< Lucas 24 +

1 Y o brotoboro e dramia chaláron muy de clarico al sepulchro, lliguerando o bue, sos terelaban quinado.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ ọ̀sẹ̀, àwọn obìnrin wá sí ibojì, wọ́n sì mú ìkunra olóòórùn dídùn ti wọ́n tí pèsè sílẹ̀ wá.
2 Y alacháron a bar revueltisarada del sepulchro.
Òkúta ti yí kúrò ní ẹnu ibojì.
3 Y chalando enrún, na alacháron o trupos e Erañoró Jesus,
Nígbà tí wọ́n sì wọ inú rẹ̀, wọn kò rí òkú Jesu Olúwa.
4 Y anacó, que sinando perelales de dal por ocono, he acoi dui gachés, sos se mequeláron dicar sunparal á siras sat coneles resplandecientes.
Bí wọ́n ti dààmú kiri níhà ibẹ̀, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì aláṣọ dídán dúró tì wọ́n.
5 Y sasta sinaban medrosas, y voltisaraban a chiche ostely al chiquen, les penáron: ¿Presas orotais enrun os mules al que vivisarela?
Nígbà tí ẹ̀rù ń bà wọ́n, tí wọ́n sì dojúbolẹ̀, àwọn angẹli náà bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá alààyè láàrín àwọn òkú?
6 Na sinela acoi, presas se ha ardiñado: ojaraos de ma penó á sangue, sinando aun andré Galiléa,
Kò sí níhìn-ín yìí, ṣùgbọ́n ó jíǹde; ẹ rántí bí ó ti wí fún yín nígbà tí ó wà ní Galili.
7 Penando: Jomte que o Chaboro e manu sinele entreguisarado andré bastes es manuces chores, y que sinele trijulado, y ardiñele al trincho chibes.
Pé, ‘A ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ lọ́wọ́, a ó sì kàn án mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.’”
8 Entonces se ojaráron de las vardas de ó.
Wọ́n sì rántí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
9 Y chalando abrí del sepulchro, se guilláron á penar saro ocono á os once, y á sares os averes.
Wọ́n sì padà ti ibojì wá, wọ́n sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún àwọn mọ́kànlá, àti fún gbogbo àwọn ìyókù.
10 Y siras sos laneláron á os Apóstoles oconas buchias sinaban Maria Magdalena, y Juana, y Maria Dai de Santiago, y as averes sos sinaban sat siras.
Maria Magdalene, àti Joanna, àti Maria ìyá Jakọbu, àti àwọn mìíràn pẹ̀lú wọn sì ni àwọn tí ó ròyìn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn aposteli.
11 Y junos tereláron por chichi oconas vardas, y na las pachibeláron.
Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sì dàbí ìsọkúsọ lójú wọn, wọn kò sì gbà wọ́n gbọ́.
12 Tami Pedro ardiñandose, se guilló al sepulchro, y bajandose, dicó solo á os dicles, sos sinaban chibados oté, y se chaló zibando enré sí ma habia anacado.
Nígbà náà ni Peteru dìde, ó súré lọ sí ibojì; nígbà tí ó sì bẹ̀rẹ̀, ó rí aṣọ àlà lọ́tọ̀ fúnra wọn, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀, ẹnu yà á sí ohun tí ó ṣe.
13 Y dui de janos ocola matejo chibes, chalaban á yeque gau araquerado Emmaus, dur de Jerusalém sasta de zoi millas.
Sì kíyèsi i, àwọn méjì nínú wọn ń lọ ní ọjọ́ náà sí ìletò kan tí a ń pè ní Emmausi, tí ó jìnnà sí Jerusalẹmu níwọ̀n ọgọ́ta ibùsọ̀.
14 Y junos chalában chamuliando enré si de sarias oconas buchias sos habian anacado.
Wọ́n ń bá ara wọn sọ̀rọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣẹlẹ̀.
