< Luke 1 >

1 My noble [friend] Theophilus, many people saw the things that [Jesus] did while he was with us, from the time when he started [MTY] [his ministry]. They served God [by teaching people] the message [about the Lord Jesus]. Many of those who heard what they taught wrote down for us accounts of the things that [Jesus did from the time when] he began [his ministry].
Ọ̀pọ̀ ènìyàn ni ó ti dáwọ́lé títo àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì jọ lẹ́sẹẹsẹ, èyí tí ó ti múlẹ̀ ṣinṣin láàrín wa,
2
àní gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó ṣe ojú wọn láti ìbẹ̀rẹ̀ ti fi lé wa lọ́wọ́.
3 I myself have studied these accounts carefully. So I decided that it would be good for me also to write for you [(sg)] an accurate account of these matters.
Nítorí náà, ó sì yẹ fún èmi pẹ̀lú, láti kọ̀wé sí ọ lẹ́sẹẹsẹ bí mo ti wádìí ohun gbogbo fínní fínní sí láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, Teofilu ọlọ́lá jùlọ,
4 I want you to know the truth about what you have been taught {what others have taught you}.
kí ìwọ kí ó le mọ òtítọ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti kọ́ ọ.
5 When King Herod [the Great ruled] Judea [district], there was a [Jewish] priest named Zechariah. He belonged to the [group of priests called] the Abijah group. He and his wife Elizabeth were both descended from the [first priest of Israel], Aaron.
Nígbà ọjọ́ Herodu ọba Judea, àlùfáà kan wà, láti ìran Abijah, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Sekariah: aya rẹ̀ sì ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Aaroni, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Elisabeti.
6 [God considered that] both of them were righteous, because they constantly completely obeyed everything that God had commanded.
Àwọn méjèèjì sì ṣe olódodo níwájú Ọlọ́run, wọ́n ń rìn ní gbogbo òfin àti ìlànà Olúwa ní àìlẹ́gàn.
7 But they had no children, because Elizabeth had been unable to bear children. Furthermore, she and her husband were very old.
Ṣùgbọ́n wọn kò ní ọmọ, nítorí tí Elisabeti yàgàn; àwọn méjèèjì sì di arúgbó.
8 One day [Zechariah’s] group was doing their work [in the Temple in Jerusalem], and he was serving as a priest in God’s presence.
Ó sì ṣe, nígbà tí ó ń ṣe iṣẹ́ àlùfáà níwájú Ọlọ́run ni àkókò tirẹ̀.
9 Following their custom, [the other priests] chose him by lot to enter the Lord’s temple and burn incense.
Bí ìṣe àwọn àlùfáà, ipa tirẹ̀ ni láti máa fi tùràrí jóná, nígbà tí ó bá wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
10 While he was burning the incense, many people were outside [in the courtyard], praying.
Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ń gbàdúrà lóde ní àkókò sísun tùràrí.
11 Then an angel whom God had [sent] appeared to him. The angel was standing at the right side of the place [where the priests burned] incense.
Angẹli Olúwa kan sì fi ara hàn án, ó dúró ní apá ọ̀tún pẹpẹ tùràrí.
12 When Zechariah saw the angel, he was startled and became very afraid.
Nígbà tí Sekariah sì rí i, orí rẹ̀ wú, ẹ̀rù sì bà á.
13 But the angel said to him, “Zechariah, do not be afraid! When you [(sg)] prayed [asking God for a son] (OR, [that God would send the Messiah]), God heard what you prayed. [So] your wife Elizabeth shall bear a son. You must name him John.
Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Sekariah: nítorí tí àdúrà rẹ gbà; Elisabeti aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Johanu.
14 He will cause you to be very happy, and many other people will also be happy because he is born.
Òun yóò sì jẹ́ ayọ̀ àti ìdùnnú fún ọ, ènìyàn púpọ̀ yóò sì yọ̀ sí ìbí rẹ.
15 God will consider him to be very important. He must never drink wine or any other alcoholic drink, [in order that he will be completely dedicated to God]. He will be controlled by the Holy Spirit {The Holy Spirit will control him} from before he is born.
Nítorí òun ó pọ̀ níwájú Olúwa, kì yóò sì mu ọtí wáìnì, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sì mu ọtí líle; yóò sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àní láti inú ìyá rẹ̀ wá.
