< Psalms 119 >

1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
Alef Błogosławieni ci, których droga jest nieskalana, którzy zgodnie z prawem PANA postępują.
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Błogosławieni ci, którzy strzegą jego świadectw i szukają go całym sercem;
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
[Którzy] nie czynią nieprawości, [ale] chodzą jego drogami.
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Ty rozkazałeś pilnie przestrzegać twoich nakazów.
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
Oby moje drogi były skierowane na przestrzeganie twoich praw!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Wtedy nie doznam wstydu, gdy będę zważał na wszystkie twoje przykazania.
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Będę cię wysławiał w szczerości serca, gdy nauczę się twoich sprawiedliwych praw.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
Będę przestrzegał twoich praw, nigdy mnie nie opuszczaj.
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Bet W jaki sposób oczyści młodzieniec swoją ścieżkę? Gdy zachowuje się według twego słowa.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Z całego serca cię szukam, nie pozwól mi zboczyć od twoich przykazań.
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
W swoim sercu zachowuję twoje słowa, aby nie zgrzeszyć przeciwko tobie.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Błogosławiony jesteś, PANIE; naucz mnie twoich praw.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
Swoimi wargami opowiadam wszystkie nakazy twoich ust.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
Cieszę się drogą twoich świadectw bardziej niż z wszelkiego bogactwa.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
Rozmyślam o twoich przykazaniach i przypatruję się twoim drogom.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
Rozkoszuję się twoimi prawami i nie zapominam twoich słów.
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Gimel Okaż dobroć swemu słudze, [abym] żył i przestrzegał twoich słów.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Otwórz moje oczy, abym ujrzał cuda twego prawa.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Jestem obcym na ziemi, nie ukrywaj przede mną twoich przykazań.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
Moja dusza omdlewa, tęskniąc cały czas za twoimi sądami.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Zgromiłeś pysznych, przeklęci [są ci], którzy odstępują od twoich przykazań.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Oddal ode mnie hańbę i wzgardę, gdyż przestrzegam twoich świadectw.
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Władcy też zasiadają i mówią przeciwko mnie, lecz twój sługa rozmyśla o twoich prawach.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
Twoje świadectwa też są moją rozkoszą [i] moimi doradcami.
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Dalet Moja dusza przylgnęła do prochu, ożyw mnie według twego słowa.
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Opowiedziałem [ci] moje drogi i wysłuchałeś mnie; naucz mnie twoich praw.
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Spraw, bym zrozumiał drogę twoich nakazów, a będę rozmyślał o twoich cudownych dziełach.
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Dusza moja rozpływa się [we łzach] ze smutku, umocnij mnie według twego słowa.
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
Oddal ode mnie drogę kłamstwa, a obdarz mnie swoim prawem.
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
Wybrałem drogę prawdy, a twoje nakazy stawiam [przed sobą].
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Przylgnąłem do twoich świadectw; PANIE, nie pozwól mi zaznać wstydu.
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
Pobiegnę drogą twoich przykazań, gdy rozszerzysz moje serce.
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
He Naucz mnie, PANIE, drogi twoich praw, a będę jej strzegł [aż] do końca.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Daj mi rozum, abym zachował twoje prawo; żebym go przestrzegał z całego serca.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Spraw, bym chodził ścieżką twoich przykazań, gdyż w nich mam upodobanie.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Nakłoń moje serce do twoich świadectw, a nie do chciwości.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Odwróć moje oczy, aby nie patrzyły na marność, ożyw mnie na twojej drodze.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Utwierdź swoje słowo względem twego sługi, który się oddał twojej bojaźni.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Oddal ode mnie mą hańbę, której się boję, bo twoje sądy [są] dobre.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
Oto pragnę twoich nakazów; ożyw mnie w swej sprawiedliwości.
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Waw Niech zstąpi na mnie twoja łaskawość, PANIE, twoje zbawienie według twego słowa;
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
Abym mógł dać odpowiedź temu, który mi urąga, bo ufam twojemu słowu.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
I nie wyjmuj z moich ust słowa prawdy, bo twoich sądów oczekuję.
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
I będę zawsze strzegł twego prawa, na wieki wieków.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
A będę chodził drogą przestronną, bo szukam twoich nakazów.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
Owszem, będę mówił o twoich świadectwach przed królami i nie doznam wstydu.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
Będę się rozkoszował twoimi przykazaniami, które umiłowałem.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
Wznoszę też swoje ręce ku twoim przykazaniom, które miłuję, i będę rozmyślał o twoich prawach.
