< Psalms 48 >

1 Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora. Ẹni ńlá ní Olúwa, tí ó sì yẹ láti máa yìn ní ìlú Ọlọ́run wa, lórí òkè mímọ́ rẹ̀.
Pieśń i psalm dla synów Korego. Wielki jest PAN i godzien wielkiej chwały w mieście naszego Boga, na swej świętej górze.
2 Ó dára nínú ipò ìtẹ́ rẹ̀, ayọ̀ gbogbo ayé, òkè Sioni, ní ìhà àríwá ní ìlú ọba ńlá.
Pięknie wzniesiona, radością całej ziemi [jest] góra Syjon na krańcach północy, miasto wielkiego Króla.
3 Ọlọ́run wà nínú ààbò ààfin rẹ̀; ó fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ odi alágbára.
Bóg w pałacach jego jest uznany za twierdzę.
4 Nígbà tí àwọn ọba kógun jọ pọ̀, wọ́n jùmọ̀ ń kọjá lọ.
Bo oto zgromadzili się królowie i razem ruszyli.
5 Wọn rí i, bẹ́ẹ̀ ni ẹnu sì yà wọ́n, a yọ wọ́n lẹ́nu, wọ́n yára lọ.
Gdy zobaczyli, zdumieli się, przerazili się i uciekli.
6 Ẹ̀rù sì bà wọ́n níbẹ̀, ìrora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó wà nínú ìrọbí.
Strach ich tam ogarnął i ból, jak rodzącą kobietę.
7 Ìwọ bà wọ́n jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọkọ̀ orí omi Tarṣiṣi, wọ́n fọ́nká láti ọwọ́ ìjì ìlà-oòrùn.
Wiatrem wschodnim rozbijasz okręty Tarszisz.
8 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwa rí, ní inú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ìlú Ọlọ́run wa, Ọlọ́run jẹ́ kí ó wà ní abẹ́ ààbò títí láéláé. (Sela)
To, co słyszeliśmy, [to] zobaczyliśmy w mieście PANA zastępów, w mieście naszego Boga; Bóg je ugruntuje na wieki. (Sela)
9 Láàrín tẹmpili rẹ, Ọlọ́run, àwa ti ń sọ ti ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Rozważamy, o Boże, twoje miłosierdzie we wnętrzu twej świątyni.
10 Gẹ́gẹ́ bí orúkọ rẹ Ọlọ́run, ìyìn rẹ̀ dé òpin ayé, ọwọ́ ọ̀tún rẹ kún fún òdodo.
Jak twoje imię, Boże, tak i chwała twoja [sięga] aż po krańce ziemi; twoja prawica pełna jest sprawiedliwości.
11 Jẹ́ kí òkè Sioni kí ó yọ̀ kí inú àwọn ọmọbìnrin Juda kí ó dùn nítorí ìdájọ́ rẹ.
Niech się weseli góra Syjon, niech się radują córki Judy z powodu twoich sądów.
12 Rìn Sioni kiri lọ yíká rẹ̀, ka ilé ìṣọ́ rẹ̀.
Okrążcie Syjon i obejdźcie go, policzcie jego wieże.
13 Kíyèsi odi rẹ̀, kíyèsi àwọn ààfin rẹ̀ kí ẹ̀yin lè máa wí fún ìran tí ń bọ̀.
Przyjrzyjcie się jego wałom obronnym, oglądajcie jego pałace, abyście mogli opowiadać przyszłemu pokoleniu.
14 Nítorí Ọlọ́run yìí Ọlọ́run wà ní títí ayé, Òun ni yóò ṣe amọ̀nà wa títí dè òpin ayé.
Bo ten Bóg jest naszym Bogiem na wieki wieków, on będzie nas prowadził aż do śmierci.

< Psalms 48 >