< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Wysławiajcie PANA, wzywajcie jego imienia, opowiadajcie jego dzieła wśród narodów.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Śpiewajcie mu, śpiewajcie mu psalmy, rozmawiajcie o wszystkich jego cudach.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Chlubcie się jego świętym imieniem, niech się weseli serce szukających PANA.
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Szukajcie PANA i jego mocy, szukajcie zawsze jego oblicza.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Przypominajcie sobie dzieła, które czynił; jego cuda i wyroki jego ust.
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
[Wy], potomkowie Abrahama, jego słudzy; [wy], synowie Jakuba, jego wybrańcy!
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
On jest PANEM, naszym Bogiem, jego sądy po całej ziemi.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Pamięta wiecznie o swoim przymierzu; o słowie, które nakazał po tysiąc pokoleń;
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
[O przymierzu], które zawarł z Abrahamem, i o przysiędze złożonej Izaakowi.
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Ustanowił je jako prawo dla Jakuba, dla Izraela jako wieczne przymierze;
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
Mówiąc: Tobie dam ziemię Kanaan jako dział waszego dziedzictwa;
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Kiedy ich było niewielu, nieliczni i obcy w niej.
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
I wędrowali od narodu do narodu, z [jednego] królestwa do innego ludu;
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
Nikomu nie pozwolił ich krzywdzić, nawet karcił królów z ich powodu, [mówiąc]:
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
Nie dotykajcie moich pomazańców, a moim prorokom nie czyńcie [nic] złego.
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Potem przywołał głód na ziemię i zniszczył cały zapas chleba.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Posłał przed nimi męża, Józefa, który został sprzedany jako niewolnik;
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
Którego nogi ranili pętami, a w żelazo zakuto jego ciało;
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Aż do [tego] czasu, gdy jego słowo się spełniło, słowo PANA doświadczało go.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Posłał król i kazał go uwolnić, władca narodu wypuścił go na wolność.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Ustanowił go panem swego domu i władcą wszystkich swoich posiadłości;
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Aby rządził jego dostojnikami według swego uznania i jego starszych nauczał mądrości.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Potem Izrael wszedł do Egiptu, a Jakub był gościem w ziemi Chama;
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Gdzie [Bóg] bardzo rozmnożył swój lud i uczynił go potężniejszym od jego wrogów.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Odmienił ich serca, żeby znienawidzili jego lud i postępowali przebiegle wobec jego sług.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Posłał Mojżesza, swego sługę, i Aarona, którego wybrał;
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Pokazali im jego znaki i cuda w ziemi Chama.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Zesłał ciemności i nastał mrok, i nie buntowali się przeciw jego słowu.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Zamienił ich wody w krew i pozabijał ich ryby.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Ich ziemia wydała mnóstwo żab, [były] nawet w komnatach królewskich.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Rozkazał i zjawiły się rozmaite muchy i wszy w całym ich kraju.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Zesłał grad zamiast deszczu, ogień płonący na ich ziemię.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Zniszczył ich winnice i figowce i połamał drzewa w ich kraju.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Rozkazał i zjawiła się szarańcza, niezliczone mnóstwo larw;
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
I pożarły całą zieleń w ich kraju, i zjadły płody ich ziemi.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Zabił też wszystko, co pierworodne w ich ziemi, pierwociny wszelkiej ich siły.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Wyprowadził ich ze srebrem i złotem i nie było słabego wśród ich plemion.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Egipt się radował, gdy wychodzili, bo ogarnął go strach przed nimi.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Rozpostarł obłok jak osłonę, a ogień, by świecił w nocy.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
Na [ich] żądanie zesłał przepiórki i nasycił ich chlebem z nieba.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Otworzył skałę i trysnęły wody, popłynęły po suchych miejscach [jak] rzeka;
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Pamiętał bowiem o swoim świętym słowie i o Abrahamie, swym słudze.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Wyprowadził swój lud wśród wesela, swoich wybranych wśród radości.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
I dał im ziemię pogan, i zawładnęli dorobkiem narodów;
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Aby zachowywali jego nakazy i przestrzegali jego praw. Alleluja.

< Psalms 105 >