< Luka 12 >

1 Medtem ko je bila tam skupaj zbrana brezštevilna množica ljudstva, do take mere, da so stopali drug po drugem, je najprej začel govoriti svojim učencem: »Pazite se kvasa farizejev, ki je hinavščina.
Ó sì ṣe, nígbà tí àìníye ìjọ ènìyàn péjọpọ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí wọn ń tẹ ara wọn mọ́lẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sísọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ máa ṣọ́ra yín nítorí ìwúkàrà àwọn Farisi tí í ṣe àgàbàgebè.
2 Kajti nič ni prikrito, kar ne bo razkrito niti skrito, kar se ne bo izvedelo.
Kò sí ohun tí a bò, tí a kì yóò sì fihàn; tàbí tí ó pamọ́, tí a kì yóò mọ̀.
3 Zatorej karkoli ste govorili v temi, bo slišano na svetlobi; in to, kar ste govorili v sobicah na ušesa, bo razglašeno na hišnih strehah.
Nítorí náà ohunkóhun tí ẹ̀yin sọ ní òkùnkùn, ní gbangba ni a ó ti gbọ́ ọ; àti ohun tí ẹ̀yin bá sọ sí etí ní iyàrá, lórí òrùlé ni a ó ti kéde rẹ̀.
4 Vam, svojim prijateljem, pa pravim: ›Ne bojte se teh, ki ubijejo telo in nató ne morejo nič več storiti.‹
“Èmi sì wí fún yín ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn tí ó ń pa ara ènìyàn kú, lẹ́yìn èyí, wọn kò sì ní èyí tí wọ́n lè ṣe mọ́.
5 Toda posvaril vas bom, koga se bojte: ›Bojte se njega, ki ima, potem ko je ubil, oblast, da vrže v pekel.‹ Da, pravim vam: ›Bojte se ga.‹ (Geenna g1067)
Ṣùgbọ́n èmi ó sì sọ ẹni tí ẹ̀yin ó bẹ̀rù fún yín: Ẹ bẹ̀rù ẹni tí ó lágbára lẹ́yìn tí ó bá pànìyàn tan, láti wọ́ ni lọ sí ọ̀run àpáàdì. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín òun ni kí ẹ bẹ̀rù. (Geenna g1067)
6 Ali ni pet vrabcev prodanih za dva novčiča, pa niti eden izmed njih ni pozabljen pred Bogom?
Ológoṣẹ́ márùn-ún sá à ni a ń tà ní owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì? A kò sì gbàgbé ọ̀kan nínú wọn níwájú Ọlọ́run?
7 Toda celó vsi lasje vaše glave so prešteti. Ne bojte se torej, vredni ste več kakor mnogo vrabcev.
Ṣùgbọ́n gbogbo irun orí yín ni a kà pé ṣánṣán. Nítorí náà kí ẹ má ṣe bẹ̀rù, ẹ̀yin ní iye lórí ju ológoṣẹ́ púpọ̀ lọ.
8 Prav tako vam pravim: ›Kdorkoli me bo priznal pred ljudmi, njega bo prav tako Sin človekov priznal pred Božjimi angeli, ‹
“Mo sì wí fún yín pẹ̀lú, Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́wọ́ mi níwájú àwọn ènìyàn. Ọmọ Ènìyàn yóò sì jẹ́wọ́ rẹ̀ níwájú àwọn angẹli Ọlọ́run.
9 toda kdor me zanika pred ljudmi, bo zanikan pred Božjimi angeli.
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sẹ́ mi níwájú ènìyàn, a ó sẹ́ ẹ níwájú àwọn angẹli Ọlọ́run.
10 In kdorkoli bo govoril besedo zoper Sina človekovega, mu bo odpuščeno, toda tistemu, ki preklinja zoper Svetega Duha, ne bo odpuščeno.
Àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ọmọ Ènìyàn, a ó dárí rẹ̀ jì í; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́, a kì yóò dárí rẹ̀ jì í.
11 In ko vas privedejo v sinagoge in k sodnikom in oblastem, se ne vznemirjajte in ne skrbite kakšno ali katero besedo boste odgovorili ali kaj boste rekli,
“Nígbà tí wọ́n bá sì mú yin wá sí Sinagọgu, àti síwájú àwọn olórí, àti àwọn aláṣẹ, ẹ má ṣe ṣàníyàn pé, báwo tàbí ohun kín ni ẹ̀yin yóò fèsì rẹ̀ tàbí kín ni ẹ̀yin ó wí.
