< Psalms 147 >

1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa, ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!
Chwalcie PANA, bo dobrze [jest] śpiewać naszemu Bogu; jest [to] bowiem miłe i piękna jest chwała.
2 Olúwa kọ́ Jerusalẹmu; Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.
PAN buduje Jeruzalem [i] gromadzi rozproszonych Izraela.
3 Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.
On uzdrawia skruszonych w sercu i opatruje ich rany.
4 Ó ka iye àwọn ìràwọ̀ ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ.
On liczy gwiazdy, nazywa każdą z nich po imieniu.
5 Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára òye rẹ̀ kò sì ní òpin.
Wielki [jest] nasz Pan i zasobny w moc; jego mądrość jest niezmierzona.
6 Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.
PAN podnosi pokornych, [a] niegodziwych poniża aż do ziemi.
7 Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwa fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.
Śpiewajcie PANU z dziękczynieniem; śpiewajcie naszemu Bogu przy dźwiękach harfy;
8 Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀ ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè
Który okrywa niebiosa obłokami [i] przygotowuje deszcz dla ziemi; który sprawia, że trawa rośnie na górach;
9 Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.
Który daje pokarm bydłu i młodym krukom wołającym [do niego].
10 Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin, bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin
Nie lubuje się w mocy konia ani nie ma upodobania w goleniach mężczyzny.
11 Olúwa ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.
PAN ma upodobanie w tych, którzy się go boją, którzy ufają jego miłosierdziu.
12 Yin Olúwa, ìwọ Jerusalẹmu; yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.
Chwal PANA, Jeruzalem; chwal swego Boga, Syjonie.
13 Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára, Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ
On bowiem umacnia zasuwy twoich bram i błogosławi synów twoich pośród ciebie.
14 Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀, òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.
Zapewnia pokój w twoich granicach i syci cię najwyborniejszą pszenicą.
15 Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.
On wysyła swój rozkaz na ziemię; szybko biegnie jego słowo.
16 Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú
On daje śnieg jak wełnę, rozsypuje szron jak popiół.
17 Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀
Rzuca swój lód jak okruchy; któż ostoi się przed jego zimnem?
18 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́ ó sì mú odò rẹ̀ sàn.
Posyła swoje słowo i [lody] topnieją; wionie swym wiatrem i wody spływają.
19 Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli.
Oznajmia swe słowo Jakubowi, swe prawa i sądy Izraelowi.
20 Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀ wọn ko mọ òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Nie uczynił tak żadnemu narodowi, nie poznali jego sądów. Alleluja.

< Psalms 147 >