< Psalms 18 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ Olúwa tí ó kọ sí Olúwa, ọ̀rọ̀ orin tí ó kọ sí Olúwa fún ìdáǹdè kúrò lọ́wọ́ Saulu ọ̀tá rẹ̀. Ó wí pé. Mo fẹ́ ọ, Olúwa, agbára mi.
gdy go PAN ocalił z rąk wszystkich jego wrogów i z ręki Saula. Powiedział wtedy: Będę cię miłował, PANIE, mocy moja.
2 Olúwa ni àpáta àti odi mi, àti olùgbàlà mi; Ọlọ́run mi ni àpáta mi, ẹni tí mo fi ṣe ibi ìsádi mi. Òun ni àpáta ààbò àti ìwo ìgbàlà mi àti ibi ìsádi mi.
PAN moją skałą, moją twierdzą i wybawicielem. Mój Bóg moją opoką, której będę ufał, moją tarczą i rogiem mego zbawienia, moją warownią.
3 Mo ké pe Olúwa, ẹni tí ìyìn yẹ fún, a ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi.
Wezwę PANA, [który jest] godny chwały, a będę wybawiony od moich wrogów.
4 Ìrora ikú yí mi kà, àti ìṣàn omi àwọn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Ogarnęły mnie boleści śmierci i zatrwożyły mnie potoki bezbożnych.
5 Okùn isà òkú yí mi ká, ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí. (Sheol h7585)
Boleści piekła mnie oplotły, pochwyciły mnie sidła śmierci. (Sheol h7585)
6 Nínú ìpọ́njú mo ké pe Olúwa; mo sọkún sí Olúwa mi fún ìrànlọ́wọ́. Láti inú tẹmpili rẹ̀, ó gbọ́ igbe mi; ẹkún mi wá sí iwájú rẹ̀, sí inú etí rẹ̀.
W moim utrapieniu wzywałem PANA i wołałem do mego Boga. Ze swojej świątyni usłyszał mój głos, a moje wołanie dotarło przed jego oblicze, do jego uszu.
7 Ayé wárìrì, ó sì mì tìtì, ìpìlẹ̀ àwọn òkè gíga sì ṣídìí; wọ́n wárìrì nítorí tí ó ń bínú.
Wtedy ziemia poruszyła się i zadrżała, a posady gór zatrzęsły się i zachwiały od jego gniewu.
8 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá; iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá, ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
Z jego nozdrzy unosił się dym, z jego ust [buchnął] ogień trawiący, węgle zapaliły się od niego.
9 Ó pín àwọn ọ̀run, Ó sì jáde wá; àwọsánmọ̀ dúdú sì wà ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
Nachylił niebiosa i zstąpił, a ciemność [była] pod jego stopami.
10 Ó gun orí kérúbù, ó sì fò; ó ń rábàbà lórí ìyẹ́ apá afẹ́fẹ́.
Dosiadł cherubina i latał; latał na skrzydłach wiatru.
11 Ó fi òkùnkùn ṣe ibojì rẹ̀, ó fi ṣe ìbòrí yí ara rẹ̀ ká kurukuru òjò dúdú ní ojú ọ̀run.
Z ciemności zrobił sobie ukrycie, namiotem wokół niego były ciemne wody i gęste obłoki nieba.
12 Nípa ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀, àwọsánmọ̀ ṣíṣú dudu rẹ kọjá lọ pẹ̀lú yìnyín àti ẹ̀yín iná
Przed jego blaskiem rozeszły się jego obłoki, grad i węgle ogniste.
13 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá; Ọ̀gá-ògo sì fọ ohun rẹ̀; yìnyín àti ẹ̀yin iná.
I zagrzmiał PAN na niebiosach, Najwyższy wydał swój głos, grad i węgle ogniste.
14 Ó ta àwọn ọfà rẹ̀, ó sì tú àwọn ọ̀tá náà ká, ọfà mọ̀nàmọ́ná ńlá sì dà wọ́n rú.
Wypuścił swe strzały i rozproszył ich, [cisnął] błyskawicami i ich rozgromił.
15 A sì fi ìsàlẹ̀ àwọn òkun hàn, a sì rí àwọn ìpìlẹ̀ ayé nípa ìbáwí rẹ, Olúwa, nípa fífún èémí ihò imú rẹ.
I ukazały się głębiny wód, i odsłoniły się fundamenty świata od twojego upomnienia, PANIE, i od podmuchu tchnienia twoich nozdrzy.
