< 5 Mosebog 4 >

1 Og nu, Israel! Hør de Anordninger og Lovbud, som jeg vil lære eder at holde, for at I kan blive i Live og komme ind og tage det Land i Besiddelse, som HERREN, eders Fædres Gud, vil give eder.
Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
2 I må hverken lægge noget til eller trække noget fra, hvad jeg byder eder, men I skal holde HERREN eders Guds Bud, som jeg pålægger eder.
Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
3 I har med egne Øjne set, hvad HERREN gjorde i Anledning af Ba'al Peor: Hver eneste Mand, som fulgte Ba'al Peor, udryddede HERREN din Gud af din Midte.
Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
4 Men I, som holdt fast ved HERREN eders Gud, er alle i Live den Dag i Dag.
Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
5 Se, jeg har lært eder Anordninger og Lovbud, således som HERREN min Gud har pålagt mig, for at I skal handle derefter i det Land, I skal ind og tage i Besiddelse;
Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
6 hold dem og følg dem! Thi det skal være eders Visdom og eders Kløgt i de andre Folks Øjne. Når de hører om alle disse Anordninger, skal de sige: "Sandelig, det er et vist og klogt Folk, dette store Folk!"
Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
7 Thi hvor er der vel et stort Folk, som har Guder, der kommer til det, således som HERREN vor Gud gør det, når vi kalder på ham;
Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
8 og hvor er der vel et stort Folk, der har så retfærdige Anordninger og Lovbud som hele denne Lov, jeg forelægger eder i Dag?
Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
9 Kun skal du vogte dig og omhyggeligt tage Vare på dig selv, at du ikke glemmer, hvad du med egne Øjne har set, og at det ikke viger fra dit Hjerte, så længe du lever; og du skal fortælle dine Sønner og dine Sønners Sønner derom.
Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
10 Glem ikke den Dag, du stod for HERREN din Guds Åsyn ved Horeb, da HERREN sagde til mig: "Kald mig Folket sammen, for at jeg kan kundgøre dem mine Ord, så de kan lære at frygte mig, så længe de lever på Jorden, og lære deres Sønner det samme!"
Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
11 Da trådte I frem og stod ved Bjergets Fod, medens Bjerget brændte i lys Lue helt ind i Himmelen, hylet i Mørke, Skyer og Mulm;
Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
12 og da HERREN talede til eder ud fra Ilden, hørte I kun Ordene, men nogen Skikkelse så I ikke, kun en Røst fornam I.
Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
13 Da kundgjorde han eder sin Pagt, som han bød eder at holde, de ti Ord, og han skrev dem på to Stentavler.
Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
14 Og mig bød HERREN dengang at lære eder Anordninger og Lovbud, som I skulde overholde idet Land, I nu skal over og tage i Besiddelse.
Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
15 Eftersom I ikke så nogen Skikkelse, dengang HERREN talede til eder på Horeb ud fra Ilden, så vogt eder nu omhyggeligt for
Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
16 at handle så ryggesløst, at I laver eder et Gudebillede, en Stenstøtte i en eller anden Skikkelse, enten det nu er et Afbillede af en Mand eller en Kvinde
kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
17 eller et Afbillede af et eller andet Dyr, der lever på Jorden, eller et Afbillede af en eller anden vinget Fugl, der flyver under Himmelen,
tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
18 eller et Afbillede af et eller andet Kryb, der kryber på Jorden, eller et Afbillede af en eller anden Fisk i Vandet under Jorden;
tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
19 og når du løfter dit Blik til Himmelen og ser Solen og Månen og Stjernerne, hele Himmelens Hær, så vogt dig for at lade dig forføre til at tilbede og dyrke dem. Thi HERREN din Gud har tildelt alle de andre Folk under hele Himmelen dem;
Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
20 men eder tog HERREN og førte ud af Smelteovnen, af Ægypten, for at I skulde være hans Ejendomsfolk, som I nu er.
Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
21 Men HERREN blev vred på mig for eders Skyld og svor, at jeg ikke skulde komme over Jordan ind i det herlige Land, som HERREN din Gud vil give dig i Eje,
Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
22 thi jeg skal dø i Landet her; jeg skal ikke komme over Jordan, men I skal komme over og tage dette herlige Land i Besiddelse.
Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
23 Så vogt eder for at glemme HERREN eders Guds Pagt, som han sluttede med eder, og for at lave eder noget Gudebillede i Skikkelse af noget som helst, HERREN din Gud har forbudt dig
Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
24 Thi HERREN din Gud er en fortærende Ild, en nidkær Gud!
Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
25 Når du får Børn og Børnebørn, og I bliver gamle i Landet, og I da handler så ryggesløst, at I laver eder Gudebilleder i en eller anden Skikkelse og gør, hvad der er ondt i HERREN din Guds Øjne, så at I fortørner ham,
Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
26 så kalder jeg i Dag Himmelen og Jorden til Vidne imod eder på, at I hastigt skal blive udryddet af det Land, I skal over Jordan og tage i Besiddelse; I skal ikke få noget langt Liv der, men visselig gå til Grunde;
Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
27 og HERREN vil splitte eder mellem Folkene, og kun nogle få af eder skal blive tilbage blandt de Folkeslag, HERREN driver eder hen iblandt.
Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
28 Der skal I komme til at dyrke Guder, der er Menneskehænders Værk, Træ og Sten, som hverken kan se eller høre, spise eller lugte!
Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
29 Der skal I så søge HERREN din Gud, og du skal finde ham, når du søger ham af hele dit Hjerte og hele din Sjæl.
Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
30 I de kommende Dage, når du er i Nød, og alle disse Ting kommer over dig, skal du vende om til HERREN din Gud og adlyde hans Røst.
Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
31 Thi en barmhjertig Gud er HERREN din Gud; han slipper dig ikke og lader dig ikke gå til Grunde og glemmer ikke Pagten med dine Fædre, som han tilsvor dem.
Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
32 Thi gransk dog i de henfarne Tider, der gik forud for dig, lige fra den Tid af da Gud skabte Menneskene på Jorden, og fra den ene Ende af Himmelen til den anden, om der er sket noget så stort som dette, eller om dets Lige er hørt.
Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
33 Har noget Folk hørt Guds Røst ud fra Ilden, således som du hørte det, og levet?
Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
34 Eller har nogen Gud søgt at komme og hente sig et Folk midt ud af et andet Folk ved Prøvelser, Tegn og Undere, ved Krig, med stærk Hånd og udstrakt Arm og store Rædsler, således som du med egne Øjne så HERREN eders Gud gøre med eder i Ægypten?
Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
35 Du fik det at se, for at du skulde vide, af HERREN og ingen anden er Gud.
A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
36 Fra Himmelen lod han dig høre sin Røst for at undervise dig, og på Jorden lod han dig se sin store Ild, og hans Ord hørte du ud fra Ilden.
Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
37 Og fordi han elskede dine Fædre og udvalgte deres Afkom efter dem og selv førte dig ud af Ægypten ved sin store Vælde
torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
38 for at drive Folk bort foran dig, der er større og mægtigere end du selv, og lade dig komme ind i deres Land og give dig det i Eje, som det nu er sket,
Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
39 derfor skal du i Dag vide og lægge dig på Sinde, at HERREN og ingen anden er Gud oppe i Himmelen og nede på Jorden.
Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
40 Og du skal holde hans Anordninger og Bud, som jeg pålægger dig i Dag, for at det kan gå dig og dine Børn efter dig vel, og for at du alle Dage kan leve længe i det Land, HERREN din Gud giver dig!
Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
41 På den Tid udskilte Moses tre Byer hinsides Jordan, på den østre Side,
Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
42 som Tilflugtsteder for Manddrabere, der uforsætligt slår et andet Menneske ihjel uden i Forvejen at have båret Nag til ham, for at de kan redde Livet ved at ty til en af disse Byer,
Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
43 nemlig Bezer i Ørkenen på Højsletten for Rubeniterne, Ramot i Gilead for Gaditerne og Golan i Basan for Manassiterne.
Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
44 Dette er den Lov, Moses forelagde Israelitterne.
Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
45 Dette er de Vidnesbyrd, Anordninger og Lovbud, Moses kundgjorde Israelitterne, da de drog bort fra Ægypten,
Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
46 hinsides Jordan i Dalen lige for Bet Peor i det Land, der havde tilhørt Amoriterkongen Sihon, som boede i Hesjbon, og som Moses og Israelitterne havde slået, da de drog bort fra Ægypten.
Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
47 De havde erobret hans og Kong Og af Basans Land, de to Amoriterkonger hinsides Jordan, på den østre Side,
Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
48 fra Aroer ved Arnonflodens Bred til Sirjons Bjerg, det er Hermon,
Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
49 tillige med hele Arabalavningen hinsides Jordan, på den østre Side, lige til Arabahavet neden for Pisgas Skrænter.
Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.

< 5 Mosebog 4 >