16 He will [persuade] many people in Israel to turn away [from their sins and please] the Lord their God.
Òun ó sì yí ènìyàn púpọ̀ padà nínú àwọn ọmọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
17 As [God’s] Spirit enables him [to preach] powerfully as [the prophet] Elijah did, he will precede [the Messiah]. He will cause parents [SYN] to act [peacefully] toward their children [again]. He will cause [many] people who do not obey [God to hear and obey] the wise things that righteous people [tell them]. He will do this in order to help [many] people to be ready when the Lord [comes].”
Ẹ̀mí àti agbára Elijah ni Olúwa yóò sì fi ṣáájú rẹ̀ lọ, láti pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ti àwọn aláìgbọ́ràn sí ọgbọ́n àwọn olóòtítọ́; kí ó le pèsè àwọn ènìyàn tí a múra sílẹ̀ de Olúwa.”
18 Then Zechariah said to the angel, “I am very old, and my wife is also so old [that she cannot bear a child. So] (I cannot [believe] that what you [(sg)] said [will happen]!/how can I [believe] that what you [(sg)] said [will happen]?) [RHQ]”
Sekariah sì wí fún angẹli náà pé, “Àmì wo ni èmi ó fi mọ èyí? Èmi sá ti di àgbà, àti Elisabeti aya mi sì di arúgbó.”
19 Then the angel said to him, “I am [God’s chief angel], Gabriel! [I do what God tells me, because] I constantly am in God’s presence! I was sent {[He] sent me} to tell you [(sg)] something good [that is going to happen to you].
Angẹli náà sì dáhùn ó wí fún un pé, “Èmi ni Gabrieli, tí máa ń dúró níwájú Ọlọ́run; èmi ni a rán wá láti sọ fún ọ, àti láti mú ìròyìn ayọ̀ wọ̀nyí fún ọ wá.
20 What I have told you will certainly happen at the time [God decides], but you did not believe what I told you. So now [God will make] you will be unable to talk until the day [your son is born]”!
Sì kíyèsi i, ìwọ ó yadi, ìwọ kì yóò sì le fọhùn, títí ọjọ́ náà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ, nítorí ìwọ kò gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́ tí yóò ṣẹ ní àkókò wọn.”
21 While [Zechariah and the angel] were talking, the people [in the courtyard] were waiting for Zechariah [to come out]. They wondered, “Why is he staying in the Temple for such a long time?”
Àwọn ènìyàn sì ń dúró de Sekariah, ẹnu sì yà wọ́n nítorí tí ó pẹ́ nínú tẹmpili.
22 When Zechariah came out, he was not able to speak to the people. Because he could not talk, he made motions with his hands [to try to convey what had happened]. Then they realized that he had seen (a vision [from God]/something that [God] showed him) while he was in the Temple.
Nígbà tí ó sì jáde wá, òun kò le bá wọn sọ̀rọ̀. Wọn sì kíyèsi wí pé ó ti rí ìran nínú tẹmpili, ó sì ń ṣe àpẹẹrẹ sí wọn, nítorí tí ó yadi.
23 When Zechariah’s time to work [as a priest in the Temple] was finished, he [left Jerusalem and] returned to his home.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ pé, ó lọ sí ilé rẹ̀.
24 Some time later his wife Elizabeth became pregnant [EUP]. She did not leave their house for five months, [because she knew that people would laugh at her if she told them that she was pregnant].
Lẹ́yìn èyí ni Elisabeti aya rẹ̀ lóyún, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́ ní oṣù márùn-ún,
25 But she thought, “God has enabled me to become pregnant. He has pitied me and I will no longer be ashamed [because I have no children]!”
Ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa ṣe fún mi ní ọjọ́ tí ó síjú wò mí, láti mú ẹ̀gàn mi kúrò láàrín àwọn ènìyàn.”
26 When Elizabeth had been [pregnant] [EUP] [for almost] six months, the angel Gabriel was sent by God {God sent the angel Gabriel} [again].
Ní oṣù kẹfà Ọlọ́run sì rán angẹli Gabrieli sí ìlú kan ní Galili, tí à ń pè ní Nasareti,
27 [This time] he went to Nazareth [town] in Galilee [district], to a virgin whose name was Mary. It had been {[Her parents] had} promised that she would marry a man named Joseph, who was descended from [King] David.
sí wúńdíá kan tí a ṣèlérí láti fẹ́ fún ọkùnrin kan, tí a ń pè ní Josẹfu, ti ìdílé Dafidi; orúkọ wúńdíá náà a sì máa jẹ́ Maria.