16 Ó sọ̀kalẹ̀ láti ibi gíga, ó sì dì mímú; Ó fà mí jáde láti inú omi jíjìn.
Posłał z wysoka, chwycił mnie, wyciągnął mnie z wielkich wód.
17 Ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára, láti ọwọ́ àwọn ọ̀tá, ti ó lágbára jù fún mi.
Ocalił mnie od potężnego wroga mego i od tych, którzy mnie nienawidzą, choć byli ode mnie mocniejsi.
18 Wọ́n dojúkọ mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi; ṣùgbọ́n Olúwa ni alátìlẹ́yìn mi.
Zaskoczyli mnie w dniu mego utrapienia, lecz PAN był moją podporą.
19 Ó mú mi jáde wá sínú ibi ńlá; Ó gbà mí nítorí tí ó ní inú dídùn sí mi.
Wyprowadził mnie na miejsce przestronne, wybawił mnie, bo mnie sobie upodobał.
20 Olúwa ti hùwà sí mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi, ó ti fi èrè fún mi.
Nagrodził mnie PAN według mojej sprawiedliwości, oddał mi według czystości moich rąk.
21 Nítorí mo ti pa ọ̀nà Olúwa mọ́; èmi kò ṣe búburú nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
Strzegłem bowiem dróg PANA i nie odstąpiłem niegodziwie od mego Boga.
22 Gbogbo òfin rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; èmi kò sì yípadà kúrò nínú ìlànà rẹ̀.
Bo miałem przed oczyma wszystkie jego nakazy i nie odrzucałem od siebie jego praw.
23 Mo ti jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú rẹ̀; mo sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
Byłem wobec niego nienaganny i wystrzegałem się swojej nieprawości.
24 Olúwa san ẹ̀san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi níwájú rẹ̀.
Dlatego oddał mi PAN według mojej sprawiedliwości, według czystości moich rąk przed jego oczyma.
25 Fún olóòtítọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní olóòtítọ́, sí aláìlẹ́bi, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní aláìlẹ́bi,
[Ty] z miłosiernym miłosiernie się obejdziesz, a z człowiekiem nienagannym postąpisz nienagannie.
26 sí ọlọ́kàn mímọ́, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní ọlọ́kàn mímọ́, ṣùgbọ́n sí ọlọ́kàn-wíwọ́, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní òǹrorò.
Wobec czystego okażesz się czysty, a wobec przewrotnego postąpisz przewrotnie;
27 O pa onírẹ̀lẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ó rẹ àwọn ti ń gbéraga sílẹ̀.
Ty bowiem lud strapiony wybawisz, a oczy wyniosłe poniżysz.
28 Ìwọ, Olúwa, jẹ́ kí fìtílà mi kí ó máa tàn; Ọlọ́run mi, yí òkùnkùn mi padà sí ìmọ́lẹ̀.
Bo ty zapalisz moją pochodnię; PAN, Bóg mój, rozjaśni moje ciemności.
29 Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ rẹ̀, èmi sáré tọ ogun lọ; pẹ̀lú Ọlọ́run mi mo lè fo odi kan.
Bo z tobą przebiłem się przez wojsko, z moim Bogiem przeskoczyłem mur.
30 Bí ó ṣe ti Ọlọ́run mi, ọ̀nà rẹ̀ pé, a ti rídìí ọ̀rọ̀ Olúwa òun ni àpáta ààbò fún gbogbo àwọn tí ó fi ṣe ààbò.
Droga Boga [jest] doskonała, słowo PANA w ogniu wypróbowane. Tarczą jest dla wszystkich, którzy mu ufają.
31 Nítorí ta ni ṣe Ọlọ́run bí kò ṣe Olúwa? Ta ní àpáta bí kò ṣe Olúwa wa?
Bo któż jest Bogiem oprócz PANA? Któż skałą oprócz naszego Boga?
32 Ọlọ́run ni ẹni tí ó fi agbára dì mí ní àmùrè ó sì mú ọ̀nà mi pé.
To Bóg, który przepasuje mnie mocą i doskonałą czyni moją drogę.
33 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi gẹ́gẹ́ bi ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó jẹ́ ki n lè dúró lórí ibi gíga.
Moje nogi czyni jak u łani i stawia mnie na wyżynach.
34 Ó kọ́ ọwọ́ mi ni ogun jíjà; apá mi lè tẹ ọrùn idẹ.
Ćwiczy moje ręce do walki, tak że mogę kruszyć spiżowy łuk swymi ramionami.