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
Zain Pamiętaj o słowie danym twemu słudze, na którym [to słowie] kazałeś mi polegać.
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
To jest moja pociecha w utrapieniu, bo twoje słowo mnie ożywia.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
Pyszni bardzo się ze mnie naśmiewają, lecz nie odstępuję od twego prawa.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Pamiętam o twoich wiecznych sądach, PANIE, i pocieszam się nimi.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
Strach mnie ogarnął z powodu niegodziwych, którzy porzucają twoje prawo.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
Twoje prawa są dla mnie pieśniami w domu mego pielgrzymowania.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
Nocą wspominam twoje imię, PANIE, i strzegę twego prawa.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
To mam, bo przestrzegam twoich przykazań.
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Het PANIE, [ty jesteś] moim udziałem, przyrzekłem przestrzegać twoich słów.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Modliłem się przed twoim obliczem z całego serca, zlituj się nade mną według twego słowa.
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
Rozmyślałem nad moimi drogami i zwracałem kroki ku twoim świadectwom.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Spieszyłem się i nie zwlekałem z przestrzeganiem twoich przykazań.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Hufce niegodziwych złupiły mnie, [ale] nie zapominam twojego prawa.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
O północy wstaję, aby wysławiać cię za twoje sprawiedliwe sądy.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Jestem przyjacielem wszystkich, którzy boją się ciebie, i tych, którzy przestrzegają twoich przykazań.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
PANIE, ziemia jest pełna twego miłosierdzia; naucz mnie twoich praw.
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
Tet Wyświadczyłeś dobro twemu słudze, PANIE, według twego słowa.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Naucz mnie trafnego sądu i wiedzy, bo uwierzyłem twoim przykazaniom.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Zanim doznałem utrapienia, błądziłem; lecz teraz przestrzegam twego słowa.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Jesteś dobry i czynisz dobro; naucz mnie twoich praw.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
Zuchwali zmyślili przeciwko mnie kłamstwo, [ale] ja całym sercem strzegę twoich przykazań.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Serce ich utyło jak sadło, [ale] ja rozkoszuję się twoim prawem.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
Dobrze to dla mnie, że zostałem uciśniony, abym się nauczył twoich praw.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
Prawo twoich ust [jest] lepsze dla mnie niż tysiące [sztuk] złota i srebra.
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
Jod Twoje ręce mnie uczyniły i ukształtowały; daj mi rozum, abym się nauczył twoich przykazań;
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Bojący się ciebie, widząc mnie, będą się radować, że pokładam nadzieję w twoim słowie.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Wiem, PANIE, że twoje sądy [są] sprawiedliwe i [że] słusznie mnie trapiłeś.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
Proszę cię, niech mnie ucieszy twoje miłosierdzie według twego słowa do twego sługi.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Niech przyjdzie na mnie twoje miłosierdzie, abym żył; bo twoje prawo jest moją rozkoszą.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Niech się zawstydzą zuchwali, bo niesłusznie znieważali mnie, ale ja będę rozmyślać o twoich przykazaniach.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Niech się zwrócą do mnie ci, którzy się boją ciebie, i ci, którzy znają twoje świadectwa.
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Niech moje serce będzie nienaganne w twoich prawach, abym nie doznał wstydu.
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Kaf Moja dusza tęskni do twego zbawienia, pokładam nadzieję w twoim słowie.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
Moje oczy słabną, [czekając] na twoje słowo, gdy mówię: Kiedy mnie pocieszysz?
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Chociaż jestem jak bukłak w dymie, [jednak] nie zapomniałem twoich praw.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
Ile będzie dni twego sługi? Kiedy wykonasz wyrok na tych, którzy mnie prześladują?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
Doły wykopali dla mnie zuchwali, którzy nie postępują według twego prawa.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Wszystkie twoje przykazania są prawdą; bez powodu mnie prześladują; pomóż mi.
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Omal nie zgładzili mnie na ziemi; ja zaś nie porzuciłem twoich przykazań.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
Według twego miłosierdzia ożyw mnie, abym strzegł świadectwa twoich ust.
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
Lamed Na wieki, o PANIE, twoje słowo trwa w niebie.