28 The angel greeted her and said, “(The Lord/God) is with you [(sg)] and you will be greatly blessed {[has decided to] greatly bless you}!”
Angẹli náà sì tọ̀ ọ́ wá, ó ní, “Àlàáfíà fun ọ, ìwọ ẹni tí a kọjú sí ṣe ní oore, Olúwa ń bẹ pẹ̀lú rẹ.”
29 But Mary was very confused [when she heard] that. She wondered what [the angel meant] by these words.
Ṣùgbọ́n ọkàn Maria kò lélẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ náà, ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, irú kíkí kín ni èyí.
30 Then the angel said to her, “Mary, God is very pleased with you [(sg)], so do not be afraid.
Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Maria, nítorí ìwọ ti rí ojúrere lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
31 You will become pregnant and bear a son, and you must name him Jesus.
Ìwọ yóò lóyún nínú rẹ, ìwọ ó sì bí ọmọkùnrin kan, ìwọ ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu.
32 He will become great. He will be called {[People will] call him} (the Son of God/the man who is also God). God, the Lord, will make him a king [MTY] as his ancestor [King] David was.
Òun ó pọ̀, ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó sì máa pè é, Olúwa Ọlọ́run yóò sì fi ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀ fún.
33 He will be the King of [the] Jews, the descendants [MTY] of [your ancestor] Jacob, forever. He will rule as king forever!” (aiōn g165)
Yóò sì jẹ ọba lórí ilé Jakọbu títí láé; ìjọba rẹ̀ kì yóò sì ní ìpẹ̀kun.” (aiōn g165)
34 Then Mary said to the angel, “I am a virgin, so how can I [have a baby]?”
Nígbà náà ni Maria béèrè lọ́wọ́ angẹli náà pé, “Èyí yóò ha ti ṣe rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí èmi kò tí ì mọ ọkùnrin.”
35 The angel replied, “The Holy Spirit will come to you; the power of God [MTY/EUP] will overshadow you [and enable you to become pregnant]. So the child [you will] bear will be completely set apart {give himself completely} to obey God, and he will be called {[people] will say that he is} (the Son of God/the man who is also God).
Angẹli náà sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ yóò tọ̀ ọ́ wá, agbára Ọ̀gá-ògo jùlọ yóò síji bò ọ́. Nítorí náà ohun mímọ́ tí a ó ti inú rẹ bí, Ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè é.
36 [I also need to tell you something else]. Your cousin Elizabeth is very old, and it was thought {[people] said} that she could not bear any children. But she has been [pregnant] [EUP] [for almost] six months, and will bear a son!
Sì kíyèsi i, Elisabeti ìbátan rẹ náà yóò sì ní ọmọkùnrin kan ní ògbólógbòó rẹ̀, èyí sì ni oṣù kẹfà fún ẹni tí à ń pè ní àgàn.
37 [You should not be surprised at that], because God can do everything!”
Nítorí kò sí ohun tí Ọlọ́run kò le ṣe.”
38 Then Mary said, “All right, I want to serve (the Lord/God), so may what you [(sg)] have said about me come true!” Then the angel left her.
Maria sì dáhùn wí pé, “Wò ó ọmọ ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.
39 Very soon after that, Mary got ready and went quickly to a town in the highlands of Judea [district] where Zechariah lived.
Ní àkókò náà ni Maria sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Judea;
40 She entered his house and greeted [his wife] Elizabeth.
Ó sì wọ ilé Sekariah lọ ó sì kí Elisabeti.
41 As soon as Elizabeth heard Mary greet her, the baby moved inside [Elizabeth’s] womb. The Holy Spirit took complete control of Elizabeth,
Ó sì ṣe, nígbà tí Elisabeti gbọ́ kíkí Maria, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Elisabeti sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́,
42 and she said loudly [to Mary], “[God] has blessed you [more than] he has blessed [any other] woman, and [he has] blessed the child you will bear!
Ó sì ké ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni ìwọ nínú àwọn obìnrin, alábùkún fún sì ni ọmọ tí ìwọ yóò bí.
43 (I am not worthy that [God would allow you] to visit me!/Why is [God allowing you] to visit me?) [RHQ] You will be the mother of my Lord!
