< ⳘⲀⲢⲔⲞⲚ 1 >

1 ⲁ̅ ⲦⲀⲢⲬⲎ ⲘⲠⲒⲈⲨⲀⲄⲄⲈⲖⲒⲞⲚ ⲚⲦⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ.
Ìbẹ̀rẹ̀ ìyìnrere nípa Jesu Kristi, Ọmọ Ọlọ́run.
2 ⲃ̅ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲤϦⲎⲞⲨⲦ ϦⲈⲚⲎⲤⲀⲒⲀⲤ ⲠⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ϪⲈ ϨⲎⲠⲠⲈ ϮⲚⲀⲞⲨⲰⲢⲠ ⲘⲠⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ ϦⲀⲦϨⲎ ⲘⲠⲈⲔϨⲞ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀⲤⲞⲂϮ ⲘⲠⲈⲔⲘⲰⲒⲦ ϦⲀϪⲰⲔ.
Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé wòlíì Isaiah pé, “Èmi yóò ran oníṣẹ́ mi síwájú rẹ, Ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe.”
3 ⲅ̅ ⲠϦⲢⲰⲞⲨ ⲘⲠⲈⲦⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒ ⲠϢⲀϤⲈ ϪⲈ ⲤⲈⲂⲦⲈ ⲪⲘⲰⲒⲦ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲤⲞⲨⲦⲈⲚ ⲚⲈϤⲘⲀⲚⲘⲞϢⲒ.
“Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’”
4 ⲇ̅ ⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲠⲒⲢⲈϤϮⲰⲘⲤ ϨⲒ ⲠϢⲀϤⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤϨⲒⲰⲒϢ ⲚⲞⲨⲰⲘⲤ ⲘⲘⲈⲦⲀⲚⲞⲒⲀ ϦⲈⲚⲞⲨⲬⲰ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲦⲈϨⲀⲚⲚⲞⲂⲒ.
Johanu dé, ẹni tí ó ń tẹnibọmi ní aginjù, tí ó sì ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.
5 ⲉ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲚⲎⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲚⲀ ϮⲒⲞⲨⲆⲈⲀ ⲦⲎⲢⲤ ⲚⲬⲰⲢⲀ ⲚⲈⲘ ⲚⲀ ⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϬⲒⲰⲘⲤ ⲚⲦⲞⲦϤ ϦⲈⲚⲠⲒⲒⲞⲢⲆⲀⲚⲎ ⲤⲚⲒⲀⲢⲞ ⲈⲨⲞⲨⲰⲚϨ ⲚⲚⲞⲨⲚⲞⲂⲒ ⲈⲂⲞⲖ.
Gbogbo àwọn tí ń gbé ní agbègbè Judea, àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu jáde tọ̀ ọ́ lọ, a sì ti ọwọ́ rẹ̀ tẹ gbogbo wọn bọ omi ni odò Jordani, wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
6 ⲋ̅ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲆⲈ ⲚⲀⲢⲈ ϨⲀⲚϤⲰⲒ ⲚϬⲀⲘⲞⲨⲖ ⲦⲞⲒ ϨⲒⲰⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤⲘⲎⲢ ⲚⲞⲨⲘⲞϪϦ ⲚϢⲀⲢ ⲈϪⲈⲚ ⲦⲈϤϮⲠⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲞⲨⲈⲘ ϢϪⲈ ⲚⲈⲘ ⲈⲂⲒⲰ ⲚⲦⲈⲦⲔⲞⲒ.
Johanu sì wọ aṣọ irun ìbákasẹ. Ó sì di àmùrè awọ mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀.
7 ⲍ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϨⲒⲰⲒϢ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ϤⲚⲎ ⲞⲨ ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲰⲒ ⲚϪⲈⲪⲎ ⲈⲦϪⲞⲢ ⲈϨⲞⲦⲈⲢⲞⲒ ⲪⲎ ⲈⲦⲈ ⲚϮⲘⲠϢⲀ ⲀⲚ ⲈϪⲞⲂⲤⲦ ⲈϦⲢⲎⲒ ⲈϮⲞⲨⲰ ⲚⲞⲨⲘⲞⲨⲤⲈⲢ ⲚⲦⲈⲠⲈϤⲐⲰⲞⲨⲒ.
Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù wí pé, “Ẹnìkan tí ó tóbi jù mí lọ ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó ẹni tí ń tú.
8 ⲏ̅ ⲀⲚⲞⲔ ⲈⲦⲀⲒϮⲰⲘⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲰⲞⲨ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ϤⲚⲀⲈⲘⲤ ⲐⲎⲚⲞⲨ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈϤⲞⲨⲀⲂ.
Èmi ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi yín, ṣùgbọ́n Òun yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ ṣe ìtẹ̀bọmi yín.”
9 ⲑ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲚⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲀϤⲒ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲀⲌⲀⲢⲈⲐ ⲚⲦⲈϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϬⲒⲰⲘⲤ ϦⲈⲚⲠⲒⲒⲞⲢⲆⲀⲚⲎ ⲤⲚⲦⲞⲦϤ ⲚⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ
Ó sì ṣe ní ọjọ́ kan Jesu ti Nasareti ti Galili jáde wá, a sì ti ọwọ́ Johanu ṣe ìtẹ̀bọmi fún ní odò Jordani.
10 ⲓ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲈϤⲚⲎⲞⲨ ⲈⲠϢⲰⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲰⲞⲨ ⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲚⲒⲪⲎⲞⲨⲒ ⲈⲀⲨⲪⲰϦ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲀϤⲒ ⲈϦⲢⲎⲒ ⲈϪⲰϤ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚⲞⲨϬⲢⲞⲘⲠⲒ
Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ tí Jesu ń ti inú omi jáde wá, ó rí ọ̀run tí ó ṣí sílẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ bí àdàbà sọ̀kalẹ̀ lé e lórí.
11 ⲓ̅ⲁ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲤⲘⲎ ⲚⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲪⲎⲞⲨⲒ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈ ⲠⲀϢⲎⲢⲒ ⲠⲀⲘⲈⲚⲢⲒⲦ ⲈⲦⲀⲒϮⲘⲀϮ ⲚϦⲎⲦϤ
Ohùn kan sì ti ọ̀run wá wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ Ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
12 ⲓ̅ⲃ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀϨⲒⲦϤ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲠϢⲀϤⲈ
Lẹ́sẹ̀kan náà, Ẹ̀mí Mímọ́ sì darí Jesu sí ijù,
13 ⲓ̅ⲅ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲬⲎ ⲠⲈ ϨⲒ ⲠϢⲀϤⲈ ⲚⲘⲚⲈϨⲞⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲈϪⲰⲢϨ ⲈϤⲈⲢⲠⲒⲢⲀⲌⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲚϪⲈⲠⲤⲀⲦⲀⲚⲀⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲬⲎ ⲠⲈ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲐⲎ ⲢⲒⲞⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ ⲚⲀⲨϢⲈⲘϢⲒ ⲘⲘⲞϤ.
Ó sì wà ní ogójì ọjọ́ ní aginjù. A sì ti ọwọ́ Satani dán an wò, ó sì wà pẹ̀lú àwọn ẹranko ìgbẹ́. Àwọn angẹli sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un.
14 ⲓ̅ⲇ̅ ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲀ ⲐⲢⲞⲨϮ ⲆⲈ ⲚⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲀϤⲒ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ⲈϤϨⲒⲰⲒϢ ⲘⲠⲒⲈⲨⲀⲄⲄⲈⲖⲒⲞⲚ ⲚⲦⲈⲪϮ
Lẹ́yìn ìgbà tí ọba Herodu ti fi Johanu sínú ẹ̀wọ̀n tan, Jesu lọ sí Galili, ó ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run.
15 ⲓ̅ⲉ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀϤϪⲰⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲠⲒⲤⲎⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϦⲰⲚⲦ ⲚϪⲈϮⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲀⲢⲒⲘⲈⲦⲀⲚⲞⲒⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϨϮ ⲈⲠⲒⲈⲨⲀⲄⲄⲖⲒⲞⲚ.
