+ Lucas 1 >

1 Á cána que sares han penchabado chibar de pacuaró a narracion es buchías que andré amángue han sinado quereladas.
Ọ̀pọ̀ ènìyàn ni ó ti dáwọ́lé títo àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì jọ lẹ́sẹẹsẹ, èyí tí ó ti múlẹ̀ ṣinṣin láàrín wa,
2 Sásta junos as penáron á amángue sos desde o principio as diqueláron sa’ desquerias aquías, y sináron ministres e varda.
àní gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó ṣe ojú wọn láti ìbẹ̀rẹ̀ ti fi lé wa lọ́wọ́.
3 Pre o matéjo ha parecido lachó á mángue, despues de orotar mistós sasta se las quereláron desde o principio, libanartelas de pacuaró, ó baro Theophilo.
Nítorí náà, ó sì yẹ fún èmi pẹ̀lú, láti kọ̀wé sí ọ lẹ́sẹẹsẹ bí mo ti wádìí ohun gbogbo fínní fínní sí láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, Teofilu ọlọ́lá jùlọ,
4 Somia que pincharéles a chachipen de ocolas buchías andré que has sinado instruido.
kí ìwọ kí ó le mọ òtítọ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti kọ́ ọ.
5 Sinaba andré os chibéses de Herodes, Crállis de Judea; yeque erajai, sos se hetó Zacharias, e baji de Abías, y desqueri romi es dugidas de Aaron, y o nao de ocóna Elisabeth.
Nígbà ọjọ́ Herodu ọba Judea, àlùfáà kan wà, láti ìran Abijah, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Sekariah: aya rẹ̀ sì ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Aaroni, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Elisabeti.
6 Y sinaban os dui lachés anglal de Debél, pirando bi grecos andré os sares mandamientos y eschastras e Erañoró.
Àwọn méjèèjì sì ṣe olódodo níwájú Ọlọ́run, wọ́n ń rìn ní gbogbo òfin àti ìlànà Olúwa ní àìlẹ́gàn.
7 Y na terelaban chaboro, presas Elisabeth sinaba estéril, y os dui chalados dur andré sus chibéses.
Ṣùgbọ́n wọn kò ní ọmọ, nítorí tí Elisabeti yàgàn; àwọn méjèèjì sì di arúgbó.
8 Y anacó que querelando Zacharias desquero ministerio anglal de Debél andré o orden de desqueri begai,
Ó sì ṣe, nígbà tí ó ń ṣe iṣẹ́ àlùfáà níwájú Ọlọ́run ni àkókò tirẹ̀.
9 Segun o costumbre es erajais, sicabó por desquerí baji á chibar o incienso, chalando andré a cangri e Erañoró.
Bí ìṣe àwọn àlùfáà, ipa tirẹ̀ ni láti máa fi tùràrí jóná, nígbà tí ó bá wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
10 Y os hambés catanés sinaban abrí manguelando á Un-debél á la ocana e incienso.
Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ń gbàdúrà lóde ní àkókò sísun tùràrí.
11 Y dicó al Manfariel e Erañoró, sinando en pindré á la bastarí e altar e incienso.
Angẹli Olúwa kan sì fi ara hàn án, ó dúró ní apá ọ̀tún pẹpẹ tùràrí.
12 Y Zacharias al dicarle cangueló, y peró dal opré ó.
Nígbà tí Sekariah sì rí i, orí rẹ̀ wú, ẹ̀rù sì bà á.
13 Tami o Manfariel le penó: Na darañeles Zacharias, presas tirias ocanagimias han sinado juneladas: y tiri romi Elisabeth chindará á tucue yeque chaboro, y araquelarás desquero nao Juan.
Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Sekariah: nítorí tí àdúrà rẹ gbà; Elisabeti aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Johanu.
14 Y terelarás pesquital y alegría, y se asaselarán baribustres manuces andré desquero nacimiento.
Òun yóò sì jẹ́ ayọ̀ àti ìdùnnú fún ọ, ènìyàn púpọ̀ yóò sì yọ̀ sí ìbí rẹ.
15 Presas sinará haro anglal o Erañoró; y na piyará mol ni peñacoró, y sinará perelaló e Peniche desde as poriás de sun dai.
