< ⲖⲞⲨⲔⲞⲚ 4 >

1 ⲁ̅ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲆⲈ ⲈϤⲘⲈϨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲐⲞⲨⲀⲂ ⲀϤⲦⲀⲤⲐⲞ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒ ⲠⲒⲒⲞⲢⲆⲀⲚⲎⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲖϤ ⲚϪⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲠϢⲀϤⲈ.
Jesu sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó padà ti Jordani wá, a sì ti ọwọ́ Ẹ̀mí darí rẹ̀ sí ijù,
2 ⲃ̅ ⲚⲘ ⲚⲈϨⲞⲞⲨ ⲈϤⲈⲢⲠⲒⲢⲀⲌⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲚϪⲈⲠⲒⲆⲒⲀⲂⲞⲖⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈϤⲞⲨⲈⲘ ϨⲖⲒ ϦⲈⲚⲚⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨϪⲰⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲀϤϨⲔⲞ.
Ogójì ọjọ́ ni a fi dán an wò lọ́wọ́ èṣù. Kò sì jẹ ohunkóhun ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: nígbà tí wọ́n sì parí, lẹ́yìn náà ni ebi wá ń pa á.
3 ⲅ̅ ⲠⲈϪⲀϤ ⲆⲈ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲠⲒⲆⲒⲀⲂⲞⲖⲞⲤ ϪⲈ ⲒⲤϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲀϪⲞⲤ ⲘⲠⲀⲒⲰⲚⲒ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲈⲢⲰⲒⲔ.
Èṣù sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, pàṣẹ fún òkúta yìí kí ó di àkàrà.”
4 ⲇ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲤⲤϦⲎ ⲞⲨⲦ ϪⲈ ⲚⲀⲢⲈ ⲠⲒⲢⲰⲘⲒ ⲚⲀⲰⲚϦ ⲈⲰⲒⲔ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲀⲚ.
Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ènìyàn kì yóò wà láààyè nípa àkàrà nìkan.’”
5 ⲉ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲞⲖϤ ⲈⲠϢⲰⲒ ⲀϤⲦⲀⲘⲞϤ ⲈⲚⲒⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲰⲞⲨ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲚⲦⲈϮⲞⲒⲔⲞⲨⲘⲈⲚⲎ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲦⲒⲄⲘⲎ ⲚⲦⲈⲞⲨⲬⲢⲞⲚⲞⲤ.
Lójúkan náà, èṣù sì mú un lọ sí orí òkè gíga, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ ọba ayé hàn án.
6 ⲋ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲠⲒⲆⲒⲀⲂⲞⲖⲞⲤ ϪⲈ ϮⲚⲀϮ ⲚⲀⲔ ⲘⲠⲀⲒⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲦⲎⲢϤ ⲚⲈⲘ ⲠⲞⲨⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ⲈⲦⲈϤⲦⲞⲒ ⲈⲦⲞⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲎ ⲈϮⲞⲨⲀϢϤ ϢⲀⲒⲦⲎⲒϤ ⲚⲀϤ.
Èṣù sì wí fún un pé, “Ìwọ ni èmi ó fi gbogbo agbára yìí àti ògo wọn fún: nítorí á sá ti fi fún mi. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wù mí, èmi a fi í fún.
7 ⲍ̅ ⲚⲐⲞⲔ ⲞⲨⲚ ⲀⲔϢⲀⲚⲞⲨⲰϢⲦ ⲘⲠⲀⲘⲐⲞ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϤⲈϢⲰⲠⲒ ⲚⲀⲔ ⲦⲎⲢϤ.
Ǹjẹ́ bí ìwọ bá foríbalẹ̀ fún mi, gbogbo rẹ̀ ni yóò jẹ́ tìrẹ.”
8 ⲏ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ϪⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲠⲈⲔⲚⲞⲨϮ ⲠⲈ ⲈⲦⲈⲔⲈⲞⲨⲰϢⲦ ⲘⲘⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲞϤ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲠⲈⲦⲈⲔⲈϢⲈⲘϢⲒ ⲘⲘⲞϤ.
Jesu sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Kúrò lẹ́yìn mi, Satani, nítorí tí a kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ìwọ foríbalẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, òun nìkan ṣoṣo ni kí ìwọ kí ó sì máa sìn.’”
