< Luke 2 >

1 About that time the Emperor Augustus commanded that ([his officials must] write down the names/[a census be taken]) of all the people who lived in countries [controlled] by the Roman [government] {that the Roman [government controlled]}, [so that the government could collect taxes from them].
Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àṣẹ ti ọ̀dọ̀ Kesari Augustu jáde wá pé, kí a kọ orúkọ gbogbo ayé sínú ìwé.
2 That was the first time that they (wrote down the names/took a census) in Syria [province, which included Judea district]. They did this while Quirinius was the governor of the province.
(Èyí ni ìkọ sínú ìwé èkínní tí a ṣe nígbà tí Kirene fi jẹ baálẹ̀ Siria.)
3 Every person had to go to the town where his [most famous ancestor] had lived, so that [the officials] could write down their names.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì lọ láti kọ orúkọ wọn sínú ìwé, olúkúlùkù sí ìlú ara rẹ̀.
4 So, because Joseph was a descendant of [King] David, he went up from Nazareth, the town in Galilee [district where he lived], to the town of Bethlehem in Judea [district]. That was the town where [King] David [grew up].
Josẹfu pẹ̀lú sì gòkè láti Nasareti ni Galili, sí ìlú Dafidi ní Judea, tí à ń pè ní Bẹtilẹhẹmu; nítorí ti ìran àti ìdílé Dafidi ní í ṣe,
5 Joseph went with Mary, who [was considered] {whom [people considered]} [to be] his wife, who was now pregnant. They went so that they could put his name and Mary’s name [in the record book].
láti kọ orúkọ rẹ̀, pẹ̀lú Maria aya rẹ̀ àfẹ́sọ́nà, tí oyún rẹ̀ ti tó bí.
6 When they arrived [in Bethlehem], there was no place for them to stay in the house where travelers stay. [So they stayed in a cattle shed]. When the time for Mary to give birth arrived, she gave birth to her first son there. She wrapped him in strips of cloth and placed him in a trough where [people] put food for the animals.
Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n wà níbẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ pé tí òun yóò bí.
7
Ó sì bí àkọ́bí rẹ̀ ọmọkùnrin, ó sì fi ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran; nítorí tí ààyè kò sí fún wọn nínú ilé èrò.
8 That night, there were [some] shepherds who were taking care of their sheep [as usual] in the fields near [Bethlehem].
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn ń bẹ tí wọ́n ń gbé ní ìlú náà, wọ́n ń ṣọ́ agbo àgùntàn wọn ní òru ní pápá tí wọ́n ń gbé.
9 An angel from God appeared to them. A great light (from the Lord/from God) shone on them and around them. [So] they became very afraid.
Angẹli Olúwa sì yọ sí wọn, ògo Olúwa sì ràn yí wọn ká, ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi.
10 But the angel said to them, “Do not be afraid! I have come to tell you good news, which will [make you] very happy! This message is for everyone [to hear].
Angẹli náà sì wí fún wọn pé, “Má bẹ̀rù: sá wò ó, mo mú ìyìnrere ayọ̀ ńlá fún yín wá, tí yóò ṣe ti ènìyàn gbogbo.
11 [The message is that] today a baby has been born in [Bethlehem, the town where King] David grew up. That baby will [eventually] save you [from the guilt of your sins]! He is the Messiah, [your] Lord!
Nítorí a ti bí Olùgbàlà fún yín lónìí ní ìlú Dafidi, tí í ṣe Kristi Olúwa.
12 I will tell you how [you will recognize him] (OR, how you will know [that what I say is true]): [In Bethlehem] you will find a baby who has been wrapped {[whose mother] has wrapped him} in strips of cloth and placed in a trough where [people] put food for the animals.”
Èyí ni yóò sì ṣe àmì fún yín; ẹ̀yin yóò rí ọmọ ọwọ́ tí a fi ọ̀já wé, ó dùbúlẹ̀ ní ibùjẹ ẹran.”
13 Suddenly a large group of angels from heaven appeared and joined the other angel. They all praised God, singing/saying,
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ angẹli náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,
14 “May [all the angels] in the highest heaven praise God! And on the earth may the people to whom God has shown his favor have peace [with him]!”
“Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run, àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”
15 After the angels left them [and returned] to heaven, the shepherds said to each other, “Let’s go to Bethlehem to see this [wonderful] thing that has happened, which (the Lord/God) has told us about!”
Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn angẹli náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tààrà sí Bẹtilẹhẹmu, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀, tí Olúwa fihàn fún wa.”
16 So they went quickly. They found the [place where] Mary and Joseph [were staying], and [they saw] the baby lying in the trough where [people] put food for the animals.
Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Maria àti Josẹfu, àti ọmọ ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran.
17 Then they told [Mary and Joseph and others] what had been told them {what [the angel] had told them} about this child.
Nígbà tí wọ́n sì ti rí i, wọ́n sọ ohun tí a ti wí fún wọn nípa ti ọmọ yìí.
18 Everyone who heard what was said by the shepherds {what the shepherds said} to them was amazed.
Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ sí nǹkan wọ̀nyí tí a ti wí fún wọn láti ọ̀dọ̀ àwọn olùṣọ́-àgùntàn wá.
19 But Mary [did not talk to others about what the angels said]; she just kept thinking very much about it.
Ṣùgbọ́n Maria pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́, ó ń rò wọ́n nínú ọkàn rẹ̀.
20 The shepherds returned [to their sheep]. They kept praising God very much for all the things that they had heard and seen, [because] everything [happened] exactly like [the angels] told them.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn sì padà lọ, wọ́n ń fi ògo fún Ọlọ́run, wọ́n sì yìn ín, nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti gbọ́ àti tí wọ́n ti rí, bí a ti wí i fún wọn.
21 Seven days later, when [the priests] circumcised the baby, [his parents] named him Jesus. That was the name that [they were told by] the angel {the angel [told them]} [to] give him before Mary became pregnant.
Nígbà tí ọjọ́ mẹ́jọ sì pé láti kọ ọmọ náà nílà, wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu, bí a ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀ láti ọ̀dọ̀ angẹli náà wá kí á tó lóyún rẹ̀.
22 It had been written by Moses {Moses had written} [long ago] in a law that God gave him, that when a woman gave birth to her first son, the parents had to take him [to the Temple] in Jerusalem in order that they might dedicate him (to the Lord/to God). So when the time came for them to do those rituals so that [God would consider] them pure again, Mary and Joseph took Jesus there.
Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nù Maria sì pé gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, Josẹfu àti Maria gbé Jesu wá sí Jerusalẹmu láti fi í fún Olúwa
(bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”),
24 God had commanded in his laws that if the first child [of a couple] was a boy, his parents should offer as a sacrifice to God two turtledoves or two young pigeons. [So Joseph and Mary gave the priest two birds so he could offer them].
àti láti rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “Àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì.”
25 At that time there was an [old] man in Jerusalem whose name was Simeon. He habitually did what was pleasing to God and he obeyed God’s laws. The Holy Spirit was [directing] him as he was waiting for [God] [MTY] [to] encourage the Israeli [people by sending the Messiah].
Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà ní Jerusalẹmu, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Simeoni; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Israẹli, Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e.
26 It was [previously] revealed by the Holy Spirit {The Holy Spirit [previously] revealed} to him that he would see God’s [promised] Messiah before he died.
A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí Kristi Olúwa.
27 When Joseph and Mary brought their baby Jesus [to the Temple] in order to perform the rituals that [God had commanded] in his laws, the Spirit led Simeon to enter the Temple [courtyard, and revealed to him that Jesus was the Messiah].
Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹmpili. Nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé Jesu wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin.
28 So he took Jesus up in his arms and praised God, saying,
Nígbà náà ni Simeoni gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:
29 Lord, you promised me that I would see the one [MTY] who would enable you to save people of all people-groups from the guilt of their sins. He will be [MET] like a light that will reveal your truth to non-Jews, and he will cause people to think highly of your people, the Israeli people. Since I [SYN] have now seen this one that you promised to send, now let me die peacefully.
“Olúwa Olódùmarè, nígbà yìí ni ó tó jọ̀wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ, ní àlàáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,
tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;
ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà, àti ògo Israẹli ènìyàn rẹ̀.”
33 His parents marveled about what [Simeon] said about [Jesus]. Then Simeon blessed them, and said to Mary,
Ẹnu sì ya Josẹfu àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí.
34 “Note what I say: [God] has determined that because of this child, many Israeli people will [turn away from God], and many others will turn to God [MET]. Although he will be like a sign [MET] [to warn people], [many] people will oppose him.