Nítorí òun ó pọ̀ níwájú Olúwa, kì yóò sì mu ọtí wáìnì, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sì mu ọtí líle; yóò sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àní láti inú ìyá rẹ̀ wá.
16 Y á baribústres es chabores de Israel querelará limbidiar al Erañó, o Debél de junós.
Òun ó sì yí ènìyàn púpọ̀ padà nínú àwọn ọmọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
17 Presas ó chalará anglal de ó sa’ la suncai y sila de Elias, somia querelar limbidiar os carlochines es batuces á os chabores, y os sos na pachibélan al drun es majarés, somia preparar al Erañó una sueti perfecta.
Ẹ̀mí àti agbára Elijah ni Olúwa yóò sì fi ṣáájú rẹ̀ lọ, láti pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ti àwọn aláìgbọ́ràn sí ọgbọ́n àwọn olóòtítọ́; kí ó le pèsè àwọn ènìyàn tí a múra sílẹ̀ de Olúwa.”
18 Y penó Zacharias al Manfariel: ¿en que pincharé ocóno? presas menda sinelo puró, y minri romí sinela dur andré desqueres chibéses.
Sekariah sì wí fún angẹli náà pé, “Àmì wo ni èmi ó fi mọ èyí? Èmi sá ti di àgbà, àti Elisabeti aya mi sì di arúgbó.”
19 Y rudeló o Manfariel y penó: sinelo Gabriel, sos asisto anglal de Debél: y sinelo bichabado á penarte, y á lanarte ocóna nueva lachi.
Angẹli náà sì dáhùn ó wí fún un pé, “Èmi ni Gabrieli, tí máa ń dúró níwájú Ọlọ́run; èmi ni a rán wá láti sọ fún ọ, àti láti mú ìròyìn ayọ̀ wọ̀nyí fún ọ wá.
20 Y tucue sinarás musilé, y no astisararás chamuliar disde o chibés andré sos ocóno sinará querelado, presas na pachibelaste á minrias vardas, sos se cumplirán á sun chiros.
Sì kíyèsi i, ìwọ ó yadi, ìwọ kì yóò sì le fọhùn, títí ọjọ́ náà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ, nítorí ìwọ kò gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́ tí yóò ṣẹ ní àkókò wọn.”
21 Y os manuces sinaban ujarando á Zacharias: y os sares zibaban de que tasiabase ó andré a cangri.
Àwọn ènìyàn sì ń dúró de Sekariah, ẹnu sì yà wọ́n nítorí tí ó pẹ́ nínú tẹmpili.
22 Y pur se sicobó abrí, na les astisaraba chamuliar; y chaneláron que habia dicado buchí andré a cangri, y ó lo penó por simaches, y sinaba musilé.
Nígbà tí ó sì jáde wá, òun kò le bá wọn sọ̀rọ̀. Wọn sì kíyèsi wí pé ó ti rí ìran nínú tẹmpili, ó sì ń ṣe àpẹẹrẹ sí wọn, nítorí tí ó yadi.
23 Y pur sináron cumplidos os chibéses de desquero ministerio, se chaló á su quer.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ pé, ó lọ sí ilé rẹ̀.
24 Y á la anda de ocónos chibéses se dicó cambri Elisabeth a romi de ó, y sinaba escondida pansch chonos, penando:
Lẹ́yìn èyí ni Elisabeti aya rẹ̀ lóyún, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́ ní oṣù márùn-ún,
25 Presas o Erañó me ha querelado ocono andré os chibéses, en que penchabó á nicabar minrio oprobio de enré os manuces.
Ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa ṣe fún mi ní ọjọ́ tí ó síjú wò mí, láti mú ẹ̀gàn mi kúrò láàrín àwọn ènìyàn.”
26 Y al zobio chonos o Manfariel Gabriel sinaba bichabado de Debél á yeque foros de Galiléa, sos se hetó Nazareth,
Ní oṣù kẹfà Ọlọ́run sì rán angẹli Gabrieli sí ìlú kan ní Galili, tí à ń pè ní Nasareti,
27 A yeque bedori romandiñada sat manu, sos se hetó Joseph, e quer de David, y o nao e bedori sinaba Maria.
sí wúńdíá kan tí a ṣèlérí láti fẹ́ fún ọkùnrin kan, tí a ń pè ní Josẹfu, ti ìdílé Dafidi; orúkọ wúńdíá náà a sì máa jẹ́ Maria.