12 kajti Sveti Duh vas bo v tej isti uri poučil, kaj morate reči.«
Nítorí Ẹ̀mí Mímọ́ yóò kọ́ yín ní wákàtí kan náà ní ohun tí ó yẹ kí ẹ sọ.”
13 Eden iz skupine pa mu je rekel: »Učitelj, spregovori mojemu bratu, naj dediščino deli z menoj.«
Ọ̀kan nínú àwùjọ wí fún un pé, “Olùkọ́, sọ fún arákùnrin mi kí ó pín mi ní ogún.”
14 Rekel mu je: »Človek, kdo me je naredil sodnika ali delivca nad vama?«
Ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin yìí, ta ni ó fi mí jẹ onídàájọ́ tàbí olùpíngún fún yín?”
15 In rekel jim je: »Pazite in čuvajte se pohlepnosti, kajti bistvo človeškega življenja ni v obilju stvari, ki jih poseduje.«
Ó sì wí fún wọn pé, “Kíyèsára kí o sì máa ṣọ́ra nítorí ojúkòkòrò: nítorí ìgbésí ayé ènìyàn kò dúró lé ọ̀pọ̀ ohun tí ó ní.”
16 In povedal jim je prispodobo, rekoč: »Zemlja nekega bogataša je obilno obrodila
Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ilẹ̀ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ so ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso.
17 in mislil si je sam pri sebi, rekoč: ›Kaj bom storil, ker nimam prostora, kamor bi spravil svoje sadove?‹
Ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, ‘Èmi ó ti ṣe, nítorí tí èmi kò ní ibi tí èmi ó gbé kó èso mi jọ sí.’
18 Pa je rekel: ›To bom storil, podrl bom svoje skednje in zgradil večje in tja bom spravil vse svoje sadove in svoje dobrine.‹
“Ó sì wí pé, ‘Èyí ni èmi ó ṣe: èmi ó wó àká mi palẹ̀, èmi ó sì kọ́ èyí tí ó tóbi; níbẹ̀ ni èmi ó gbé to gbogbo èso àti ọrọ̀ mi jọ sí.
19 Svoji duši pa bom rekel: ›Duša, veliko dobrin imaš spravljenih za mnogo let; vzemi si počitek, jej, pij in bodi vesela.‹
Èmi ó sì wí fún ọkàn mi pé, ọkàn, ìwọ ní ọrọ̀ púpọ̀ tí a tò jọ fún ọ̀pọ̀ ọdún; sinmi, máa jẹ, máa mu, máa yọ̀.’
20 Toda Bog mu je rekel: ›Ti bedak, to noč bo tvoja duša zahtevana od tebe. Čigave bodo potem te stvari, ki si jih priskrbel?‹
“Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wí fún un pé, ‘Ìwọ aṣiwèrè, lóru yìí ni a ó béèrè ọkàn rẹ lọ́wọ́ rẹ; ǹjẹ́ ti ta ni nǹkan wọ̀nyí yóò ha ṣe, tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀?’
21 Tak je, kdor zaklade shranjuje zase, ni pa bogat pred Bogom.«
“Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó to ìṣúra jọ fún ara rẹ̀, tí kò sì ní ọrọ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
22 Svojim učencem pa je rekel: »Zatorej vam pravim: ›Ne vznemirjajte se in ne skrbite za svoje življenje, kaj boste jedli; niti za telo, kaj boste oblekli.
Jesu sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Nítorí náà mo wí fún yín pé, ẹ má ṣe ṣe àníyàn nítorí ẹ̀mí yín pé, kín ni ẹ̀yin yóò jẹ tàbí nípa ara yin pe kín ni ẹyin o fi bora.
23 Življenje je več kakor hrana in telo je več kakor oblačilo.
Ẹ̀mí sá à ju oúnjẹ lọ, ara sì ju aṣọ lọ.
24 Preudarite o krokarjih, kajti niti ne sejejo niti ne žanjejo; ki nimajo niti skladišča niti skednja, pa jih Bog hrani. Kako silno ste vi boljši kakor perjad?
Ẹ kíyèsi àwọn ẹyẹ ìwò: wọn kì í fúnrúgbìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í kórè: wọn kò ní àká, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní abà, Ọlọ́run sá à ń bọ́ wọn: mélòó mélòó ni tí ẹ̀yin fi sàn ju ẹyẹ lọ!
