< Jérémie 18 >

1 Cette parole fut [adressée] de par l'Eternel à Jérémie, disant:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá wí pe:
2 Lève-toi, et descends dans la maison d'un potier, et là je te ferai entendre mes paroles.
“Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé amọ̀kòkò, níbẹ̀ ni èmi yóò ti bá ọ sọ̀rọ̀.”
3 Je descendis donc dans la maison d'un potier, et voici, il faisait son ouvrage, assis sur sa selle.
Nígbà náà ni mo lọ sí ilé amọ̀kòkò mo sì rí i tí ó ń ṣiṣẹ́ kan lórí kẹ̀kẹ́.
4 Et le vase qu'il faisait de l'argile qui [était] en sa main, fut gâté, et il en fit encore un autre vase, comme il lui sembla bon de [le] faire.
Ṣùgbọ́n ìkòkò tí ó ń mọ láti ara amọ̀ bàjẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀, nítorí náà ni amọ̀kòkò fi ṣe ìkòkò mìíràn, ó mọ ọ́n bí èyí tí ó dára jù ní ojú rẹ̀.
5 Alors la parole de l'Eternel me fut [adressée], en disant:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
6 Maison d'Israël, ne vous pourrai-je pas faire comme a fait ce potier; dit l'Eternel? voici, comme l'argile est dans la main d'un potier, ainsi êtes-vous dans ma main, maison d'Israël.
“Ẹyin ilé Israẹli, èmi kò ha lè ṣe fún un yín gẹ́gẹ́ bí amọ̀kòkò yìí ti ṣe?” ni Olúwa wí. “Gẹ́gẹ́ bí amọ̀ ní ọwọ́ amọ̀kòkò bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin rí ní ọwọ́ mi, ẹ̀yin ilé Israẹli.
7 En un instant je parlerai contre une nation, et contre un Royaume, pour arracher, pour démolir, et pour détruire;
Bí ó bá jẹ́ ìgbà kan, tí èmi kéde kí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan di fífà tu láti dojúdé àti láti parun,
8 Mais si cette nation contre laquelle j'aurai parlé se détourne du mal qu'elle aura fait, je me repentirai aussi du mal que j'avais pensé de lui faire.
tí orílẹ̀-èdè ti mo kìlọ̀ fún bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú wọn, nígbà náà ni Èmi yóò yí ọkàn mi padà nínú àjálù tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.
9 Et si en un instant je parle d'une nation et d'un Royaume, pour l'édifier et pour le planter;
Ní ìgbà mìíràn tí èmi bá tún kéde láti tẹ̀dó tàbí gbin orílẹ̀-èdè kan tàbí ìjọba kan.
10 Et que cette nation fasse ce qui me déplaît, en sorte qu'elle n'écoute point ma voix, je me repentirai aussi du bien que j'avais dit que je lui ferais.
Bí ó bá sì ṣe búburú níwájú mi, tí kò sì gba ohùn mi gbọ́, nígbà náà ni èmi yóò yí ọkàn mi padà ní ti rere, èyí tí mo wí pé, èmi ó ṣe fún wọn.
11 Or donc parle maintenant aux hommes de Juda, et aux habitants de Jérusalem, en disant: ainsi a dit l'Eternel: voici, je projette du mal contre vous, et je forme un dessein contre vous; abandonnez donc maintenant chacun sa mauvaise voie, et changez votre voie, et vos actions.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, sọ fún àwọn ènìyàn Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa wí: Wò ó! Èmi ń gbèrò ibi sí yin, èmi sì ń ṣe ìpinnu kan lórí yín. Nítorí náà ẹ yípadà kúrò lọ́nà búburú yín kí olúkúlùkù yín sì tún ọ̀nà àti ìṣe rẹ̀ ṣe.’
12 Et ils répondirent: il n'y a plus d'espérance; c'est pourquoi nous suivrons nos pensées, et chacun de nous fera selon la dureté de son cœur mauvais.
Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Kò ṣe nǹkan kan, àwa yóò tẹ̀síwájú nínú èrò wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa, yóò hùwà agídí ọkàn búburú rẹ̀.’”
13 C'est pourquoi ainsi a dit l'Eternel: Demandez maintenant aux nations qui a entendu de telles choses? la vierge d'Israël a fait une chose très-énorme.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: “Ẹ béèrè nínú orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá ti gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí ri? Ohun tí ó burú gidi ni wúńdíá Israẹli ti ṣe.
14 N'abandonnera-t-on pas la neige du Liban pour la roche du champ? et ne laissera-t-on pas les eaux qui ne sont point naturelles, et qui sont froides, [encore] qu'elles coulent?
Ǹjẹ́ omi ojo dídì Lebanoni yóò ha dá láti máa sàn láti ibi àpáta? Tàbí odò tí ó jìnnà, tí ó tútù, tí ó ń sàn, yóò ha gbẹ bí?