35 Ìwọ fi asà ìṣẹ́gun rẹ̀ fún mi, ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ gbé mí dúró; àti ìwà pẹ̀lẹ́ rẹ̀ sọ mí di ńlá.
Dałeś mi też tarczę swego zbawienia i wspierała mnie twoja prawica, a twoja dobrotliwość uczyniła mnie wielkim.
36 Ìwọ sọ ìrìn ẹsẹ̀ mi di ńlá ní ìsàlẹ̀ mi, kí kókó-ẹsẹ̀ mi má ṣe yẹ̀.
Rozszerzyłeś ścieżkę dla mych kroków, tak że moje stopy się nie zachwiały.
37 Èmi lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì bá wọn èmi kò sì padà lẹ́yìn wọn títí a fi run wọ́n.
Ścigałem moich wrogów i dopadłem [ich], nie zawróciłem, aż ich nie wytraciłem.
38 Èmi sá wọn ní ọgbẹ́ tí wọn ko fi le è dìde; wọ́n ṣubú ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi.
Powaliłem ich tak, że nie mogli powstać, upadli pod moje stopy.
39 Nítorí ìwọ fi agbára dì mí ní àmùrè fún ogun náà; ìwọ ti mú àwọn tí ó dìde si mí tẹríba ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi.
Przepasałeś mnie mocą do walki, powaliłeś pod moje stopy moich przeciwników.
40 Ìwọ yí ẹ̀yìn àwọn ọ̀tá mí padà sí mi èmi sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
Zmuszałeś moich wrogów do ucieczki, abym wykorzenił tych, którzy mnie nienawidzą.
41 Wọ́n kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbà wọ́n, àní sí Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá wọn lóhùn.
Wołali, lecz nie [było] nikogo, kto by [ich] wybawił; [wołali] do PANA, lecz ich nie wysłuchał.
42 Mo lù wọ́n gẹ́gẹ́ bí eruku níwájú afẹ́fẹ́; mo dà wọ́n síta gẹ́gẹ́ bí ẹrọ̀fọ̀.
Starłem ich jak proch na wietrze, wyrzuciłem jak błoto uliczne.
43 Ìwọ ti gbà mí lọ́wọ́ ìkọlù àwọn ènìyàn; Ìwọ ti fi mí ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn ti èmi kò mọ, yóò sì máa sìn mí,
Wyzwoliłeś mnie od kłótni ludzkich, ustanowiłeś mnie głową narodów. Będzie mi służył lud, którego nie znałem.
44 ni wéré ti wọ́n gbọ́ ohùn mi, wọ́n pa àṣẹ mi mọ́; àwọn ọmọ àjèjì yóò tẹríba fún mi.
Jak tylko usłyszą [o mnie], będą mi posłuszni, cudzoziemcy będą udawać uległość.
45 Àyà yóò pá àlejò; wọn yóò sì fi ìbẹ̀rù jáde láti ibi kọ́lọ́fín wọn.
Cudzoziemcy zmarnieją i będą drżeć w swoich warowniach.
46 Olúwa wà láààyè! Olùbùkún ni àpáta mi! Gbígbéga ní Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
PAN żyje, [niech będzie] błogosławiona moja skała, niech będzie wywyższony Bóg mego zbawienia.
47 Òun ni Ọlọ́run tí ó ń gbẹ̀san mi, tí ó sì ń ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní abẹ́ mi,
Bóg dokonuje za mnie zemsty i poddaje mi narody.
48 tí ó pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mí. Ìwọ gbé mi ga ju àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí mi lọ; lọ́wọ́ àwọn ènìyàn alágbára ni ìwọ ti gbà mí.
[Ty] wyzwalasz mnie od moich wrogów; ty wywyższyłeś mnie ponad moich przeciwników, ocaliłeś mnie od gwałtownika.
49 Títí láéláé, èmi yóò máa yìn ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ Olúwa; èmi yóò sì máa kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ.
Dlatego będę cię, PANIE, sławił wśród narodów i będę śpiewał twemu imieniu.
50 Ó fún ọba rẹ̀ ni ìṣẹ́gun ńlá; ó fi ìkáàánú àìṣẹ̀tàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Dafidi àti ìran rẹ̀ títí láé.
Bo dajesz wielkie wybawienie swemu królowi i na wieki okazujesz miłosierdzie swemu pomazańcowi Dawidowi i jego potomstwu.

< Psalms 18 >