< اعداد 31 >

و خداوند موسی را خطاب کرده، گفت: ۱ 1
Olúwa sọ fún Mose pé,
«انتقام بنی‌اسرائیل را از مدیانیان بگیر، و بعد از آن به قوم خود ملحق خواهی شد.» ۲ 2
“Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”
پس موسی قوم را مخاطب ساخته، گفت: «ازمیان خود مردان برای جنگ مهیا سازید تا به مقابله مدیان برآیند، و انتقام خداوند را از مدیان بکشند. ۳ 3
Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn.
هزار نفر از هر سبط از جمیع اسباطاسرائیل برای جنگ بفرستید.» ۴ 4
Rán ẹgbẹ̀rún ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.”
پس از هزاره های اسرائیل، از هر سبط یک هزار، یعنی دوازده هزار نفر مهیا شده برای جنگ منتخب شدند. ۵ 5
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá mẹ́fà ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun.
و موسی ایشان را هزار نفر از هرسبط به جنگ فرستاد، ایشان را با فینحاس بن العازار کاهن و اسباب قدس و کرناها برای نواختن در دستش به جنگ فرستاد. ۶ 6
Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.
و با مدیان به طوری که خداوند موسی را امر فرموده بود، جنگ کرده، همه ذکوران را کشتند. ۷ 7
Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn.
و در میان کشتگان ملوک مدیان یعنی اوی و راقم و صور و حور و رابع، پنج پادشاه مدیان را کشتند، بلعام بن بعور را به شمشیر کشتند. ۸ 8
Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori.
و بنی‌اسرائیل زنان مدیان واطفال ایشان را به اسیری بردند، و جمیع بهایم وجمیع مواشی ایشان و همه املاک ایشان را غارت کردند. ۹ 9
Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
و تمامی شهرها و مساکن و قلعه های ایشان را به آتش سوزانیدند. ۱۰ 10
Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
و تمامی غنیمت و جمیع غارت را از انسان و بهایم گرفتند. ۱۱ 11
Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.
واسیران و غارت و غنیمت را نزد موسی و العازارکاهن و جماعت بنی‌اسرائیل در لشکرگاه درعربات موآب، که نزد اردن در مقابل اریحاست، آوردند. ۱۲ 12
Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.
و موسی و العازار کاهن و تمامی سروران جماعت بیرون از لشکرگاه به استقبال ایشان آمدند. ۱۳ 13
Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó.
و موسی بر روسای لشکر یعنی سرداران هزاره‌ها و سرداران صدها که از خدمت جنگ باز آمده بودند، غضبناک شد. ۱۴ 14
Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún tí wọ́n ti ogun dé.
و موسی به ایشان گفت: «آیا همه زنان را زنده نگاه داشتید؟ ۱۵ 15
Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí?
اینک اینانند که برحسب مشورت بلعام، بنی‌اسرائیل را واداشتند تا در امر فغور به خداوندخیانت ورزیدند و در جماعت خداوند وباعارض شد. ۱۶ 16
Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa.
پس الان هر ذکوری از اطفال رابکشید، و هر زنی را که مرد را شناخته، با اوهمبستر شده باشد، بکشید. ۱۷ 17
Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin,
و از زنان هردختری را که مرد را نشناخته، و با او همبسترنشده برای خود زنده نگاه دارید. ۱۸ 18
ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.
و شما هفت روز بیرون از لشکرگاه خیمه زنید، و هر شخصی را کشته و هر‌که کشته‌ای را لمس نموده باشد ازشما و اسیران شما در روز سوم و در روز هفتم، خود را تطهیر نماید. ۱۹ 19
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje. Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́.
و هر جامه و هرظرف چرمی و هر‌چه از پشم بز ساخته شده باشد و هرظرف چوبین را تطهیر نمایید.» ۲۰ 20
Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”
و العازار کاهن به مردان جنگی که به مقاتله رفته بودند، گفت: «این است قانون شریعتی که خداوند به موسی‌امر فرموده است: ۲۱ 21
Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose.
طلا و نقره و برنج و آهن و روی و سرب، ۲۲ 22
Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé.
یعنی هر‌چه متحمل آتش بشود، آن را از آتش بگذرانید و طاهر خواهد شد، و به آب تنزیه نیز آن را طاهرسازند و هر‌چه متحمل آتش نشود، آن را از آب بگذرانید. ۲۳ 23
Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi.
و در روز هفتم رخت خود رابشویید تا طاهر شوید، و بعد از آن به لشکرگاه داخل شوید.» ۲۴ 24
Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”
و خداوند موسی را خطاب کرده، گفت: ۲۵ 25
Olúwa sọ fún Mose pé,
«تو و العازار کاهن و سروران خاندان آبای جماعت، حساب غنایمی که گرفته شده است، چه از انسان و چه از بهایم بگیرید. ۲۶ 26
“Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn.