Ó sì kéde wí pé, “Àkókò náà dé wàyí, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀. Ẹ yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, kí ẹ sì gba ìyìnrere yìí gbọ́.”
16 ⲓ̅ⲋ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲤⲒⲚⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀ ⲪⲒⲞⲘ ⲚⲦⲈϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲤⲒⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘ ⲀⲚⲆⲢⲈⲀⲤ ⲠⲤⲞⲚ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ⲈⲨϨⲒ ϢⲚⲈ ⲚⲤⲒϮ ⲈⲪⲒⲞⲘ ϪⲈ ⲞⲨⲎⲒ ⲄⲀⲢ ⲚⲈϨⲀⲚⲞⲨⲞϨⲒ ⲚⲈ.
Ní ọjọ́ kan, bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, Ó rí Simoni àti Anderu arákùnrin rẹ̀, wọ́n ń fi àwọ̀n wọn pẹja torí pé apẹja ni wọ́n.
17 ⲓ̅ⲍ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲀⲘⲰⲒⲚⲒ ⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰⲒ ⲚⲦⲀⲈⲢ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚϨⲀⲚⲞⲨⲞϨⲒ ⲚⲢⲈϤⲦⲀϨⲈ ⲢⲰⲘⲒ.
Jesu sì ké sí wọn wí pé, “Ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn. Èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.”
18 ⲓ̅ⲏ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲬⲀ ⲚⲒϢⲚⲎⲞⲨ ⲚⲤⲰⲞⲨ ⲤⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲀⲨⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰϤ
Ní kánkán wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.
19 ⲓ̅ⲑ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲤⲒⲚⲒ ⲈⲦϨⲎ ⲚⲔⲈⲔⲞⲨϪⲒ ⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲒⲀⲔⲰⲂⲞⲤ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲌⲈⲂⲈⲆⲈⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲠⲈϤⲤⲞⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲰⲞⲨ ϨⲰⲞⲨ ⲈⲨϨⲒ ⲠⲒϪⲞⲒ ⲈⲨⲤⲞⲂϮ ⲚⲚⲞⲨϢⲚⲎⲞⲨ
Bí Ó sì ti rìn síwájú díẹ̀, ní etí Òkun, Ó rí Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ nínú ọkọ̀, wọ́n ń tún àwọ̀n wọn ṣe.
20 ⲕ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀϤⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲬⲀ ⲠⲞⲨⲒⲰⲦ ⲚⲤⲰⲞⲨ ⲌⲈⲂⲈⲆⲈⲞⲤ ϨⲒ ⲠⲒϪⲞⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲘⲒⲤⲐⲰⲦⲎⲤ ⲀⲨϢⲈⲚ ⲰⲞⲨ ⲀⲨⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰϤ
Ó sì ké sí àwọn náà lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, wọ́n fi Sebede baba wọn sílẹ̀ nínú ọkọ̀ pẹ̀lú àwọn alágbàṣe, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
21 ⲕ̅ⲁ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲔⲀⲪⲀⲢⲚⲀⲞⲨⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϮⲤⲂⲰ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ϦⲈⲚⲚⲒⲤⲀⲂⲂⲀⲦⲞⲚ ϦⲈⲚⲚⲒⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ
Lẹ́yìn náà, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ ìlú Kapernaumu, nígbà tí ó di òwúrọ̀ ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sínú Sinagọgu, ó sì ń kọ́ni.
22 ⲕ̅ⲃ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲦⲈϤⲤⲂⲰ ⲚⲀϤϮⲤⲂⲰ ⲄⲀⲢ ⲚⲰⲞⲨ ⲠⲈ ϨⲰⲤ ⲈⲢⲈ ⲠⲈϤⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲀⲚ ⲚⲚⲒⲤⲀϦ
Ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn nítorí ìkọ́ni rẹ̀, nítorí pé ó ń kọ́ni bí ẹni tí ó ní àṣẹ, kì í ṣe bí àwọn olùkọ́ òfin ṣe ń kọ́ àwọn ènìyàn.