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
Z pokolenia na pokolenie twoja prawda; ugruntowałeś ziemię i trwa.
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
[Wszystko] trwa do dziś według twego rozporządzenia; to wszystko służy tobie.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
Gdyby twoje prawo nie było moją rozkoszą, dawno zginąłbym w moim utrapieniu.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Nigdy nie zapomnę twoich przykazań, bo nimi mnie ożywiłeś.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Twoim jestem, wybaw mnie, bo szukam twoich przykazań.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Czyhają na mnie niegodziwi, aby mnie stracić, [ale ja] rozważam twoje świadectwa.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
Widziałem koniec wszelkiej doskonałości, [ale] twoje przykazanie jest bezkresne.
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
Mem O, jakże miłuję twoje prawo! Przez cały dzień o nim rozmyślam.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
Czynisz mnie mądrzejszym od moich nieprzyjaciół dzięki twoim przykazaniom, bo mam je zawsze przed sobą.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
Stałem się rozumniejszy od wszystkich moich nauczycieli, bo rozmyślam o twoich świadectwach.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
Jestem roztropniejszy od starszych, bo przestrzegam twoich przykazań.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
Powstrzymuję swoje nogi od wszelkiej drogi złej, abym strzegł twego słowa.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
Nie odstępuję od twoich nakazów, bo ty mnie uczysz.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
O, jakże słodkie są twoje słowa dla mego podniebienia! [Są słodsze] niż miód dla moich ust.
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
Dzięki twoim przykazaniom nabywam rozumu; dlatego nienawidzę wszelkiej ścieżki fałszywej.
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
Nun Twoje słowo jest pochodnią dla moich nóg i światłością na mojej ścieżce.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
Złożyłem przysięgę i wypełnię ją, będę przestrzegał twoich sprawiedliwych nakazów.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
Jestem bardzo strapiony; PANIE, ożyw mnie według słowa twego.
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
PANIE, przyjmij dobrowolne ofiary moich ust i naucz mnie twoich nakazów.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Moja dusza jest stale w niebezpieczeństwie, ale nie zapominam twojego prawa.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Niegodziwi zastawili na mnie sidła, lecz [ja] nie odstępuję od twoich przykazań.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
Wziąłem twoje świadectwa jako wieczne dziedzictwo, bo są radością mego serca.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
Nakłoniłem moje serce, by zawsze wykonywać twoje prawa, aż do końca.
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
Samech Nienawidzę [chwiejnych] myśli, ale miłuję twoje prawo.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Ty jesteś moją ucieczką i tarczą, pokładam nadzieję w twoim słowie.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Odstąpcie ode mnie, złoczyńcy, będę strzegł przykazania mojego Boga.
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Wesprzyj mnie według słowa twego, abym żył, i niech nie doznam wstydu ze względu na moją nadzieję.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Podtrzymaj mnie, a będę wybawiony i będę rozmyślał zawsze o twoich prawach.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Podeptałeś wszystkich, którzy odstępują od twoich praw, bo ich zdrada to fałsz.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
Odrzucasz [jak] żużel wszystkich niegodziwych ziemi; dlatego miłuję twoje świadectwa.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
Moje ciało drży ze strachu przed tobą, bo lękam się twoich sądów.
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
Ajin Sprawowałem sąd i sprawiedliwość; nie wydawaj mnie moim ciemięzcom.
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Bądź poręczycielem dla twego sługi ku dobremu, aby nie uciskali mnie zuchwalcy.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Moje oczy słabną, [czekając] na twoje zbawienie i na słowo twojej sprawiedliwości.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Postąp ze swoim sługą według twego miłosierdzia i naucz mnie twoich praw.
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Jestem twoim sługą, daj mi rozum, abym poznał twoje świadectwa.
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
Już czas, PANIE, abyś działał, [bo] naruszono twoje prawo.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
Dlatego umiłowałem twoje przykazania nad złoto, nad szczere złoto.
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
Bo wszystkie [twoje] przykazania uznaję za prawdziwe, [a] nienawidzę wszelkiej fałszywej drogi.
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
Pe Twoje świadectwa są przedziwne, dlatego moja dusza ich strzeże.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
Początek twoich słów oświeca [i] daje rozum prostym.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
Otwieram usta i wzdycham, bo pragnąłem twoich przykazań.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Spójrz na mnie i zmiłuj się nade mną, jak postępujesz z tymi, którzy miłują twoje imię.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Utwierdź moje kroki w twoim słowie, niech nie panuje nade mną żadna nieprawość.