28 Y pur chaló o Manfariel andré, anduque sinaba, penó: Un-debél te diñele golipén, perelali de gracia: O Erañó con tucue: Majari tucue enré as cadchiás.
Angẹli náà sì tọ̀ ọ́ wá, ó ní, “Àlàáfíà fun ọ, ìwọ ẹni tí a kọjú sí ṣe ní oore, Olúwa ń bẹ pẹ̀lú rẹ.”
29 Y pur siró juneló ocono, se darañó sat as vardas de ó, y penchababa, que salutacion sinaba ocola.
Ṣùgbọ́n ọkàn Maria kò lélẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ náà, ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, irú kíkí kín ni èyí.
30 Y o Manfariel le penó: na cangueles Maria, presas has alachado gracia anglal de Debél.
Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Maria, nítorí ìwọ ti rí ojúrere lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
31 He acoi concebirás andré tiro chepo, y chindarás chaboro, y araquerarás desquero nao Jesus.
Ìwọ yóò lóyún nínú rẹ, ìwọ ó sì bí ọmọkùnrin kan, ìwọ ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu.
32 Ocóla sinará baro, y sinará araquerado chaboro e Udscho, y le diñará Un-debél Erañó o throno de David desquero batu;
Òun ó pọ̀, ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó sì máa pè é, Olúwa Ọlọ́run yóò sì fi ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀ fún.
33 y sinará Crallis deltó andré o quer de Jacob. Y desquero chim na terelará anda. (aiōn g165)
Yóò sì jẹ ọba lórí ilé Jakọbu títí láé; ìjọba rẹ̀ kì yóò sì ní ìpẹ̀kun.” (aiōn g165)
34 Y penó Maria al Manfariel: ¿Sasta sinará, ocono? y menda na pincharelo manu.
Nígbà náà ni Maria béèrè lọ́wọ́ angẹli náà pé, “Èyí yóò ha ti ṣe rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí èmi kò tí ì mọ ọkùnrin.”
35 Y rudelando o Manfariel, penó: se bestelará opré tucue, y te querelará sombra a sila e Udscho. Y por ocono o Majaro, sos se chindará de tucue, sinará araquerado Chaboro de Debél.
Angẹli náà sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ yóò tọ̀ ọ́ wá, agbára Ọ̀gá-ògo jùlọ yóò síji bò ọ́. Nítorí náà ohun mímọ́ tí a ó ti inú rẹ bí, Ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè é.
36 Y Elisabeth tiri cachicálli siró tambien sinela cambri de yeque chaboro, sinando puri: y ocono sinela o zobio chonos de siró, sos sinela araquerada a esteril.
Sì kíyèsi i, Elisabeti ìbátan rẹ náà yóò sì ní ọmọkùnrin kan ní ògbólógbòó rẹ̀, èyí sì ni oṣù kẹfà fún ẹni tí à ń pè ní àgàn.
37 Presas na sinela chi n’astis para Un-debél.
Nítorí kò sí ohun tí Ọlọ́run kò le ṣe.”
38 Y penó Maria: Menda a lacrí e Erañoró, querelese andré mangue segun tiri varda. Y se chaló o Manfariel.
Maria sì dáhùn wí pé, “Wò ó ọmọ ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.
39 Y andré ocolas chibéses se ardiñó Maria y chaló al bur, á yeque foros e chim de Judá.
Ní àkókò náà ni Maria sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Judea;
40 Y chaló andré o quer de Zacharias, y saludisaró á Elisabeth.
Ó sì wọ ilé Sekariah lọ ó sì kí Elisabeti.
41 Y pur Elisabeth juneló a salutacion de Maria, o chinoró diñó saltos andré desquero trupo: y sinaba Elisabeth perelalí e Peniche.
Ó sì ṣe, nígbà tí Elisabeti gbọ́ kíkí Maria, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Elisabeti sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́,
42 Y diñó yeque gole y penó: Majari tucue andré as cadchiás, y majaró o mibao e tiro trupo.
Ó sì ké ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni ìwọ nínú àwọn obìnrin, alábùkún fún sì ni ọmọ tí ìwọ yóò bí.
