< Psalms 12 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́; olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
Przewodnikowi chóru, na Seminit. Psalm Dawida. Ratuj, PANIE, bo [już] nie ma pobożnego, zniknęli wierni spośród synów ludzkich.
2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
Wszyscy mówią kłamliwie do bliźniego, mówią schlebiającymi wargami i z obłudnym sercem.
3 Kí Olúwa kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
Niech PAN wytępi wszystkie wargi schlebiające [i] język mówiący przechwałki.
4 tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
Oni mówią: Swoim językiem zwyciężymy, nasze wargi należą do nas, któż jest naszym panem?
5 “Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
Ze względu na ucisk ubogich [i] jęk nędzarzy teraz powstanę – mówi PAN – zapewnię bezpieczeństwo [temu], na kogo zastawiają sidła.
6 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
Słowa PANA to słowa czyste jak srebro wypróbowane w ziemnym tyglu, siedmiokrotnie oczyszczone.
7 Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
Ty, PANIE, zachowasz ich, będziesz ich strzegł od tego pokolenia aż na wieki.
8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.
Niegodziwi krążą wokoło, gdy najpodlejsi z ludzi zostają wywyższeni.

< Psalms 12 >