23 ⲕ̅ⲅ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ϦⲈⲚϮⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲈϤϦⲈⲚ ⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲀⲔⲀⲐⲀⲢⲦⲞⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ
Ní àsìkò náà gan an ni ọkùnrin kan tí ó wà nínú Sinagọgu wọn, tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe wí pé,
24 ⲕ̅ⲇ̅ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀϦⲞⲔ ⲚⲈⲘⲀⲚ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲒⲢⲈⲘⲚⲀⲌⲀⲢⲈⲐ ⲈⲦⲀⲔⲒ ⲈⲦⲀⲔⲞⲚ ⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲔ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲚⲒⲘ ⲠⲒⲀⲄⲒⲞⲤ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
“Kí ni ìwọ ń wá lọ́dọ̀ wa, Jesu ti Nasareti? Ṣé ìwọ wá láti pa wá run ni? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe; Ìwọ ní ẹni Mímọ́ Ọlọ́run!”
25 ⲕ̅ⲉ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲈⲠⲒⲦⲒⲘⲀⲚ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲐⲰⲘ ⲚⲢⲰⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲘⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎⲦϤ
Jesu si bá a wí, ó wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí ó sì jáde kúrò lára rẹ̀.”
26 ⲕ̅ⲋ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲦⲈⲢⲐⲰⲢϤ ⲚϪⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲀⲔⲀⲐⲀⲢⲦⲞⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϦⲢⲰⲞⲨ ⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲰⲦϤ
Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì gbé e ṣánlẹ̀ lógèdèǹgbé, ó ké ní ohùn rara, ó sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà.
27 ⲕ̅ⲍ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲈⲢϨⲞϮ ⲦⲎⲢⲞⲨ ϨⲰⲤⲦⲈ ⲚⲦⲞⲨⲔⲰϮ ⲚⲈⲘ ⲚⲞⲨⲈⲢⲎⲞⲨ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈ ⲪⲀⲒ ⲞⲨⲤⲂⲰ ⲘⲂⲈⲢⲒ ⲠⲈ ϪⲈ ϦⲈⲚⲞⲨⲈⲢϢⲒϢⲒ ϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲚⲚⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲀⲔⲀⲐⲀⲢⲦⲞⲚ ⲤⲈⲤⲰⲦⲈⲘ ⲚⲀϤ
Ẹnu sì ya àwọn ènìyàn, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi ń sọ láàrín ara wọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Wọ́n béèrè pẹ̀lú ìgbóná ara, pé, “Kí ni èyí? Irú ẹ̀kọ́ tuntun wo ni èyí? Ó ń fi agbára pàṣẹ fún àwọn ẹ̀mí àìmọ́ pàápàá wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀.”
28 ⲕ̅ⲏ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲦⲈϤⲤⲘⲎ ⲤⲰⲢ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲠⲈⲢⲒⲬⲰⲢⲞⲤ ⲦⲎⲢⲤ ⲚⲦⲈϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ.
Ìròyìn nípa rẹ̀ tàn ká gbogbo agbègbè Galili.
29 ⲕ̅ⲑ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲀⲨⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲎⲒ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘ ⲀⲚⲆⲢⲈⲀⲤ ⲈⲢⲈ ⲒⲀⲔⲰⲂⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ
Nígbà tí wọn sì jáde kúrò nínú Sinagọgu, wọ́n lọ pẹ̀lú Jakọbu àti Johanu sí ilé Simoni àti Anderu.
30 ⲗ̅ ⲦϢⲰⲘⲒ ⲆⲈ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ⲚⲀⲤⲚⲔⲞⲦ ⲠⲈ ⲈⲤϦⲎⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲀⲨϪⲞⲤ ⲚⲀϤ ⲈⲐⲂⲎ ⲦⲤ.
Ìyá ìyàwó Simoni tí ó dùbúlẹ̀ àìsàn ibà, wọ́n sì sọ fún Jesu nípa rẹ̀.
31 ⲗ̅ⲁ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲒ ⲀϤⲦⲞⲨⲚⲞⲤⲤ ⲈⲀϤⲀⲘⲞⲚⲒ ⲚⲦⲈⲤϪⲒϪ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲬⲀⲤ ⲚϪⲈⲠⲒϦⲘⲞⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲤϢⲈⲘϢⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ.
Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó fà á lọ́wọ́, ó sì gbé e dìde; lójúkan náà ibà náà fi sílẹ̀, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
32 ⲗ̅ⲃ̅ ⲈⲦⲀ ⲢⲞⲨϨⲒ ⲆⲈ ϢⲰⲠⲒ ϨⲞⲦⲈ ⲈⲦⲀ ⲪⲢⲎ ϨⲰⲦⲠ ⲀⲨⲒⲚⲒ ⲚⲀϤ ⲚⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲦϨⲈⲘⲔⲎ ⲞⲨⲦ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦⲈ ⲚⲒⲆⲈⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ
Nígbà tí ó di àṣálẹ́, tí oòrùn wọ̀, wọ́n gbé gbogbo àwọn aláìsàn àti àwọn tó ni ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá.
33 ⲗ̅ⲅ̅ ⲞⲨⲞϨ ϮⲂⲀⲔⲒ ⲦⲎⲢⲤ ⲀⲤⲐⲰⲞⲨϮ ϨⲒⲢⲈⲚ ⲠⲒⲢⲞ.
Gbogbo ìlú si péjọ ni ẹnu-ọ̀nà.
34 ⲗ̅ⲇ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲪⲀϦⲢⲒ ⲈⲞⲨⲘⲎϢ ⲈⲨⲦϨⲈⲘⲔⲎ ⲞⲨⲦ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲢⲎϮ ⲚϢⲰⲚⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϨⲒ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲆⲈⲘⲰⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲬⲰ ⲚⲚⲒⲆⲈⲘⲰⲚ ⲈⲤⲀϪⲒ ⲀⲚ ⲠⲈ ϪⲈ ⲞⲨⲎⲒ ⲄⲀⲢ ⲚⲀⲨⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲀⲚ ⲠⲈ ϪⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲠⲈ
Jesu sì wo ọ̀pọ̀ tí wọ́n ní onírúurú ààrùn sàn. Bákan náà ni ó lé ọ̀pọ̀ ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Ṣùgbọ́n kò sì jẹ́ kí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà kí ó sọ̀rọ̀, nítorí tí wọ́n mọ ẹni tí òun í ṣe.
35 ⲗ̅ⲉ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲚϨⲀⲚⲀⲦⲞⲞⲨⲒ ⲚϢⲞⲢⲠ ⲈⲘⲀϢⲰ ⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲨⲘⲀⲚϢⲀϤⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲈⲢⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲈⲤⲐⲈ ⲘⲘⲀⲨ
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ilẹ̀ tó mọ́, Jesu nìkan jáde lọ sí aginjù kan, láti lọ gbàdúrà.
36 ⲗ̅ⲋ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲰϤ ⲚϪⲈⲤⲒⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲈⲘⲀϤ
Simoni àti àwọn ènìyàn rẹ̀ yòókù lọ láti wá a.
37 ⲗ̅ⲍ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨϪⲈⲘϤ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲤⲈⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲔ ⲦⲎⲢⲞⲨ
Nígbà tí wọ́n sì rí I, wọ́n sọ fún wí pé, “Gbogbo ènìyàn ń wá ọ!”
38 ⲗ̅ⲏ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲘⲀⲢⲞⲚ ⲈⲔⲈⲘⲀ ⲈⲚⲒⲔⲰⲘⲞⲠⲞⲖⲒⲤ ⲈⲦϦⲈⲚⲦ ⲈⲢⲞⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲚϨⲒⲰⲒϢ ⲘⲘⲀⲨ ϨⲰϤ ⲈⲦⲀⲒⲒ ⲄⲀⲢ ⲈⲠⲀⲒϨⲰⲂ.
Jesu sì dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sí àwọn ìlú mìíràn, kí ń lè wàásù níbẹ̀ pẹ̀lú. Nítorí èyí ni èmi sá à ṣe wá.”
