< 1 Chroniques 27 >

1 Or quant aux enfants d'Israël, selon leur dénombrement, il y avait des Chefs de pères, des Gouverneurs de milliers et de centaines, et leurs prévôts, qui servaient le Roi selon tout l'état des départements, dont l'un entrait, et l'autre sortait, de mois en mois, durant tous les mois de l'année; et chaque département était de vingt et quatre mille hommes.
Wọ̀nyí ni ìwé àkójọ orúkọ àwọn ọmọ Israẹli, àwọn olórí àwọn ìdílé, àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn ìjòyè wọn. Tí ó n sin ọba nínú gbogbo ohun tí ó kan ìpín àwọn ọmọ-ogun tí ó wà lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn ní oṣooṣù ní gbogbo ọdún. Ìpín kọ̀ọ̀kan jẹ́ ẹgbàá méjìlá ọkùnrin.
2 Et Jasobham fils de Zabdiël [présidait] sur le premier département, pour le premier mois; et dans son département il y avait vingt et quatre mille hommes.
Ní ti alákòóso lórí ìpín kìn-ín-ní fún oṣù kìn-ín-ní jẹ́ Jaṣobeamu ọmọ Sabdieli àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní abẹ́ ìpín tirẹ̀.
3 Il était des enfants de Pharés, Chef de tous les capitaines de l'armée du premier mois.
Ó jẹ́ ìran ọmọ Peresi àti olóyè fún gbogbo àwọn ìjòyè ológun fún oṣù kìn-ín-ní.
4 Dodaï Ahohite [présidait] sur le département du second mois, ayant Mikloth pour Lieutenant en son département; et dans son département il y avait vingt et quatre mille hommes.
Alákòóso fún ìpín àwọn ọmọ-ogun fún oṣù kejì jẹ́ Dodai ará Ahohi; Mikloti jẹ́ olórí ìpín tirẹ̀. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
5 Le Chef de la troisième armée pour le troisième mois, était Bénaja fils de Jéhojadah Sacrificateur, [et capitaine en] Chef; et dans son département il y avait vingt et quatre mille hommes.
Olórí àwọn ọmọ-ogun ẹlẹ́ẹ̀kẹta fún oṣù kẹta jẹ́ Benaiah ọmọ Jehoiada àlùfáà. Ó jẹ́ olóyè, àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
6 C'est ce Bénaja qui était fort entre les trente, et par dessus les trente; et Hammizabad son fils était dans son département.
Èyí ni Benaiah náà tí ó jẹ́ ọkùnrin ńlá láàrín àwọn ọgbọ̀n àti lórí àwọn ọgbọ̀n. Ọmọ rẹ̀ Amisabadi jẹ́ alákòóso lórí ìpín tirẹ̀.
7 Le quatrième pour le quatrième mois était Hazaël frère de Joab, et Zébadia son fils, après lui; et il y avait dans son département vingt et quatre mille hommes.
Ẹlẹ́ẹ̀kẹrin fún oṣù kẹrin, jẹ́ Asaheli arákùnrin Joabu: ọmọ rẹ̀ Sebadiah jẹ́ arọ́pò rẹ̀. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
8 Le cinquième pour le cinquième mois était le capitaine Samhuth de Jizrah; et dans son département il y avait vingt et quatre mille hommes.
Ẹ̀karùnún fún oṣù karùn-ún, jẹ́ olórí Ṣamhuti ará Israhi. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
9 Le sixième pour le sixième mois était Hira fils d'Hikkés Tékohite; et dans son département il y avait vingt et quatre mille hommes.
Ẹ̀kẹfà fún oṣù kẹfà jẹ́ Ira ọmọ Ikẹsi, ará Tekoi. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
10 Le septième pour le septième mois était Hélets Pélonite, des enfants d'Ephraïm; et il y avait dans son département vingt et quatre mille hommes.
Èkeje fún oṣù keje jẹ́ Helesi ará Peloni, ará Efraimu. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni o wà ní ìpín rẹ̀.
