplier l'Eternel, et rechercher l'Eternel des armées; Je m'y en irai moi aussi.
Àwọn ẹni tí ń gbé ìlú ńlá kan yóò lọ sí òmíràn, wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a yára lọ gbàdúrà kí a sì wá ojúrere Olúwa, àti láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi pẹ̀lú yóò sì lọ.’
22 Ainsi plusieurs peuples, et de puissantes nations viendront rechercher l'Eternel des armées à Jérusalem, et y supplier l'Eternel.
Nítòótọ́, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn àti àwọn alágbára orílẹ̀-èdè yóò wá láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní Jerusalẹmu; àti láti gbàdúrà, àti láti wá ojúrere Olúwa.”
23 Ainsi a dit l'Eternel des armées: Il arrivera en ces jours-là que dix hommes de toutes les langues des nations empoigneront et tiendront ferme le pan de la robe d'un Juif, en disant: Nous irons avec vous; car nous avons entendu que Dieu est avec vous.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni ọkùnrin mẹ́wàá láti inú gbogbo èdè àti orílẹ̀-èdè yóò dìímú, àní yóò di etí aṣọ ẹni tí i ṣe Júù mú, wí pé, ‘Àwa yóò ba ọ lọ, nítorí àwa tí gbọ́ pé, Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.’”

< Zacharie 8 >