< Psalms 73 >

1 A psalm for Asaph. How good is God to Israel, to them that are of a right heart!
Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
2 But my feet were almost moved; my steps had well nigh slipped.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
3 Because I had a zeal on occasion of the wicked, seeing the prosperity of sinners.
Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
4 For there is no regard to their death, nor is there strength in their stripes.
Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
5 They are not in the labour of men: neither shall they be scourged like other men.
Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
6 Therefore pride hath held them fast: they are covered with their iniquity and their wickedness.
Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
7 Their iniquity hath come forth, as it were from fatness: they have passed into the affection of the heart.
Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
8 They have thought and spoken wickedness: they have spoken iniquity on high.
Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
9 They have set their mouth against heaven: and their tongue hath passed through the earth.
Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
10 Therefore will my people return here and full days shall be found in them.
Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
11 And they said: How doth God know? and is there knowledge in the most High?
Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
12 Behold these are sinners; and yet abounding in the world they have obtained riches.
Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
13 And I said: Then have I in vain justified my heart, and washed my hands among the innocent.
Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
14 And I have been scourged all the day; and my chastisement hath been in the mornings.
Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
15 If I said: I will speak thus; behold I should condemn the generation of thy children.
Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
16 I studied that I might know this thing, it is a labour in my sight:
Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
17 Until I go into the sanctuary of God, and understand concerning their last ends.
títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
18 But indeed for deceits thou hast put it to them: when they were lifted up thou hast cast them down.
Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
19 How are they brought to desolation? they have suddenly ceased to be: they have perished by reason of their iniquity.
Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
20 As the dream of them that awake, O Lord; so in thy city thou shalt bring their image to nothing.
Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
21 For my heart hath been inflamed, and my reins have been changed:
Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
22 And I am brought to nothing, and I knew not.
mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
23 I am become as a beast before thee: and I am always with thee.
Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
24 Thou hast held me by my right hand; and by thy will thou hast conducted me, and with thy glory thou hast received me.
Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
25 For what have I in heaven? and besides thee what do I desire upon earth?
Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
26 For thee my flesh and my heart hath fainted away: thou art the God of my heart, and the God that is my portion for ever.
Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
27 For behold they that go far from thee shall perish: thou hast destroyed all them that are disloyal to thee.
Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
28 But it is good for me to adhere to my God, to put my hope in the Lord God: That I may declare all thy praises, in the gates of the daughter of Sion.
Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.

< Psalms 73 >