11 Le huitième pour le huitième mois était Sibbecaï Husathite, [de la famille] des Zarhites; et il y avait dans son département vingt et quatre mille hommes.
Ẹ̀kẹjọ fún oṣù kẹjọ jẹ́ Sibekai ará Huṣati, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
12 Le neuvième pour le neuvième mois était Abihézer Hanathothite, des Benjamites; et il y avait dans son département vingt et quatre mille hommes.
Ẹ̀kẹsànán fún oṣù kẹsànán jẹ́. Abieseri ará Anatoti, ará Benjamini ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
13 Le dixième pour le dixième mois [était] Naharaï Nétophathite, [de la famille] des Zarhites; et il y avait dans son département vingt et quatre mille hommes.
Ẹ̀kẹwàá fún oṣù kẹwàá jẹ́ Maharai ará Netofa, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
14 L'onzième pour l'onzième mois [était] Bénaja Pirhathonite, des enfants d'Ephraïm; et il y avait dans son département vingt et quatre mille hommes.
Ìkọkànlá fún oṣù kọkànlá jẹ́ Benaiah ará Piratoni ará Efraimu ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
15 Le douzième pour le douzième mois était Heldaï Nétophathite, [appartenant] à Hothniël; et il y avait dans son département vingt et quatre mille hommes.
Èkejìlá fún oṣù kejìlá jẹ́ Heldai ará Netofa láti ìdílé Otnieli. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
16 Et [ceux-ci présidaient] sur les Tribus d'Israël; Elihézer fils de Zicri était le conducteur des Rubénites. Des Siméonites, Séphatia fils de Mahaca.
Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà tí Israẹli: lórí àwọn ará Reubeni: Elieseri ọmọ Sikri; lórí àwọn ọmọ Simeoni: Ṣefatia ọmọ Maaka;
17 Des Lévites, Hasabia fils de Kémuël. De ceux d'Aaron, Tsadoc.
lórí Lefi: Haṣabiah ọmọ Kemueli; lórí Aaroni: Sadoku;
18 De Juda, Elihu, qui était des frères de David. De ceux d'Issacar, Homri fils de Micaël.
lórí Juda: Elihu arákùnrin Dafidi; lórí Isakari: Omri ọmọ Mikaeli;
19 De ceux de Zabulon, Jismahia, fils de Hobadia. De ceux de Nephthali, Jérimoth fils de Hazriël.
lórí Sebuluni: Iṣmaiah ọmọ Obadiah; lórí Naftali: Jerimoti ọmọ Asrieli;
20 Des enfants d'Ephraïm, Hosée fils de Hazazia. De la demi-Tribu de Manassé, Joël fils de Pédaja.
lórí àwọn ará Efraimu: Hosea ọmọ Asasiah; lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase: Joẹli ọmọ Pedaiah;
21 De l'autre demi-Tribu de Manassé en Galaad, Jiddo fils de Zacharie. De ceux de Benjamin, Jahasiël fils d'Abner.
lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ní Gileadi: Iddo ọmọ Sekariah; lórí Benjamini: Jaasieli ọmọ Abneri;
22 De ceux de Dan, Hazaréël fils de Jéroham. Ce sont là les principaux des Tribus d'Israël.
lórí Dani: Asareeli ọmọ Jerohamu. Wọ̀nyí ni àwọn ìjòyè lórí ẹ̀yà Israẹli.
23 Mais David ne fit point le dénombrement des Israélites, depuis l'âge de vingt ans et au dessous; parce que l'Eternel avait dit qu'il multiplierait Israël comme les étoiles du ciel.
Dafidi kò kọ iye àwọn ọkùnrin náà ní ogún ọdún sẹ́yìn tàbí dín nítorí Olúwa ti ṣe ìlérí láti ṣe Israẹli gẹ́gẹ́ bí iye ìràwọ̀ ojú ọ̀run.
24 Joab fils de Tséruiä avait bien commencé à en faire le dénombrement, mais il n'acheva pas, parce que l'indignation de Dieu s'était répandue à cause de cela sur Israël; c'est pourquoi ce dénombrement ne fut point mis parmi les dénombrements enregistrés dans les Chroniques du Roi David.
