< Psalms 89 >

1 Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
Hymne d'Éthan l'Ézrahite. Je chanterai toujours les bontés de l'Éternel; D'âge en âge, ma bouche proclamera sa fidélité.
2 Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
J'ai dit: «Ta grâce est un édifice éternel; Tu as établi dans les cieux les fondements de ta fidélité.»
3 Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
— «J'ai conclu, dit l'Éternel, cette alliance avec mon élu; J'ai fait ce serment à David, mon serviteur:
4 ‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
J'affermirai ta postérité pour toujours; J'ai fondé ton trône à jamais.» (Pause)
5 Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
Les cieux, ô Éternel, célèbrent tes merveilles. Ainsi que ta fidélité, dans l'assemblée des saints.
6 Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
Qui, dans les cieux, est comparable à l'Éternel? Qui ressemble à l'Éternel parmi les fils de Dieu?
7 Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
Dieu est très redoutable dans l'assemblée des saints. Plus terrible que tous ceux qui l'entourent.
8 Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
Éternel, Dieu des armées. Qui est puissant comme toi? Éternel, ton amour fidèle Rayonne autour de toi!
9 Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
Tu domptes l'orgueil de la mer: Quand ses vagues s'élèvent, c'est toi qui les apaises.
10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
Tu as écrasé l'Egypte, tu l'as blessée à mort; Par la force de ton bras, tu as dispersé tes ennemis.
11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
A toi sont les cieux, à toi aussi la terre; Tu as fondé le monde et tout ce qu'il renferme.
12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
Le Nord et le Midi, c'est toi qui les as créés; Le Thabor et l'Hermon sont dans l'allégresse A cause de ton nom.
13 Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Ton bras est armé de puissance. Ta main est forte; ta main droite exerce l'autorité suprême.
14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
La justice et le droit sont la base de ton trône; La bonté et la vérité marchent devant ta face.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
Heureux le peuple qui connaît les chants de triomphe: Il s'avance à la clarté de ta face, ô Éternel!
16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
Il se réjouit en célébrant ton nom chaque jour, Et il se glorifie de ta justice.
17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
Car c'est toi qui es la splendeur de notre puissance. Et c'est ta faveur qui nous fait relever la tête.
18 Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Oui, notre bouclier protecteur Est dans les mains de l'Éternel: Notre roi appartient au Saint d'Israël!
19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
Tu parlas jadis dans une vision à tes bien-aimés, Et tu dis: J'ai prêté mon appui à un héros; J'ai choisi dans les rangs du peuple un élu.
20 Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
J'ai trouvé David, mon serviteur; Je l'ai oint de mon huile sainte.
21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
Ma main le soutiendra, Et mon bras le fortifiera.
22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
L'ennemi ne pourra le surprendre, Et le méchant ne l'opprimera point.
23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
Je briserai devant lui ses adversaires. Et je frapperai ceux qui le haïssent.
24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
Ma fidélité et ma bonté seront avec lui, Et par la puissance de mon nom, il pourra relever la tête.
25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
J'étendrai sa main puissante sur la mer. Et son empire sur les fleuves.
26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
Il m'invoquera, disant: «Tu es mon Père, Mon Dieu, mon rocher protecteur.»
27 Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
Aussi ferai-je de lui le premier-né, Le souverain des rois de la terre.
28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
Je lui conserverai ma faveur éternellement, Et mon alliance avec lui sera inébranlable.
29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
Je lui donnerai une postérité éternelle. Et son trône durera autant que les cieux.
30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
Si ses fils abandonnent ma loi Et n'obéissent pas à mes ordres,
31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
S'ils violent mes commandements Et s'ils n'observent pas mes préceptes,
32 nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
Je châtierai leurs transgressions en les frappant de la verge, Et leurs iniquités en leur envoyant des fléaux.
33 ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
Mais je ne leur retirerai pas ma faveur; Je ne mentirai pas à mes promesses.
34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
Je ne violerai pas mon alliance. Et je ne changerai pas la parole sortie de mes lèvres.
35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
J'en ai fait le serment, au nom de ma sainteté: Je ne mentirai pas à David.
36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
Sa postérité durera éternellement; Son trône subsistera devant moi aussi longtemps que le soleil.
37 A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
Comme la lune, il sera inébranlable à jamais; Le témoin qui est dans les cieux est fidèle. (Pause)
38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
Cependant, tu as repoussé ton oint; tu l'as rejeté, Tu t'es indigné contre lui.
39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
Tu as rompu l'alliance conclue avec ton serviteur; Tu as traîné sa couronne dans la poussière.
40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
Tu as renversé toutes ses forteresses: Tu as mis en ruines ses remparts.
41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
Tous les passants le mettent au pillage; Il est couvert d'opprobre par ses voisins.
42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
Tu as fortifié le bras de ses adversaires; Tu as rempli de joie tous ses ennemis.
43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
Tu as émoussé le tranchant de son épée. Et tu ne l'as pas soutenu dans le combat.
44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
Tu as mis fin à sa splendeur, Et tu as jeté son trône à terre.
45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
Tu as abrégé les jours de sa jeunesse. Et tu l'as couvert de honte. (Pause)
46 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
Jusques à quand, ô Éternel, te cacheras-tu sans cesse. Et ta colère brûlera-t-elle comme un feu?
47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
Rappelle-toi quelle est la durée de ma vie. Pour quel néant tu as créé tous les fils des hommes!
48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol h7585)
Quel homme pourrait vivre et ne pas voir la mort? Qui sauvera son âme de la puissance du Sépulcre? (Pause) (Sheol h7585)
49 Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
Seigneur, où sont tes bontés premières, Que toi, le Dieu fidèle, tu avais promises à David par serment?
50 Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
Souviens-toi, Seigneur, de l'opprobre de tes serviteurs; Je porte en mon sein l'injure de tant de grands peuples!
51 ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
Car tes ennemis ont jeté l'outrage, ô Éternel, Tes ennemis ont jeté l'outrage sur les pas de ton oint.
52 Olùbùkún ní Olúwa títí láé.
Béni soit l'Éternel a perpétuité! Amen, Amen!

< Psalms 89 >