25 In kdo izmed vas lahko z vznemirjanjem in skrbmi svoji postavi doda en komolec?
Ta ni nínú yín nípa àníyàn ṣíṣe tí ó lè fi ìgbọ̀nwọ́ kan kún ọjọ́ ayé rẹ̀?
26 Če torej niste zmožni storiti te stvari, ki je najmanj pomembna, zakaj se vznemirjate in skrbite za ostalo?
Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin kò ti lè ṣe èyí tí ó kéré bí eléyìí, èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣàníyàn nítorí ìyókù?
27 Preudarite lilije, kako rastejo; ne garajo, ne predejo in vendar vam jaz pravim, da Salomon v vsej svoji slavi ni bil oblečen kakor ena izmed teh.
“Ẹ kíyèsi àwọn lílì bí wọ́n ti ń dàgbà; wọn kì í ṣiṣẹ́, wọn kì í rànwú; ṣùgbọ́n kí èmi wí fún yín, a kò ṣe Solomoni pàápàá lọ́ṣọ̀ọ́ ní gbogbo ògo rẹ̀ tó ọ̀kan nínú ìwọ̀nyí.
28 Če torej Bog tako oblači travo, ki je danes na polju in je jutri vržena v peč; kako mnogo bolj bo oblačil vas, oh vi maloverni?
Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run bá wọ koríko igbó ní aṣọ tó bẹ́ẹ̀ èyí tí ó wà lónìí, tí a sì gbá a sínú iná lọ́la: mélòó mélòó ni yóò wọ̀ yín láṣọ, ẹ̀yin onígbàgbọ́ kékeré.
29 In ne iščite, kaj boste jedli ali kaj boste pili niti ne bodite dvomljivega mišljenja.
Kí ẹ má sì ṣe lé ohun tí ẹ ó jẹ, tàbí ohun tí ẹ ó mu, kí ẹ má sì ṣe ṣe àníyàn nínú ọkàn.
30 Kajti za vsemi temi stvarmi povprašujejo narodi sveta in vaš Oče ve, da imate potrebo za temi stvarmi.
Nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè ayé ń wá kiri. Baba yín sì mọ̀ pé, ẹ̀yin ń fẹ́ nǹkan wọ̀nyí.
31 Toda raje iščite Božje kraljestvo in vse te stvari vam bodo dodane.
Ṣùgbọ́n ẹ máa wá ìjọba Ọlọ́run, gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni a ó sì fi kún un fún yín.
32 Ne bojte se, mali trop, kajti dobra volja vašega Očeta je, da vam da kraljestvo.
“Má bẹ̀rù, agbo kékeré, nítorí dídùn inú Baba yín ni láti fi ìjọba fún yín.
33 Prodajte, kar imate in dajte miloščino. Priskrbite si mošnje, ki ne ostarijo, zaklad v nebesih, ki ne izneveri, kjer se noben tat ne približa niti molj ne razkraja.
Ẹ ta ohun tí ẹ̀yin ní, kí ẹ sì tọrẹ àánú kí ẹ sì pèsè àpò fún ara yín, tí kì í gbó, ìṣúra ní ọ̀run tí kì í tán, ní ibi tí olè kò lè súnmọ́, àti ibi tí kòkòrò kì í bà á jẹ́.
34 Kajti kjer je vaš zaklad, tam bo tudi vaše srce.
Nítorí ní ibi tí ìṣúra yín gbé wà, níbẹ̀ ni ọkàn yín yóò gbé wà pẹ̀lú.
35 Naj bodo vaša ledja opasana in vaše svetilke prižgane,
“Ẹ di àmùrè yín, kí fìtílà yín sì máa jó.
36 vi sami pa podobni ljudem, ki čakajo na svojega gospodarja, kdaj se bo vrnil s poroke, da kadar pride in potrka, mu lahko takoj odprejo.
Kí ẹ̀yin tìkára yín dàbí ẹni tí ń retí olúwa wọn, nígbà tí òun ó padà ti ibi ìgbéyàwó dé, pé nígbà tí ó bá dé, tí ó sì kànkùn, kí wọn lè ṣí i sílẹ̀ fún un lọ́gán.
