< Zacharie 7 >

1 Puis il arriva la quatrième année du Roi Darius, que la parole de l'Eternel fut [adressée] à Zacharie le quatrième jour du neuvième mois, [qui est le mois de] Kisleu.
Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dariusi ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekariah wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kisleu tí ń ṣe oṣù kẹsànán.
2 lorsqu'on eut envoyé Saretser, et Réguem-mélec et ses gens, à la maison du [Dieu] Fort, pour supplier l'Eternel.
Nígbà tí wọ́n ènìyàn Beteli rán Ṣareseri àti Regemmeleki, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojúrere Olúwa.
3 Et pour parler aux Sacrificateurs de la maison de l'Eternel des armées, et aux Prophètes, en disant: Pleurerai-je au cinquième mois, me tenant séparé, comme j'ai déjà fait pendant plusieurs années?
Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù karùn-ún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”
4 Et la parole de l'Eternel me fut [adressée], en disant:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,
5 Parle à tout le peuple du pays, et aux Sacrificateurs, et [leur] dis: Quand vous avez jeûné, et pleuré au cinquième [mois], et au septième, il y a déjà soixante et dix ans, avez-vous célébré ce jeûne pour l’amour de moi?
“Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti fún àwọn àlùfáà pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin gbààwẹ̀, tí ẹ sì ṣọ̀fọ̀ ní oṣù karùn-ún àti keje, àní fun àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, ǹjẹ́ èmi ni ẹ̀yin ha ń gbààwẹ̀ yín fún?
6 Et quand vous buvez et mangez, n'est-ce pas vous qui mangez, et vous qui buvez?
Nígbà tí ẹ sì jẹ, àti nígbà tí ẹ mu, fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin jẹ, àti fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin mú bí?
7 Ne sont-ce pas les paroles que l'Eternel a fait entendre par le moyen des Prophètes qui ont été ci-devant, lorsque Jérusalem était habitée et paisible, elle et ses villes qui sont autour d'elle, et lors qu'on habitait vers le midi, et dans la plaine?
Wọ̀nyí kọ́ ni ọ̀rọ̀ ti Olúwa ti kígbe láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì ìṣáájú wá, nígbà tí a ń gbé Jerusalẹmu, tí ó sì wà ní àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀ tí ó yí i káàkiri, nígbà tí a ń gbé gúúsù àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.’”
8 Puis la parole de l'Eternel fut [adressée] à Zacharie, en disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sekariah wá, wí pé,
9 Ainsi avait parlé l'Eternel des armées, en disant: Faites ce qui est vraiment juste, et exercez la miséricorde et la compassion chacun envers son frère.
“Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ṣe ìdájọ́ òtítọ́, kí ẹ sì ṣe àánú àti ìyọ́nú olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀.
10 Et ne faites point de tort à la veuve, ni à l'orphelin, ni à l'étranger, ni à l'affligé, et ne méditez aucun mal dans vos cœurs chacun contre son frère.
Má sì ṣe ni opó lára tàbí aláìní baba, àlejò, tàbí tálákà; kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ṣe gbèrò ibi ní ọkàn sí arákùnrin rẹ̀.’
11 Mais ils n'y ont point voulu entendre, et ont tiré l'épaule en arrière, et ils ont appesanti leurs oreilles pour ne point ouïr.
“Ṣùgbọ́n wọ́n kọ̀ láti gbọ́, wọ́n sì gún èjìká, wọ́n sì pa ẹ̀yìn dà, wọ́n di etí wọn, kí wọn má ba à gbọ́.
12 Et ils ont rendu leur cœur [dur comme] le diamant, pour ne point écouter la Loi, et les paroles que l'Eternel des armées envoyait par son Esprit, par le moyen des Prophètes qui ont été ci-devant; c'est pourquoi il y a eu une grande indignation de par l'Eternel des armées.
Wọ́n sé ọkàn wọn bí òkúta líle, kí wọn má ba à gbọ́ òfin, àti ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti fi ẹ̀mí rẹ̀ rán nípa ọwọ́ àwọn wòlíì ìṣáájú wá. Ìbínú ńlá sì dé láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
13 Et il est arrivé, que comme quand on leur a crié, ils n'ont point écouté; ainsi, quand ils ont crié, je n'ai point écouté, a dit l'Eternel des armées.
“‘Ó sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ó ti kígbe, tí wọn kò sì fẹ́ gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kígbe, tí èmi kò sì fẹ́ gbọ́,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
14 Et je les ai dispersés [comme] par un tourbillon parmi toutes les nations qu'ils ne connaissaient point, et le pays a été désolé après eux, tellement qu'il n'y a eu personne qui y passât, ni repassât, et on a mis le pays désirable en désolation.
‘Mo sì fi ìjì tú wọn ká sí gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀. Ilẹ̀ náà sì dahoro lẹ́yìn wọn, tí ẹnikẹ́ni kò là á kọjá tàbí kí ó padà bọ̀, wọ́n sì sọ ilẹ̀ ààyò náà dahoro.’”

< Zacharie 7 >