< Psalms 96 >

1 When the house was built after the Captivity, a Song of David. Sing to the Lord a new song; sing to the Lord, all the earth.
Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa, ẹ kọrin sí Olúwa gbogbo ayé.
2 Sing to the Lord, bless his name: proclaim his salvation from day to day.
Ẹ kọrin sí Olúwa, yin orúkọ rẹ̀ ẹ sọ ti ìgbàlà rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́.
3 Publish his glory amongst the Gentiles, his wonderful works amongst all people.
Ẹ sọ ti ògo rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrín gbogbo ènìyàn.
4 For the Lord is great, and greatly to be praised: he is terrible above all gods.
Nítorí títóbi ní Olúwa ẹni tí ìyìn tọ́ sí; òun ní o yẹ kí a bẹ̀rù ju gbogbo òrìṣà lọ.
5 For all the gods of the heathen are devils: but the Lord made the heavens.
Nítorí asán ni gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
6 Thanksgiving and beauty are before him: holiness and majesty are in his sanctuary.
Ọlá àti ọláńlá wà ní iwájú rẹ̀ agbára àti ògo wà ní ibi mímọ́ rẹ̀.
7 Bring to the Lord, you families of the Gentiles, bring to the Lord glory and honour.
Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìbátan ènìyàn, ẹ fi agbára àti ògo fún Olúwa.
8 Bring to the Lord the glory [becoming] his name: take offerings, and go into his courts.
Ẹ fi ògo tí ó tọ́ sí Olúwa fún un; ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá rẹ̀.
9 Worship the Lord in his holy court: let all the earth tremble before him.
Ẹ máa sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́ rẹ̀; ẹ wárìrì níwájú rẹ̀ gbogbo ayé.
10 Say amongst the heathen, The Lord reigns: for he has established the world so that it shall not be moved: he shall judge the people in righteousness.
Sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, “Olúwa jẹ ọba.” A fi ìdí ayé múlẹ̀, tí kò sì lè yí; ẹni tí yóò fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ ènìyàn.
11 Let the heavens rejoice, and the earth exult; let the sea be moved, and the fullness of it.
Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, kí ayé sì pariwo jẹ́ kí pápá òkun kí ó hó pẹ̀lú ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀.
12 The plains shall rejoice, and all things in them: then shall all the trees of the wood exult before the presence of the Lord:
Jẹ́ kí oko kún fún ayọ̀, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀; nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóò máa yọ̀.
13 for he comes, for he comes to judge the earth; he shall judge the world in righteousness, and the people with his truth.
Wọn yóò kọrin níwájú Olúwa, nítorí tí ó ń bọ̀ wá, ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé. Yóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé àti ti àwọn ènìyàn ni yóò fi òtítọ́ rẹ̀ ṣe.

< Psalms 96 >