43 De duque sinela ocono á mangue, que a Dai e minrio Erañó abillela á mangue?
Èéṣe tí èmi fi rí irú ojúrere yìí, tí ìyá Olúwa mi ìbá fi tọ̀ mí wá?
44 Presas yescotria que bigoreó a varda de tiri salutacion á minres canés, o chinoró diñó saltos de pesquital andré minrio trupo.
Sá wò ó, bí ohùn kíkí rẹ ti bọ́ sí mi ní etí, ọlẹ̀ sọ nínú mi fún ayọ̀.
45 Y majaró ma andré tun men, presas sinará querelado o saro ma fué penado á tucue de parte e Erañoró.
Alábùkún fún sì ni ẹni tí ó gbàgbọ́, nítorí nǹkan wọ̀nyí tí a ti sọ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò ṣẹ.”
46 Y penó Maria: Minri ochi engrandece al Erañó:
Maria sì dáhùn, ó ní: “Ọkàn mi yin Olúwa lógo.
47 Y minri suncai se asaseló andré Debél minrío Salvador.
Ẹ̀mí mi sì yọ̀ sí Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
48 Presás ha dicado a chinoría de desqueri lacrí: pues ya desde acana as sarias generaciones araquelarán mangue majari.
Nítorí tí ó síjú wo ìwà ìrẹ̀lẹ̀ ọmọbìnrin ọ̀dọ̀ rẹ̀. Sá wò ó, láti ìsinsin yìí lọ gbogbo ìran ènìyàn ni yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
49 Ha querdi buchías bariás á mangue ó sos terela sila, y majaró o nao de ó.
Nítorí ẹni tí ó ní agbára ti ṣe ohun tí ó tóbi fún mi; Mímọ́ sì ni orúkọ rẹ̀.
50 Su canrea sinela de generacion andré generacion opré os sares que le darañelan.
Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, láti ìrandíran.
51 Queró sila sat su murcia: queró najar á os superbios sat as imaginaciones de sus carlochines.
Ó ti fi agbára hàn ní apá rẹ̀; o ti tú àwọn onígbèéraga ká ní ìrònú ọkàn wọn.
52 Queró á os silares perar sus besti, y ardiñó á os humildes.
Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn, o sì gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ lékè.
53 Hinchió de buchias lachias á os que terelaban bóquis; y á os balbales mecó chichi.
Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebi ń pa ó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.
54 Ustiló andré sun chepó á Israel sun lacró, enjallandose de sun canrea.
Ó ti ran Israẹli ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́, ní ìrántí àánú rẹ̀;
55 Andiar sasta penó á amáres batuces, á Abraham y á sus chaborés deltó. (aiōn g165)
sí Abrahamu àti àwọn ìran rẹ̀ láéláé, baba wa, àti bí ó ti sọ fún àwọn baba wa.” (aiōn g165)
56 Y Maria sinaba sat siró sasta trin chonos: y se limbidió á desquero quer.
Maria sì jókòó tì Elisabeti níwọ̀n oṣù mẹ́ta, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
57 Tami Elisabeth se le chaló o chiros de chindar, y chindó yeque chaboro.
Nígbà tí ọjọ́ Elisabeti pé tí yóò bí; ó sì bí ọmọkùnrin kan.
58 Y juneláron os quiribés y os cachicállis de siró que o Erañó habia querelado canrea bari sat siró, y se alendáron sat siró.
Àwọn aládùúgbò, àti àwọn ìbátan rẹ̀ gbọ́ bí Olúwa ti fi àánú ńlá hàn fún un, wọ́n sì bá a yọ̀.
59 Y sinaba que al otoró chibés abilláron á chinar o postin e quilén al chaboró, y le araqueráron del nao de desquero batu, Zacharias.
Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n wá láti kọ ọmọ náà nílà; wọ́n sì fẹ́ sọ orúkọ rẹ̀ ní Sekariah, gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba rẹ̀.
60 Y rudelando desqueri dai, penó: nanai, sino Juan sinará araquerado.
Ìyá rẹ̀ sì dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Johanu ni a ó pè é.”
61 Y le penáron: cayque sinela andré tiri ráti, sos se heta sat ocola nao.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ará rẹ̀ tí à ń pè ní orúkọ yìí.”
