< Psalms 145 >

1 Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
E HIILANI aku no au ia oe, e ko'u Akua, e ke Alii, E hoomaikai aku no wau i kou inoa, A hiki a kau, a mau loa aku no.
2 Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
I na la a pau, e hoomaikai aku no au ia oe; A e halelu aku i kou inoa, A hiki a kau, a mau loa aku no.
3 Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
He nui no o Iehova, a ua pono ke halelu nui ia'ku oia; Aole e pau kona nui i ka ikeia ma ka huli ana.
4 Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
E hookaulana aku kekahi hanauna i kau mau hana a i kekahi hanauna, A e hoike aku hoi i kou mau mea nui.
5 Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
E hoike aku no wau i ka nani ihiihi o kou hanohano, A me na mea o kau mau hana kupanaha.
6 Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
E hai aku no hoi lakou i ka mana o kau mau hana weliweli; A e hoike aku no wau i kou nui.
7 Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
E hoikeike no lakou i ka hoomanao i kou maikai nui, A e hauoli no lakou i kou pono.
8 Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
He aloha, a he lokomaikai o Iehova; He lohi ma ka huhu, a nui wale hoi kona aloha.
9 Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
He maikai no o Iehova i na mea a pau; A aia hoi kona lokomaikai maluna o kana mau hana a pau.
10 Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
E mililani aku kau mau hana a pau ia oe, e Iehova, A e hoomaikai aku kou poe haipule ia oe.
11 Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
E olelo no lakou i ka nani o kou aupuni, A e kamailio no hoi i kou mana;
12 kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
E hoikeike aku i kona mau mea nui i na keiki a kanaka, A me ka nani hanohano o kona aupuni.
13 Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
He aupuni mau loa no kou aupuni, A ua mau hoi kou alii ana, a i na hanauna a pau.
14 Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
Ua kokua no o Iehova i ka poe hina a pau, A hoala mai no hoi oia i ka poe a pau i kulou ilalo.
15 Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
Kakali no na maka o na mea a pau ia oe, A haawi mai oe i ka lakou ai i ka wa pono.
16 Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
Hohola aku oe i kou poholima, A hoomaona mai i ka makemake o na mea ola a pau.
17 Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
He pono no o Iehova i kona mau aoao a pau, A ua lokomaikai hoi ma na hana ana a pau.
18 Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
Ua kokoke mai o Iehova i ka poe a pau e kahea aku ia ia, I ka poe hoi i kahea aku ia ia ma ka oiaio.
19 Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
E hana mai no o Iehova i ka makemake o ka poe i makau aku ia ia, E hoolohe mai no hoi oia i ka lakou pule a e hoola ia lakou.
20 Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
Malama mai no o Iehova i ka poe a pau i aloha aku ia ia; Aka, e luku mai no oia i ka poe hewa a pau.
21 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.
E hai aku no ko'u waha i na halelu o Iehova; A e hoomaikai aku hoi na mea ola a pau i kona inoa hoano, A hiki a kau, a mau loa aku no.

< Psalms 145 >