Simeoni sì súre fún wọn, ó sì wí fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “Kíyèsi i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Israẹli; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀-òdì sí;
35 As a result, the [evil] thoughts of many people will be made evident {he will reveal the [evil] thoughts of many people}. [Furthermore, the cruel things that they will do to him] [MET] [will be like] a sword that will pierce your (soul/inner being).”
(idà yóò sì gún ìwọ náà ní ọkàn pẹ̀lú) kí á lè fi ìrònú ọ̀pọ̀ ọkàn hàn.”
36 There was also [in the Temple courtyard] a very old woman named Anna. She was a prophetess. Her father Phanuel was a member of the tribe of Asher. After she had been married seven years, her husband died.
Ẹnìkan sì ń bẹ, Anna wòlíì, ọmọbìnrin Penueli, nínú ẹ̀yà Aṣeri: ọjọ́ ogbó rẹ̀ pọ̀, ó ti bá ọkọ gbé ní ọdún méje láti ìgbà wúńdíá rẹ̀ wá;
37 After that, she lived until she was 84 years old, and she was still a widow. She stayed in the Temple [area] all the time, night and day, worshipping God. She often (abstained from food/fasted) as she prayed.
Ó sì ṣe opó títí ó fi di ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin, ẹni tí kò kúrò ní tẹmpili, ṣùgbọ́n ó ń fi àwẹ̀ àti àdúrà sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru.
38 [While Joseph and Mary and the baby were] still [in the Temple, Anna came to them. She thanked God for the baby]. Then she spoke about Jesus to many people who were expecting [God to send the Messiah] [MTY] to set [the people of] [MTY] Jerusalem free [from their enemies].
Ó sì wólẹ̀ ní àkókò náà, ó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pẹ̀lú, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún gbogbo àwọn tí ó ń retí ìdáǹdè Jerusalẹmu.
39 After Joseph and Mary had finished performing the rituals that (the Lord/God) required [the parents of a first son] to perform, they returned to their own town, Nazareth, in Galilee [district].
Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe nǹkan gbogbo tán gẹ́gẹ́ bí òfin Olúwa, wọ́n padà lọ sí Galili, sí Nasareti ìlú wọn.
40 As Jesus grew up, he became strong and very wise, and God was very pleased with him.
Ọmọ náà sì ń dàgbà, ó sì ń lágbára, ó sì kún fún ọgbọ́n: oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sì ń bẹ lára rẹ̀.
41 Every year Jesus’ parents went to Jerusalem to [celebrate] the Passover festival.
Àwọn òbí rẹ̀ a sì máa lọ sí Jerusalẹmu ní ọdọọdún sí àjọ ìrékọjá.
42 So when Jesus was twelve years old, they went up [to Jerusalem] as they always did.
Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà.
43 When the celebration ended, his parents started to return home, but Jesus stayed in Jerusalem. [His parents] did not realize that [Jesus stayed there].
Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jesu dúró lẹ́yìn ní Jerusalẹmu; Josẹfu àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀.
44 They thought that he was with the other people who were traveling with them. They walked all day. Then they started to look for him among their relatives and friends.
Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn.
45 They did not find him, so they returned to Jerusalem to search for him.
Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerusalẹmu, wọ́n ń wá a kiri.
46 Two days later, they found him. He was in the Temple [courtyard], sitting with the [Jewish] religious teachers. He was listening to what they said, and he was asking them questions.
Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹmpili ó jókòó ní àárín àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ tiwọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè.
47 Everyone who heard what he [said] was amazed at how much he understood and [how well] he answered [the questions that the teachers asked].
Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀.
48 When his parents saw him, they were very surprised. His mother said to him, “My son, why have you done this to us? Your father and I have been very worried as we [(exc)] have been searching for you!”
Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n, ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, baba rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbànújẹ́ wá ọ kiri.”
49 He said to them, [speaking about the Temple being God his Father’s house], “(I am surprised that you [(dl)] did [not know] where to find me!/Why did you [not know] where to find me?) [RHQ] (You [(dl)] should have known that it was necessary for me to be in my Father’s house!/Did you not know that it was necessary for me to be in my Father’s house?) [RHQ]”
Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri? Ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?”
50 But they did not understand [the meaning of] what he said to them.
Ọ̀rọ̀ tí o sọ kò sì yé wọn.
51 Then he returned with them down to Nazareth. He always obeyed them. But his mother kept thinking about all those things.
Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Nasareti, sì fi ara balẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀.
52 [As the years passed], Jesus continued to become wiser and he grew taller. God and people continued to approve of him more and more.
Jesu sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.

< Luke 2 >