62 Y pucháron por simaches al batu e chaboro, como camelaba que se le araquerase.
Wọ́n sì ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀, bí ó ti ń fẹ́ kí a pè é.
63 Y mangando li, libanó, penando: Juan sinela su nao: y os sares se zibáron.
Ó sì béèrè fún wàláà, ó sì kọ ọ wí pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu sì ya gbogbo wọn.
64 Y yescotria sinaba pendrabado desquero mui, y su chipe, y chamuliaba majarificando á Debél.
Ẹnu rẹ̀ sì ṣí lọ́gán, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì sọ̀rọ̀, ó sì ń yin Ọlọ́run.
65 Y peró dal opré os sares sunparales: y se penáron de sarias oconas buchias por os sares bures de Judéa.
Ẹ̀rù sì ba gbogbo àwọn tí ń bẹ ní agbègbè wọn, a sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí ká gbogbo ilẹ̀ òkè Judea.
66 Y os sares que as junelaban, as ujaraban andré sus carlochines, penando: ¿coin penchabais, que sinará ocona chaboro? Presas a baste e Erañoró sinaba sat ó.
Ó sì jẹ́ ohun ìyanu fún gbogbo àwọn tí ó gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì tò ó sínú ọkàn wọn, wọ́n ń wí pé, “Irú-ọmọ kín ni èyí yóò jẹ́?” Nítorí tí ọwọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.
67 Y Zacharias sun batu sinaba perelalo e Peniche, y garló baji, penando.
Sekariah baba rẹ̀ sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì sọtẹ́lẹ̀, ó ní:
68 Majaró o Eraño Debél de Israel, presas abilló y diñó mestepé á sun sueti.
“Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli; nítorí tí ó ti bojú wò, tí ó sì ti dá àwọn ènìyàn rẹ̀ nídè,
69 Y ardiñó á amangue o rogos de golipen andré o quer de David sun lacró.
Ó sì ti gbé ìwo ìgbàlà sókè fún wa ní ilé Dafidi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀;
70 Como penó por mui de sus majarés Prophetas, andré os sarés gresés. (aiōn g165)
(bí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tipẹ́tipẹ́), (aiōn g165)
71 Mestepé de amáres daschmanuces, y de la baste de os sares que na camelan amangue.
Pé, a ó gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa àti lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wá.
72 Somia querelar canrea sat amáres batuces, y ojararse de su majarí varda.
Láti ṣe àánú tí ó ṣèlérí fún àwọn baba wa, àti láti rántí májẹ̀mú rẹ̀ mímọ́,
73 O juramento sos juró á amaro batu Abraham, que ó diñaria á amangue;
ìbúra tí ó ti bú fún Abrahamu baba wa,
74 Somia que listrabados de las bastes de amáres daschmanuces, le querelemos servicio bi dal,
láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, kí àwa kí ó lè máa sìn láìfòyà,
75 André majaridad, y andré justicia anglal de ó, os sares chibeses de amári chipén.
ni ìwà mímọ́ àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.
76 Y tucue, chaboro, sinarás araquerado Propheta e muy Udscho, presas chalarás anglal la chiché e Erañoró, somia aparejar desqueres drunés:
“Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́: nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;
77 Somia diñar conocimiento de golipen á sun sueti para a remision de desqueres grecos.
láti fi ìmọ̀ ìgbàlà fún àwọn ènìyàn rẹ̀ fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
78 Por as porias de canrea de amaro Debél con qué visitó amangue del Udscho e Oriente:
nítorí ìyọ́nú Ọlọ́run wà; nípa èyí tí ìlà-oòrùn láti òkè wá bojú wò wá,
79 Somia diñar dut a junós sos bestelélan andré a rachi, y andré o butron de meripen: somia enseelar amáres pindrés á drun de paz.
Láti fi ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó jókòó ní òkùnkùn àti ní òjìji ikú, àti láti fi ẹsẹ̀ wa lé ọ̀nà àlàáfíà.”
80 Y o chaboro se querelaba baro, y sinaba querdi silnó andré suncai; y sinaba andré os desiertos, disde o chibes pur nichobeló á Israel.
Ọmọ náà sì dàgbà, ó sì le ní ọkàn, ó sì ń gbé ní ijù títí ó fi di ọjọ́ ìfihàn rẹ̀ fún Israẹli.

+ Lucas 1 >