9 ⲑ̅ ⲀϤⲈⲚϤ ⲆⲈ ⲞⲚ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲀϨⲞϤ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲦⲈⲚϨ ⲚⲦⲈⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲒⲤϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ϨⲒⲦⲔ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ⲈⲂⲞⲖ ⲦⲀⲒ.
Èṣù sì mú un lọ sí Jerusalẹmu, ó sì gbé e lé ibi ṣóńṣó tẹmpili, ó sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, bẹ́ sílẹ̀ fún ara rẹ láti ibí yìí.
10 ⲓ̅ ⲤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ⲄⲀⲢ ϪⲈ ⲈϤⲈϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲈⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚⲚⲈϤⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ ⲈⲐⲂⲎⲦⲔ ϪⲈ ⲚⲦⲞⲨⲀⲢⲈϨ ⲈⲢⲞⲔ
A sá ti kọ̀wé rẹ̀ pé, “‘Yóò pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀ nítorí rẹ, láti máa ṣe ìtọ́jú rẹ;
11 ⲓ̅ⲁ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲞⲨϤⲒⲦⲔ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲞⲨϬⲚⲀⲨϨ ⲘⲎⲠⲞⲦⲈ ⲚⲦⲈⲔϬⲒϬⲢⲞⲠ ⲈⲞⲨⲰⲚⲒ ⲚⲦⲈⲔϬⲀⲖⲞϪ.
àti pé ní ọwọ́ wọn ni wọn ó gbé ọ sókè, kí ìwọ kí ó má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gbún òkúta.’”
12 ⲓ̅ⲃ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲨϪⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲚⲈⲔⲈⲢⲠⲒⲢⲀⲌⲒⲚ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲠⲈⲔⲚⲞⲨϮ.
Jesu sì dáhùn ó wí fún un pé, “A ti kọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run rẹ wò.’”
13 ⲓ̅ⲅ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤϪⲈⲔ ⲠⲒⲢⲀⲤⲘⲞⲤ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲠⲒⲆⲒⲀⲂⲞⲖⲞⲤ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀⲢⲞϤ ϢⲀ ⲞⲨⲤⲎⲞⲨ.
Nígbà tí èṣù sì parí ìdánwò náà gbogbo, ó fi í sílẹ̀ lọ fun sá à kan.
14 ⲓ̅ⲇ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲀⲤⲐⲞ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ϦⲈⲚϮϪⲞⲘ ⲚⲦⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲤⲘⲎ ⲀⲤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲠⲈⲢⲒⲬⲰⲢⲞⲤ ⲦⲎⲢⲤ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ.
Jesu sì fi agbára Ẹ̀mí padà wá sí Galili, òkìkí rẹ̀ sì kàn kálẹ̀ ní gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
15 ⲓ̅ⲉ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲞϤ ⲚⲀϤϮⲤⲂⲰ ϦⲈⲚⲚⲞⲨⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲈⲨϮⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ.
Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu wọn; a ń yìn ín lógo láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn ènìyàn wá.
16 ⲓ̅ⲋ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲒ ⲈⲚⲀⲌⲀⲢⲈⲐ ⲠⲒⲘⲀ ⲈⲦⲀⲨϢⲀⲚⲞⲨϢϤ ⲘⲘⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϮⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲘⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲚⲦⲈⲚⲒⲤⲀⲂⲂⲀⲦⲞⲚ ⲔⲀⲦⲀ ϮⲔⲀϨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲈⲰϢ
Ó sì wá sí Nasareti, níbi tí a gbé ti tọ́ ọ dàgbà: bí ìṣe rẹ̀ ti rí, ó sì wọ inú Sinagọgu lọ ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì dìde láti kàwé.
17 ⲓ̅ⲍ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϮ ⲚⲀϤ ⲘⲠϪⲰⲘ ⲚⲦⲈⲎⲤⲀⲎⲀⲤ ⲠⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲞⲨⲰⲚ ⲈⲠⲒϪⲰⲘ ⲀϤϪⲒⲘⲒ ⲘⲠⲒⲘⲀ ⲈⲚⲀϤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ⲘⲘⲞϤ.
A sì fi ìwé wòlíì Isaiah fún un. Nígbà tí ó sì ṣí ìwé náà, ó rí ibi tí a gbé kọ ọ́ pé:
18 ⲓ̅ⲏ̅ ϪⲈ ⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲦⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲠⲈⲦⲬⲎ ϨⲒϪⲰⲒ ⲈⲐⲂⲈ ⲪⲀⲒ ⲀϤⲐⲀϨⲤⲦ ⲀϤⲞⲨⲰⲢⲠ ⲘⲘⲞⲒ ⲈϨⲒϢⲈⲚⲚⲞⲨϤⲒ ⲚⲚⲒϨⲎⲔⲒ ⲈϨⲒⲰⲒϢ ⲚⲚⲒⲈⲬⲘⲀⲖⲰⲦⲞⲤ ⲚⲞⲨⲬⲰ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲚⲀⲨ ⲘⲂⲞⲖ ⲚⲚⲒⲂⲈⲖⲖⲈⲨ ⲈⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚⲚⲎ ⲈⲦⲤⲞⲚϨ ϦⲈⲚⲞⲨⲬⲰ ⲈⲂⲞⲖ.
“Ẹ̀mí Olúwa ń bẹ lára mi, nítorí tí ó fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì. Ó ti rán mi wá láti wàásù ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn, àti ìmúnríran fún àwọn afọ́jú, àti láti jọ̀wọ́ àwọn tí a pa lára lọ́wọ́,
19 ⲓ̅ⲑ̅ ⲈϨⲒⲰⲒϢ ⲚⲞⲨⲢⲞⲘⲠⲒ ⲈⲤϢⲎⲠ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ.
láti kéde ọdún ojúrere Olúwa.”
20 ⲕ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲔⲈⲖ ⲠⲒϪⲰⲘ ⲀϤⲦⲎⲒϤ ⲘⲠⲒϨⲨⲠⲎ ⲢⲈⲦⲎⲤ ⲀϤϨⲈⲘⲤⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦϦⲈⲚ ϮⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲚⲀⲢⲈ ⲚⲞⲨⲂⲀⲖ ϪⲞⲨϢⲦ ⲈϨⲢⲎⲒ ϨⲰⲒⲦϤ ⲠⲈ.
Ó sì pa ìwé náà dé, ó fi í fún ìránṣẹ́, ó sì jókòó. Gbogbo àwọn tí ó ń bẹ nínú Sinagọgu sì tẹjúmọ́ ọn.
21 ⲕ̅ⲁ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲚϪⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲤϪⲰⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲪⲞⲞⲨ ⲚϪⲈⲦⲀⲒⲄⲢⲀⲪⲎ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲘⲀϢϪ.
Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wí fún wọn pé, “Lónìí ìwé mímọ́ yìí ṣẹ ní etí yín.”
22 ⲕ̅ⲃ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚⲀϤ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲒⲤⲀϪⲒ ⲚⲦⲈⲠⲒϨⲘⲞⲦ ⲚⲎ ⲈⲚⲀⲨⲚⲎⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲢⲰϤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲎ ⲪⲀⲒ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲒⲰⲤⲎⲪ
Gbogbo wọn sì jẹ́rìí rẹ̀, háà sì ṣe wọ́n sí ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ tí ń jáde ní ẹnu rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ọmọ Josẹfu kọ́ yìí?”
23 ⲕ̅ⲅ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲠⲀⲚⲦⲰⲤ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϪⲈ ⲦⲀⲒⲠⲀⲢⲀⲂⲞⲖⲎ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲠⲒⲤⲎⲒⲚⲒ ⲀⲢⲒⲪⲀϦⲢⲒ ⲈⲢⲞⲔ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦⲔ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲚⲤⲞⲐⲘⲞⲨ ⲈⲀⲨϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲔⲀⲪⲀⲢⲚⲀⲞⲨⲘ ⲀⲢⲒⲦⲞⲨ ⲘⲠⲀⲒⲘⲀ ϨⲰϤ ϦⲈⲚⲦⲈⲔⲂⲀⲔⲒ.
Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni ẹ̀yin ó pa òwe yìí sí mi pé, ‘Oníṣègùn, wo ara rẹ̀ sàn! Àwọn ohun tí àwa gbọ́ pé o ti ọwọ́ rẹ ṣe ní Kapernaumu, ṣe é níhìn-ín yìí pẹ̀lú ní ilẹ̀ ara rẹ.’”
