< Psalms 73 >

1 Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
Psalm Asafa. Doprawdy Bóg [jest] dobry dla Izraela; dla tych, którzy są czystego serca.
2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
Ale moje nogi niemal się potknęły, moje kroki omal się nie zachwiały;
3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
Bo zazdrościłem głupcom, widząc pomyślność niegodziwych.
4 Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
Nie mają bowiem więzów aż do śmierci, ale w całości zostaje ich siła.
5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
Nie doznają trudu ludzkiego ani cierpień jak inni ludzie.
6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
Dlatego są opasani pychą jak złotym łańcuchem i odziani w okrucieństwo jak w szatę ozdobną.
7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
Ich oczy wystają od tłuszczu; mają więcej niż serce mogłoby sobie życzyć.
8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
Oddali się rozpuście i mówią przewrotnie o ucisku, mówią wyniośle.
9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
Zwracają swe usta przeciwko niebu, a ich język krąży po ziemi.
10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Dlatego jego lud wraca dotąd i obficie leją się na nich wody;
11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
Bo mówią: Jakże Bóg może o tym wiedzieć? Czy Najwyższy ma wiedzę?
12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
Oto ci są niegodziwi, a powodzi im się na świecie i pomnażają bogactwa.
13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
A więc na próżno oczyściłem swoje serce i w niewinności obmywałem ręce.
14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
Cały dzień bowiem znoszę cierpienia i co rano jestem chłostany.
15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
Gdybym powiedział: Będę mówił tak samo, skrzywdziłbym ród twoich synów.
16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
Starałem się to rozumieć, ale było dla mnie zbyt trudne;
17 títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
Aż wszedłem do świątyni Bożej [i] tu zrozumiałem, jaki jest ich koniec.
18 Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
Doprawdy na śliskich miejscach ich postawiłeś i strącasz ich na zatracenie.
19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
[Oto] jak doznali zguby! Nagle niszczeją, strawieni przerażeniem.
20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
Jak sen po przebudzeniu, Panie, gdy się ockniesz, wzgardzisz ich obrazem.
21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
Gdy gorycz miałem w sercu, a w nerkach czułem kłucie;
22 mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
Byłem głupi i nic nie rozumiałem, byłem przed tobą [jak] zwierzę.
23 Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
A jednak zawsze [jestem] z tobą, [bo] mnie trzymałeś za prawą rękę.
24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
Poprowadzisz mnie według swej rady, a potem przyjmiesz mnie do chwały.
25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
Kogo [innego] mam w niebie? I na ziemi oprócz ciebie w nikim [innym] nie mam upodobania.
26 Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
Choć moje ciało i serce ustanie, Bóg jest skałą mego serca i moim dziedzictwem na wieki.
27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
Oto bowiem ci, którzy się oddalają od ciebie, zginą; wytracasz tych, którzy cudzołożą, [odstępując] od ciebie.
28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.
Mnie zaś dobrze jest zbliżyć się do Boga; pokładam w Panu BOGU moją ufność, aby opowiadać wszystkie jego dzieła.

< Psalms 73 >