37 Blagoslovljeni so tisti služabniki, ki jih bo gospodar, ko pride, našel čuječe. Resnično, pravim vam, da se bo opasal in jih primoral, da se usedejo k obedu in bo prišel naprej ter jim stregel.
Ìbùkún ni fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ náà nígbà tí olúwa náà bá dé tí yóò bá wọn tí wọn ń ṣọ́nà; lóòótọ́ ni mo wí fún yín, yóò di ara rẹ̀ ní àmùrè yóò sì mú wọn jókòó láti jẹun, yóò sì jáde wá láti ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
38 In če bo prišel ob drugi straži ali če pride ob tretji straži in jih najde takó, blagoslovljeni so tisti služabniki.
Bí olúwa wọn bá sì dé nígbà ìṣọ́ kejì, tàbí tí ó sì dé nígbà ìṣọ́ kẹta, tí ó sì bá wọn bẹ́ẹ̀, ìbùkún ni fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ náà.
39 In vedite to, da če bi hišni oče vedel, katero uro bi prišel tat, bi stražil in ne bi dovolil, da bi bila njegova hiša vlomljena.
Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, baálé ilé ìbá mọ wákàtí tí olè yóò wá, òun ìbá máa ṣọ́nà, kì bá tí jẹ́ kí a já wọ inú ilé òun.
40 Bodite torej tudi vi pripravljeni, kajti Sin človekov prihaja ob uri, za katero ne mislite.‹«
Nítorí náà, kí ẹ̀yin múra pẹ̀lú, nítorí Ọmọ Ènìyàn ń bọ̀ ní wákàtí tí ẹ̀yin kò nírètí.”
41 Potem mu je Peter rekel: »Gospod, govoriš to prispodobo nam ali celó vsem?«
Peteru sì wí pé, “Olúwa, ìwọ pa òwe yìí fún wa, tàbí fún gbogbo ènìyàn?”
42 Gospod pa je rekel: »Kdo je potem tisti zvesti in modri oskrbnik, ki ga bo njegov gospodar naredil za vladarja nad njegovo družino, da jim ob pravšnjem obdobju da njihove deleže hrane?
Olúwa sì dáhùn wí pé, “Ta ni olóòtítọ́ àti ọlọ́gbọ́n ìríjú náà, tí olúwa rẹ̀ fi jẹ olórí agbo ilé rẹ̀, láti máa fi ìwọ̀n oúnjẹ wọ́n fún wọn ní àkókò?
43 Blagoslovljen je tisti služabnik, ki ga bo njegov gospodar, ko pride, našel tako početi.
Ìbùkún ni fún ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nígbà tí olúwa rẹ̀ bá dé, tí yóò bá a kí ó máa ṣe bẹ́ẹ̀.
44 Resnično vam povem, da ga bo naredil za vladarja nad vsem, kar ima.
Lóòótọ́ ni mo wí fún yín yóò fi jẹ olórí ohun gbogbo tí ó ní.
45 Toda če pa ta služabnik v svojem srcu reče: ›Moj gospodar odlaša svoj prihod‹ in bo začel pretepati sluge in dekle, jesti in piti ter biti pijan,
Ṣùgbọ́n bí ọmọ ọ̀dọ̀ náà bá wí ní ọkàn rẹ̀, pé, ‘Olúwa mi fi ìgbà bíbọ̀ rẹ̀ falẹ̀!’ Tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í lu àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ àti sí mu àmupara:
46 bo gospodar tega služabnika prišel na dan, ko ga ne pričakuje in ob uri, ki se je ne zaveda in ga bo razsekal narazen ter mu določil njegov delež z neverniki.
Olúwa ọmọ ọ̀dọ̀ náà yóò dé ní ọjọ́ tí kò retí rẹ̀, àti ní wákàtí tí kò dábàá, yóò sì jẹ ẹ́ ní yà gidigidi, yóò sì yan ipò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn aláìgbàgbọ́.
47 Ta služabnik pa, ki je poznal voljo svojega gospodarja in se ni pripravil niti ni storil glede na njegovo voljo, bo pretepen z mnogimi udarci biča.
“Àti ọmọ ọ̀dọ̀ náà, tí ó mọ ìfẹ́ olúwa rẹ̀, tí kò sì múra sílẹ̀, tí kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, òun ni a ó nà púpọ̀.
