< Psalms 74 >

1 Understanding for Asaph. O God, why hast thou cast us off unto the end: why is thy wrath enkindled against the sheep of thy pasture?
Maskili ti Asafu. Ọlọ́run, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ wá sílẹ̀ títí láé? Èéṣe tí ìbínú rẹ̀ fi dìde sí àwọn àgùntàn pápá rẹ?
2 Remember thy congregation, which thou hast possessed from the beginning. The sceptre of thy inheritance which thou hast redeemed: mount Sion in which thou hast dwelt.
Rántí àwọn ènìyàn tí ìwọ ti rà nígbà àtijọ́, ẹ̀yà ilẹ̀ ìní rẹ, tí ìwọ ti rà padà. Òkè Sioni, níbi tí ìwọ ń gbé.
3 Lift up thy hands against their pride unto the end; see what things the enemy hath done wickedly in the sanctuary.
Yí ẹsẹ̀ rẹ padà sí ìparun ayérayé wọn, gbogbo ìparun yìí tí ọ̀tá ti mú wá sí ibi mímọ́.
4 And they that hate thee have made their boasts, in the midst of thy solemnity. They have set up their ensigns for signs,
Àwọn ọ̀tá rẹ ń bú ramúramù láàrín ènìyàn rẹ, wọ́n ń gbé àsíá wọn sókè fún àmì.
5 And they knew not both in the going out and on the highest top. As with axes in a wood of trees,
Wọ́n ń rí bí ọkùnrin tí ó gbé àáké rẹ̀ sókè láti gé igi igbó dídí.
6 They have cut down at once the gates thereof, with axe and hatchet they have brought it down.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, iṣẹ́ ọnà fínfín, ni wọ́n fi àáké wó lulẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan náà.
7 They have set fire to thy sanctuary: they have defiled the dwelling place of thy name on the earth.
Wọ́n sun ibi mímọ́ rẹ lulẹ̀ wọ́n ba ibùgbé orúkọ rẹ jẹ́.
8 They said in their heart, the whole kindred of them together: Let us abolish all the festival days of God from the land.
Wọ́n wí ní ọkàn wọn. “Àwa ó run wọ́n pátápátá!” Wọ́n sun gbogbo ibi ìjọ́sìn Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà.
9 Our signs we have not seen, there is now no prophet: and he will know us no more.
A kò fún wa ní àmì iṣẹ́ ìyanu kankan; kò sí wòlíì kankan ẹnìkankan wa kò mọ ìgbà tí eléyìí yóò dà.
10 How long, O God, shall the enemy reproach: is the adversary to provoke thy name for ever?
Àwọn ọ̀tá yóò ti kùn sí ọ pẹ́ tó, Ọlọ́run? Àwọn ọ̀tá yóò ha ba orúkọ rẹ jẹ́ títí láé?
11 Why dost thou turn away thy hand: and thy right hand out of the midst of thy bosom for ever?
Èéṣe tí ìwọ fi dá ọwọ́ rẹ dúró, ọwọ́ ọ̀tún rẹ? Mú un kúrò nínú ìṣẹ́po aṣọ rẹ kí o sì run wọ́n!
12 But God is our king before ages: he hath wrought salvation in the midst of the earth.
Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run ni ọba mi láti ìgbà pípẹ́; Ó mú ìgbàlà wá sórí ilẹ̀ ayé.
13 Thou by thy strength didst make the sea firm: thou didst crush the heads of the dragons in the waters.
Ìwọ ni ó la òkun sílẹ̀ nípa agbára rẹ; ìwọ fọ́ orí ẹ̀mí búburú nínú omi.
14 Thou hast broken the heads of the dragon: thou hast given him to be meat for the people of the Ethiopians.
Ìwọ fọ́ orí Lefitani túútúú, o sì fi ṣe oúnjẹ fun àwọn ẹ̀dá tí ń gbé inú ijù tìrẹ ni ọ̀sán, tìrẹ sì ni alẹ́ pẹ̀lú; ìwọ fi ìdí oòrùn àti òṣùpá lélẹ̀.
15 Thou hast broken up the fountains and the torrents: thou hast dried up the Ethan rivers.
Ìwọ ya orísun omi àti ìṣàn omi; Ìwọ mú kí odò tó ń sàn gbẹ.
16 Thine is the day, and thine is the night: thou hast made the morning light and the sun.
Tìrẹ ni ọ̀sán, tìrẹ ni òru pẹ̀lú; ìwọ yà oòrùn àti òṣùpá.
17 Thou hast made all the borders of the earth: the summer and the spring were formed by thee.
Ìwọ pààlà etí ayé; Ìwọ dá ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn àti ìgbà òtútù.
18 Remember this, the enemy hath reproached the Lord: and a foolish people hath provoked thy name.
Rántí bí àwọn ọ̀tá ń kẹ́gàn rẹ, Olúwa bí àwọn aṣiwèrè ènìyàn ti ń ba orúkọ rẹ jẹ́.
19 Deliver not up to beasts the souls that confess to thee: and forget not to the end the souls of thy poor.
Má ṣe fi ẹ̀mí àdàbà rẹ fún ẹranko igbó búburú; má ṣe gbàgbé ẹ̀mí àwọn ènìyàn rẹ tí a ń pọ́n lójú títí láé.
20 Have regard to thy covenant: for they that are the obscure of the earth have been filled with dwellings of iniquity.
Bojú wo májẹ̀mú rẹ, nítorí ibi òkùnkùn ayé kún fún ibùgbé ìkà.
21 Let not the humble be turned away with confusion: the poor and needy shall praise thy name.
Má ṣe jẹ́ kí àwọn aninilára padà sẹ́yìn nínú ìtìjú jẹ́ kí àwọn aláìní àti tálákà yin orúkọ rẹ.
22 Arise, O God, judge thy own cause: remember thy reproaches with which the foolish man hath reproached thee all the day.
Dìde, Ọlọ́run, gba ẹjọ́ ara rẹ rò; rántí bí àwọn aṣiwèrè ti ń kẹ́gàn rẹ ní gbogbo ọjọ́.
23 Forget not the voices of thy enemies: the pride of them that hate thee ascendeth continually.
Má ṣe gbàgbé ohùn àwọn ọ̀tá rẹ, bíbú àwọn ọ̀tá rẹ, tí ó ń pọ̀ sí i nígbà gbogbo.

< Psalms 74 >