< اعداد 30 >

و موسی سروران اسباط بنی‌اسرائیل راخطاب کرده، گفت: «این است کاری که خداوند امر فرموده است: ۱ 1
Mose sì sọ fún olórí àwọn ẹ̀yà ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ,
چون شخصی برای خداوند نذر کند یا قسم خورد تا جان خود را به تکلیفی الزام نماید، پس کلام خود را باطل نسازد، بلکه برحسب هر‌آنچه از دهانش برآمد، عمل نماید. ۲ 2
nígbà tí ọkùnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀ ní ìdè kí òun má bà ba ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ́ kí ó ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sọ.
«و اما چون زن برای خداوند نذر کرده، خودرا در خانه پدرش در جوانی‌اش به تکلیفی الزام نماید، ۳ 3
“Nígbà tí ọmọbìnrin kan bá sì wà ní ilé baba rẹ̀ tó bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀
و پدرش نذر او و تکلیفی که خود را برآن الزام نموده، شنیده باشد، و پدرش درباره اوساکت باشد، آنگاه تمامی نذرهایش استوار، و هرتکلیفی که خود را به آن الزام نموده باشد، قایم خواهد بود. ۴ 4
tí baba rẹ̀ bá sì gbọ́ ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí ìdè rẹ̀ tí kò sì sọ nǹkan kan sí i, kí gbogbo ẹ̀jẹ́ rẹ̀ kí ó dúró àti gbogbo ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ yóò sì dúró.
اما اگر پدرش در روزی که شنید اورا منع کرد، آنگاه هیچ کدام از نذرهایش و ازتکالیفش که خود را به آن الزام نموده باشد، استوار نخواهد بود، و از این جهت که پدرش او رامنع نموده است، خداوند او را خواهد آمرزید. ۵ 5
Ṣùgbọ́n tí baba rẹ̀ bá kọ̀ fun un ní ọjọ́ tí ó gbọ́, kò sí ọ̀kan nínú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí nínú ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tí yóò dúró; Olúwa yóò sì tú u sílẹ̀ nítorí baba rẹ̀ kọ̀ fún un.
«و اگر به شوهری داده شود، و نذرهای او یاسخنی که از لبهایش جسته، و جان خود را به آن الزام نموده، بر او باشد، ۶ 6
“Tí ó bá sì ní ọkọ lẹ́yìn ìgbà tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí lẹ́yìn ìgbà tí ó sọ ọ̀rọ̀ kan láti ẹnu rẹ̀ jáde nínú èyí tí ó fi de ara rẹ̀ ní ìdè,
و شوهرش شنید و درروز شنیدنش به وی هیچ نگفت، آنگاه نذرهایش استوار خواهد ماند. و تکلیفهایی که خویشتن را به آنها الزام نموده است، قایم خواهند ماند. ۷ 7
tí ọkọ rẹ̀ sì gbọ́ nípa èyí ṣùgbọ́n tí kò sọ nǹkan kan, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tó dúró.
لیکن اگر شوهرش در روزی که آن را شنید، او را منع نماید، و نذری را که بر او است یا سخنی را که ازلبهایش جسته، و خویشتن را به آن الزام نموده باشد، باطل سازد، پس خداوند او را خواهدآمرزید. ۸ 8
Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá kọ̀ nígbà tí ó gbọ́, ǹjẹ́ òun yóò mú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tí ó jẹ́ àti ohun tí ó ti ti ẹnu rẹ̀ jáde, èyí tí ó fi de ara rẹ̀ dasán, Olúwa yóò sì dáríjì í.
اما نذر زن بیوه یا مطلقه، در هر‌چه خود را به آن الزام نموده باشد، بر وی استوارخواهد ماند. ۹ 9
“Ṣùgbọ́n ẹ̀jẹ́ kí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè kí ìdè tí opó tàbí obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ bá ṣe yóò wà lórí rẹ̀.
و اما اگر زنی در خانه شوهرش نذر کند، یا خویشتن را با قسم به تکلیفی الزام نماید، ۱۰ 10
“Bí obìnrin tí ó ń gbé pẹ̀lú ọkọ rẹ̀ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí de ara rẹ̀ ní ìdè lábẹ́ ìbúra,
و شوهرش بشنود و او را هیچ نگوید ومنع ننماید، پس تمامی نذرهایش استوار، و هرتکلیفی که خویشتن را به آن الزام نموده باشد، قایم خواهد بود. ۱۱ 11
tí ọkọ rẹ̀ bá sì gbọ́, ṣùgbọ́n tí kò sọ̀rọ̀, tí kò sì kọ̀, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ rẹ̀ yóò dúró.
و اما اگر شوهرش در روزی که بشنود، آنها را باطل سازد. پس هر‌چه ازلبهایش درآمده باشد درباره نذرهایش یا تکالیف خود، استوار نخواهد ماند. چونکه شوهرش آن راباطل نموده است، خداوند او را خواهد آمرزید. ۱۲ 12
Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá sọ wọ́n dasán, nígbà tí ó gbọ́, nígbà náà kò sí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde tí yóò dúró, ọkọ rẹ̀ ti sọ wọ́n dasán, Olúwa yóò tú u sílẹ̀.
هر نذری و هر قسم الزامی را برای ذلیل ساختن جان خود، شوهرش آن را استوار نماید، وشوهرش آن را باطل سازد. ۱۳ 13
Ọkọ rẹ̀ lè ṣe ìwádìí tàbí sọ ọ́ dasán ẹ̀jẹ́ tàbí ìbúra ìdè tí ó ti ṣe láti fi de ara rẹ̀.
اما اگر شوهرش روز به روز به او هیچ نگوید، پس همه نذرهایش وهمه تکالیفش را که بر وی باشد استوار نموده باشد، چونکه در روزی که شنید به وی هیچ نگفت، پس آنها را استوار نموده است. ۱۴ 14
Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ kò bá sọ nǹkan kan sí í nípa rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́, nígbà náà ni ó ṣe ìwádìí nípa ẹ̀jẹ́ àti ìbúra ìdè tí ó dè é. Kí ọkùnrin náà ṣe ìwádìí lórí rẹ̀ láìsọ nípa rẹ̀ si nígbà tí ó gbọ́ nípa rẹ̀.
و اگربعد از شنیدن، آنها را باطل نمود، پس او گناه وی را متحمل خواهد بود.» ۱۵ 15
Bí ó ti wù kí ó rí, bí ọkùnrin náà bá sọ ọ́ dasán, ní àkókò kan lẹ́yìn tí ó ti gbọ́ wọn, nígbà náà ó jẹ̀bi ọ̀rọ̀ náà.”
این است فرایضی که خداوند به موسی‌امرفرمود، در میان مرد و زنش و در میان پدر ودخترش، در زمان جوانی او در خانه پدر وی. ۱۶ 16
Èyí ni ìlànà tí Olúwa fún Mose nípa ìbátan láàrín ọkùnrin àti obìnrin àti láàrín baba àti ọ̀dọ́mọbìnrin rẹ̀ tí ó sì ń gbé ní ilé rẹ̀.

< اعداد 30 >