< 1 Chroniques 26 >

1 Et quant aux départements des portiers; il y eut pour les Corites, Mésélémia fils de Coré, d'entre les enfants d'Asaph.
Àwọn ìpín tí àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà. Láti ìran Kora: Meṣelemiah ọmọ Kore, ọ̀kan lára àwọn ọmọ Asafu.
2 Et les enfants de Mésélémia furent, Zacharie le premier-né; Jédihaël le second; Zébadia le troisième; Jathniël le quatrième,
Meṣelemiah ní àwọn ọmọkùnrin: Sekariah àkọ́bí, Jediaeli ẹlẹ́ẹ̀kejì, Sebadiah ẹlẹ́ẹ̀kẹta, Jatnieli ẹlẹ́ẹ̀kẹrin,
3 Hélam le cinquième, Johanum le sixième; Eliehohenaï le septième.
Elamu ẹlẹ́ẹ̀karùnún, Jehohanani ẹlẹ́ẹ̀kẹfà àti Elihoenai ẹlẹ́ẹ̀keje.
4 Et les enfants de Hobed-Edom furent, Sémahja le premier-né, Jéhozabad le second, Joah le troisième, Sacar le quatrième, Nathanaël le cinquième,
Obedi-Edomu ni àwọn ọmọkùnrin pẹ̀lú: Ṣemaiah àkọ́bí, Jehosabadi ẹlẹ́ẹ̀kejì, Joah ẹlẹ́ẹ̀kẹta, Sakari ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Netaneli ẹlẹ́ẹ̀karùnún,
5 Hammiel le sixième, Issacar le septième, Pehulletaï le huitième; car Dieu l'avait béni.
Ammieli ẹ̀kẹfà, Isakari èkeje àti Peulltai ẹ̀kẹjọ. (Nítorí tí Ọlọ́run ti bùkún Obedi-Edomu).
6 Et à Sémahja son fils naquirent des enfants, qui eurent le commandement sur la maison de leur père, parce qu'ils étaient hommes forts et vaillants.
Ọmọ rẹ̀ Ṣemaiah ní àwọn ọmọkùnrin pẹ̀lú tí wọ́n jẹ́ olórí ní ìdílé baba a wọn nítorí wọ́n jẹ́ ọkùnrin tó lágbára.
7 Les enfants donc de Sémahja furent, Hothni, et Réphaël, Hobed, et Elzabad, ses frères, hommes vaillants, Elihu et Sémacia.
Àwọn ọmọ Ṣemaiah: Otni, Refaeli, Obedi àti Elsabadi; àwọn ìbátan rẹ̀ Elihu àti Samakiah jẹ́ ọkùnrin alágbára.
8 Tous ceux-là étaient des enfants d'Hobed-Edom, eux et leurs fils, et leurs frères, hommes vaillants, et forts pour le service; ils étaient soixante-deux d'Hobed-Edom.
Gbogbo wọ̀nyí ní ìran ọmọ Obedi-Edomu; àwọn àti ọmọkùnrin àti ìbátan wọn jẹ́ alágbára ọkùnrin pẹ̀lú ipá láti ṣe ìsìn náà. Ìran Obedi-Edomu méjìlélọ́gọ́ta ni gbogbo rẹ̀.
9 Et les enfants de Mésélémia avec ses frères étaient dix-huit, vaillants hommes.
Meṣelemiah ní àwọn ọmọ àti àwọn ìbátan, tí ó jẹ́ alágbára méjìdínlógún ni gbogbo wọn.
10 Et les enfants de Hoza, d'entre les enfants de Mérari, furent Simri le Chef; car quoiqu'il ne fût pas l'aîné, néanmoins son père l'établit pour Chef.
Hosa ará Merari ní àwọn ọmọkùnrin: Ṣimri alákọ́kọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé kì i ṣe àkọ́bí, baba a rẹ̀ ti yàn an ní àkọ́kọ́.
11 Hilkija était le second, Tebalia le troisième, Zacharie le quatrième; tous les enfants et frères de Hoza furent treize.
Hilkiah ẹlẹ́ẹ̀kejì, Tabaliah ẹ̀kẹta àti Sekariah ẹ̀kẹrin. Àwọn ọmọ àti ìbátan Hosa jẹ́ mẹ́tàlá ni gbogbo rẹ̀.
12 On fit à ceux-là les départements des portiers, en sorte que les charges furent distribuées aux Chefs de famille, en égalant les uns aux autres, afin qu'ils servissent dans la maison de l'Eternel.