24 ⲕ̅ⲇ̅ ⲠⲈϪⲀϤ ⲆⲈ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲘⲎⲚ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ⲘⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲈϤϢⲎⲠ ϦⲈⲚⲦⲈϤⲂⲀⲔⲒ.
Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, kò sí wòlíì tí a tẹ́wọ́gbà ní ilẹ̀ baba rẹ̀.
25 ⲕ̅ⲉ̅ ⲦⲀⲪⲘⲎⲒ ⲆⲈ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲬⲎⲢⲀ ⲠⲈ ϦⲈⲚⲠⲒⲤⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲚⲦⲈⲎⲖⲒⲀⲤ ϨⲞⲦⲈ ⲈⲦⲀⲤϢⲐⲀⲘ ⲚϪⲈⲦⲪⲈ ⲚⲄ ⲚⲢⲞⲘⲠⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲀⲂⲞⲦ ϨⲰⲤⲦⲈ ⲚⲦⲈϤϢⲰⲠⲒ ⲚϪⲈⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϨⲂⲰⲚ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲔⲀϨⲒ ⲦⲎⲢϤ.
Ṣùgbọ́n mo wí fún un yín nítòótọ́, opó púpọ̀ ni ó wà ní Israẹli nígbà ọjọ́ wòlíì Elijah, nígbà tí ọ̀run fi sé ní ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà, nígbà tí ìyàn ńlá fi mú ká ilẹ̀ gbogbo.
26 ⲕ̅ⲋ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲞⲨⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚⲎⲖⲒⲀⲤ ϨⲀ ϨⲖⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲈⲂⲎⲖ ϨⲀ ⲞⲨⲤϨⲒⲘⲒ ⲚⲬⲎⲢⲀ ⲐⲎ ⲈⲦϦⲈⲚ ⲤⲀⲢⲈⲠⲦⲀ ⲚⲦⲈϮⲤⲒⲆⲰⲚⲒⲀ.
Kò sì sí ẹnìkan nínú wọn tí a rán Elijah sí, bí kò ṣe sí obìnrin opó kan ní Sarefati, ìlú kan ní Sidoni.
27 ⲕ̅ⲍ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲔⲀⲔⲤⲈϨⲦ ⲠⲈ ϦⲈⲚⲠⲒⲤⲖ ⲚⲀϨⲢⲀϤ ⲚⲈⲖⲒⲤⲈⲞⲤ ⲠⲒⲠⲢⲞⲪⲎ ⲦⲎⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ ⲦⲞⲨⲂⲞ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲚⲈⲘⲀⲚ ⲠⲒⲤⲨⲢⲞⲤ.
Adẹ́tẹ̀ púpọ̀ ní sì ń bẹ ní Israẹli nígbà wòlíì Eliṣa; kò sì ṣí ọ̀kan nínú wọn tí a wẹ̀nùmọ́, bí kò ṣe Naamani ará Siria.”
28 ⲕ̅ⲏ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲘⲞϨ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲚϪⲰⲚⲦ ⲈⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲚⲀⲒ
Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó wà nínú Sinagọgu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, inú bi wọ́n gidigidi,
29 ⲕ̅ⲑ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲦⲰⲞⲨⲚⲞⲨ ⲀⲨϨⲒⲦϤ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲚϮⲂⲀⲔⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲈⲚϤ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϪⲈⲚ ⲠϬⲒⲤⲒ ⲘⲠⲒⲦⲰⲞⲨ ⲪⲎ ⲈⲚⲀⲢⲈ ⲦⲞⲨⲂⲀⲔⲒ ⲬⲎ ϨⲒϪⲰϤ ϨⲰⲤⲦⲈ ⲚⲦⲞⲨϪⲞⲖⲔϤ ⲈϦⲢⲎⲒ.
wọ́n sì dìde, wọ́n tì í sóde sí ẹ̀yìn ìlú, wọ́n sì fà á lọ sí bèbè òkè níbi tí wọ́n gbé tẹ ìlú wọn dó, kí wọn bá à lè sọ sílẹ̀ ní ògèdèǹgbé.
30 ⲗ̅ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤⲤⲒⲚⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲞⲨⲘⲎϮ ⲚⲀϤⲘⲞϢⲒ ⲠⲈ.
