< Proverbs 3 >

1 Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi. Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
Synu mój, nie zapominaj mego prawa, a niech twoje serce strzeże moich przykazań;
2 Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà, ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.
Bo przyniosą ci długie dni i lata życia oraz pokoju.
3 Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ, kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
Niech cię nie opuszczają miłosierdzie i prawda, przywiąż je do swojej szyi, wypisz je na tablicy swojego serca.
4 Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.
Wtedy znajdziesz łaskę i uznanie w oczach Boga i ludzi.
5 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.
Ufaj PANU z całego swego serca i nie polegaj na swoim rozumie.
6 Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.
Zważaj na niego we wszystkich swoich drogach, a on będzie prostować twoje ścieżki.
7 Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
Nie bądź mądrym we własnych oczach, [ale] bój się PANA i odstąp od zła.
8 Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ àti okun fún àwọn egungun rẹ.
[To] da twemu ciału zdrowie i pokrzepienie twoim kościom.
9 Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa, pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ,
Czcij PANA swoim majątkiem i pierwocinami wszystkich twoich dochodów.
10 nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
A twoje spichrze będą napełnione dostatkiem i twoje prasy będą przelewać się od nowego wina.
11 Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
Synu mój, nie gardź karceniem PANA i nie zniechęcaj się jego upomnieniem.
12 nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
Bo kogo PAN miłuje, tego karze, jak ojciec syna, [którego] kocha.
13 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀, ẹni tí ó tún ní òye sí i,
Błogosławiony człowiek, który znajduje mądrość, i człowiek, który nabiera rozumu;
14 nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
Gdyż jego nabycie jest lepsze niż nabycie srebra, jego zdobycie [bardziej pożyteczne] niż złoto.
15 Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ; kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
Jest droższa nad perły i żadna rzecz, której pragniesz, nie dorówna jej.
16 Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
Długie dni są w jej prawej ręce, a w lewej bogactwa i chwała.
17 Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura, òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
Jej drogi są drogami rozkoszy i wszystkie jej ścieżki spokojne.
18 Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á; àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.
Jest drzewem życia dla tych, którzy się jej chwycą; a ci, którzy się jej trzymają, są błogosławieni.
19 Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
PAN ugruntował ziemię mądrością, a niebiosa umocnił rozumem.
20 nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà, àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.
Dzięki jego wiedzy rozstąpiły się głębiny, a obłoki spuszczają rosę.
21 Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́, má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
Synu mój, niech [one] ci [z] oczu nie schodzą; strzeż prawdziwej mądrości i roztropności;
22 Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ, àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
A będą życiem twojej duszy i ozdobą twojej szyi.
23 Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu, ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀.
Wtedy będziesz bezpiecznie chodził swoją drogą, a noga twoja się nie potknie.
24 Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù, nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
Gdy się położysz, nie będziesz się lękał; a gdy zaśniesz, twój sen będzie przyjemny.
25 Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì, tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
Nie lękaj się nagłego strachu ani spustoszenia niegodziwych, gdy przyjdzie.
26 Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ, kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.
PAN bowiem będzie twoją ufnością i twojej nogi będzie strzegł od sideł.
27 Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ, nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
Nie wzbraniaj się dobrze czynić potrzebującemu, gdy stać cię na to, aby [dobrze] czynić.
28 Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé, “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,” nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
Nie mów bliźniemu: Idź i przyjdź znowu, dam ci jutro, gdy masz to u siebie.
29 Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ, ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
Nie knuj zła przeciwko swemu bliźniemu, gdy spokojnie mieszka obok ciebie.
30 Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí, nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.
Nie spieraj się z człowiekiem bez przyczyny, jeśli ci nic złego nie wyrządził.
31 Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Nie zazdrość ciemięzcy i nie wybieraj żadnej z jego dróg.
32 Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
Przewrotny bowiem budzi w PANU odrazę, ale jego tajemnica [jest] z prawymi.
33 Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
Przekleństwo PANA [jest] w domu niegodziwego, lecz [PAN] błogosławi mieszkanie sprawiedliwych.
34 Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́, ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
On szydzi z szyderców, ale daje łaskę pokornym.
35 Ọlọ́gbọ́n jogún iyì, ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.
Mądrzy odziedziczą chwałę, a głupi poniosą hańbę.

< Proverbs 3 >