و غنیمت رادر میان مردان جنگی که به مقاتله بیرون رفته‌اند، وتمامی جماعت نصف نما. ۲۷ 27
Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ.
و از مردان جنگی که به مقاتله بیرون رفته‌اند زکات برای خداوندبگیر، یعنی یک نفر از پانصد چه از انسان و چه ازگاو و چه از الاغ و چه از گوسفند. ۲۸ 28
Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà, ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.
از قسمت ایشان بگیر و به العازار کاهن بده تا هدیه افراشتنی برای خداوند باشد. ۲۹ 29
Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.
و از قسمت بنی‌اسرائیل یکی که از هر پنجاه نفر گرفته شده باشد چه ازانسان و چه از گاو و چه از الاغ و چه از گوسفند وچه از جمیع بهایم بگیر، و آنها را به لاویانی که ودیعت مسکن خداوند را نگاه می‌دارند، بده.» ۳۰ 30
Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”
پس موسی و العازار کاهن برحسب آنچه خداوند به موسی‌امر فرموده بود، عمل کردند. ۳۱ 31
Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
و غنیمت سوای آن غنیمتی که مردان جنگی گرفته بودند، از گوسفند ششصد و هفتاد و پنج هزار راس بود. ۳۲ 32
Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.
و از گاو هفتاد و دو هزار راس. ۳۳ 33
Ẹgbàá méjìléláàádọ́rin màlúù
و از الاغ شصت و یک هزار راس. ۳۴ 34
ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
و ازانسان از زنانی که مرد را نشناخته بودند، سی و دوهزار نفر بودند. ۳۵ 35
pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.
و نصفه‌ای که قسمت کسانی بود که به جنگ رفته بودند، سیصد و سی و هفت هزار و پانصد گوسفند بود. ۳۶ 36
Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́: ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.
و زکات خداوند ازگوسفند ششصد و هفتاد و پنج راس بود. ۳۷ 37
Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn;
وگاوان سی و شش هزار بود و از آنها زکات خداوند هفتاد و دو راس بود. ۳۸ 38
ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàádọ́rin;
و الاغها سی هزار و پانصد و از آنها زکات خداوند شصت ویک راس بود. ۳۹ 39
kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta.
و مردمان شانزده هزار و ازایشان زکات خداوند سی و دو نفر بودند. ۴۰ 40
Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n.
وموسی زکات را هدیه افراشتی خداوند بود به العازار کاهن داد، چنانکه خداوند به موسی‌امرفرموده بود. ۴۱ 41
Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
و از قسمت بنی‌اسرائیل که موسی آن را ازمردان جنگی جدا کرده بود، ۴۲ 42
Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun.
و قسمت جماعت از گوسفندان، سیصد و سی هزار وپانصد راس بود. ۴۳ 43
Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn,
و از گاوان سی و شش هزارراس. ۴۴ 44
pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún màlúù
و از الاغها، سی هزار و پانصد راس. ۴۵ 45
tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
واز انسان، شانزده هزار نفر. ۴۶ 46
Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ.
و موسی از قسمت بنی‌اسرائیل یکی را که از هر پنجاه گرفته شده بود، چه از انسان و چه از بهایم گرفت، و آنها را به لاویانی که ودیعت مسکن خداوند را نگاه می‌داشتند، داد، چنانکه خداوند به موسی‌امرفرموده بود. ۴۷ 47
Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.
و روسایی که بر هزاره های لشکر بودند، سرداران هزاره‌ها با سرداران صدها نزد موسی آمدند. ۴۸ 48
Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose.
و به موسی گفتند: «بندگانت حساب مردان جنگی را که زیردست ما می‌باشند گرفتیم، و از ما یک نفر مفقود نشده است. ۴۹ 49
Wọ́n sì sọ fún un pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín.
پس ما ازآنچه هر کس یافته است هدیه‌ای برای خداوندآورده‌ایم از زیورهای طلا و خلخالها ودست بندها و انگشترها و گوشواره‌ها وگردن بندها تا برای جانهای ما به حضور خداوند کفاره شود.» ۵۰ 50
Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”
و موسی و العازار کاهن، طلا وهمه زیورهای مصنوعه را از ایشان گرفتند. ۵۱ 51
Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́.
وتمامی طلای هدیه‌ای که از سرداران هزاره‌ها وسرداران صدها برای خداوند گذرانیدند، شانزده هزار و هفتصد و پنجاه مثقال بود. ۵۲ 52
Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta ṣékélì.
زیرا که هریکی از مردان جنگی غنیمتی برای خود برده بودند. ۵۳ 53
Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀.
و موسی و العازار کاهن، طلا را ازسرداران هزاره‌ها و صدها گرفته، به خیمه اجتماع آوردند تا بجهت بنی‌اسرائیل، به حضور خداوندیادگار باشد. ۵۴ 54
Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.

< اعداد 31 >