Ìpín wọ̀nyí ti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà nípasẹ̀ olóyè ọkùnrin wọn, ní iṣẹ́ ìsìn fún jíjíṣẹ́ nínú ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìbátan wọn ti ṣe.
13 Car ils jetèrent les sorts autant pour le plus petit que pour le plus grand, selon leurs familles, pour chaque porte.
Wọ́n ṣẹ́ kèké fún ẹnu-ọ̀nà kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ìdílé wọn bí ọ̀dọ́ àti arúgbó.
14 Et ainsi le sort [pour la porte] vers l'Orient échut à Sélémia. Puis on jeta le sort pour Zacharie son fils, sage conseiller, et son sort échut [pour la porte] vers le Septentrion.
Kèké fún ẹnu-ọ̀nà ilà oòrùn bọ́ sí ọ̀dọ̀ Ṣelemiah. Nígbà náà a dá kèké fún ọmọkùnrin rẹ̀ Sekariah, ọlọ́gbọ́n onímọ̀ràn, kèké fún ẹnu-ọ̀nà àríwá sì bọ́ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.
15 Le sort d'Hobed-Edom échut [pour la porte] vers le Midi, et la maison des assemblées échut à ses fils.
Kèké fún ẹnu-ọ̀nà ìhà gúúsù bọ́ sí ọ̀dọ̀ Obedi-Edomu, kèké fún ilé ìṣúra sì bọ́ sí ọ̀dọ̀ ọmọ rẹ̀.
16 A Suppim et à Hosa [pour la porte] vers l'Occident, auprès de la porte de Salleketh, au chemin montant; une garde [étant] vis-à-vis de l'autre.
Kèké fún ẹnu-ọ̀nà ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Ṣaleketi ẹnu-ọ̀nà ní ọ̀nà apá òkè bọ́ sí ọ̀dọ̀ Ṣuppimu àti Hosa. Olùṣọ́ wà ní ẹ̀bá olùṣọ́.
17 Il y avait vers l'Orient, six Lévites; vers le Septentrion, quatre par jour; vers le Midi, quatre aussi par jour; et vers [la maison] des assemblées deux de chaque côté.
Àwọn ará Lefi mẹ́fà ní ó wà ní ọjọ́ kan ní ìhà ìlà-oòrùn, mẹ́rin ní ọjọ́ kan ní ìhà àríwá, mẹ́rin ní ọjọ́ kan ní ìhà gúúsù àti méjì ní ẹ̀ẹ̀kan ṣoṣo ní ilé ìṣúra.
18 A Parbar vers l'Occident, il y en avait quatre au chemin, [et] deux à Parbar.
Ní ti ilé ẹjọ́ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, mẹ́rin sì wà ní ojú ọ̀nà àti méjì ní ilé ẹjọ́ fúnra rẹ̀.
19 Ce sont là les départements des portiers pour les enfants des Corites, et pour les enfants de Mérari.
Wọ̀nyí ni ìpín ti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí wọ́n jẹ́ àwọn ìran ọmọ Kora àti Merari.
20 Ceux-ci aussi étaient Lévites; Ahija commis sur les trésors de la maison de Dieu, et sur les trésors des choses consacrées.
Láti inú àwọn ọmọ Lefi, Ahijah ni ó wà lórí ìṣúra ti ilé Ọlọ́run àti lórí ìṣúra nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a yà sí mímọ́.
21 Des enfants de Lahdan, qui étaient d'entre les enfants des Guersonites; du côté de Lahdan, d'entre les Chefs des pères appartenant à Lahdan Guersonite, Jéhiëli.
Àwọn ìran ọmọ Laadani tí wọn jẹ́ ará Gerṣoni nípasẹ̀ Laadani àti tí wọn jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé tí ó jẹ́ ti Laadani ará Gerṣoni ni Jehieli.
22 D'entre les enfants de Jéhiëli, Zétham, et Joël son frère, commis sur les trésors de la maison de l'Eternel.
Àwọn ọmọ Jehieli, Setamu àti arákùnrin rẹ̀ Joẹli. Wọ́n ṣalábojútó ilé ìṣúra ti ilé ìṣúra ti ilé Olúwa.
23 Pour les Hamramites, Jitsharites, Hébronites, et Hoziëlites.
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ará Amramu, àwọn ará Isari, àwọn ará Hebroni àti àwọn ará Usieli.
24 Et Sébuël fils de Guersom, fils de Moïse, était commis sur les autres trésors.
Ṣubaeli, ìran ọmọ Gerṣomu ọmọ Mose jẹ́ olórí tí ó bojútó ilé ìṣúra.