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Wybaw mnie z ludzkiego ucisku, abym strzegł twoich nakazów.
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Rozjaśnij swe oblicze nad twoim sługą i naucz mnie twoich praw.
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Strumienie wód płyną z mych oczu, bo nie strzegą twego prawa.
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
Cade Sprawiedliwy jesteś, PANIE, i słuszne [są] twoje sądy.
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
Twoje świadectwa, które nadałeś, są sprawiedliwe i bardzo wierne.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Gorliwość pożarła mnie, bo moi nieprzyjaciele zapominają twoje słowa.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
Twoje słowo jest w pełni wypróbowane, dlatego twój sługa je kocha.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Ja jestem mały i wzgardzony, [lecz] nie zapominam twoich przykazań.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
Twoja sprawiedliwość jest sprawiedliwością wieczną, a twoje prawo jest prawdą.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
Ucisk i utrapienie spadły na mnie, lecz twoje przykazania są moją rozkoszą.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
Sprawiedliwość twoich świadectw [trwa] na wieki; daj mi rozum, a będę żył.
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Kof Wołam z całego serca, wysłuchaj mnie, o PANIE, a będę strzegł twoich praw.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
Wołam do ciebie, wybaw mnie, a będę strzegł twoich świadectw.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Wstaję przed świtem i wołam, oczekuję na twoje słowo.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Moje oczy wyprzedzają straże nocne, abym mógł rozmyślać o twoim słowie.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
PANIE, usłysz mój głos według twego miłosierdzia; ożyw mnie według twego wyroku.
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Zbliżają się niegodziwi prześladowcy, są daleko od twego prawa.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
Blisko [jesteś], PANIE, i wszystkie twoje przykazania [są] prawdą.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
Od dawna wiem o twoich świadectwach, że ugruntowałeś je na wieki.
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
Resz Wejrzyj na moje utrapienie i wyzwól mnie, bo nie zapomniałem twojego prawa.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Broń mojej sprawy i wybaw mnie; ożyw mnie według twego słowa.
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
Zbawienie [jest] daleko od niegodziwych, bo nie szukają twoich praw.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Wielka jest twoja litość, PANIE; ożyw mnie według twoich wyroków.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
Liczni są moi prześladowcy i nieprzyjaciele; [lecz] nie uchylam się od twoich świadectw.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
Widziałem przestępców i czułem odrazę, że nie przestrzegali twego słowa.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Patrz, jak miłuję twoje nakazy, PANIE; ożyw mnie według twego miłosierdzia.
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
Podstawą twego słowa [jest] prawda, a wszelki wyrok twojej sprawiedliwości [trwa] na wieki.
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Szin Władcy prześladują mnie bez przyczyny; moje serce zaś boi się twoich słów.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Raduję się z twego słowa jak ten, który znajduje wielki łup.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
Nienawidzę kłamstwa i brzydzę się [nim, ale] miłuję twoje prawo.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
Chwalę cię siedem razy dziennie za twoje sprawiedliwe sądy.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
Wielki pokój dla tych, którzy miłują twoje prawo, a nie doznają żadnego zgorszenia.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
PANIE, oczekuję na twoje zbawienie i zachowuję twoje przykazania.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
Moja dusza przestrzega twoich świadectw, bo bardzo je miłuję.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
Przestrzegam twoich przykazań i świadectw, bo wszystkie moje drogi są przed tobą.
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Taw PANIE, niech dotrze moje wołanie przed twoje oblicze, daj mi zrozumienie według słowa twego.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Niech dojdzie moja prośba przed twoje oblicze, ocal mnie według twojej obietnicy.
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Moje wargi wygłoszą chwałę, gdy nauczysz mnie twoich praw.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
Mój język będzie głosił twoje słowo, bo wszystkie twoje przykazania są sprawiedliwością.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
Niech twoja ręka będzie mi pomocą, [bo] wybrałem twoje przykazania.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
PANIE, pragnę twego zbawienia, a twoje prawo [jest] moją rozkoszą.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
Pozwól mojej duszy żyć, a będzie cię chwalić; niech twoje nakazy będą dla mnie pomocą.
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
Błądzę jak zgubiona owca; szukaj twego sługi, bo nie zapominam twoich przykazań.

< Psalms 119 >