39 ⲗ̅ⲑ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲒ ⲈϨⲒⲰⲒϢ ϦⲈⲚⲚⲞⲨⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ϦⲈⲚϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ⲦⲎⲢⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲆⲈⲘⲰⲚ ⲈϤϨⲒⲞⲨⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ
Nítorí náà, ó ń kiri gbogbo agbègbè Galili, ó ń wàásù nínú Sinagọgu. Ó sì ń lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde.
40 ⲙ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲞⲨⲔⲀⲔⲤⲈϨⲦ ⲈϤϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤϨⲒⲞⲨⲒ ⲘⲘⲞϤ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲈϤⲔⲈⲖⲒ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲈϢⲰⲠ ⲚⲦⲈⲔⲞⲨⲰϢ ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲘⲞⲔ ⲈⲦⲞⲨⲂⲞⲒ
Ọkùnrin adẹ́tẹ̀ kan tọ̀ ọ́ wá, ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀. Ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ìmúláradá. Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè mú mi láradá.”
41 ⲙ̅ⲁ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲈⲚϨⲎⲦ ϦⲀⲢⲞϤ ⲀϤⲤⲞⲨⲦⲈⲚ ⲦⲈϤϪⲒϪ ⲈⲂⲞⲖ ⲀϤϬⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ϮⲞⲨⲰϢ ⲘⲀⲦⲞⲨⲂⲞ.
Jesu kún fún àánú, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó fi ọwọ́ rẹ̀ bà a, ó wí pé, “Èmí fẹ́. Di mímọ́.”
42 ⲙ̅ⲃ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀⲠⲒⲤⲈϨⲦ ϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲰⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲞⲨⲂⲞ.
Lójúkan náà ẹ̀tẹ̀ náà fi sílẹ̀ lọ, ọkùnrin náà sì rí ìwòsàn.
43 ⲙ̅ⲅ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲤⲢⲈⲘⲢⲰⲘϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲢⲞϤ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀϤϨⲒⲦϤ ⲈⲂⲞⲖ
Jesu sì kìlọ̀ fún un gidigidi
44 ⲙ̅ⲇ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲚⲀⲨ ⲘⲠⲈⲢⲦⲀⲘⲈ ϨⲖⲒ ⲀⲖⲖⲀ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲘⲀⲦⲀⲘⲈ ⲠⲒⲞⲨⲎⲂ ⲈⲢⲞⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲒⲞⲨⲒ ⲘⲠⲒⲆⲰⲢⲞⲚ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲈⲔⲦⲞⲨⲂⲞ ⲪⲎ ⲈⲦⲀ ⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲨⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚⲰⲞⲨ.
Ó wí pé, “Lọ fi ara rẹ̀ hàn àlùfáà Júù fún àyẹ̀wò. Ṣùgbọ́n má ṣe dúró sọ ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni ní ọ̀nà. Mú ẹ̀bùn lọ́wọ́, èyí tí Mose pàṣẹ fún adẹ́tẹ̀ tí a mú láradá. Èyí tí í ṣe ẹ̀rí pé, ó ti rí ìwòsàn.”
45 ⲙ̅ⲉ̅ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲀϤⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲚϨⲒⲰⲒϢ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲤⲈⲢ ⲠⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲰⲤⲦⲈ ⲚⲦⲈϤϢⲦⲈⲘϢϪⲈⲘϪⲞⲘ ⲈⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲂⲀⲔⲒ ⲚⲞⲨⲰⲚϨ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲀϤϢⲞⲠ ⲠⲈ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲘⲰⲒⲦ ⲚϢⲀϤⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲚⲎⲞⲨ ϨⲀⲢⲞϤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲘⲀⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ.
Ṣùgbọ́n ó jáde lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í pòkìkí, ó ń tan ìròyìn kálẹ̀. Nítorí èyí, Jesu kò sì le wọ ìlú ní gbangba mọ́, ṣùgbọ́n ó wà lẹ́yìn odi ìlú ní aginjù. Síbẹ̀, àwọn ènìyàn tọ̀ ọ́ wá láti ibi gbogbo.

< ⳘⲀⲢⲔⲞⲚ 1 >