15 Mais mon peuple m'a oublié, et il a fait des parfums à ce qui n'est que vanité, et qui les a fait broncher dans leurs voies, pour [les faire retirer] des sentiers anciens, afin de marcher dans les sentiers d'un chemin qui n'est point battu;
Nítorí àwọn ènìyàn mi gbàgbé mi, wọ́n sun tùràrí fún òrìṣà asán, tí ó mú wọn kọsẹ̀ ní ọ̀nà wọn, àti ọ̀nà wọn àtijọ́. Wọ́n mú wọn rìn ní ọ̀nà àtijọ́, àti ní ojú ọ̀nà ti a kò ṣe.
16 Pour faire venir sur leur pays une désolation et un opprobre perpétuel; [tellement que] quiconque passera par là en sera étonné, et branlera la tête.
Ilẹ̀ wọn yóò wà lásán yóò sì di nǹkan ẹ̀gàn títí láé, gbogbo àwọn tí ó ń kọjá yóò bẹ̀rù, wọn yóò sì mi orí wọn.
17 Je les disperserai devant l'ennemi, comme par le vent d'Orient; je leur tournerai le dos, au jour de leur calamité.
Gẹ́gẹ́ bí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn, Èmi yóò tú wọn ká lójú àwọn ọ̀tá wọn. Èmi yóò sì kọ ẹ̀yìn sí wọn, n kì yóò kọjú sí wọn ní ọjọ́ àjálù wọn.”
18 Et ils ont dit: venez, et faisons quelques machinations contre Jérémie; car la Loi ne se perdra pas chez le Sacrificateur, ni le conseil chez le Sage, ni la parole chez le Prophète; venez, et frappons-le de la langue, et ne soyons point attentifs à aucun de ses discours.
Wọ́n sọ wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ ṣọ̀tẹ̀ sí Jeremiah, nítorí òfin ìkọ́ni láti ẹnu àwọn àlùfáà kì yóò jásí asán, tàbí ìmọ̀ràn fún àwọn ọlọ́gbọ́n tàbí ọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì. Nítorí náà wá, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú pẹ̀lú ahọ́n wa, kí a má sì ṣe tẹ́tí sí ohunkóhun tí ó bá sọ.”
19 Eternel, entends-moi, et écoute la voix de ceux qui plaident contre moi.
Dẹtí sí ọ̀rọ̀ mi Olúwa, gbọ́ ohun tí àwọn tí ó fi mí sùn ń sọ.
20 Le mal sera-t-il rendu pour le bien? car ils ont creusé une fosse pour mon âme. Souviens-toi que je me suis présenté devant toi afin de parler pour leur bien, [et] afin de détourner d'eux ta grande colère.
Ṣe kí a fi rere san búburú? Síbẹ̀ wọ́n ti gbẹ́ kòtò fún mi. Rántí pé mo dúró níwájú rẹ, mo sì sọ̀rọ̀ nítorí wọn, láti yí ìbínú rẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
21 C'est pourquoi livre leurs enfants à la famine, et fais couler leur sang à coups d'épée; que leurs femmes soient privées d'enfants, et veuves, et que leurs maris soient mis à mort; et leurs jeunes gens tués avec l'épée dans la bataille.
Nítorí náà, jẹ́ kí ìyàn mú ọmọ wọn jọ̀wọ́ wọn fún ọwọ́ idà jẹ́ kí ìyàwó wọn kí ó di aláìlọ́mọ àti opó jẹ́ kí a pa àwọn ọkùnrin wọn kí a sì fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn lójú ogun.
22 Que le cri soit ouï de leurs maisons, quand tu auras fait venir subitement des troupes contre eux; parce qu'ils ont creusé une fosse pour me prendre, et qu'ils ont tendu des filets à mes pieds.
Jẹ́ kí a gbọ́ ohùn ẹkún láti ilé wọn nígbà tí ó bá mu àwọn jagunjagun kọlù wọ́n lójijì nítorí wọ́n ti gbẹ́ kòtò láti mú mi. Wọ́n ti dẹ okùn fún ẹsẹ̀ mi.
23 Or tu sais, ô Eternel! que tout leur conseil est contre moi pour me mettre à mort; ne sois point apaisé à l'égard de leur iniquité, et n'efface point leur péché de devant ta face, mais qu'on les fasse tomber en ta présence; agis contre eux au temps de ta colère.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa mọ gbogbo ète wọn láti pa mí, má ṣe dárí ẹ̀bi wọn jì wọ́n bẹ́ẹ̀ ni má ṣe pa ẹ̀ṣẹ̀ wọn rẹ́ kúrò lójú rẹ. Jẹ́ kí wọn kí ó ṣubú níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó sì ṣe sí wọn nígbà ìbínú rẹ.

< Jérémie 18 >