15 Y sasta sinaban penando y chamuliando o yeque sat o aver, bigoreó á junos o matejo Jesus, y piraba sat junos.
Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń bá ara wọn sọ̀rọ̀, tí wọ́n sì ń bá ara wọn jíròrò, Jesu tìkára rẹ̀ súnmọ́ wọn, ó sì ń bá wọn rìn lọ.
16 Tami as aquias de junos sinaban ucharadas, somia que na le pincharasen.
Ṣùgbọ́n a rú wọn lójú, kí wọn má le mọ̀ ọ́n.
17 Y les penó: ¿Qué vardas sinelan oconas, sos chamulais enré sangue pirando? Y presas sinelais charavares?
Ó sì bi wọ́n pé, “Ọ̀rọ̀ kín ni ẹ̀yin ń bá ara yín sọ, bí ẹ̀yin ti ń rìn?” Wọ́n sì dúró jẹ́, wọ́n fajúro.
18 Y rudelando yeque de junos, arquerado Cleóphas, le penó: ¿Tucue gringó andré Jerusalém: y na chanelas ma ha anacado oté oconas chibéses.
Ọ̀kan nínú wọn, tí a ń pè ní Kileopa, sì dáhùn wí fún un pé, “Àlejò sá à ni ìwọ ní Jerusalẹmu, tí ìwọ kò sì mọ ohun tí ó ṣẹ̀ níbẹ̀ ní ọjọ́ wọ̀nyí?”
19 O les penó: ¿Que buchí? Y rudeláron: De Jesus Nazareno, sos sinaba yeque gacho Propheta, silnó andré obras y andré vardas anglal de Debél y de sari a sueti;
Ó sì bi wọ́n pé, “Kín ni?” Wọ́n sì wí fún un pé, “Ní ti Jesu ti Nasareti, ẹni tí ó jẹ́ wòlíì, tí ó pọ̀ ní ìṣe àti ní ọrọ̀ níwájú Ọlọ́run àti gbogbo ènìyàn,
20 Y sasta le entreguisaráron os Pontesquerés y amáres Manclayes á condenacion de meripen, y o trijuláron:
àti bí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn alàgbà wa ti fi òun lé wọn lọ́wọ́ láti dá a lẹ́bi ikú, àti bí wọ́n ti kàn án mọ́ àgbélébùú.
21 Tami mu fronsaperabamos, que ó sinaba sos terelaba de diñar mestepé á Israel; o mas choro sinela, que sejonia sinela o trincho chibés, que oconas buchias han anacado.
Bẹ́ẹ̀ ni òun ni àwa ti ní ìrètí pé, òun ni ìbá dá Israẹli ní ìdè. Àti pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, òní ni ó di ọjọ́ kẹta tí nǹkan wọ̀nyí ti ṣẹlẹ̀.
22 Aunque yeques cadchias de amarias nos han querelado darañar; siras anglal e clarico chaláron al sepulchro.
Àwọn obìnrin kan pẹ̀lú nínú ẹgbẹ́ wa, tí wọ́n lọ si ibojì ní kùtùkùtù, sì wá yà wá lẹ́nu,
23 Y na terelando alachado desquero trupo, limbidiáron, penando que habian dicado oté vision de Manfarieles, sos penelan que ó vivisarela.
nígbà tí wọn kò sì rí òkú rẹ̀, wọ́n wá wí pé, àwọn rí ìran àwọn angẹli tí wọ́n wí pé, ó wà láààyè.
24 Y yeques de amares plalores chaláron al sepulchro, y lo alacháron andiar sasta as cadchias lo habian penado; tami á ó na lo alacháron.
Àti àwọn kan tí wọ́n wà pẹ̀lú wa lọ sí ibojì, wọ́n sì rí i gẹ́gẹ́ bí àwọn obìnrin náà ti wí, ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ ni wọn kò rí.”
25 Y Jesus penó á junos: ¡O dinelés y tardos de carlochin, para pachibelar o saro sos os Prophetas han penado!
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin tí òye kò yé, tí ẹ sì yigbì ní àyà láti gba gbogbo èyí tí àwọn wòlíì ti wí gbọ́,
26 ¿Na jomte, que o Christo urjiyase oconas buchias, y que andiar chalase enré desquero chimusolano?
kò ha yẹ kí Kristi ó jìyà nǹkan wọ̀nyí kí ó sì wọ inú ògo rẹ̀ lọ.”