25 Et quant à ses frères du côté d'Elihézer, dont Réhabia fut fils, qui eut pour fils Esaïe, qui eut pour fils Joram, qui eut pour fils Zicri, qui eut pour fils Sélomith.
Àwọn ìbátan rẹ̀ nípasẹ̀ Elieseri: Rehabiah ọmọ rẹ̀, Jeṣaiah ọmọ rẹ̀, Joramu ọmọ rẹ̀, Sikri ọmọ rẹ̀, Ṣelomiti ọmọ rẹ̀.
26 Ce Sélomith et ses frères furent commis sur les trésors des choses saintes que le Roi David, les Chefs des pères, les Gouverneurs de milliers, et de centaines; et les Capitaines de l'armée avaient consacrées;
Ṣelomiti àti àwọn ìbátan rẹ̀ jẹ́ alábojútó ilé ìṣúra fún àwọn ohun tí à ti yà sọ́tọ̀ nípa ọba Dafidi, nípasẹ̀ àwọn olórí àwọn ìdílé tí wọ́n jẹ́ alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti nípasẹ̀ alákòóso ọmọ-ogun mìíràn.
27 Qu'ils avaient, dis-je, consacrées des batailles et des dépouilles, pour le bâtiment de la maison de l'Eternel.
Díẹ̀ nínú ìkógun tí wọ́n kó nínú ogun ni wọ́n yà sọ́tọ̀ fún títún ilé Olúwa ṣe.
28 Et tout ce qu'avait consacré Samuël le voyant, et Saül fils de Kis, et Abner fils de Ner, et Joab fils de Tséruïa; tout ce, enfin, qu'on consacrait, était mis entre les mains de Sélomith et de ses frères.
Pẹ̀lú gbogbo nǹkan tí a yà sọ́tọ̀ láti ọ̀dọ̀ Samuẹli aríran láti nípasẹ̀ Saulu ọmọ Kiṣi, Abneri ọmọ Neri àti Joabu ọmọ Seruiah gbogbo ohun tí a yà sọ́tọ̀ sì wà ní abẹ́ ìtọ́jú Ṣelomiti àti àwọn ìbátan rẹ̀.
29 D'entre les Jitsharites, Kénania et ses fils [étaient employés] aux affaires de dehors sur Israël, pour être prévôts et juges.
Láti ọ̀dọ̀ àwọn Isari: Kenaniah àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni a pín iṣẹ́ ìsìn fún kúrò ní apá ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí àwọn oníṣẹ́ àti àwọn adájọ́ lórí Israẹli.
30 Quant aux Hébronites, Hasabia et ses frères, hommes vaillants, au nombre de mille sept cents, [présidaient] sur le gouvernement d'Israël au deçà du Jourdain, vers l'Occident, pour tout ce qui concernait l'Eternel, et pour le service du Roi.
Láti ọ̀dọ̀ àwọn Hebroni: Haṣabiah àti àwọn ìbátan rẹ̀ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ọkùnrin alágbára ní ó dúró ni Israẹli, ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani fún gbogbo iṣẹ́ Olúwa àti fún iṣẹ́ ọba.
31 Quant aux Hébronites, selon leurs générations dans les familles des pères, Jérija fut le Chef des Hébronites. On en fit la recherche en la quarantième année du règne de David, et on trouva parmi eux à Jahzer de Galaad des hommes forts et vaillants.
Ní ti àwọn ará Hebroni, Jeriah jẹ́ olóyè wọn gẹ́gẹ́ bí ìwé ìrántí ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, ní ti ìdílé wọn. Ní ọdún kẹrin ìjọba Dafidi, a ṣe ìwádìí nínú ìwé ìrántí, àwọn ọkùnrin alágbára láàrín àwọn ará Hebroni ni a rí ní Jaseri ní Gileadi.
32 Les frères donc de [Jérija], hommes vaillants, furent deux mille sept cents, issus des Chefs des pères; et le Roi David les établit sur les Rubénites, sur les Gadites, et sur la demi-Tribu de Manassé, pour tout ce qui concernait Dieu, et pour les affaires du Roi.
Jeriah ní ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ìbátan, tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbára àti olórí àwọn ìdílé ọba Dafidi sì fi wọ́n ṣe àkóso lórí àwọn ará Reubeni àwọn ará Gadi àti ààbọ̀ ẹ̀yà ti Manase fún gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó jọ mọ́ ti Ọlọ́run àti fún ọ̀ràn ti ọba.

< 1 Chroniques 26 >