Èéṣe tí èmi fi rí irú ojúrere yìí, tí ìyá Olúwa mi ìbá fi tọ̀ mí wá?
44 [I realize this because] as soon as I heard you greet me, the baby inside my womb moved because he was so happy [that you had come].
Sá wò ó, bí ohùn kíkí rẹ ti bọ́ sí mi ní etí, ọlẹ̀ sọ nínú mi fún ayọ̀.
45 [God] is pleased with you [because] you believed that what (the Lord/God) told you would come true.”
Alábùkún fún sì ni ẹni tí ó gbàgbọ́, nítorí nǹkan wọ̀nyí tí a ti sọ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò ṣẹ.”
46 Then Mary [praised God by] saying/singing: “, how I [SYN] praise (the Lord/God)!
Maria sì dáhùn, ó ní: “Ọkàn mi yin Olúwa lógo.
47 I am happy because God is the one who saves me.
Ẹ̀mí mi sì yọ̀ sí Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
48 I was only his lowly servant girl, but he did not forget me. So from now on, everyone will say that God was pleased with me,
Nítorí tí ó síjú wo ìwà ìrẹ̀lẹ̀ ọmọbìnrin ọ̀dọ̀ rẹ̀. Sá wò ó, láti ìsinsin yìí lọ gbogbo ìran ènìyàn ni yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
49 because they will hear about the things that God [MTY], the mighty one, has done for me. He [MTY] is awesome!
Nítorí ẹni tí ó ní agbára ti ṣe ohun tí ó tóbi fún mi; Mímọ́ sì ni orúkọ rẹ̀.
50 He acts mercifully toward all those who respect him.
Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, láti ìrandíran.
51 He shows people that he [MTY] is very powerful. He scatters those who think proudly.
Ó ti fi agbára hàn ní apá rẹ̀; o ti tú àwọn onígbèéraga ká ní ìrònú ọkàn wọn.
52 He does not let mighty kings rule [MTY] any more, but he honors people who are oppressed (OR, humble).
Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn, o sì gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ lékè.
53 He gives good things to eat to those who are hungry, but he sends away the rich people without giving them anything.
Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebi ń pa ó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.
54 And now he has remembered what he promised. So he has helped me and all the other people of [MTY] Israel who serve him.
Ó ti ran Israẹli ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́, ní ìrántí àánú rẹ̀;
55 He promised to Abraham and all our other ancestors who descended from him that he would act mercifully toward them forever.” (aiōn g165)
sí Abrahamu àti àwọn ìran rẹ̀ láéláé, baba wa, àti bí ó ti sọ fún àwọn baba wa.” (aiōn g165)
56 Mary stayed with Elizabeth for about three months. Then she returned to her home.
Maria sì jókòó tì Elisabeti níwọ̀n oṣù mẹ́ta, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
57 When it was time for Elizabeth to give birth to her child, she bore a son.
Nígbà tí ọjọ́ Elisabeti pé tí yóò bí; ó sì bí ọmọkùnrin kan.
58 Her neighbors and relatives heard how (the Lord/God) had greatly blessed her [by enabling her to bear a child], so they were happy along with [Elizabeth].
Àwọn aládùúgbò, àti àwọn ìbátan rẹ̀ gbọ́ bí Olúwa ti fi àánú ńlá hàn fún un, wọ́n sì bá a yọ̀.
59 Seven days later they gathered together for the [ceremony for] circumcising the baby [to show that he belonged to God]. They wanted to give the baby the same name as his father, Zechariah.
Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n wá láti kọ ọmọ náà nílà; wọ́n sì fẹ́ sọ orúkọ rẹ̀ ní Sekariah, gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba rẹ̀.
60 But his mother said, “No, [his name will not be Zechariah]. His name will be John!”
Ìyá rẹ̀ sì dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Johanu ni a ó pè é.”
61 [So] they said to her, “[John] is not the name of any of your [(dl)] relatives, [so you(dl) should not give him that name]!”
Wọ́n sì wí fún un pé, “Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ará rẹ̀ tí à ń pè ní orúkọ yìí.”
62 Then they made motions with their hands to Zechariah, [for him] to indicate what name [he] wanted to be given {to give} to his son.
Wọ́n sì ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀, bí ó ti ń fẹ́ kí a pè é.
63 [So] he signaled that they [should give him] a tablet [to write on. When they gave him one], he wrote [on it], “His name is John.” All those [who were there] were surprised!
