< 5 Mosebog 5 >

1 Moses kaldte hele Israel sammen og sagde til dem: Hør, Israel, de Anordninger og Lovbud, som jeg kundgør eder i Dag! Lær dem og hold dem omhyggeligt.
Mose sì pe gbogbo Israẹli jọ, ó sì wí pé, Gbọ́ ìwọ Israẹli, gbọ́ ìlànà àti òfin tí mo mú wá sí etí ìgbọ́ ọ yín lónìí. Ẹ kọ wọ́n, kí ẹ sì ri dájú pé ẹ̀ ń ṣe wọ́n.
2 HERREN vor Gud sluttede en Pagt med os ved Horeb.
Olúwa Ọlọ́run wa bá wa dá májẹ̀mú ní Horebu.
3 Det var ikke med vore Fædre, HERREN sluttede den Pagt, men med os, vi, der i Dag er her til Stede, alle vi, der er i Live.
Kì í ṣe àwọn baba wa ni Olúwa bá dá májẹ̀mú yìí bí kò ṣe àwa, àní pẹ̀lú gbogbo àwa tí a wà láààyè níbí lónìí.
4 Ansigt til Ansigt talede HERREN med eder på Bjerget ud fra Ilden.
Olúwa bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú láàrín iná lórí òkè.
5 Jeg stod dengang som Mellemmand mellem HERREN og eder og kundgjorde eder HERRENs Ord; thi I var bange for Ilden og turde ikke stige op på Bjerget.
(Ní ìgbà yìí, mo wà láàrín ẹ̀yin pẹ̀lú Ọlọ́run láti sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un yín torí pé ẹ̀rù Ọlọ́run ń bà yín, ẹ kò sì lè kọjá lọ sórí òkè.) Ó sì wí pé,
6 Han sagde: Jeg er HERREN din Gud, som førte dig ud af Ægypten, af Trællehuset.
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
7 Du må ikke have andre Guder end mig.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
8 Du må ikke gøre dig noget udskåret Billede eller noget Afbillede af det, som er oppe i Himmelen eller nede på Jorden eller i Vandet under Jorden;
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
9 du må ikke tilbede eller dyrke det, thi jeg HERREN din Gud er en nidkær Gud, der indtil tredje og fjerde Led straffer Fædres Brøde på Børn af dem, som hader mig,
Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
10 men i tusind Led viser Miskundhed mod dem, der elsker mig og holder mine Bud!
Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
11 Du må ikke misbruge HERREN din Guds Navn, thi HERREN lader ikke den ustraffet, der misbruger hans Navn!
Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
12 Tag Vare på Hviledagen, så du holder den hellig, således som HERREN din Gud har pålagt dig!
Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín.
13 I seks Dage skal du arbejde og gøre al din Gerning,
Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ.
14 men den syvende Dag skal være Hviledag for HERREN din Gud; da må du intet Arbejde udføre, hverken du selv, din Søn eller Datter, din Træl eller Trælkvinde, din Okse eller dit Æsel eller noget af dit Kvæg eller den fremmede inden dine Porte, for at din Træl og Trælkvinde kan hvile ud ligesom du selv.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti akọ màlúù rẹ, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, àti ohun ọ̀sìn rẹ kan, àti àlejò tí ń bẹ nínú ibodè rẹ; kí ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin kí ó lè sinmi gẹ́gẹ́ bí ìwọ.
15 Kom i Hu, at du selv var Træl i Ægypten, og at HERREN din Gud førte dig ud derfra med stærk Hånd og udstrakt Arm; det er derfor, HERREN din Gud har pålagt dig at fejre Hviledagen!
Sì rántí pé, ìwọ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, àti pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yọ ọ́ kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá, àti nína ọwọ́ rẹ̀. Torí èyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe pàṣẹ fún ọ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́.
16 Ær din Fader og din Moder, således som HERREN din Gud har pålagt dig, for at du kan få et langt Liv, og det må gå dig vel i det Land, HERREN din Gud vil give dig.
Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún ọ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́, àti kí ó lè dára fún ọ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
17 Du må ikke slå ihjel!
Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
18 Du må ikke bedrive Hor!
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
19 Du må ikke stjæle!
Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
20 Du må ikke sige falsk Vidnesbyrd imod din Næste!
Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
21 Du må ikke begære din Næstes Hustru. Du må ikke attrå din Næstes Hus, hans Mark, hans Træl eller Trælkvinde, hans Okse eller Æsel eller noget, der hører din Næste til!
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéji rẹ, oko rẹ̀, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéji rẹ.”
22 Disse Ord talede HERREN til hele eders Forsamling på Bjerget ud fra Ilden, Skyen og Mulmet med vældig Røst uden at føje noget til; og han skrev dem op på to Stentavler og gav mig dem.
Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ Olúwa tí a kéde rẹ̀ sí gbogbo ìpéjọpọ̀ ọ yín, níbẹ̀ ní orí òkè, láàrín iná, ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri, kò sì fi ohunkóhun kún un mọ́. Ó sì kọ wọ́n sínú wàláà méjì, Ó sì fi wọ́n lé mi lọ́wọ́.
23 Men da I hørte Røsten, der lød ud fra Mørket, medens Bjerget stod i lys Lue, kom I, alle Overhovederne for eders Stammer og eders Ældste, hen til mig
Nígbà tí ẹ gbóhùn láti inú òkùnkùn wá, nígbà tí iná náà ń yọ iná lala, àwọn aṣáájú ẹ̀yà a yín àti àwọn àgbàgbà yín tọ̀ mí wá.
24 og sagde: "Se, HERREN vor Gud har ladet os skue sin Herlighed og Storhed, og hans Røst har vi hørt ud fra Ilden; i Dag har vi oplevet, at Gud kan tale med Mennesker, uden at de dør.
Ẹ sì sọ pé, “Olúwa Ọlọ́run wa ti fi ògo rẹ̀ hàn wá, àti títóbi rẹ̀ a sì ti gbóhùn rẹ̀ láti àárín iná wá. A ti rí i lónìí pé, ènìyàn sì lè wà láààyè lẹ́yìn tí Ọlọ́run bá bá a sọ̀rọ̀.
25 Men hvorfor skal vi dø? Thi denne vældige Ild vil fortære os; hvis vi skal blive ved at høre på HERREN vor Guds Røst, må vi dø!
Ṣùgbọ́n èéṣe tí àwa yóò fi kú? Iná ńlá yìí yóò jó wa run, bí àwa bá sì tún gbọ́ ohun Olúwa Ọlọ́run wa, àwa ó kú.
26 Thi hvilken dødelig har nogen Sinde som vi hørt den levende Guds Røst ud fra Ilden og levet?
Ta ni nínú ẹlẹ́ran ara tí ó ti gbọ́ ohun Ọlọ́run alààyè láti inú iná rí, bí àwa ti gbọ́ ọ, tí a sì wà láyé?
27 Træd du hen og hør alt, hvad HERREN vor Gud siger; siden skal du så sige os alt, hvad HERREN vor Gud taler til dig, og vi skal høre det og gøre derefter."
Súnmọ́ tòsí ibẹ̀ kí o sì gbọ́ gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò sọ, nígbà náà sọ ohunkóhun tí Olúwa Ọlọ́run wa sọ fún ọ fún wa. A ó sì fetísílẹ̀, a ó sì gbọ́rọ̀.”
28 Og da HERREN hørte, hvorledes I talte til mig, sagde han til mig: "Jeg har hørt, hvad dette Folk siger til dig, og alt, hvad de har sagt til dig, er ret;
Olúwa ń gbọ́ nígbà tí ẹ̀yin ń bá mi sọ̀rọ̀, Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti gbọ́ ohun tí àwọn ènìyàn yí sọ fún ọ. Gbogbo ohun tí wọ́n sọ dára,
29 gid de alle Dage må have et sådant Hjerte, at de frygter mig og holder alle mine Bud, for at det må gå dem og deres Børn vel evindelig.
ìbá ti dára tó, bí ọkàn wọn bá lè bẹ̀rù mi, tí ó sì ń pa gbogbo òfin mi mọ́ nígbà gbogbo, kí ó bá à lè dára fún wọn, àti àwọn ọmọ wọn láéláé.
30 Gå derfor hen og byd dem at vende tilbage til deres Telte;
“Lọ sọ fún wọn kí wọn padà sínú àgọ́ wọn.
31 men bliv du stående her hos mig, så skal jeg kundgøre dig alle Budene, Anordningerne og Lovbudene, som du skal lære dem, og som de skal holde i det Land, jeg vil give dem i Eje!"
Ṣùgbọ́n ìwọ túbọ̀ dúró síbí pẹ̀lú mi, kí n bá à lè fún ọ ní àwọn àṣẹ tí o gbọdọ̀ fi kọ́ wọn láti máa tẹ̀lé ní ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún wọn láti ní.”
32 Gør derfor omhyggeligt således, som HERREN eders Gud har pålagt eder, uden at vige til højre eller venstre;
Torí èyí, ẹ ṣọ́ra láti máa ṣe ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín tí pa ní àṣẹ fún un yín; ẹ má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì.
33 følg altid den Vej, som HERREN eders Gud har pålagt eder at gå, at I kan blive i Live og få det godt og leve længe i det Land, I skal tage i Besiddelse!
Ẹ rìn ní gbogbo ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín, kí ẹ bá à le yè, kí ó sì dára fún un yín, kí ọjọ́ ọ yín bá à lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin yóò gbà.

< 5 Mosebog 5 >