27 Y se chitó á penar desde Moysés y de sarés os Prophetas, chibando en dundun as randiñipenes sos chamulian de ó.
Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti Mose àti gbogbo àwọn wòlíì wá, ó sì túmọ̀ nǹkan fún wọn nínú ìwé mímọ́ gbogbo nípa ti ara rẹ̀.
28 Y bigoreáron al gau, á duque chalaban: Y ó diñó simaches de chalar mas dur.
Wọ́n sì súnmọ́ ìletò tí wọ́n ń lọ, ó sì ṣe bí ẹni pé yóò lọ sí iwájú.
29 Tami o detereláron sat sila, penando: Queda tucue sat amangue, presas tasata sinela, y o cam ha chalado ostely. Y chaló andré sat junós.
Wọ́n sì rọ̀ ọ́, pé, “Bá wa dúró: nítorí ó di ọjọ́ alẹ́, ọjọ́ sì kọjá tán.” Ó sì wọlé lọ, ó bá wọn dúró.
30 Y sinando bejelado sat junos á la mensalli, ustiló o tato, y o majarificó: y terelando asparabado, se lo diñaba.
Ó sì ṣe, bí ó ti bá wọn jókòó ti oúnjẹ, ó mú àkàrà, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún wọn.
31 Y sináron despandadas as aquias de junós, y lo pincharáron; y ó entonces se najó de desquerias aquias.
Ojú wọn sì là, wọ́n sì mọ̀ ọ́n, ó sì nù mọ́ wọn ní ojú.
32 Y penáron yeque á aver: ¿Pre baji na bucharaba amaro carlochin enrún amangue, pur andré o drun chamuliaba sat amangue, chibando en dundun as randiñipenes?
Wọ́n sì bá ara wọn sọ pé, “Ọkàn wa kò ha gbiná nínú wa, nígbà tí ó ń bá wa sọ̀rọ̀ tí ó sì ń túmọ̀ ìwé mímọ́ fún wa!”
33 Y ardiñandose andré a mateja ocána, limbidiáron á Jerusalém: y alacháron catanés á os once, y á junos sos sinaban sat junós,
Wọ́n sì dìde ní wákàtí kan náà, wọ́n padà lọ sí Jerusalẹmu, wọ́n sì bá àwọn mọ́kànlá péjọ, àti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ wọn.
34 Sos penáron; Chachipen, ha ardiñado o Erañó, y se ha diado á Simón.
Wọn si wí pé, “Olúwa jíǹde nítòótọ́, ó sì ti fi ara hàn fún Simoni!”
35 Y junos penáron ma les terelaba anacado andré o drun y sasta le habian pincherado al asparabar o tato.
Àwọn náà sì ròyìn nǹkan tí ó ṣe ní ọ̀nà, àti bí ó ti di mí mọ̀ fún wọn ní bíbu àkàrà.
36 Y sinando chamuliando oconas buchias, se chitó Jesus en medio de junos, y les penó: Paz á sangue: menda sinelo, na darañeleis.
Bí wọ́n sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí Jesu tìkára rẹ̀ dúró láàrín wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”
37 Presas junos perelales de dal, y canguelo, penchababan que diquelaban yeque barbalé.
Ṣùgbọ́n àyà fò wọ́n, wọ́n sì wárìrì, wọ́n ṣe bí àwọn rí ẹ̀mí kan.
38 Y les penó: ¿Presás terelais dal, y costunelan pensamientos á jirés carlochines?
Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ara yín kò lélẹ̀? Èé sì ti ṣe tí èròkerò fi ń sọ nínú ọkàn yín?
39 Diquelad minrias bastes y minrés pindrés, que menda matejo sinelo: pajabelad y diquelad, presas yeque barbalé na terela brinza ta cocális, sasta diquelais que terelo menda.