Ṣùgbọ́n ó kọjá láàrín wọn, ó bá tirẹ̀ lọ.
31 ⲗ̅ⲁ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲒ ⲈϦⲢⲎⲒ ⲈⲔⲀⲪⲀⲢⲚⲀⲞⲨⲘ ⲞⲨⲂⲀⲔⲒ ⲚⲦⲈϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϮⲤⲂⲰ ⲚⲰⲞⲨ ϦⲈⲚⲚⲒⲤⲀⲂⲂⲀⲦⲞⲚ.
Ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Kapernaumu, ìlú kan ní Galili, ó sì ń kọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi.
32 ⲗ̅ⲃ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲦⲰⲘⲦ ⲈϪⲈⲚ ⲦⲈϤⲤⲂⲰ ϪⲈ ⲚⲀⲢⲈ ⲠⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲬⲎ ϦⲈⲚⲞⲨⲈⲢϢⲒϢⲒ.
Ẹnu sì yà wọ́n sí ẹ̀kọ́ rẹ̀: nítorí tàṣẹtàṣẹ ni ọ̀rọ̀ rẹ̀.
33 ⲗ̅ⲅ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ϦⲈⲚϮⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲀⲔⲀⲐⲀⲢⲦⲞⲚ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲰϢ ⲈⲠϢⲰⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϦⲢⲰⲞⲨ
Ọkùnrin kan sì wà nínú Sinagọgu, ẹni tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, ó kígbe ní ohùn rara,
34 ⲗ̅ⲇ̅ ϪⲈ ⲀϦⲞⲔ ⲚⲈⲘⲀⲚ ϨⲰⲔ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲒⲢⲈⲘⲚⲀⲌⲀⲢⲈⲐ ⲈⲦⲀⲔⲒ ⲈⲦⲀⲔⲞⲚ ϮⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲔ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲚⲒⲘ ⲠⲒⲀⲄⲒⲞⲤ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
“Ó wí pé, kín ni ṣe tàwa tìrẹ, Jesu ará Nasareti? Ìwọ́ wá láti pa wá run bí? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe, Ẹni Mímọ́ Ọlọ́run.”
35 ⲗ̅ⲉ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲈⲠⲒⲦⲒⲘⲀⲚ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲐⲰⲘ ⲚⲢⲰⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲘⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀ ⲠⲒⲆⲈⲘⲰⲚ ⲤⲀⲦϤ ⲈⲐⲘⲎϮ ⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎⲦϤ ⲘⲠⲈϤϮ ϨⲖⲒ ⲚⲈⲘⲔⲀϨ ⲚⲀϤ.
Jesu sì bá a wí gidigidi, ó wí fun pe, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí o sì jáde lára rẹ̀.” Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà sì gbé e ṣánlẹ̀ ní àwùjọ, ó jáde kúrò lára rẹ̀, kò sì pa á lára.
36 ⲗ̅ⲋ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϨⲞϮ ϢⲰⲠⲒ ϨⲒϪⲰⲞⲨ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲞⲨⲈⲢⲎ ⲞⲨ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈ ⲠⲀⲒⲤⲀϪⲒ ϪⲈ ϦⲈⲚⲞⲨⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲚⲈⲘ ⲞⲨϪⲞⲘ ϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲚⲚⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲀⲔⲀⲐⲀⲢⲦⲞⲚ ⲤⲈⲚⲎⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ.
Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì ń bá ara wọn sọ wí pé, “Irú ẹ̀kọ́ kín ni èyí? Nítorí pẹ̀lú àṣẹ àti agbára ni ó fi bá àwọn ẹ̀mí àìmọ́ wí, wọ́n sì jáde kúrò.”
37 ⲗ̅ⲍ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲤⲘⲎ ⲤⲎⲢ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ϦⲈⲚⲘⲀⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲦⲈϮⲠⲈⲢⲒⲬⲰⲢⲞⲤ.
Òkìkí rẹ̀ sì kàn níbi gbogbo ní agbègbè ilẹ̀ náà yíká.
38 ⲗ̅ⲏ̅ ⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲎⲒ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ⲦϢⲰⲘⲒ ⲆⲈ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϦⲘⲞⲘ ⲚⲈⲘⲀⲤ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰⲤ
Nígbà tí ó sì dìde kúrò nínú Sinagọgu, ó sì wọ̀ ilé Simoni lọ; ibà sì ti dá ìyá ìyàwó Simoni dùbúlẹ̀, wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ nítorí rẹ̀.