Joabu ọmọ Seruiah bẹ̀rẹ̀ sí ní kà wọ́n, ṣùgbọ́n kò parí kíkà wọ́n nítorí, ìbínú dé sórí àwọn Israẹli nípasẹ̀ kíka iye àti iye náà, a kò kọ ọ́ sínú ìwé ìtàn ayé ti ọba Dafidi.
25 Or Hazmaveth fils d'Hadiël était commis sur les finances du Roi; mais Jonathan fils d'Huzija était commis sur les finances qui étaient à la campagne, dans les villes et aux villages et aux châteaux.
Asmafeti ọmọ Adieli wà ní ìdí ilé ìṣúra ti ọba. Jonatani ọmọ Ussiah wà ní ìdí ilé ìṣúra ní iwájú agbègbè nínú àwọn ìlú, àwọn ìletò àti àwọn ilé ìṣọ́.
26 Et Hezri, fils de Kélub, était commis sur ceux qui travaillaient dans la campagne au labourage de la terre.
Esri ọmọ Kelubu wà ní ìdí àwọn òṣìṣẹ́ lórí pápá, tí wọ́n ń ko ilẹ̀ náà.
27 Et Simhi Ramathite sur les vignes, et Zabdi Siphmien sur ce qui provenait des vignes, et sur les celliers du vin.
Ṣimei ará Ramoti wà ní ìdí àwọn ọgbà àjàrà. Sabdi ará Sifmi wà ní ìdí mímú jáde ti èso àjàrà fún ọpọ́n ńlá tí a ń fi ọ̀tún èso àjàrà sí.
28 Et Bahal-hanan Guéderite sur les oliviers, et sur les figuiers qui étaient en la campagne; et Johas sur les celliers à huile.
Baali-Hanani ará Gederi wà ní ìdí olifi àti àwọn igi sikamore ní apá ìhà ìwọ̀-oòrùn àwọn ní ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀. Joaṣi wà ní ìdí fífún ni ní òróró olifi.
29 Et Sitraï Saronite, était commis sur le gros bétail qui paissait en Saron; et Saphat fils de Hadlaï sur le gros bétail qui paissait dans les vallées.
Ṣitrai ará Ṣaroni wà ní ìdí fífi ọwọ́ ẹran jẹ oko ní Ṣaroni. Ṣafati ọmọ Adlai wà ní ìdí àwọn ọ̀wọ́ ẹran ní àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀.
30 Et Obil Ismaëlite sur les chameaux; Jéhdeja Méronothite, sur les ânesses.
Obili ará Iṣmaeli wà ní ìdí àwọn ìbákasẹ. Jehdeiah ará Meronoti wà ní ìdí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
31 Et Jaziz Hagarénien sur les troupeaux du menu bétail. Tous ceux-là avaient la charge du bétail qui appartenait au Roi David.
Jasisi ará Hagari wà ní ìdí àwọn agbo ẹran. Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn oníṣẹ́ tí wọ́n wà ní ìdí ẹrù ọba Dafidi.
32 Mais Jonathan, oncle de David, était conseiller, homme fort intelligent et scribe, et Jéhiël fils de Hacmoni était avec les enfants du Roi.
Jonatani, arákùnrin Dafidi jẹ́ olùdámọ̀ràn, ọkùnrin onímọ̀ àti akọ̀wé. Jehieli ọmọ Hakmoni bojútó àwọn ọmọ ọba.
33 Et Achitophel était le conseiller du Roi; et Cusaï Arkite était l'intime ami du Roi.
Ahitofeli jẹ́ olùdámọ̀ràn ọba. Huṣai ará Arki jẹ́ ọ̀rẹ́ ọba.
34 Après Achitophel était Jéhojadah fils de Bénaja et Abiathar; et Joab était le Général de l'armée du Roi.
(Jehoiada ọmọ Benaiah àti nípasẹ̀ Abiatari jẹ ọba rọ́pò Ahitofeli.) Joabu jẹ́ olórí ọmọ-ogun ọba.

< 1 Chroniques 27 >