Ẹ wo ọwọ́ mi àti ẹsẹ̀ mi, pé èmi tìkára mi ni! Ẹ dì mímú kí ẹ wò ó nítorí tí iwin kò ní ẹran àti egungun lára, bí ẹ̀yin ti rí tí èmi ní.”
40 Y penado ocono, les dió as bastes y os pindrés.
Nígbà tí ó sì wí bẹ́ẹ̀ tan, ó fi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ hàn wọ́n.
41 Tami sasta aun na astisirasen creer, sinando maravillados de pesquital, les penó: ¿Terelais acoi buchi que jamar?
Nígbà tí wọn kò sì tí ì gbàgbọ́ fún ayọ̀, àti fún ìyanu, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ní ohunkóhun jíjẹ níhìn-ín yìí?”
42 Y junos le laneláron yeque arecata de macho querabado, y yeque frimita de anguin.
Wọ́n sì fún un ní ẹja tí a fi oyin sè.
43 Y habiendo jamado anglal de junos, ustiló as sobras, y se les diñó.
Ó sì gbà á, ó jẹ ẹ́ lójú wọn.
44 Y les penó: Oconas sinelan as vardas sos pené á sangue, sinando aun con-a-sangue, que jomte que se perele o saro ma sinela libanado de mangue andré a Eschastra de Moysés, y andré os Prophetas, y andré os Psalmes.
Ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún yín, nígbà tí èmí ti wà pẹ̀lú yín pé, a ní láti mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ nínú òfin Mose, àti nínú ìwé àwọn wòlíì, àti nínú Saamu, nípasẹ̀ mi.”
45 Entonces les despandó a suncai, somia que jabillasen as randiñapenes.
Nígbà náà ni ó ṣí wọn ní iyè, kí ìwé mímọ́ lè yé wọn.
46 Y les penó: Andiar sinela libanado, y andiar jomte que o Christo urjiyaráse, y ardiñáse al trincho chibes de enrún os mulés:
Ó sì wí fún wọn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni a ti kọ̀wé rẹ̀, pé: kí Kristi jìyà, àti kí ó sì jíǹde ní ọjọ́ kẹta kúrò nínú òkú,
47 Y que se chamuliase andré desquero nao penitencia y mecos de grecos á sari a sueti, y brotoboro á Jerusalém.
àti pé kí a wàásù ìrònúpìwàdà àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ lórúkọ rẹ̀, ní orílẹ̀-èdè gbogbo, bẹ̀rẹ̀ láti Jerusalẹmu lọ.
48 Y sangue marchirés sinelais de ocónas buchias.
Ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí.
49 Y menda bichabelo opré sangue á la buchi prometida de minrio Dada: Tami sangue permaneced acoi andré o foros, disde que sinelais perelalés de la sila e udscho.
Èmi yóò rán ohun tí Baba mi ṣe ìlérí sí yín, ṣùgbọ́n ẹ jókòó ní ìlú Jerusalẹmu, títí a ó fífi agbára wọ̀ yín, láti òkè ọ̀run wá.”
50 Y os sicabó abrí disde Bethania: y ardiñando desqueres hastes os majarificó.
Ó sì mú wọn jáde lọ títí wọ́n fẹ́rẹ̀ dé Betani, nígbà tí ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó súre fún wọn.
51 Y anacó, que o chiros que os majarificaba, se najó de junos, y sinaba lliguerado al Tarpe.
Ó sì ṣe, bí ó ti ń súre fún wọn, ó yà kúrò lọ́dọ̀ wọn, a sì gbé e lọ sí ọ̀run.
52 Y junos despues de buchararse al chiquen y querelarle adoracion, se limbidiáron á Jerusalém sat bari pesquital.
Wọ́n sì foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì padà lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ayọ̀ púpọ̀.
53 Y sinaban deltó andré a cangrí loando ta majarificando á Debél. Unga. Saboca Enrecar Debel Ererio. Chachipè.
Wọ́n sì wà ní tẹmpili nígbà gbogbo, wọ́n ń fi ìyìn, àti ìbùkún fún Ọlọ́run.

< Lucas 24 +