39 ⲗ̅ⲑ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲤⲀⲠϢⲰⲒ ⲘⲘⲞⲤ ⲀϤⲈⲢⲈⲠⲒⲦⲒⲘⲀⲚ ⲘⲠⲒϦⲘⲞⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲬⲀⲤ ⲤⲀⲦⲞⲦⲤ ⲆⲈ ⲀⲤⲦⲰⲚⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϢⲈⲘϢⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ.
Ó sì súnmọ́ ọ, ó bá ibà náà wí; ibà sì náà sì fi sílẹ̀. O sì dìde lọ́gán, ó ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
40 ⲙ̅ ⲈⲦⲀ ⲪⲢⲎ ⲆⲈ ϨⲰⲦⲠ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲈ ⲞⲨⲞⲚⲦⲞⲨ ⲢⲈϤϢⲰⲚⲒ ⲘⲘⲀⲨ ϦⲈⲚϨⲀⲚϢⲰⲚⲒ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲢⲎϮ ⲈⲨⲈⲚⲞⲨ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤⲬⲀ ϪⲒϪ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲀϤⲈⲢⲪⲀϦⲢⲒ ⲈⲢⲰⲞⲨ.
Nígbà tí oòrùn sì ń wọ̀, àwọn ènìyàn gbe àwọn aláìsàn, tó ní onírúurú àìsàn wá sọ́dọ̀ Jesu; ó sì fi ọwọ́ lé olúkúlùkù wọn, ó sì mú wọn láradá.
41 ⲙ̅ⲁ̅ ⲚⲀⲨⲚⲎⲞⲨ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲔⲈⲆⲈⲘⲰⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲘⲎϢ ⲈⲨⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲈⲢⲈⲠⲒⲦⲒⲘⲀⲚ ⲚⲰⲞⲨ ⲠⲈ ⲚϤⲬⲰ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲀⲚ ⲈⲤⲀϪⲒ ϪⲈ ⲚⲀⲨⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ϪⲈ ⲚⲐⲞϤ ⲠⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ.
Àwọn ẹ̀mí èṣù sì jáde lára ẹni púpọ̀ pẹ̀lú, wọ́n ń kígbe, wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run!” Ó sì ń bá wọn wí kò sì jẹ́ kí wọn kí ó fọhùn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé Òun ni Kristi náà.
42 ⲙ̅ⲃ̅ ⲈⲦⲀ ⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲆⲈ ϢⲰⲠⲒ ⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲞⲨⲘⲀ ⲚϢⲀϤⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲔⲰϮ ⲚⲤⲰϤ ⲠⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲘⲎϢ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲀⲘⲞⲚⲒ ⲘⲘⲞϤ ⲠⲈ ⲈϢⲦⲈⲘⲈⲐⲢⲈϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀⲢⲰⲞⲨ.
Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, Jesu sì jáde lọ, ó sì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀. Ìjọ ènìyàn sì ń wá a kiri, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì dá a dúró, nítorí kí ó má ba à lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
43 ⲙ̅ⲅ̅ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ϨⲰϮ ⲠⲈ ⲚⲦⲀϨⲒϢⲈⲚⲚⲞⲨϤⲒ ϦⲈⲚⲚⲒⲔⲈⲂⲀⲔⲒ ⲚϮⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ϪⲈ ⲞⲨⲎⲒ ⲈⲦⲀⲨⲦⲀⲞⲨⲞⲒ ⲈⲐⲂⲈ ⲪⲀⲒ.
Ṣùgbọ́n ó sì wí fún wọn pé, “Èmi kò lè ṣàìmá wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run fún àwọn ìlú mìíràn pẹ̀lú, nítorí náà ni a sá ṣe rán mi.”
44 ⲙ̅ⲇ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϨⲒⲰⲒϢ ⲠⲈ ϦⲈⲚⲚⲒⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲚⲦⲈϮⲒⲞⲨⲆⲈⲀ.
Ó sì ń wàásù nínú Sinagọgu ti Judea.

< ⲖⲞⲨⲔⲞⲚ 4 >