48 Toda kdor ni vedel, pa je zagrešil stvari, vredne bičanja, bo pretepen z malo udarci biča. Kajti komurkoli je mnogo dano, se bo od njega mnogo zahtevalo, in komur so ljudje mnogo izročili, bodo od njega terjali tem več.
Ṣùgbọ́n èyí tí kò mọ̀, tí ó ṣe ohun tí ó yẹ sí lílù, òun ni a ó lù níwọ̀n. Nítorí ẹnikẹ́ni tí a fún ní púpọ̀, lọ́dọ̀ rẹ̀ ni a ó gbé béèrè púpọ̀: lọ́dọ̀ ẹni tí a bá gbé fi púpọ̀ sí, lọ́dọ̀ rẹ ni a ó gbé béèrè sí i.
49 Prišel sem, da pošljem ogenj na zemljo in kako si želim, da bi bil ta prižgan?
“Iná ni èmi wá láti sọ sí ayé; kín ni èmi sì ń fẹ́ bí kò ṣe kí iná náà ti jo!
50 Toda imam krst, da bom z njim krščen in kako sem omejen, dokler se to ne dovrši!
Ṣùgbọ́n èmi ní bamitiisi kan tí a ó fi bamitiisi mi; ara ti ń ni mí tó títí yóò fi parí!
51 Mislite, da sem prišel, da dam mir na zemljo? Povem vam: ›Ne, temveč prej razkol,
Ẹ̀yin ṣe bí àlàáfíà ni èmi fi sí ayé? Mo wí fún yín, bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n bí kò ṣe ìyapa.
52 kajti odslej jih bo v eni hiši pet razdeljenih, trije proti dvema in dva proti trem.
Nítorí láti ìsinsin yìí lọ, ènìyàn márùn-ún yóò wà ní ilé kan náà tí a ó yà ní ipa, mẹ́ta sí méjì, àti méjì sí mẹ́ta.
53 Oče bo razdeljen proti sinu in sin proti očetu; mati proti hčeri in hči proti materi; tašča proti snahi in snaha proti svoji tašči.‹
A ó ya baba nípa sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọkùnrin sí baba; ìyá sí ọmọbìnrin, àti ọmọbìnrin sí ìyá rẹ̀, ìyá ọkọ sí ìyàwó ọmọ, àti ìyàwó ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀.”
54 Množici pa je rekel tudi: ›Ko vidite oblak dvigati se iz zahoda, nemudoma pravite: ›Dež prihaja, ‹ in tako se zgodi.
Ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pẹ̀lú pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá rí àwọsánmọ̀ tí ó ṣú ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, lọ́gán ni ẹ̀yin yóò sọ pé, ‘Ọ̀wààrà òjò ń bọ̀,’ a sì rí bẹ́ẹ̀.
55 In ko vidite pihati južni veter, pravite: ›Vroče bo, ‹ in tako se pripeti.
Nígbà tí afẹ́fẹ́ gúúsù bá ń fẹ́, ẹ̀yin á ní, ‘Oòrùn yóò mú,’ yóò sì ṣe bẹ́ẹ̀.
56 Vi hinavci, lahko razpoznate obličje neba in zemlje, toda kako to, da ne razpoznate tega časa?
Ẹ̀yin àgàbàgebè! Ẹ̀yin le mòye ojú ọ̀run àti ti ayé. Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin kò mọ àkókò yìí?
57 Da, in zakaj celó sami od sebe ne sodite, kar je prav?
“Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin tìkára yín kò fi ro ohun tí ó tọ́?
58 Ko greš s svojim nasprotnikom k oblastniku, ko si še na poti, se posveti prizadevanju, da boš lahko osvobojen pred njim; da te ta ne bi privlekel k sodniku in sodnik te izroči častniku, častnik pa te vrže v ječo.
Nígbà tí ìwọ bá bá ọ̀tá rẹ lọ sọ́dọ̀ onídàájọ́, rí i pé o bá a parí ọ̀rọ̀ ní ọ̀nà kí ó má ba à fà ọ́ fún adájọ́, adájọ́ a fi ọ́ lé ẹ̀ṣọ́ lọ́wọ́, òun a sì tì ọ́ sínú túbú.
59 Povem ti; ne boš odšel od tam, dokler ne odplačaš tudi zadnjega kovanca.«
Kí èmi wí fún ọ, ìwọ kì yóò jáde kúrò níbẹ̀, títí ìwọ ó fi san ẹyọ owó kan tí ó kù!”

< Luka 12 >