< Jérémie 19 >

1 Ainsi a dit l'Eternel: va, et achète une bouteille de terre d'un potier, et [prends] des anciens du peuple, et des anciens des Sacrificateurs;
Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbàgbà ọkùnrin àti wòlíì.
2 Et sors à la vallée du fils de Hinnom, qui est auprès de l'entrée de la porte Orientale, et crie là les paroles que je te dirai.
Kí o sì lọ sí àfonífojì ọmọ Beni-Hinnomu, níwájú ẹnu ibodè Harsiti, níbẹ̀ ni kí o sì kéde gbogbo ọ̀rọ̀ tí èmi yóò sọ fún ọ.
3 Dis donc: Rois de Juda, et vous habitants de Jérusalem, écoutez la parole de l'Eternel: ainsi a dit l'Eternel des armées, le Dieu d'Israël: voici, je m'en vais faire venir sur ce lieu-ci un mal, tel que quiconque l'entendra, les oreilles lui en tinteront.
Kí o sì wí pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba àwọn Juda àti ẹ̀yin ará Jerusalẹmu. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya.
4 Parce qu'ils m'ont abandonné, et qu'ils ont profané ce lieu, et y ont fait des encensements à d'autres dieux, que ni eux, ni leurs pères, ni les Rois de Juda n'ont point connus, et parce qu'ils ont rempli ce lieu du sang des innocents;
Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjèjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí ọba Juda kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kún ilẹ̀ yìí.
5 Et qu'ils ont bâti des hauts lieux de Bahal, afin de brûler au feu leurs fils pour en faire des holocaustes à Bahal, ce que je n'ai point commandé, et dont je n'ai point parlé, et à quoi je n'ai jamais pensé;
Wọ́n ti kọ́ ibi gíga fún Baali láti sun ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí ohun ẹbọ sísun sí Baali—èyí tí èmi kò pàṣẹ láti ṣe, tí èmi kò sì sọ, tàbí tí kò sì ru sókè láti inú ọkàn mi.
6 A cause de cela voici, les jours viennent, dit l'Eternel, que ce lieu-ci ne sera plus appelé Topheth, ni la vallée du fils de Hinnom, mais la vallée de la tuerie.
Nítorí náà ṣọ́ra ọjọ́ ń bọ̀ ni Olúwa wí nígbà tí àwọn ènìyàn kì yóò pe ibí ní Tofeti mọ́ tàbí àfonífojì ọmọ Hinnomu, ṣùgbọ́n àfonífojì Ìpakúpa.
7 Et j'anéantirai le conseil de Juda et de Jérusalem en ce lieu-ci, et je les ferai tomber par l'épée en la présence de leurs ennemis, et en la main de ceux qui cherchent leur vie; et je donnerai leurs corps morts à manger aux oiseaux des cieux et aux bêtes de la terre.
“‘Ní ibí yìí ni èmi yóò ti pa èrò Juda àti Jerusalẹmu run. Èmí yóò mú wọn ṣubú nípa idà níwájú àwọn ọ̀tá wọn, lọ́wọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn. Èmi yóò sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.
8 Je détruirai cette ville, et je la couvrirai d'opprobre; quiconque passera près d'elle sera étonné, et lui insultera à cause de toutes ses plaies.
Èmi yóò sọ ìlú yìí di ahoro àti ohun ẹ̀gàn, gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò bẹ̀rù wọn yóò sì máa fòyà nítorí gbogbo ọgbẹ́ rẹ̀.
9 Et je leur ferai manger la chair de leurs fils, et la chair de leurs filles; et chacun mangera la chair de son compagnon durant le siège, et dans l'extrémité où les réduiront leurs ennemis, et ceux qui cherchent leur vie.
Èmi yóò mú kí wọ́n jẹ ẹran-ara ọmọ wọn ọkùnrin àti ẹran-ara ọmọ wọn obìnrin, ẹnìkínní yóò sì jẹ ẹran-ara ẹnìkejì, nígbà ìdótì àti ìhámọ́ láti ọwọ́ ọ̀tá wọn, àti àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn.’
10 Puis tu casseras la bouteille en présence de ceux qui seront allés avec toi;
“Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní ojú àwọn tí ó bá ọ lọ.
11 Et tu leur diras: ainsi a dit l'Eternel des armées: je briserai ce peuple et cette ville, de même qu'on brise un vaisseau de potier, qui ne peut être soudé, et ils seront ensevelis à Topheth, parce qu'il [n'y aura] plus d'autre lieu pour [les] ensevelir.
Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀-èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tofeti títí tí kò fi ní sí ààyè mọ́.
12 Je ferai ainsi à ce lieu-ci, dit l'Eternel, et à ses habitants; tellement que je réduirai cette ville au même état que Topheth;
Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tofeti.
13 Et les maisons de Jérusalem, et les maisons des Rois de Juda seront souillées, comme le lieu de Topheth, à cause de toutes les maisons sur les toits desquelles ils ont fait des parfums à toute l'armée des cieux, et des aspersions à d'autres dieux.
Àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu àti ti ọba ìlú Juda ni a ó sọ di àìmọ́ bí Tofeti, gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí òrùlé sí gbogbo ogun ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ mímu sí ọlọ́run mìíràn.’”
14 Puis Jérémie s'en vint de Topheth là où l'Eternel l'avait envoyé pour prophétiser, et il se tint debout au parvis de la maison de l'Eternel, et dit à tout le peuple:
Jeremiah sì padà láti Tofeti níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba tẹmpili Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé,
15 Ainsi a dit l'Eternel des armées, le Dieu d'Israël: voici, je m'en vais faire venir sur cette ville, et sur toutes ses villes, tout le mal que j'ai prononcé contre elle, parce qu'ils ont raidi leur cou, pour ne point écouter mes paroles.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbèríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’”

< Jérémie 19 >