Ó sì béèrè fún wàláà, ó sì kọ ọ wí pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu sì ya gbogbo wọn.
64 Immediately Zechariah was able to speak again [MTY], and he praised God.
Ẹnu rẹ̀ sì ṣí lọ́gán, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì sọ̀rọ̀, ó sì ń yin Ọlọ́run.
65 All their neighbors were amazed/awestruck! They told other people who lived all over the highlands of Judea about what had happened.
Ẹ̀rù sì ba gbogbo àwọn tí ń bẹ ní agbègbè wọn, a sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí ká gbogbo ilẹ̀ òkè Judea.
66 Everyone who heard about it kept thinking about it. They were saying, “We wonder what will this child do [for God when] he [grows up] [RHQ]!” They wondered that because [from what had happened they were sure that] God would be helping that child [SYN] [in a powerful way].
Ó sì jẹ́ ohun ìyanu fún gbogbo àwọn tí ó gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì tò ó sínú ọkàn wọn, wọ́n ń wí pé, “Irú-ọmọ kín ni èyí yóò jẹ́?” Nítorí tí ọwọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.
67 [After] Zechariah’s [son was born], Zechariah was completely directed by the Holy Spirit {the Holy Spirit completely directed Zechariah} as he spoke these words that came from God:
Sekariah baba rẹ̀ sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì sọtẹ́lẹ̀, ó ní:
68 “Praise the Lord, the God whom we(inc) people of Israel worship, because he has come to set us, his people, free from our enemies.
“Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli; nítorí tí ó ti bojú wò, tí ó sì ti dá àwọn ènìyàn rẹ̀ nídè,
69 He is sending us someone who will powerfully [MTY] save us, someone who is descended from [MTY] King David, who served God well.
Ó sì ti gbé ìwo ìgbàlà sókè fún wa ní ilé Dafidi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀;
70 Long ago God caused his prophets to say that he would do that. (aiōn g165)
(bí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tipẹ́tipẹ́), (aiōn g165)
71 He will rescue us from our enemies, and he will save us from the power of all those who hate us.
Pé, a ó gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa àti lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wá.
72 He will do this because he has not forgotten what he promised our ancestors; he made an agreement that he would act mercifully to us, their descendants.
Láti ṣe àánú tí ó ṣèlérí fún àwọn baba wa, àti láti rántí májẹ̀mú rẹ̀ mímọ́,
73 That is what he strongly promised our ancestor Abraham that he would do.
ìbúra tí ó ti bú fún Abrahamu baba wa,
74 God told him that we would be rescued {he would rescue us} from the power of our enemies, that he would enable us to serve him without being afraid,
láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, kí àwa kí ó lè máa sìn láìfòyà,
75 that he would cause us to be completely dedicated to him, and enable us to live righteously all of our lives.”
ni ìwà mímọ́ àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.
76 [Then Zechariah said this to] his little son: “My child, you will be called {people will say that you are} a prophet whom God [MTY/EUP] has sent; you will begin your work before (the Lord/Messiah) comes; you will prepare people so that they will be ready for him. (OR, you will begin your work before the Messiah comes).
“Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́: nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;
77 You will tell God’s people how he will forgive them and save them from being punished for their sins.
láti fi ìmọ̀ ìgbàlà fún àwọn ènìyàn rẹ̀ fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
78 Our God will do that because he is very kind to us. Just like a new day begins when the sun rises [MET], God will do that new thing for us when the Messiah comes to us from heaven.
nítorí ìyọ́nú Ọlọ́run wà; nípa èyí tí ìlà-oòrùn láti òkè wá bojú wò wá,
79 People who do not know God [MET] are like those who sit in the darkness. They are afraid [MTY] that they will soon die. But when the Messiah tells us God’s message, it will be like causing such people to see a bright light. He will guide us [SYN] so that we will be living peacefully.”
Láti fi ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó jókòó ní òkùnkùn àti ní òjìji ikú, àti láti fi ẹsẹ̀ wa lé ọ̀nà àlàáfíà.”
80 [Later], Zechariah’s son grew up and became spiritually strong. Then he lived in a desolate region until he began to preach to the Israeli people.
Ọmọ náà sì dàgbà, ó sì le ní ọkàn, ó sì ń gbé ní ijù títí ó fi di ọjọ́ ìfihàn rẹ̀ fún Israẹli.

< Luke 1 >