< Psalms 24 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
Psalm Dawida. Do PANA należy ziemia i wszystko, co ją napełnia, świat i jego mieszkańcy.
2 nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
Na morzach bowiem ugruntował go i utwierdził na rzekach.
3 Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
Któż wstąpi na górę PANA? Kto stanie w jego świętym miejscu?
4 Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
[Człowiek] rąk nieskalanych i czystego serca, który nie skłania swej duszy ku marności i nie przysięga podstępnie.
5 Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
On otrzyma błogosławieństwo od PANA i sprawiedliwość od Boga, swego Zbawiciela.
6 Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
To jest pokolenie tych, którzy go szukają, którzy szukają twego oblicza, [Boże] Jakuba. (Sela)
7 Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
Podnieście, o bramy, wasze głowy; podnieście się, wrota odwieczne, aby wszedł Król chwały.
8 Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
Któż jest tym Królem chwały? PAN mocny i potężny, PAN potężny w boju.
9 Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
Podnieście, o bramy, wasze głowy; podnieście się, wrota odwieczne, aby wszedł Król chwały.
10 Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)
Któż jest tym Królem chwały? PAN zastępów, on [jest] Królem chwały. (Sela)

< Psalms 24 >