< Psalms 115 >

1 Kì í ṣe fún wa, Olúwa kì í ṣe fún wa, ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ rẹ.
Nicht uns, Jehovah, nicht uns, sondern Deinem Namen gib Herrlichkeit, um Deiner Barmherzigkeit, um Deiner Wahrheit willen!
2 Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà.
Warum sollen die Völkerschaften sagen: Wo ist nun ihr Gott?
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.
Aber unser Gott ist in den Himmeln, Er kann tun, wozu Er Lust hat.
4 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
Ihre Götzenbilder sind Silber und Gold, gemacht von den Händen des Menschen.
5 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀, wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
Einen Mund haben sie und reden nicht, Augen haben sie und sehen nicht;
6 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn.
Ohren haben sie und hören nicht, eine Nase haben sie und riechen nicht;
7 Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.
Ihre Hände, und sie tasten nicht, ihre Füße, und sie gehen nicht, sie sprechen nicht aus ihrer Kehle.
8 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
Wie sie sind die, so sie machen, jeder, der auf sie vertraut.
9 Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn
Israel, vertraue auf Jehovah! Ihr Beistand und ihr Schild ist Er.
10 Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
Haus Aharons, vertrauet auf Jehovah; ihr Beistand und ihr Schild ist Er.
11 Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
Ihr, die ihr Jehovah fürchtet, vertrauet auf Jehovah; ihr Beistand und ihr Schild ist Er.
12 Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli; yóò bùkún ilé Aaroni.
Jehovah gedenkt unser, Er segnet: Er segnet das Haus Israel, Er segnet das Haus Aharons.
13 Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, àti kékeré àti ńlá.
Er segnet die, so Jehovah fürchten, die Kleinen mit den Großen.
14 Olúwa yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Jehovah wird zu euch hinzutun, zu euch und zu euren Söhnen.
15 Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Gesegnet seid ihr dem Jehovah, Der Himmel und Erde gemacht.
16 Ọ̀run àní ọ̀run ni ti Olúwa: ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn.
Die Himmel, die Himmel sind Jehovahs, und die Erde gab Er den Söhnen des Menschen.
17 Òkú kò lè yìn Olúwa, tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́.
Die Toten loben nicht Jah, noch alle, die zur Stille hinabfahren.
18 Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún Olúwa láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. Ẹ yin Olúwa.
Wir aber segnen Jah von nun an und bis in Ewigkeit. Hallelujah!

< Psalms 115 >